< Ezekiel 6 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé,
A palavra de Javé veio a mim, dizendo:
2 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn òkè Israẹli; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí wọn
“Filho do homem, dirige teu rosto para as montanhas de Israel, e profetiza para elas,
3 wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ẹ̀yin òkè ńlá àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn odò ṣíṣàn àti sí àfonífojì, èmi yóò mú idà wa sórí yín, èmí yóò sì pa ibi gíga yín run.
e diz: 'Vós, montanhas de Israel, escutai a palavra do Senhor Javé! O Senhor Javé diz às montanhas e às colinas, aos cursos de água e aos vales: “Eis que eu, eu mesmo, trarei uma espada sobre vós e destruirei vossos lugares altos”.
4 Èmi yóò wó pẹpẹ yín lulẹ̀, èmi yóò sì fọ́ pẹpẹ tùràrí yín túútúú; èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn yín síwájú àwọn òrìṣà wọn.
Seus altares se tornarão desolados, e seus altares de incenso serão quebrados”. Eu derrubarei seus homens mortos diante de seus ídolos”.
5 Èmi yóò tẹ́ òkú àwọn ará Israẹli síwájú òrìṣà wọn, èmi yóò sì fọ́n egungun wọn yí pẹpẹ wọn ká.
Depositarei os cadáveres dos filhos de Israel diante de seus ídolos. Espalharei seus ossos ao redor de seus altares.
6 Gbogbo ibi tí ẹ ń gbé àti àwọn ibi gíga yín ni yóò di píparun, gbogbo pẹpẹ yín ni yóò di ahoro, àwọn òrìṣà yín yóò di fífọ́ túútúú, àwọn pẹpẹ tùràrí yín ni a ó gé lulẹ̀, gbogbo iṣẹ́ yín yóò parẹ́.
Em todos os seus lugares de moradia, as cidades serão assoladas e os lugares altos serão desolados, para que seus altares sejam assolados e desolados, e seus ídolos sejam quebrados e cessem, e seus altares de incenso sejam cortados, e suas obras sejam abolidas.
7 Àwọn ènìyàn yín yóò ṣubú láàrín yín, ẹ ó sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Os mortos cairão entre vocês e vocês saberão que eu sou Yahweh.
8 “‘Ṣùgbọ́n èmi yóò dá àwọn kan sí nítorí pé díẹ̀ nínú yín ni yóò bọ́ lọ́wọ́ idà, nígbà tí a bá fọ́n yín ká sí gbogbo ilẹ̀ àti orílẹ̀-èdè.
“““No entanto, deixarei um remanescente, na medida em que você terá alguns que escapam da espada entre as nações, quando você estiver espalhado pelos países.
9 Àwọn ti ó bọ́ nínú yin yóò sì rántí mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè níbi tí wọn yóò dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ, nítorí wọ́n yóò máa rántí mi bí wọ́n ti bà mí lọ́kàn jẹ́ nípa àgbèrè wọn, tí ó yà wọ́n kúrò lọ́dọ̀ mi àti nípa ojú wọn tí ó ṣàfẹ́rí àwọn òrìṣà. Wọn yóò sì ṣú ara wọn nítorí ìwà ibi tí wọ́n ti hù nípa gbogbo ìríra wọn.
Aqueles de vocês que escaparem se lembrarão de mim entre as nações onde são levados cativos, como fui quebrado com seu coração lascivo, que se afastou de mim, e com seus olhos, que se fazem de prostituta depois de seus ídolos”. Então eles se abominarão aos seus próprios olhos pelos males que cometeram em todas as suas abominações.
10 Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; àti pé kì í ṣe lásán ni mo ń lérí pé èmi yóò mú ìdààmú bá wọn.
Eles saberão que eu sou Yahweh. Eu não disse em vão que lhes faria este mal”.
11 “‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, Pàtẹ́wọ́ kí o tún fẹsẹ̀ janlẹ̀, kí o wá kígbe síta pé, “Ó ṣe!” Ilé Israẹli yóò ṣubú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn nítorí gbogbo ìwà ìríra búburú tí wọ́n hù. Wọn yóò ṣubú nípa idà àti ìyàn.
“O Senhor Javé diz: 'Golpeia com tua mão, e carimba com teu pé, e diz: “Ai de mim!”, por causa de todas as abominações malignas da casa de Israel; pois elas cairão pela espada, pela fome, e pela peste.
12 Ẹni tó wà lókèèrè yóò kú pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, àti ẹni tó wà nítòsí yóò ṣubú pẹ̀lú idà, ìyàn ni yóò pa ẹni tó bá ṣẹ́kù sílẹ̀. Báyìí ni èmi yóò ṣe mú ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn.
Aquele que está longe morrerá da peste. Aquele que está próximo cairá pela espada. Aquele que ficar e for sitiado morrerá pela fome. Assim, eu cumprirei minha ira sobre eles.
13 Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí òkú àwọn ènìyàn wọn bá wà níbẹ̀ láàrín òrìṣà wọn yí pẹpẹ wọn ká, lórí àwọn òkè gíga gbogbo, àti lórí góńgó òkè àti lábẹ́ igi tútù àti lábẹ́ igi óákù, níbi tí wọ́n ti ń fi tùràrí olóòórùn dídùn rú ẹbọ sí gbogbo òrìṣà wọn.
Você saberá que eu sou Yahweh quando seus homens mortos estiverem entre seus ídolos ao redor de seus altares, em cada colina alta, em todos os cumes das montanhas, debaixo de cada árvore verde e debaixo de cada carvalho grosso - os lugares onde eles ofereciam aroma agradável a todos os seus ídolos.
14 Èmi yóò na ọwọ́ mi jáde sí wọn láti mú kí ilẹ̀ náà ṣòfò, kí ó sì dahoro dé aṣálẹ̀ ìhà Dibila—ní gbogbo ibùgbé wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Estenderei minha mão sobre eles e tornarei a terra desolada e desperdiçada, desde o deserto até Dibla, em todas as suas habitações. Então eles saberão que eu sou Yahweh”.

< Ezekiel 6 >