< Lamentations 1 >

1 Báwo ni ìlú ṣe jókòó nìkan, nígbà kan tí ó sì kún fún ènìyàn! Ó ti fìgbà kan jẹ́ ìlú olókìkí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó wà ní ipò opó, ẹni tí ó jẹ́ ọmọ ọbabìnrin láàrín ìlú ni ó padà di ẹrú.
Como a cidade é solitária, que estava cheio de gente! Ela se tornou viúva, que foi grande entre as nações! Ela que foi uma princesa entre as províncias tornou-se um escravo!
2 Ọ̀gànjọ́ òru ni ó fi máa ń sọkún kíkorò pẹ̀lú omijé ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ tí ó dúró sí ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀. Nínú gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ọ̀kan nínú wọn láti rẹ̀ ẹ́ lẹ́kún. Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ ti jọ̀wọ́ rẹ̀ wọ́n ti di alátakò rẹ̀.
She chora amargamente durante a noite. Suas lágrimas estão em suas bochechas. Entre todos os seus amantes ela não tem ninguém que a conforte. Todos os seus amigos lidaram traiçoeiramente com ela. Eles se tornaram seus inimigos.
3 Lẹ́yìn ìjìyà àti ìpọ́njú nínú oko ẹrú, Juda lọ sí àjò Ó tẹ̀dó láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n kò rí ibi ìsinmi. Àwọn tí ó ń tẹ̀lé ká á mọ́ ibi tí kò ti le sá àsálà.
Judah foi para o cativeiro por causa da aflição e por causa de uma grande servidão. Ela mora entre as nações. Ela não encontra descanso. Todos os seus perseguidores a ultrapassaram em sua angústia.
4 Gbogbo ọ̀nà tí ó wọ Sioni ń ṣọ̀fọ̀, nítorí ẹnìkan kò wá sí àjọ̀dún tí a yàn. Gbogbo ẹnu-bodè rẹ̀ dahoro, àwọn àlùfáà rẹ̀ kẹ́dùn, àwọn wúńdíá rẹ̀ sì ń káàánú, òun gan an wà ní ọkàn kíkorò.
Os caminhos para Zion lamentam, porque ninguém comparece à assembléia solene. Todos os seus portões estão desolados. Seus padres suspiram. Suas virgens são afligidas, e ela mesma está em amargura.
5 Àwọn aninilára rẹ̀ gbogbo di olúwa rẹ̀, nǹkan sì rọrùn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀, Olúwa ti fún un ní ìjìyà tó tọ́ nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Àwọn ẹ̀ṣọ́ wẹ́wẹ́ rẹ̀ lọ sí oko ẹrú, ìgbèkùn níwájú àwọn ọ̀tá.
Seus adversários se tornaram a cabeça. Seus inimigos prosperam; pois Yahweh a afligiu pela multidão de suas transgressões. Seus filhos pequenos foram para o cativeiro diante do adversário.
6 Gbogbo ẹwà ti di ohun ìgbàgbé kúrò lọ́dọ̀ ọmọbìnrin Sioni. Àwọn ìjòyè rẹ̀ dàbí i àgbọ̀nrín tí kò rí ewé tútù jẹ; nínú àárẹ̀ wọ́n sáré níwájú ẹni tí ó ń lé wọn.
Toda majestade partiu da filha de Sião. Seus príncipes se tornaram como veados que não encontram pasto. Eles ficaram sem forças diante do perseguidor.
7 Ní ọjọ́ ìpọ́njú àti àrìnká rẹ̀ ni Jerusalẹmu rántí àwọn ohun ìní dáradára rẹ̀ tí ó jẹ́ tirẹ̀ ní ọjọ́ pípẹ́. Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ṣubú ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá, kò sì ṣí olùrànlọ́wọ́ fún un. Àwọn ọ̀tá rẹ̀ wò ó wọ́n sì ń fi ìparun rẹ̀ ṣẹlẹ́yà.
Jerusalém lembra-se nos dias de sua aflição e de suas misérias todas as suas coisas agradáveis que eram dos dias de antigamente; quando seu povo caiu nas mãos do adversário, e ninguém a ajudou. Os adversários a viram. Eles zombaram de suas desolações.
8 Jerusalẹmu sì ti dẹ́ṣẹ̀ púpọ̀ ó sì ti di aláìmọ́. Àwọn tí ó ń tẹríba fún un sì kẹ́gàn rẹ̀, nítorí wọ́n ti rí ìhòhò rẹ̀; ó kérora fúnra rẹ̀, ó sì lọ kúrò.
Jerusalém pecou gravemente. Portanto, ela se tornou impura. Todos os que a honraram a desprezam, porque eles viram sua nudez. Sim, ela suspira e se vira para trás.
9 Ìdọ̀tí wà ní etí aṣọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò wo ọjọ́ iwájú rẹ̀. Ìṣubú rẹ̀ ya ni lẹ́nu; olùtùnú kò sì ṣí fún un. “Wo ìpọ́njú mi, Olúwa, nítorí àwọn ọ̀tá ti borí.”
Sua sujeira estava em suas saias. Ela não se lembrava de seu último fim. Portanto, ela desceu espantosamente. Ela não tem confortador. “Veja, Yahweh, minha aflição; pois o inimigo se engrandeceu”.
10 Ọ̀tá ti gbọ́wọ́ lé gbogbo ìní rẹ; o rí pé àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n wọ ibi mímọ́ rẹ— àwọn tí o ti kọ̀sílẹ̀ láti wọ ìpéjọpọ̀ rẹ.
O adversário estendeu sua mão sobre todas as coisas agradáveis dela; pois ela viu que as nações entraram em seu santuário, sobre quem o senhor ordenou que não entrassem em sua assembléia.
11 Àwọn ènìyàn rẹ̀ ń kérora bí wọ́n ti ń wá oúnjẹ; wọ́n fi ohun ìní wọn ṣe pàṣípàrọ̀ oúnjẹ láti mú wọn wà láààyè. “Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó, nítorí a kọ̀ mí sílẹ̀.”
Todo o seu povo suspira. Eles procuram o pão. Eles deram suas coisas agradáveis para que a comida refresque sua alma. “Olhe, Yahweh, e veja, pois eu me tornei desprezado”.
12 “Kò ha jẹ́ nǹkan kan sí i yín? Gbogbo ẹ̀yin tí ń rékọjá. Ǹjẹ́ ẹnìkan ń jìyà bí èmi ti ń jìyà tí a fi fún mi, ti Olúwa mú wá fún mi ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ̀.
“Não é nada para vocês, todos vocês que passam por aqui? Veja, e veja se há alguma tristeza como a minha tristeza, que é trazido sobre mim, com o qual Yahweh me afligiu no dia de sua raiva feroz.
13 “Ó rán iná láti òkè sọ̀kalẹ̀ sínú egungun ara mi. Ó dẹ àwọ̀n fún ẹsẹ̀ mi, ó sì yí mi padà. Ó ti pa mí lára mó ń kú lọ ní gbogbo ọjọ́.
“Do alto, ele mandou fogo aos meus ossos, e prevalece contra eles. Ele espalhou uma rede para os meus pés. Ele me fez voltar atrás. Ele me deixou desolado e eu desmaiei o dia inteiro.
14 “Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti di sísopọ̀ sí àjàgà; ọwọ́ rẹ̀ ni a fi hun ún papọ̀. Wọ́n ti yí ọrùn mi ká Olúwa sì ti dín agbára mi kù. Ó sì ti fi mí lé àwọn tí n kò le dojúkọ lọ́wọ́.
“O jugo de minhas transgressões está preso por sua mão. Eles são tricotados juntos. Eles subiram no meu pescoço. Ele fez minha força falhar. O Senhor me entregou em suas mãos, contra quem eu não sou capaz de ficar de pé.
15 “Olúwa kọ àwọn akọni mi sílẹ̀, ó rán àwọn ológun lòdì sí mi kí wọn pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mi run. Nínú ìfúntí wáìnì rẹ̀ Olúwa tẹ́ àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Juda.
“O Senhor não pôs em nada todos os meus poderosos homens dentro de mim. Ele convocou uma assembléia solene contra mim para esmagar meus jovens. O Senhor pisou a filha virgem de Judá como num lagar de vinho.
16 “Ìdí nìyí tí mo fi ń sọkún tí omijé sì ń dà lójú mi. Olùtùnú àti ẹni tí ó le mú ọkàn mi sọjí jìnnà sí mi, kò sí ẹni tí yóò dá ẹ̀mí mi padà. Àwọn ọmọ mi di aláìní nítorí ọ̀tá ti borí.”
“Por estas coisas eu choro. Meu olho, meu olho escorre com água, porque o consolador que deveria refrescar minha alma está longe de mim. Meus filhos estão desolados, porque o inimigo tem prevalecido”.
17 Sioni na ọwọ́ jáde, ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún un. Olúwa ti pàṣẹ fún Jakọbu pé àwọn ará ilé rẹ̀ di ọ̀tá fún un Jerusalẹmu ti di ohun aláìmọ́ láàrín wọn.
Zion estende suas mãos. Não há ninguém para confortá-la. Yahweh comandou em relação a Jacob, que aqueles que estão ao seu redor devem ser seus adversários. Jerusalém está entre eles como uma coisa impura.
18 “Olóòtítọ́ ni Olúwa, ṣùgbọ́n mo ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀. Ẹ gbọ́, gbogbo ènìyàn; ẹ wò mí wò ìyà mi. Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi ni a ti kó lọ sí ìgbèkùn.
“Yahweh é justo, pois eu me revoltei contra seu mandamento. Por favor, ouçam todos vocês, povos, e ver minha tristeza. Minhas virgens e meus jovens foram para o cativeiro.
19 “Mo pe àwọn ọ̀rẹ́ mi ṣùgbọ́n wọ́n dà mí. Àwọn olórí àlùfáà àti àgbàgbà mi ṣègbé sínú ìlú nígbà tí wọ́n ń wá oúnjẹ tí yóò mú wọn wà láààyè.
“Eu chamei por meus amantes, mas eles me enganaram. Meus sacerdotes e meus anciãos desistiram do espírito na cidade, enquanto procuravam alimento para si mesmos para refrescar suas almas.
20 “Olúwa, wò ó, bí mo ti wà nínú ìnira! Tí mo sì ń jẹ̀rora nínú mi, ìdààmú dé bá ọkàn mi nítorí pé a ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi gidigidi. Ní gbangba ni idà ń parun; ikú wà nínú ilé pẹ̀lú.
“Olha, Yahweh; pois estou em apuros. Meu coração está perturbado. Meu coração se vira dentro de mim, pois eu me revoltei gravemente. No exterior, a espada enlutouce. Em casa, é como a morte.
21 “Àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìrora mi, ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún mi. Àwọn ọ̀tá mi ti gbọ́ ìparun mi; wọ́n yọ̀ sí ohun tí o ṣe. Kí o mú ọjọ́ tí o ti kéde, kí wọ́n le dàbí tèmi.
“Eles ouviram que eu suspiro. Não há ninguém para me confortar. Todos os meus inimigos já ouviram falar do meu problema. Eles estão felizes que você tenha feito isso. Você trará o dia que você proclamou, e eles serão como eu.
22 “Jẹ́ kí ìwà ìkà wọn wá síwájú rẹ; jẹ wọ́n ní yà bí o ṣe jẹ mí ní yà nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi. Ìrora mi pọ̀ ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.”
“Que toda a maldade deles venha à sua frente. Faça com eles o que você fez comigo por todas as minhas transgressões. Pois os meus suspiros são muitos, e meu coração está desmaiado.

< Lamentations 1 >