< Ezekiel 39 >

1 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí Gogu, kí ó sì wí pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, Ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé ti Meṣeki àti Tubali.
«Əmdi sǝn, i insan oƣli, Gogni ǝyiblǝp bexarǝt berip xundaⱪ degin: — Rǝb Pǝrwǝrdigar xundaⱪ dǝydu: — Mana, i Gog, — Rox, Mǝxǝk wǝ Tubalning ǝmiri, Mǝn sanga ⱪarximǝn;
2 Èmi yóò dá ọ padà, èmi yóò sì darí rẹ. Èmi yóò mú ọ wá láti jìnnàjìnnà ìhà àríwá, Èmi yóò rán ọ lòdì sí orí àwọn òkè gíga Israẹli.
Mǝn seni arⱪingƣa yandurup, yetkilǝp, seni ximalning ǝng ⱪǝridin qiⱪirimǝn, Israilning taƣliri üstigǝ tajawuz ⱪildurimǝn;
3 Nígbà náà èmi yóò lu ọrùn awọ rẹ ní ọwọ́ òsì rẹ, èmi yóò sì mú kí àwọn ọfà rẹ jábọ́ ni ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
Mǝn oⱪyayingni sol ⱪolungdin urup taxliƣuziwetimǝn, oⱪliringni ong ⱪolungdin qüxüriwetimǝn;
4 Ìwọ yóò sì ṣubú ní orí àwọn òkè Israẹli, ìwọ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn onírúurú ẹyẹ àti fún àwọn ẹranko igbó.
sǝn Israil taƣlirining üstigǝ yiⱪilisǝn; sǝn wǝ sening barliⱪ ⱪoxunliring, sanga ⱨǝmraⱨ bolƣan ǝllǝr yiⱪilisilǝr; Mǝn seni barliⱪ yirtⱪuq uqar-ⱪanatlarƣa gɵx, daladiki barliⱪ ⱨaywanlarƣa ow boluxⱪa tǝⱪdim ⱪildim.
5 Ìwọ yóò ṣubú ní gbangba pápá, nítorí tì mo ti sọ̀rọ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Sǝn dalada yiⱪilisǝn; qünki Mǝn xundaⱪ sɵz ⱪildim, — dǝydu Rǝb Pǝrwǝrdigar.
6 Èmi yóò fi iná sí Magogu àti sí àwọn tí ń gbé ní agbègbè ilẹ̀ ibẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
Mǝn Magog üstigǝ wǝ dengiz boyida aman-esǝn turƣanlarƣa ot yaƣdurimǝn; ular Mening Pǝrwǝrdigar ikǝnlikimni tonup yetidu.
7 “‘Èmi yóò sọ orúkọ mímọ́ mí di mí mọ̀ láàrín àwọn ènìyàn mì Israẹli. Èmi ki yóò jẹ́ kí orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́ àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, Èmi ni ẹni mímọ́ ní Israẹli.
Mening pak-muⱪǝddǝs namimni hǝlⱪim Israil arisida tonutimǝn; pak-muⱪǝddǝs namimning ⱪaytidin bulƣinixⱪa ⱪǝt’iy yol ⱪoymaymǝn; ǝllǝr Mening Pǝrwǝrdigar, Israilda turƣan Muⱪǝddǝs Bolƣuqisi ikǝnlikimni bilip yetidu.
8 Ó ń bọ̀! Ó dájú pé yóò ṣẹlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè. Èyí yìí ni ọjọ́ tí mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.
Mana, u kelidu! Bu ixlar qoⱪum bolidu, — dǝydu Rǝb Pǝrwǝrdigar, — bu dǝl Mǝn eytⱪan künidur.
9 “‘Nígbà náà, àwọn ti ó ń gbé nì àárín àwọn ìlú tí ó wà ni Israẹli yóò jáde, wọn yóò sì lo àwọn ohun ìjà bi epo ìdáná yóò sì jó wọ́n kanlẹ̀—àpáta kéékèèké àti àpáta ńlá, àwọn ọfà, àwọn kùmọ̀ ogun àti ọ̀kọ̀ fún ọdún méje wọn yóò lò wọ́n bi epo ìdáná.
Israil xǝⱨǝrliridǝ turuwatⱪanlar qiⱪip ⱪorallarni, jümlidin sipar-ⱪalⱪanlar, oⱪyalar, toⱪmaⱪlar wǝ nǝyzilǝrni kɵydürüp ot ⱪalaydu — ular bular bilǝn yǝttǝ yil ot ⱪalaydu.
10 Wọn kò ní nílò láti kó igi jọ láti inú pápá, tàbí gé e láti inú igbó, nítorí pé wọ́n yóò lo òhun ìjà ogun bi epo ìdáná. Wọn yóò sì kógun àwọn tí ó ṣe ìgárá sí wọn, wọn yóò sì bo ilé àwọn tí ó bo ilé wọn, ni Olúwa Olódùmarè.
Daladin ⱨeq otun elinmaydu, ormanlardin ⱨeq yaƣaq kesilmǝydu; qünki ular ⱪorallarni ot ⱪalaxⱪa ixlitidu; ular ɵzliridin olja tutⱪanlarni olja tutidu, ɵzlirini bulang-talang ⱪilƣanlarni bulang-talang ⱪilidu, — dǝydu Rǝb Pǝrwǝrdigar.
11 “‘Ní ọjọ́ náà èmi yóò sì fi ibi ìsìnkú fún Gogu ní Israẹli, ni àfonífojì àwọn ti ó rìn ìrìnàjò lọ sí agbègbè ilà oòrùn Òkun. Yóò di ojú ọ̀nà àwọn arìnrìn-àjò, nítorí Gogu àti gbogbo ìjọ rẹ̀ ni àwa yóò sin síbẹ̀. Nítorí náà, a yóò pè é ní àfonífojì tí Ammoni Gogu.
Wǝ xu künidǝ xundaⱪ boliduki, Israil zeminidin, yǝni dengizning xǝrⱪiy ⱪirƣiⱪidin ɵtidiƣanlarning jilƣisidin Gogⱪa bir yǝrlik boluxi üqün bir orunni berimǝn; bu yǝrlik bolsa ɵtküqilǝrning yolini tosidu; ular xu yǝrdǝ Gog wǝ uning barliⱪ top-top adǝmlirini kɵmidu; u «Ⱨamon-Gog jilƣisi» dǝp atilidu.
12 “‘Fún oṣù méje ní ilé Israẹli yóò fi máa sìn wọ́n láti ṣe àfọ̀mọ́ ilẹ̀ náà.
Israil jǝmǝti zeminini ⱨalal ⱪilix üqün, ularni yǝttǝ ay kɵmidu;
13 Gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà yóò sìn wọ́n, ọjọ́ tí a yìn mi lógo yóò jẹ́ ọjọ́ ìrántí, ní Olúwa Olódùmarè wí.
zemindiki barliⱪ hǝlⱪ ularni yǝrlikkǝ ⱪoyidu; xuning bilǝn Ɵzüm uluƣlanƣan muxu künidǝ bu ix ularƣa xǝrǝp bolidu, — dǝydu Rǝb Pǝrwǝrdigar.
14 “‘Wọn yóò gbà àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ lóòrèkóòrè láti ṣe àfọ̀mọ́ náà. Ọ̀pọ̀ yóò lọ káàkiri ilẹ̀ náà, ní àfikún pẹ̀lú wọn, àwọn tókù yóò sìn àwọn tí ó kú lórí ilẹ̀. Ní ìparí oṣù keje wọn yóò bẹ̀rẹ̀ wíwá kiri wọn.
Ular birnǝqqǝ adǝmni zeminni dawamliⱪ arilap, tajawuzqilarning zemin yüzidǝ ⱪalƣan jǝsǝtlirini kümüxtǝk alaⱨidǝ ixni ⱪilix üqün ayriydu; ular xu yǝttǝ ay tügigǝndǝ, andin jǝsǝtlǝrni izdǝx hizmitini baxlaydu.
15 Bí wọ́n n lọ káàkiri ilẹ̀ náà ọ̀kan nínú wọn rí egungun ènìyàn, òun yóò gbé àmì ńlá kalẹ̀ ni ẹ̀gbẹ́ rẹ títí àwọn asìnkú yóò fi sìn ín ní àfonífojì Hamoni Gogu.
Bu «zemindin ɵtküqilǝr» aylinip yüridu; ǝgǝr birsi adǝmning ustihinini kɵrgǝn bolsa, u uning yeniƣa bir bǝlgǝ tiklǝydu; «izdǝp kɵmgüqilǝr» uni Ⱨamon-Gog jilƣisiƣa dǝpnǝ ⱪilƣuqǝ bǝlgǝ turidu
16 Bákan náà ìlú kan tí a ń pè ni Hamona yóò wà níbẹ̀. Nítorí náà wọn yóò wẹ ilẹ̀ náà.’
([jilƣida] «Ⱨamonaⱨ» dǝp atalƣan bir xǝⱨǝr bolidu). Ular xu yol bilǝn zeminni paklaydu».
17 “Ọmọ ènìyàn èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí pé, pe gbogbo oríṣìíríṣìí ẹyẹ àti gbogbo àwọn ẹranko igbó jáde, ‘Kí wọn péjọpọ̀ láti gbogbo agbègbè sí ìrúbọ tí mó ń múra rẹ̀ fún ọ, ìrúbọ ńlá náà ní orí òkè gíga tí Israẹli. Níbẹ̀ ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀.
— «Wǝ sǝn, i insan oƣli, Rǝb Pǝrwǝrdigar xundaⱪ dǝydu: — Ⱨǝrⱪandaⱪ uqar-ⱪanatlar, daladiki barliⱪ ⱨaywanlarƣa mundaⱪ degin: «Yiƣilixip kelinglar, Mǝn silǝrgǝ ⱪilmaⱪqi bolƣan ⱪurbanliⱪimƣa, yǝni Israil taƣliri üstidǝ ⱪilinƣan qong ⱪurbanliⱪⱪa ⱨǝryandin jǝm bolunglar! Silǝr xu yǝrdǝ gɵx yǝp, ⱪan iqisilǝr.
18 Ẹ̀yin yóò jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn ńlá, ẹ o sì mú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ-aládé ayé bí ẹni pé wọn jẹ́ àgbò àti ọ̀dọ́-àgùntàn, ewúrẹ́ àti akọ màlúù gbogbo wọn jẹ́ ẹran ọlọ́ràá láti Baṣani.
Silǝr baturlarning gɵxini, yǝr yüzidiki xaⱨzadilarning ⱪenini — ⱪoqⱪarlarning, ɵqkilǝrning, torpaⱪlarning ⱪenini iqisilǝr — ularning ⱨǝmmisi Baxandiki bordalƣan mallardur!
19 Níbi ìrúbọ tí mo ń múra kalẹ̀ fún yín, ẹ̀yin yóò jẹ ọ̀rá títí ẹ̀yin yóò fi jẹ àjẹkì, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ títí ẹ̀yin yóò fi yó.
Silǝr Mǝn silǝrgǝ ⱪilmaⱪqi bolƣan ⱪurbanliⱪimdin, toyƣuqǝ may yǝp, toyƣuqǝ ⱪan iqisilǝr!
20 Ní orí tábìlì mi ni àwa yóò ti fi ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin bọ yín yó, pẹ̀lú àwọn alágbára ńlá àti oríṣìíríṣìí jagunjagun,’ ni Olúwa Olódùmarè wí.
Silǝr dastihinimda atlar wǝ jǝng ⱨarwisidikilǝr, baturlar, barliⱪ jǝngqi palwanlar bilǝn toyunisilǝr» — dǝydu Rǝb Pǝrwǝrdigar.
21 “Èmi yóò ṣe àfihàn ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì rí ìyà tí mo fi jẹ wọ́n.
— wǝ Mǝn Ɵz xan-xǝripimni ǝllǝr arisiƣa kɵrsitimǝn, barliⱪ ǝllǝr Mening yürgüzgǝn jazalirimni wǝ ularning üstigǝ ⱪoyƣan ⱪolumni kɵridu.
22 Láti ọjọ́ náà lọ, ilé Israẹli yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.
Wǝ xu kündin tartip Israil jǝmǝti Mening Pǝrwǝrdigar, ularning Hudasi ikǝnlikimni bilip yetidu.
23 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì mọ̀ pé àwọn ènìyàn Israẹli lọ sí ìgbèkùn nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí pé wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi. Nítorí náà mo mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, mo sì fi wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, gbogbo wọn sì ṣubú nípasẹ̀ idà.
Əllǝr Israil jǝmǝtining ⱪǝbiⱨliki, Manga asiyliⱪ ⱪilƣanliⱪi tüpǝylidin sürgün bolƣanliⱪini bilip yetidu; mana, Mǝn yüzümni ulardin yoxurup, ularni düxmǝnlirining ⱪoliƣa tapxurdum; ularning ⱨǝmmisi ⱪiliqlinip yiⱪildi.
24 Mo ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí àìmọ́ àti àìṣedéédéé wọn, mo sì mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Ularning paskiniqiliⱪi wǝ asiyliⱪliri boyiqǝ Mǝn ularni bir tǝrǝp ⱪildim, yüzümni ulardin yoxurdum».
25 “Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Jakọbu padà kúrò ní oko ẹrú, èmi yóò ní ìyọ́nú si gbogbo ènìyàn Israẹli, èmi yóò sì ní ìtara fún orúkọ mímọ́ mi.
Xunga Rǝb Pǝrwǝrdigar xundaⱪ dǝydu: — Mǝn ⱨazir Yaⱪupni sürgün bolƣanliⱪidin ǝsligǝ ⱪayturup, pütkül Israil jǝmǝti üstigǝ rǝⱨim ⱪilip, Ɵz pak-muⱪǝddǝs namim üqün otluⱪ ⱪizƣinliⱪimni kɵrsitimǝn.
26 Wọn yóò gbàgbé ìtìjú wọn àti gbogbo àìṣòdodo tí wọ́n fihàn sí mi nígbà tí wọn ń gbé ni àìléwu ni ilẹ̀ wọn níbi tí kò ti sí ẹnikẹ́ni láti dẹ́rùbà wọ́n.
Ɵz zeminida aman-esǝn turƣinida, ⱨeqkim ularni ⱪorⱪutmaydiƣan qaƣ kǝlgǝndǝ, Mǝn ularni ǝllǝrdin ⱪayturup, düxmǝnlirining zeminliridin yiƣⱪinimda, wǝ kɵp ǝllǝrning kɵz aldida Ɵzümning pak-muⱪǝddǝs ikǝnlikimni kɵrsǝtkinimdǝ, xu qaƣda ular hijalitini wǝ Mǝndin yüz ɵrüp ⱪilƣan asiyliⱪining barliⱪ gunaⱨini kɵtüridu;
27 Nígbà tí mo ti mú wọn padà kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì kó wọn jọ pọ̀ kúrò ni ìlú àwọn ọ̀tá wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ wọn ní ojú àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀.
28 Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn nítorí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo rán wọn lọ sí ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò kó wọn jọ sí orí ilẹ̀ wọn, láìfi nǹkan kan sẹ́yìn.
ular Mening ularni ǝllǝr arisiƣa sürgün ⱪildurƣanliⱪim tüpǝylidin, wǝ andin ulardin ⱨeqⱪaysisini xu yǝrdǝ ⱪaldurmay ɵz zeminiƣa yiƣⱪanliⱪim tüpǝylidin, ular Mening Pǝrwǝrdigar ikǝnlikimni bilip yetidu;
29 Èmi kì yóò sì fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn mọ nítorí èmi yóò tú èémí mi jáde sí ilé Israẹli, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
wǝ Mǝn yüzümni ulardin ⱪayta ⱨeq yoxurmaymǝn; qünki Mǝn Israil jǝmǝti üstigǝ Ɵz Roⱨimni ⱪuyƣan bolimǝn, — dǝydu Rǝb Pǝrwǝrdigar.

< Ezekiel 39 >