< Ezekiel 38 >

1 Ọrọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Et la parole du Seigneur me fut adressée, disant:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí Gogu, ti ilẹ̀ Magogu; olórí ọmọ-aládé, Meṣeki, àti Tubali sọtẹ́lẹ̀ ní ìlòdì sí i
Fils d’un homme, tourne ta face vers Gog, vers la terre de Magog, prince et chef de Mosoch et de Thubal, et prophétise sur lui,
3 kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé, Meṣeki àti Tubali.
Et tu lui diras: Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Voilà que je viens vers toi, Gog, prince et chef de Mosoch et de Thubal;
4 Èmi yóò yí ọ kiri, èmi yóò sì fi ìwọ̀ kọ́ ọ ní ẹnu, èmi yóò sì fà ọ́ jáde pẹ̀lú gbogbo ọmọ-ogun rẹ, àwọn ẹṣin àti àwọn agẹṣinjagun nínú ìhámọ́ra, àti ìpéjọ ńlá pẹ̀lú asà ogun ńlá àti kéékèèké, gbogbo wọn ń fi idà wọn.
Et je te ferai tourner de tous côtés, et je mettrai un frein dans tes mâchoires; et je te ferai sortir, toi et toute ton armée, tous tes chevaux, et tes cavaliers couverts de cuirasses, et la grande multitude de ceux qui ont pris la lance, le bouclier et le glaive.
5 Persia, Kuṣi àti Puti yóò wà pẹ̀lú wọn, gbogbo wọn yóò wà pẹ̀lú asà àti ìṣíborí wọn
Les Perses, les Ethiopiens, et les Libyens seront avec eux, tous armés de boucliers et coiffés d’un casque.
6 Gomeri náà pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti Beti-Togarma láti jìnnàjìnnà àríwá pẹ̀lú gbogbo àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ̀—ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
Gomer et tous ses bataillons, la maison de Thogorma, les côtés de l’aquilon, et toute sa force, et des peuples nombreux seront avec toi.
7 “‘Múra sílẹ̀, múra tán, kí ìwọ àti gbogbo ìjọ náà péjọpọ̀ pẹ̀lú rẹ, kí o sì pàṣẹ fún wọn.
Prépare-toi et dispose-toi avec toute ta multitude qui s’est rassemblée auprès de toi; et prends le commandement sur eux.
8 Lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, àwa yóò bẹ̀ ọ wò; ní ọdún ìkẹyìn ìwọ yóò dó ti ilẹ̀ tí a ti gbà padà lọ́wọ́ idà, tí àwọn ènìyàn wọn kórajọ pọ̀ láti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè sí àwọn òkè gíga ti Israẹli, tí ó ti di ahoro fún ìgbà pípẹ́. A ti mú wọn jáde láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, nísinsin yìí gbogbo wọn ń gbé ní àìléwu.
, Après de longs jours tu seras visité; et dans les dernières années tu viendras dans une terre qui a échappé au glaive, et a été rassemblée d’entre des peuples nombreux vers les montagnes d’Israël qui furent continuellement désertes; cette terre a été retirée d’entre les peuples, et ils y habiteront tous avec confiance.
9 Ìwọ àti ọ̀wọ́ ogun rẹ àti ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ yóò gòkè, ẹ̀yin yóò tẹ̀síwájú bí ìjì; ìwọ yóò dàbí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀ mọ́lẹ̀.
Mais, montant comme une tempête et comme un nuage, tu viendras, afin que tu couvres la terre, toi, et tous tes bataillons, et des peuples nombreux avec toi.
10 “‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà èrò kan yóò wá sọ́kàn rẹ, ìwọ yóò sì pète ìlànà búburú.
Voici ce que dit le Seigneur Dieu: En ce jour-là, des projets monteront dans ton cœur et tu penseras une pensée très mauvaise;
11 Ìwọ yóò wí pé, “Èmi yóò gbé ogun ti ilẹ̀ àwọn tí a kò fi odi yíká, Èmi yóò gbé ogun ti àwọn ènìyàn àlàáfíà tí a kò funra sí gbogbo wọn ń gbé ní àìsí odi, ní àìsí ẹnu-ọ̀nà òde àti àsígbè-irin.
Et tu diras: Je monterai dans une terre sans mur; je viendrai vers ceux qui demeurent en repos, et qui habitent en sécurité; tous ceux-là habitent sans mur; ils n’ont ni verrous ni portes;
12 Èmi yóò mú ohun ọdẹ, èmi yóò sì kó ìkógun, èmi yóò sì yí ọwọ́ mi padà sí ibi ìwólulẹ̀ ti a ti tún kọ́, àwọn ènìyàn tí a kójọpọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó ní ọrọ̀ nínú ẹran ọ̀sìn àti ẹrú, tí ó ń gbé ní àárín gbùngbùn ilẹ̀ náà.”
Afin que tu ravisses des dépouilles, et que tu saisisses une proie; que tu portes ta main sur ceux qui avaient été abandonnés et qui après cela ont été rétablis, et sur un peuple qui a été rassemblé d’entre des nations, et qui commençait à posséder, et à être habitant de l’éminence de la terre.
13 Ṣeba, Dedani àti àwọn oníṣòwò Tarṣiṣi àti gbogbo àwọn ọmọ kìnnìún wọn, yóò sọ fún un yín pé, “Ṣé ẹ̀yin wá fún ìkógun? Ṣé ẹ̀yin ti kó àwọn ogun yín jọ pọ̀ fún ìkógun, láti kó fàdákà àti wúrà lọ, láti kó ẹran ọ̀sìn àti ẹrú àti láti gba ọ̀pọ̀ ìkógun?”’”
Saba et Dédan, et les marchands de Tharsis, et tous ses lions te diront: Est-ce que tu ne viens pas pour prendre des dépouilles? Voici que tu as rassemblé ta multitude pour saisir une proie, afin d’emporter de l’argent et de l’or, et d’enlever des meubles et des richesses, et d’emporter un butin immense.
14 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì sọ fún Gogu: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ náà, nígbà tí àwọn ènìyàn mi Israẹli ń gbé ní àìléwu, ìwọ kì yóò ha ṣe àkíyèsí rẹ̀?
À cause de cela, prophétise, fils d’un homme, et dis à Gog: Voici ce que dit le Seigneur Dieu: N’est-ce pas qu’en ce jour-là, lorsque mon peuple Israël habitera avec confiance, tu le sauras?
15 Ìwọ yóò wá láti ààyè rẹ ní jìnnàjìnnà àríwá, ìwọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ, gbogbo wọn yóò sì gun ẹṣin ẹgbẹ́ ńlá, jagunjagun alágbára.
Et tu viendras de ton lieu, des côtés de l’aquilon, toi, et des peuples nombreux avec toi, tous montés sur des chevaux, grande assemblée et armée redoutable.
16 Ìwọ yóò tẹ̀síwájú ní ìlòdì sí àwọn Israẹli ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí ìkùùkuu tí ó bo ilẹ̀. Ni àwọn ọjọ́ tí ń bọ̀, ìwọ Gogu, èmi yóò mú ọ wá ní ìlòdì sí ilẹ̀ mi, kí àwọn orílẹ̀-èdè lè mọ̀ mi nígbà tí mo bá fi ara hàn ni mímọ́ láti ọ̀dọ̀ rẹ ní ojú wọn.
Et tu monteras contre mon peuple Israël comme un nuage, afin de couvrir la terre. Tu seras dans les derniers jours, et je t’amènerai sur ma terre, afin que les nations me connaissent, lorsque j’aurai été sanctifié en toi, à leurs yeux, ô Gog.
17 “‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ha kọ́ ni mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ ní ìgbà ìṣáájú láti ẹnu àwọn wòlíì ìránṣẹ́ mi ti Israẹli? Ní ìgbà náà wọ́n sọtẹ́lẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún pé èmi yóò mú ọ lòdì sí wọn.
Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Toi donc tu es celui dont j’ai parlé dans les jours anciens par l’entremise de mes serviteurs les prophètes d’Israël, qui ont prophétisé dans les jours de ces temps-là que je t’amènerais contre eux.
18 Èyí ni ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Gogu bá kọlu ilẹ̀ Israẹli, gbígbóná ìbínú mi yóò ru sókè, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Et il arrivera en ce jour-là, au jour de la venue de Gog sur la terre d’Israël, dit le Seigneur Dieu, mon indignation montera jusqu’à la fureur.
19 Ní ìtara mi àti ní gbígbóná ìbínú mi, mo tẹnumọ́ ọn pé; ní àsìkò náà ilẹ̀ mímì tí ó lágbára ní ilẹ̀ Israẹli yóò ṣẹlẹ̀.
Et c’est dans mon zèle, dans le feu de ma colère, que j’ai parlé. Parce qu’en ce jour-là il y aura une grande commotion dans la terre d’Israël;
20 Ẹja inú Òkun, àwọn ẹyẹ òfúrufú, àwọn ẹranko igbó, àti gbogbo ẹ̀dá tí ó ń rìn lórí ilẹ̀ yóò wárìrì fún ìfarahàn mi. A yóò yí òkè gíga po, àwọn bèbè òkúta ni àwa yóò fọ́ sí wẹ́wẹ́, gbogbo ògiri ni yóò wó palẹ̀.
Et ils seront violemment agités devant ma face, les poissons de la mer, et les oiseaux du ciel, et les bêtes de la campagne, et tout reptile qui se meut sur la terre, et tous les hommes qui sont sur la face de la terre; et les montagnes seront renversées, et les haies tomberont, et toute muraille s’écroulera sur le sol.
21 Èmi yóò fa idà yọ ni ìlòdì sí Gogu ní orí gbogbo àwọn òkè gíga mi ni Olúwa Olódùmarè wí. Idà gbogbo ènìyàn yóò lòdì sí arákùnrin rẹ̀.
Et j’appellerai contre lui sur toutes mes montagnes le glaive, dit le Seigneur Dieu; et le glaive de chacun sera dirigé contre son frère.
22 Èmi yóò gbé ìdájọ́ mi jáde lórí rẹ̀ pẹ̀lú ìyọnu àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀, Èmi yóò dá àgbàrá òjò, òkúta yìnyín àti imí-ọjọ́ tí ń jó lé e lórí àti lórí ọ̀wọ́ ogun àti lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pẹ̀lú rẹ̀.
J’exercerai mes jugements sur lui par la peste, et par le sang, et par une pluie violente, et par des pierres énormes, et je ferai pleuvoir le feu et le soufre sur lui, et sur son armée, et sur les peuples nombreux qui sont avec lui.
23 Nítorí náà, Èmi yóò fi títóbi mi àti ìjẹ́-mímọ́ mi hàn, Èmi yóò sì fi ara mi hàn ní ojú ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’
Et je serai glorifié, et je serai sanctifié, et je serai connu aux yeux d’un grand nombre de nations; et ils sauront que je suis le Seigneur.

< Ezekiel 38 >