< Ezekiel 37 >

1 Ọwọ́ Olúwa wà lára mi, ó sì mú mi jáde pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, ó mú kí ń wà ní àárín àfonífojì; ti o kún fún àwọn egungun.
La main du Seigneur fut sur moi, et elle me mena dehors par l’esprit du Seigneur, et elle me conduisit au milieu d’un champ, qui était plein d’ossements.
2 Ó mú mi lọ síwájú àti sẹ́yìn láàrín wọn, èmi sì rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn egungun ní orí ilẹ̀ àfonífojì, àwọn egungun tí ó gbẹ gan.
Elle me mena tout autour de ces ossements; or il y en avait un très grand nombre sur la face du champ, et ils étaient extrêmement desséchés.
3 Olúwa sì bi mí léèrè, “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ àwọn egungun wọ̀nyí lè yípadà di àwọn ènìyàn bí?” Èmi sì wí pé, “Ìwọ Olúwa Olódùmarè, ìwọ nìkan ni o lè dáhùn sí ìbéèrè yìí.”
Et il me dit: Fils d’un homme, penses-tu que ces ossements vivront? Et je dis: Seigneur Dieu, c’est vous qui le savez.
4 Nígbà náà ni ó wí fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn egungun kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin egungun gbígbẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
Et il me dit: Prophétise sur ces ossements, et tu leur diras: Ossements arides, écoutez la parole du Seigneur.
5 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn egungun wọ̀nyí. Èmi yóò mú kí èémí wọ inú yín ẹ̀yin yóò sì wá di ààyè.
Voici ce que dit le Seigneur Dieu à ces ossements: Voilà que moi j’enverrai en vous un esprit, et vous vivrez.
6 Èmi yóò so iṣan ara mọ́ ọn yín, Èmi yóò sì mú kí ẹran-ara wá sí ara yín, Èmi yóò sì fi awọ ara bò yín, Èmi yóò sì fi èémí sínú yín, ẹ̀yin yóò sì wà ní ààyè. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
Et je mettrai sur vous des nerfs, et je ferai croître sur vous des chairs, et j’étendrai en vous une peau; et je vous donnerai un esprit, et vous vivrez, et vous saurez que je suis le Seigneur.
7 Nítorí náà ni mo ṣe sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti pa á láṣẹ fún mi. Bí mo sì ti ń sọtẹ́lẹ̀, ariwo wá, ìró tí ó kígbe sókè, àwọn egungun sì wà papọ̀, egungun sí egungun.
Et je prophétisai comme il m’avait ordonné; et il se fit un bruit, moi prophétisant, et voilà un ébranlement; et des ossements s’approchèrent des ossements, chacun à sa jointure.
8 Mo wò ó, iṣan ara àti ẹran-ara farahàn lára wọn, awọ ara sì bò wọ́n, ṣùgbọ́n kò sí èémí nínú wọn.
Et je vis, et voilà que des nerfs et des chairs sur eux se placèrent; et une peau s’y étendit par dessus; mais un esprit, ils ne l’avaient pas.
9 Lẹ́yìn náà ni ó sọ fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí èémí; sọtẹ́lẹ̀, ọmọ ènìyàn, kí ó sì sọ fún un pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: wá láti atẹ́gùn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, ìwọ èémí, kí ó sì mí èémí sínú àwọn tí a pa wọ̀nyí, kí wọn kí ó lè wà ní ààyè.’”
Et il me dit: Prophétise à l’esprit, prophétise, fils d’un homme, et tu diras à l’esprit: Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Viens des quatre vents, esprit, et souffle sur ces hommes tués, et qu’ils revivent.
10 Nítorí náà, mo sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ṣe pa á láṣẹ fún mi, èémí sì wọ inú wọn; wọ́n di alààyè, wọ́n sì dìde dúró lórí ẹsẹ̀ wọn—pẹ̀lú ìhámọ́ra tí ó pọ̀.
Et je prophétisai comme il m’avait ordonné; et l’esprit entra dans les ossements, et ils devinrent vivants, et ils se tinrent sur leurs pieds, formant une armée innombrable.
11 Lẹ́yìn náà ó sọ fún mi: “Ọmọ ènìyàn, àwọn egungun wọ̀nyí ni gbogbo ìdílé Israẹli. Wọ́n sọ wí pé, ‘Egungun wa ti gbẹ ìrètí wa sì ti lọ; a ti gé wa kúrò.’
Et il me dit: Fils d’un homme, tous ces ossements sont les enfants de la maison d’Israël; ils disent eux-mêmes: Nos ossements sont devenus arides, et notre espérance est perdue, et nous sommes retranchés.
12 Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fun wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Ẹ̀yin ènìyàn mi, Èmi yóò ṣí àwọn ibojì yín, èmi yóò sì mú yín wá si ilẹ̀ Israẹli.
À cause de cela, prophétise, et tu leur diras: Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Voilà que moi j’ouvrirai vos tombeaux, et je vous tirerai de vos sépulcres, mon peuple, et je vous conduirai dans la terre d’Israël.
13 Ẹ̀yin o sì mọ̀ èmi ni Olúwa, nígbà tí èmi bá ti ṣí ibojì yín, ẹ̀yin ènìyàn mi, ti èmi bá si mú un yín dìde kúrò nínú ibojì yín.
Et vous saurez que je suis le Seigneur, lorsque j’aurai ouvert vos sépulcres, et que je vous aurai tirés de vos tombeaux, mon peuple;
14 Èmi yóò fi èémí mi sínú yín, ẹ̀yin yóò sì yè, èmi yóò sì mú kí ẹ fi lélẹ̀ ní ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi sì ti ṣe ni Olúwa wí.’”
Et que j’aurai mis mon esprit en vous, et que vous aurez vécu, et que je vous ferai reposer sur votre terre; et vous saurez que c’est moi le Seigneur qui ai parlée et exécuté, dit le Seigneur Dieu.
15 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá:
Et la parole du Seigneur me fut adressée, disant:
16 “Ọmọ ènìyàn, mú igi pátákó kan kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti Juda àti ti Israẹli tí ó ní àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’ Lẹ́yìn náà, kí ó mú igi pátákò mìíràn kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti tí Josẹfu (tí ó túmọ̀ sí ti Efraimu) àti gbogbo ilé Israẹli tí ó ni àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’
Et toi, fus d’un homme, prends un morceau de bois, et écris-y dessus: C’est le bois de Juda et des enfants d’Israël qui lui sont unis; et prends un autre morceau de bois et écris-y dessus: Pour Joseph, pour le bois d’Ephraïm, et pour toute la maison d’Israël et de ceux qui lui sont unis.
17 So wọ́n papọ̀ sí ara igi kan nítorí náà wọn yóò di ọ̀kan ní ọwọ́ rẹ.
Et joins-les l’un à l’autre, pour qu’ils ne soient pour toi qu’un seul bois; et ils seront unis dans ta main.
18 “Nígbà tí àwọn ara ìlú rẹ bá béèrè lọ́wọ́ rẹ pé, ‘Ṣé ìwọ kò ní sọ ohun tí èyí túmọ̀ sí fún wa?’
Mais lorsque les fils de ton peuple te diront, en parlant: Est-ce que vous ne nous indiquez pas ce que vous voulez par là?
19 Sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò gba igi Josẹfu—èyí tí ó wà ní ọwọ́ Efraimu—àti ti ẹ̀yà Israẹli tí ó parapọ̀ mọ́ ọn, kí ó sì só papọ̀ mọ́ igi Juda, láti sọ wọ́n di igi kan ṣoṣo, wọn yóò sì di ọ̀kan ní ọwọ́ mi.’
Tu leur diras: Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Voilà que moi je prendrai le bois de Joseph qui est dans la main d’Ephraïm, et les tribus d’Israël qui lui sont unies, et je les joindrai avec le bois de Juda, et j’en ferai un seul bois, et ils n’en seront qu’un dans sa main.
20 Gbé igi pátákó tí ó kọ nǹkan sí i sókè ní iwájú wọn,
Or ces bois sur lesquels tu auras écrit seront dans ta main, devant leurs yeux.
21 kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Israẹli jáde kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ. Èmi yóò ṣà wọ́n jọ pọ̀ láti gbogbo agbègbè, èmi yóò sì mú wọn padà sí ilẹ̀ ara wọn.
Et tu leur diras: Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Voilà que moi je prendrai les fils d’Israël du milieu des nations vers lesquelles ils sont allés; je les rassemblerai de toutes parts, et je les ramènerai dans leur terre,
22 Èmi yóò ṣe wọ́n ní orílẹ̀-èdè kan ní ilẹ̀ náà, ní orí òkè Israẹli, ọba kan ni yóò wà lórí gbogbo wọn, wọn kì yóò sì jẹ́ orílẹ̀-èdè méjì mọ́, tàbí kí a pín wọn sí ìjọba méjì.
Et je ferai d’eux une seule nation dans leur terre sur les montagnes d’Israël, et un seul roi commandera à tous; et à l’avenir ils ne formeront pas deux nations, et ils ne seront plus divisés en deux royaumes.
23 Wọn kì yóò sì tún fi àwọn òrìṣà wọn ba ara wọn jẹ́ mọ́, tàbí ohun ìríra wọn, tàbí ohun ìrékọjá wọn: ṣùgbọ́n èmi yóò gbà wọn là kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àgàbàgebè wọn, èmi yóò sì wẹ̀ wọn mọ́. Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
Et ils ne se souilleront plus par leurs idoles, et par leurs abominations, et par toutes leurs iniquités; je les sauverai en les retirant de tous les lieux de séjour où ils ont péché, et je les purifierai; et ils seront mon peuple, et moi je serai leur Dieu.
24 “‘Dafidi ìránṣẹ́ mi ni yóò jẹ ọba lórí wọn, gbogbo wọn yóò sì ní olùṣọ àgùntàn kan. Wọn yóò sì tẹ̀lé òfin mi, wọn yóò sì ṣe àníyàn láti pa àṣẹ mi mọ́.
Et mon serviteur David sera leur roi; un seul pasteur sera pour eux tous; ils marcheront dans mes ordonnances, ils garderont mes commandements, et ils les pratiqueront.
25 Wọn yóò gbé ní ilẹ̀ tí mo fún Jakọbu ìránṣẹ́ mi, ilẹ̀ tí àwọn baba yín ń gbé. Àwọn àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn ni yóò máa gbé ibẹ̀ láéláé, ìránṣẹ́ mi Dafidi ni yóò jẹ́ Ọmọ-aládé wọn láéláé.
Et ils habiteront sur la terre que j’ai donnée à mon serviteur Jacob, dans laquelle ont habité vos pères; et ils y habiteront, eux et leurs enfants, et les enfants de leurs enfants à jamais; et David, mon serviteur, sera leur prince pour toujours.
26 Èmi yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn, yóò sì jẹ́ májẹ̀mú títí ayérayé. Èmi yóò gbé wọn kalẹ̀, èmi yóò sì sọ wọ́n di púpọ̀ ní iye, èmi yóò sì gbé ilé mímọ́ mi kalẹ̀ ní àárín wọn títí láé.
Et je ferai avec eux une alliance de paix; un pacte avec eux sera éternel; et je les établirai solidement, et je les multiplierai, et je placerai mon sanctuaire au milieu d’eux pour toujours.
27 Ibùgbé mí yóò wà pẹ̀lú wọn, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run wọn, wọn yóò sì jẹ́ ènìyàn mi.
Et mon tabernacle sera au milieu d’eux; et je serai leur Dieu, et eux seront mon peuple.
28 Nígbà náà ni àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa sọ Israẹli di mímọ́, nígbà tí ibi mímọ́ mi bá wà ní àárín wọn títí ayérayé.’”
Et les nations sauront que je suis le Seigneur, le sanctificateur d’Israël, lorsque mon sanctuaire sera au milieu d’eux pour toujours.

< Ezekiel 37 >