< Ezekiel 37 >

1 Ọwọ́ Olúwa wà lára mi, ó sì mú mi jáde pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, ó mú kí ń wà ní àárín àfonífojì; ti o kún fún àwọn egungun.
Isandla seNkosi sasiphezu kwami, sangikhupha ngoMoya weNkosi, sangibeka phakathi kwesihotsha esasigcwele amathambo.
2 Ó mú mi lọ síwájú àti sẹ́yìn láàrín wọn, èmi sì rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn egungun ní orí ilẹ̀ àfonífojì, àwọn egungun tí ó gbẹ gan.
Yangidlulisa kuwo ngibhoda inhlangothi zonke; khangela-ke, ayemanengi kakhulu ebusweni besihotsha, njalo khangela, ayomile kakhulu.
3 Olúwa sì bi mí léèrè, “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ àwọn egungun wọ̀nyí lè yípadà di àwọn ènìyàn bí?” Èmi sì wí pé, “Ìwọ Olúwa Olódùmarè, ìwọ nìkan ni o lè dáhùn sí ìbéèrè yìí.”
Yasisithi kimi: Ndodana yomuntu, amathambo la angaphila yini? Ngasengisithi: Nkosi Jehova, nguwe owaziyo.
4 Nígbà náà ni ó wí fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn egungun kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin egungun gbígbẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
Yasisithi kimi: Profetha phezu kwalamathambo, uthi kiwo: Lina mathambo omileyo, zwanini ilizwi leNkosi.
5 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn egungun wọ̀nyí. Èmi yóò mú kí èémí wọ inú yín ẹ̀yin yóò sì wá di ààyè.
Itsho njalo iNkosi uJehova kula amathambo: Khangelani, ngizakwenza umoya ungene kini, liphile.
6 Èmi yóò so iṣan ara mọ́ ọn yín, Èmi yóò sì mú kí ẹran-ara wá sí ara yín, Èmi yóò sì fi awọ ara bò yín, Èmi yóò sì fi èémí sínú yín, ẹ̀yin yóò sì wà ní ààyè. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
Ngibeke imisipha phezu kwenu, ngivuselele inyama phezu kwenu, ngilembese ngesikhumba, ngifake umoya kini, liphile. Khona lizakwazi ukuthi ngiyiNkosi.
7 Nítorí náà ni mo ṣe sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti pa á láṣẹ fún mi. Bí mo sì ti ń sọtẹ́lẹ̀, ariwo wá, ìró tí ó kígbe sókè, àwọn egungun sì wà papọ̀, egungun sí egungun.
Ngasengiprofetha njengokulaywa kwami; kwasekusiba lomsindo ngisaprofetha, khangela-ke ukunyikinyeka, amathambo asesondelelana, ithambo kuthambo lalo.
8 Mo wò ó, iṣan ara àti ẹran-ara farahàn lára wọn, awọ ara sì bò wọ́n, ṣùgbọ́n kò sí èémí nínú wọn.
Ngasengibona, khangela-ke, kwakulemisipha phezu kwawo, yavela inyama, lesikhumba sawasibekela ngaphezulu; kodwa kwakungelamoya kiwo.
9 Lẹ́yìn náà ni ó sọ fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí èémí; sọtẹ́lẹ̀, ọmọ ènìyàn, kí ó sì sọ fún un pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: wá láti atẹ́gùn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, ìwọ èémí, kí ó sì mí èémí sínú àwọn tí a pa wọ̀nyí, kí wọn kí ó lè wà ní ààyè.’”
Yasisithi kimi: Profetha emoyeni, profetha ndodana yomuntu, uthi emoyeni: Itsho njalo iNkosi uJehova: Woza uvela emimoyeni emine, wena moya, uphefumulele kulaba ababuleweyo ukuze baphile.
10 Nítorí náà, mo sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ṣe pa á láṣẹ fún mi, èémí sì wọ inú wọn; wọ́n di alààyè, wọ́n sì dìde dúró lórí ẹsẹ̀ wọn—pẹ̀lú ìhámọ́ra tí ó pọ̀.
Ngasengiprofetha njengalokho yayingilayile; umoya wasungena kiwo, aphila, ema ngenyawo zawo, ibutho elikhulu kakhulukazi.
11 Lẹ́yìn náà ó sọ fún mi: “Ọmọ ènìyàn, àwọn egungun wọ̀nyí ni gbogbo ìdílé Israẹli. Wọ́n sọ wí pé, ‘Egungun wa ti gbẹ ìrètí wa sì ti lọ; a ti gé wa kúrò.’
Yasisithi kimi: Ndodana yomuntu, la amathambo ayindlu yonke kaIsrayeli. Khangela, bathi: Amathambo ethu omile, lethemba lethu libhubhile, siqunyiwe ngokwethu.
12 Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fun wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Ẹ̀yin ènìyàn mi, Èmi yóò ṣí àwọn ibojì yín, èmi yóò sì mú yín wá si ilẹ̀ Israẹli.
Ngakho profetha uthi kubo: Itsho njalo iNkosi uJehova: Khangelani, ngizavula amangcwaba enu, ngilikhuphule emangcwabeni enu, lina bantu bami, ngilise elizweni lakoIsrayeli.
13 Ẹ̀yin o sì mọ̀ èmi ni Olúwa, nígbà tí èmi bá ti ṣí ibojì yín, ẹ̀yin ènìyàn mi, ti èmi bá si mú un yín dìde kúrò nínú ibojì yín.
Khona lizakwazi ukuthi ngiyiNkosi, lapho ngivula amangcwaba enu, ngilikhuphule emangcwabeni enu, lina bantu bami.
14 Èmi yóò fi èémí mi sínú yín, ẹ̀yin yóò sì yè, èmi yóò sì mú kí ẹ fi lélẹ̀ ní ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi sì ti ṣe ni Olúwa wí.’”
Besengifaka umoya wami kini, liphile, besengilibeka elizweni lenu; khona lizakwazi ukuthi mina Nkosi ngikhulumile, ngakwenza, itsho iNkosi.
15 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá:
Ilizwi leNkosi lafika kimi futhi lisithi:
16 “Ọmọ ènìyàn, mú igi pátákó kan kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti Juda àti ti Israẹli tí ó ní àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’ Lẹ́yìn náà, kí ó mú igi pátákò mìíràn kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti tí Josẹfu (tí ó túmọ̀ sí ti Efraimu) àti gbogbo ilé Israẹli tí ó ni àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’
Wena-ke ndodana yomuntu, zithathele intonga eyodwa, ubhale phezu kwayo uthi: EkaJuda, leyabantwana bakaIsrayeli abangane bakhe; ubusuthatha enye intonga, ubhale phezu kwayo uthi: EkaJosefa, intonga kaEfrayimi, layo yonke indlu kaIsrayeli abangane bakhe.
17 So wọ́n papọ̀ sí ara igi kan nítorí náà wọn yóò di ọ̀kan ní ọwọ́ rẹ.
Ubusuzisondeza, enye kwenye kuwe, zibe yintonga eyodwa; njalo zizakuba ngeyodwa esandleni sakho.
18 “Nígbà tí àwọn ara ìlú rẹ bá béèrè lọ́wọ́ rẹ pé, ‘Ṣé ìwọ kò ní sọ ohun tí èyí túmọ̀ sí fún wa?’
Lalapho abantwana babantu bakini bekhuluma kuwe besithi: Kawuyikusitshela yini ukuthi lezi ziyini kuwe?
19 Sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò gba igi Josẹfu—èyí tí ó wà ní ọwọ́ Efraimu—àti ti ẹ̀yà Israẹli tí ó parapọ̀ mọ́ ọn, kí ó sì só papọ̀ mọ́ igi Juda, láti sọ wọ́n di igi kan ṣoṣo, wọn yóò sì di ọ̀kan ní ọwọ́ mi.’
Tshono kubo: Itsho njalo iNkosi uJehova: Khangela, ngizathatha intonga kaJosefa, esesandleni sikaEfrayimi, lezizwe zakoIsrayeli abangane bakhe, ngizibeke kuyo, kuyo intonga kaJuda, ngizenze zibe yintonga eyodwa, zibe ngeyodwa esandleni sami.
20 Gbé igi pátákó tí ó kọ nǹkan sí i sókè ní iwájú wọn,
Njalo izintonga obhale kizo zizakuba sesandleni sakho phambi kwamehlo abo.
21 kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Israẹli jáde kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ. Èmi yóò ṣà wọ́n jọ pọ̀ láti gbogbo agbègbè, èmi yóò sì mú wọn padà sí ilẹ̀ ara wọn.
Ubususithi kubo: Itsho njalo iNkosi uJehova: Khangelani, ngizathatha abantwana bakoIsrayeli phakathi kwezizwe, abaye kizo, ngibabuthe inhlangothi zonke, ngibalethe elizweni labo;
22 Èmi yóò ṣe wọ́n ní orílẹ̀-èdè kan ní ilẹ̀ náà, ní orí òkè Israẹli, ọba kan ni yóò wà lórí gbogbo wọn, wọn kì yóò sì jẹ́ orílẹ̀-èdè méjì mọ́, tàbí kí a pín wọn sí ìjọba méjì.
ngibenze babe yisizwe esisodwa elizweni phezu kwezintaba zakoIsrayeli; njalo inkosi eyodwa izakuba yinkosi yabo bonke; njalo kabasayikuba yizizwe ezimbili, kabasayikwehlukaniswa babe yimibuso emibili futhi.
23 Wọn kì yóò sì tún fi àwọn òrìṣà wọn ba ara wọn jẹ́ mọ́, tàbí ohun ìríra wọn, tàbí ohun ìrékọjá wọn: ṣùgbọ́n èmi yóò gbà wọn là kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àgàbàgebè wọn, èmi yóò sì wẹ̀ wọn mọ́. Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
Kabasayikuzingcolisa ngezithombe zabo, langamanyala abo, langasiphi seziphambeko zabo; kodwa ngizabasindisa baphume kuzo zonke indawo zabo zokuhlala, abona kizo, ngibahlambulule. Ngalokho bazakuba ngabantu bami, lami ngibe nguNkulunkulu wabo.
24 “‘Dafidi ìránṣẹ́ mi ni yóò jẹ ọba lórí wọn, gbogbo wọn yóò sì ní olùṣọ àgùntàn kan. Wọn yóò sì tẹ̀lé òfin mi, wọn yóò sì ṣe àníyàn láti pa àṣẹ mi mọ́.
Njalo inceku yami uDavida izakuba yinkosi phezu kwabo; labo bonke bazakuba lomalusi munye; futhi bazahamba kuzahlulelo zami, bagcine izimiso zami, bazenze.
25 Wọn yóò gbé ní ilẹ̀ tí mo fún Jakọbu ìránṣẹ́ mi, ilẹ̀ tí àwọn baba yín ń gbé. Àwọn àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn ni yóò máa gbé ibẹ̀ láéláé, ìránṣẹ́ mi Dafidi ni yóò jẹ́ Ọmọ-aládé wọn láéláé.
Bahlale elizweni engalinika inceku yami uJakobe, ababehlala kulo oyihlo, yebo, bazahlala kulo, bona, labantwana babo, labantwana babantwana babo, kuze kube phakade. Futhi uDavida inceku yami uzakuba yisiphathamandla sabo kuze kube phakade.
26 Èmi yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn, yóò sì jẹ́ májẹ̀mú títí ayérayé. Èmi yóò gbé wọn kalẹ̀, èmi yóò sì sọ wọ́n di púpọ̀ ní iye, èmi yóò sì gbé ilé mímọ́ mi kalẹ̀ ní àárín wọn títí láé.
Futhi ngizakwenza isivumelwano sokuthula labo; sizakuba yisivumelwano esilaphakade labo; ngibamise, ngibandise, ngibeke indawo yami engcwele phakathi kwabo kuze kube phakade.
27 Ibùgbé mí yóò wà pẹ̀lú wọn, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run wọn, wọn yóò sì jẹ́ ènìyàn mi.
Ithabhanekele lami lalo lizakuba kubo, njalo ngizakuba nguNkulunkulu wabo, labo bazakuba ngabantu bami.
28 Nígbà náà ni àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa sọ Israẹli di mímọ́, nígbà tí ibi mímọ́ mi bá wà ní àárín wọn títí ayérayé.’”
Lezizwe zizakwazi ukuthi mina Nkosi ngenza uIsrayeli abe ngcwele, nxa indawo yami engcwele izakuba phakathi kwabo kuze kube phakade.

< Ezekiel 37 >