< Ezekiel 36 >

1 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn òkè gíga Israẹli kí o sì wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè gíga Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Wena-ke ndodana yomuntu, profetha kuzo izintaba zakoIsrayeli, uthi: Lina zintaba zakoIsrayeli, zwanini ilizwi leNkosi.
2 Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Àwọn ọ̀tá sọ nípa yín pé, “Háà! Àwọn ibi gíga ìgbàanì ti di ohun ìní wa.”’
Itsho njalo iNkosi uJehova: Ngoba isitha sitshilo simelene lani: Aha, ngitsho izindawo zasendulo eziphakemeyo ziyilifa lethu;
3 Nítorí náà, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé wọn sọ ọ di ahoro, tí wọn sì ń dọdẹ rẹ ní gbogbo ọ̀nà kí ìwọ kí ó lè di ìní fún àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù, àti ohun ti àwọn ènìyàn ń sọ ọ̀rọ̀ ìríra àti ìdíbàjẹ́ sí,
ngakho profetha uthi: Itsho njalo iNkosi uJehova: Ngoba, yebo, ngoba bakwenze incithakalo, baliginya inhlangothi zonke, ukuze libe yilifa kuyo insali yabezizwe, liphakanyiswa endebeni zolimi, laba lunyeyo lwabantu;
4 nítorí náà, ẹ̀yin òkè gíga Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn òkè gíga àti àwọn òkè kéékèèké, fún àfonífojì ńlá àti àfonífojì kéékèèké, fún àwọn ibi ìsọdahoro ìparun àti fún àwọn ìlú tí a ti kọ̀sílẹ̀ tí a ti kó tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù ní àyíká sì fi ṣe ẹlẹ́yà,
ngakho, lina zintaba zakoIsrayeli, zwanini ilizwi leNkosi uJehova: Itsho njalo iNkosi uJehova ezintabeni, lemaqaqeni, emifuleni, lezihotsheni, lemanxiweni achithekileyo, lemizini etshiyiweyo, esibe yimpango lenhlekisa kunsali yezizwe ezizingelezeleyo.
5 èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ìgbóná ọkàn ní mo sọ̀rọ̀ sí àwọn kèfèrí yòókù, àti sí Edomu, nítorí pẹ̀lú ìbínú àti ìjowú ní ọkàn wọn ni wọ́n sọ ilé mi di ohun ìní wọn, kí wọn kí o lè kó pápá oko tútù rẹ̀.’
Ngakho itsho njalo iNkosi uJehova: Isibili ngomlilo wobukhwele bami sengikhulume ngimelene lensali yabezizwe, ngimelene leEdoma yonke, abazinikele ilizwe lami ukuthi libe yilifa ngentokozo yenhliziyo yonke, ngengqondo yokudelela, ngenxa yokuliphosa libe yimpango.
6 Nítorí náà, sọtẹ́lẹ̀ nípa ilẹ̀ Israẹli náà kí o sì sọ sí àwọn òkè gíga náà àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn àfonífojì ńlá àti sí àwọn àfonífojì kéékèèké, ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi sọ̀rọ̀ nínú ìrunú owú mi nítorí pé ìwọ ti jìyà ìfiṣẹ̀sín àwọn orílẹ̀-èdè.
Ngakho profetha ngelizwe lakoIsrayeli, uthi ezintabeni, lemaqaqeni, emifuleni, lezihotsheni: Itsho njalo iNkosi uJehova: Khangela, ngikhulumile ebukhweleni bami lelakeni lwami, ngoba lithwele ihlazo lezizwe.
7 Nítorí náà, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi ṣe ìbúra nípa nína ọwọ́ mi sókè pé; àwọn orílẹ̀-èdè àyíká rẹ náà yóò jìyà ìfiṣẹ̀sín.
Ngakho itsho njalo iNkosi uJehova: Mina ngiphakamisile isandla sami. Isibili izizwe ezilihanqileyo, yizo ezizathwala ihlazo lazo.
8 “‘Ṣùgbọ́n ìwọ, òkè gíga Israẹli, yóò mú ẹ̀ka àti èso fún àwọn ènìyàn mi Israẹli, nítorí wọn yóò wá sílé ní àìpẹ́ yìí.
Kodwa lina, zintaba zakoIsrayeli, lizaveza ingatsha zenu, lithele isithelo senu kubantu bami uIsrayeli, ngoba basondela ukubuya.
9 Èmi ń ṣe àníyàn fún ọ, èmi yóò sì fi rere wọ̀ ọ́; àwa yóò tu ọ́, àwa yóò sì gbìn ọ́,
Ngoba, khangelani, ngilani, ngiphendukele ngakini, njalo lizalinywa lihlanyelwe.
10 èmi yóò sì sọ iye àwọn ènìyàn di púpọ̀ nínú rẹ àti gbogbo ilé Israẹli. Àwọn ìlú yóò di ibùgbé, a yóò sì tún àwọn ibi ìparun kọ́.
Njalo ngizakwandisa abantu phezu kwenu, yonke indlu kaIsrayeli, yona yonke; lemizi izahlalwa, lamanxiwa azakwakhiwa.
11 Èmi yóò sọ iye ènìyàn àti ẹran dì púpọ̀ nínú yín, wọn yóò sì so èso, wọn yóò sì di púpọ̀ yanturu. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn máa gbé nínú rẹ bí ti àtẹ̀yìnwá, èmi yóò sì mú kí o ṣe rere ju ìgbà àtijọ́ lọ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ pé èmi ni Olúwa.
Njalo ngizakwandisa phezu kwenu umuntu lenyamazana, njalo kuzakwanda kuthele izithelo; ngilenze lihlale njengasezindaweni zenu zendulo, ngikwenze kube kuhle kulezikhathi zenu zokuqala. Khona lizakwazi ukuthi ngiyiNkosi.
12 Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn, àní àwọn ènìyàn Israẹli, rìn lórí rẹ̀. Wọn yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì di ogún ìní wọn; ìwọ kì yóò sì gba àwọn ọmọ wọn lọ́wọ́ wọn mọ́.
Yebo ngizakwenza abantu bahambe phezu kwenu, abantu bami uIsrayeli; badle ilifa lakho, wena ube yilifa labo, kawusayikubenza bafelwe ngabantwana futhi.
13 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé àwọn ènìyàn sọ fún ọ pé, “Ìwọ pa àwọn ènìyàn run, ìwọ sì gba àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè lọ́wọ́ wọn,”
Itsho njalo iNkosi uJehova: Ngoba bathi kini: Wena ungumudli wabantu, wenze izizwe zakho zifelwe ngabantwana.
14 nítorí náà ìwọ kì yóò pa àwọn ènìyàn run tàbí mú kì orílẹ̀-èdè di aláìlọ́mọ mọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Ngakho kawusayikudla abantu, kawusayikukhubekisa izizwe zakho, itsho iNkosi uJehova.
15 Èmi kì yóò mú ki ó gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè mọ́, ìwọ kì yóò jìyà ọ̀rọ̀ ìfiṣẹ̀sín láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tàbí mú kí orílẹ̀-èdè rẹ ṣubú, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Njalo kangisayikuzwakalisa kuwe ihlazo lezizwe, kawusayikuthwala inhloni zabantu, kawusayikukhubekisa izizwe, itsho iNkosi uJehova.
16 Síwájú sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Ilizwi leNkosi lafika kimi futhi lisithi:
17 “Ọmọ ènìyàn, nígbà tí àwọn ènìyàn Israẹli ń gbé ní ilẹ̀ wọn, wọ́n bà á jẹ́ nípa ìwà àti ìṣe wọn. Ìwà wọn dàbí nǹkan àkókò àwọn obìnrin ni ojú mi.
Ndodana yomuntu, abendlu kaIsrayeli besahlala elizweni lakibo, balingcolisa ngendlela yabo langezenzo zabo; indlela yabo phambi kwami yayifanana lokungcola kowesifazana osemfuleni.
18 Nítorí náà mo tú ìbínú mi jáde sórí wọn nítorí wọn ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ àti nítorí pé wọ́n ti fi ère wọn ba a jẹ́.
Ngakho ngathululela ulaka lwami phezu kwabo ngenxa yegazi ababelichithe elizweni, langenxa yezithombe zabo ababelingcolise ngazo.
19 Mo tú wọn ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, a sì fọ́n wọn ká sí àwọn ìlú; mo ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà àti ìṣe wọn.
Ngasengibahlakaza phakathi kwezizwe, basabalaliswa phakathi kwamazwe; ngabahlulela njengokwendlela yabo lanjengokwezenzo zabo.
20 Gbogbo ibi tí wọ́n lọ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè ni wọn ti sọ orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́, nítorí tí a sọ nípa wọn pé, ‘Ìwọ̀nyí ni àwọn ènìyàn Olúwa, síbẹ̀ wọn ní láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀.’
Lapho befika kwabezizwe, lapho abaya khona, bangcolisa ibizo lami elingcwele, lapho kwathiwa ngabo: Laba ngabantu beNkosi, baphume elizweni layo.
21 Orúkọ mímọ́ mi jẹ́ mi lógún, èyí tí ilé Israẹli sọ di aláìmọ́ ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ.
Kodwa ngalihawukela ibizo lami elingcwele, indlu kaIsrayeli eyayilingcolise phakathi kwezizwe, lapho abaya khona.
22 “Nítorí náà, sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Kì í ṣe nítorí rẹ, ìwọ ilé Israẹli, ni èmi yóò ṣe ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí, ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mímọ́ mi, èyí ti ìwọ ti sọ di aláìmọ́ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti lọ.
Ngakho tshono kuyo indlu kaIsrayeli: Itsho njalo iNkosi uJehova: Kangikwenzi ngenxa yenu, lina ndlu kaIsrayeli, kodwa ngenxa yebizo lami elingcwele, elilingcolisileyo phakathi kwezizwe, lapho elaya khona.
23 Èmi yóò fi jíjẹ́ mímọ́ orúkọ ńlá mi, èyí tí a ti sọ di aláìmọ́ hàn ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè, orúkọ tí ìwọ ti sọ di aláìmọ́ ni àárín wọn. Nígbà náà àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, ni Olúwa Olódùmarè wí, nígbà tí mo bá fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ yín ni iwájú wọn.
Njalo ngizangcwelisa ibizo lami elikhulu, elingcoliswe phakathi kwezizwe, elilingcolisileyo phakathi kwazo; lezizwe zizakwazi ukuthi ngiyiNkosi, itsho iNkosi uJehova, lapho ngizangcweliswa kini emehlweni abo.
24 “‘Nítorí èmi yóò mú yín jáde kúrò ni àwọn orílẹ̀-èdè náà; Èmi yóò ṣà yín jọ kúrò ní gbogbo àwọn ìlú náà; Èmi yóò sì mú yín padà sí ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín.
Ngoba ngizalithatha ezizweni, ngilibuthe emazweni wonke, ngililethe elizweni lenu.
25 Èmi yóò wọ́n omi tó mọ́ sí yín lára ẹ̀yin yóò sì mọ́; Èmi yóò sì fọ̀ yín mọ́ kúrò nínú gbogbo ìwà èérí yin gbogbo àti kúrò nínú gbogbo òrìṣà yin.
Khona ngizafafaza amanzi ahlambulukileyo phezu kwenu, lihlambuluke; kukho konke ukungcola kwenu, lakuzo zonke izithombe zenu, ngizalihlambulula.
26 Èmi yóò fún yín ni ọkàn tuntun, èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú yín; Èmi yóò sì mú ọkàn òkúta kúrò nínú yín, èmi yóò sì fi ọkàn ẹran fún yín.
Ngilinike inhliziyo entsha, ngifake umoya omutsha phakathi kwenu, ngisuse inhliziyo yelitshe enyameni yenu, ngilinike inhliziyo yenyama.
27 Èmi yóò fi ẹ̀mí mi sínú yín, èmi yóò sì mú ki ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ẹ sì fiyèsí àti pa òfin mi mọ́.
Ngifake uMoya wami phakathi kwenu, ngilenze ukuthi lihambe ngezimiso zami, ligcine izahlulelo zami lizenze.
28 Ẹ̀yin yóò sì máa gbé ilẹ̀ náà tí mo ti fi fún àwọn baba ńlá yín; ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
Lizahlala-ke elizweni engalinika oyihlo, libe ngabantu bami, lami ngibe nguNkulunkulu wenu.
29 Èmi yóò sì gbà yín kúrò nínú gbogbo ìwà àìmọ́ yín. Èmi yóò pèsè ọkà, èmi yóò sì mú kí ó pọ̀ yanturu, èmi kì yóò sì mú ìyàn wá sí orí yín.
Njalo ngizalisindisa kukho konke ukungcola kwenu; ngibize amabele, ngiwandise, ngingabeki ndlala phezu kwenu.
30 Èmi yóò sọ èso àwọn igi yín àti ohun ọ̀gbìn oko yín di púpọ̀, nítorí kí ẹ̀yin kí ó má ṣe jìyà ìdójútì mọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà nítorí ìyàn.
Ngandise isithelo sesihlahla, lesivuno sensimu, ukuze lingaphindi lemukele ihlazo lendlala phakathi kwezizwe.
31 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rántí àwọn ọ̀nà búburú àti àwọn ìwà ìkà yín, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ìwà tí kò bójúmu.
Khona lizakhumbula izindlela zenu ezimbi lezenzo zenu ezingalunganga; linengeke ngani ngokwenu ngobubi benu langenxa yezinengiso zenu.
32 Mo fẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ń kò ṣe nǹkan wọ̀nyí nítorí yín, ni Olúwa Olódùmarè wí. Jẹ kí ojú kí ó tì yín, kí ẹ sì gba ẹ̀tẹ́ nítorí ìwà yín ẹ̀yin ilé Israẹli!
Kangikwenzi ngenxa yenu, itsho iNkosi uJehova; kakwaziwe kini. Banini lenhloni libe lehlazo ngenxa yezindlela zenu, lina ndlu kaIsrayeli.
33 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ tí mo wẹ̀ yín kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín gbogbo, èmi yóò ṣe àtúnṣe àwọn ìlú yín, wọn yóò sì ṣe àtúnkọ́ ìwólulẹ̀.
Itsho njalo iNkosi uJehova: Mhla ngilihlambulula kubo bonke ububi benu, ngizakwenza imizi ihlalwe, lamanxiwa akhiwe.
34 Ilẹ̀ ahoro náà ní àwa yóò tún kọ́ ti kì yóò wà ní ahoro lójú àwọn tí ó ń gba ibẹ̀ kọjá mọ́.
Lelizwe elichithekileyo lizalinywa, endaweni yokuthi beliyinkangala emehlweni abo bonke abadlulayo.
35 Wọn yóò sọ wí pé, “Ilẹ̀ yìí tí ó ti wà ní ahoro tẹ́lẹ̀ ti dàbí ọgbà Edeni; àwọn ìlú tí ó wà ní wíwó lulẹ̀, ahoro tí a ti parun, ni àwa yóò mọdi sí tí yóò sì wà fún gbígbé ni ìsinsin yìí.”
Njalo bazakuthi: Lelilizwe ebeselichithekile selinjengesivande seEdeni; lemizi eyinkangala lengamanxiwa lediliziweyo isibiyelwe yahlalwa.
36 Nígbà náà àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà ní àyíká yín tí ó kù yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti tún àwọn ohun tí ó bàjẹ́ kọ́, mo sì ti tún ohun tí ó di ìṣòfo gbìn. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi yóò sì ṣe e?’
Khona izizwe ezisele zilizingelezele zizakwazi ukuthi mina iNkosi ngakha indawo ezidiliziweyo, ngihlanyele ezichithekileyo. Mina Nkosi ngikhulumile, ngizakwenza.
37 “Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò yí sí ilé Israẹli, èmi yóò sì ṣe èyí fún wọn. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn yín pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí àgùntàn,
Itsho njalo iNkosi uJehova: Langalokhu ngizacelwa yindlu kaIsrayeli, ukuthi ngiyenzele khona; ngizabandisa ngabantu njengomhlambi.
38 kí ó pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí ọ̀wọ́ ẹran fún ìrúbọ ní Jerusalẹmu ní àsìkò àjọ̀dún tí a yàn. Ìlú ti a parun yóò wá kún fún agbo àwọn ènìyàn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.”
Njengomhlambi ongcwele, njengomhlambi weJerusalema emikhosini yawo emisiweyo, ngokunjalo imizi echithekileyo izagcwala ngemihlambi yabantu. Khona bazakwazi ukuthi ngiyiNkosi.

< Ezekiel 36 >