< Ezekiel 37 >

1 Ọwọ́ Olúwa wà lára mi, ó sì mú mi jáde pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, ó mú kí ń wà ní àárín àfonífojì; ti o kún fún àwọn egungun.
La main de l'Éternel fut sur moi; il me fit sortir par l'Esprit de l'Éternel, et me déposa au milieu de la vallée, qui était pleine d'ossements.
2 Ó mú mi lọ síwájú àti sẹ́yìn láàrín wọn, èmi sì rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn egungun ní orí ilẹ̀ àfonífojì, àwọn egungun tí ó gbẹ gan.
Il me fit passer devant eux tout autour; et voici, il y en avait beaucoup dans la vallée ouverte, et voici, ils étaient très secs.
3 Olúwa sì bi mí léèrè, “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ àwọn egungun wọ̀nyí lè yípadà di àwọn ènìyàn bí?” Èmi sì wí pé, “Ìwọ Olúwa Olódùmarè, ìwọ nìkan ni o lè dáhùn sí ìbéèrè yìí.”
Il me dit: « Fils d'homme, ces os peuvent-ils vivre? » J'ai répondu: « Seigneur Yahvé, tu le sais. »
4 Nígbà náà ni ó wí fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn egungun kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin egungun gbígbẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
Il me dit encore: « Prophétise sur ces os, et dis-leur: Ossements desséchés, écoutez la parole de Yahvé.
5 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn egungun wọ̀nyí. Èmi yóò mú kí èémí wọ inú yín ẹ̀yin yóò sì wá di ààyè.
Le Seigneur Yahvé dit à ces os: « Voici, je vais faire entrer en vous un souffle, et vous vivrez.
6 Èmi yóò so iṣan ara mọ́ ọn yín, Èmi yóò sì mú kí ẹran-ara wá sí ara yín, Èmi yóò sì fi awọ ara bò yín, Èmi yóò sì fi èémí sínú yín, ẹ̀yin yóò sì wà ní ààyè. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
Je mettrai sur vous des nerfs, je ferai remonter sur vous de la chair, je vous couvrirai de peau, je ferai entrer en vous un souffle, et vous vivrez. Alors vous saurez que je suis Yahvé. »'"
7 Nítorí náà ni mo ṣe sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti pa á láṣẹ fún mi. Bí mo sì ti ń sọtẹ́lẹ̀, ariwo wá, ìró tí ó kígbe sókè, àwọn egungun sì wà papọ̀, egungun sí egungun.
Je prophétisai donc comme on me l'avait ordonné. Comme je prophétisais, il y eut un bruit, et voici qu'il y eut un tremblement de terre. Et les os se rapprochèrent les uns des autres, l'un de l'autre.
8 Mo wò ó, iṣan ara àti ẹran-ara farahàn lára wọn, awọ ara sì bò wọ́n, ṣùgbọ́n kò sí èémí nínú wọn.
Je regardai, et voici, il y avait sur eux des nerfs, de la chair qui montait, et de la peau qui les recouvrait; mais il n'y avait en eux aucun souffle.
9 Lẹ́yìn náà ni ó sọ fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí èémí; sọtẹ́lẹ̀, ọmọ ènìyàn, kí ó sì sọ fún un pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: wá láti atẹ́gùn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, ìwọ èémí, kí ó sì mí èémí sínú àwọn tí a pa wọ̀nyí, kí wọn kí ó lè wà ní ààyè.’”
Et il me dit: « Prophétise au vent, prophétise, fils de l'homme, et dis au vent: « Le Seigneur Yahvé dit: « Venez des quatre vents, soufflez, soufflez sur ces morts, et qu'ils vivent »".
10 Nítorí náà, mo sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ṣe pa á láṣẹ fún mi, èémí sì wọ inú wọn; wọ́n di alààyè, wọ́n sì dìde dúró lórí ẹsẹ̀ wọn—pẹ̀lú ìhámọ́ra tí ó pọ̀.
Et je prophétisai comme il me l'avait ordonné, et le souffle entra en eux, et ils vécurent, et se tinrent sur leurs pieds, une armée extrêmement grande.
11 Lẹ́yìn náà ó sọ fún mi: “Ọmọ ènìyàn, àwọn egungun wọ̀nyí ni gbogbo ìdílé Israẹli. Wọ́n sọ wí pé, ‘Egungun wa ti gbẹ ìrètí wa sì ti lọ; a ti gé wa kúrò.’
Il me dit alors: « Fils d'homme, ces os, c'est toute la maison d'Israël. Voici qu'ils disent: 'Nos os sont desséchés, et notre espoir est perdu. Nous sommes complètement isolés.
12 Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fun wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Ẹ̀yin ènìyàn mi, Èmi yóò ṣí àwọn ibojì yín, èmi yóò sì mú yín wá si ilẹ̀ Israẹli.
C'est pourquoi prophétise et dis-leur: « Le Seigneur Yahvé dit: « Voici que j'ouvre vos tombeaux, je vous fais sortir de vos tombeaux, mon peuple, et je vous fais entrer dans le pays d'Israël.
13 Ẹ̀yin o sì mọ̀ èmi ni Olúwa, nígbà tí èmi bá ti ṣí ibojì yín, ẹ̀yin ènìyàn mi, ti èmi bá si mú un yín dìde kúrò nínú ibojì yín.
Vous saurez que je suis l'Éternel, quand j'aurai ouvert vos tombeaux et que je vous aurai fait sortir de vos tombeaux, mon peuple.
14 Èmi yóò fi èémí mi sínú yín, ẹ̀yin yóò sì yè, èmi yóò sì mú kí ẹ fi lélẹ̀ ní ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi sì ti ṣe ni Olúwa wí.’”
Je mettrai mon Esprit en vous, et vous vivrez. Alors je vous placerai dans votre pays, et vous saurez que moi, Yahvé, j'ai parlé et que j'ai agi, dit Yahvé'".
15 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá:
La parole de Yahvé me fut adressée en ces termes:
16 “Ọmọ ènìyàn, mú igi pátákó kan kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti Juda àti ti Israẹli tí ó ní àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’ Lẹ́yìn náà, kí ó mú igi pátákò mìíràn kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti tí Josẹfu (tí ó túmọ̀ sí ti Efraimu) àti gbogbo ilé Israẹli tí ó ni àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’
« Toi, fils de l'homme, prends un bâton et écris dessus: « Pour Juda et pour les enfants d'Israël, ses compagnons ». Prends ensuite un autre bâton, et écris dessus: « Pour Joseph, le bâton d'Ephraïm, et pour toute la maison d'Israël, ses compagnons ».
17 So wọ́n papọ̀ sí ara igi kan nítorí náà wọn yóò di ọ̀kan ní ọwọ́ rẹ.
Puis tu les joindras l'un à l'autre en un seul bâton, pour qu'ils ne fassent qu'un dans ta main.
18 “Nígbà tí àwọn ara ìlú rẹ bá béèrè lọ́wọ́ rẹ pé, ‘Ṣé ìwọ kò ní sọ ohun tí èyí túmọ̀ sí fún wa?’
« Quand les enfants de ton peuple te diront: « Ne veux-tu pas nous montrer ce que tu entends par là? »
19 Sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò gba igi Josẹfu—èyí tí ó wà ní ọwọ́ Efraimu—àti ti ẹ̀yà Israẹli tí ó parapọ̀ mọ́ ọn, kí ó sì só papọ̀ mọ́ igi Juda, láti sọ wọ́n di igi kan ṣoṣo, wọn yóò sì di ọ̀kan ní ọwọ́ mi.’
dis-leur: « Le Seigneur Yahvé dit: « Voici, je prendrai le bâton de Joseph, qui est dans la main d'Ephraïm, et les tribus d'Israël qui lui sont associées; je les mettrai avec lui, avec le bâton de Juda, et j'en ferai un seul bâton, et ils ne feront qu'un dans ma main.
20 Gbé igi pátákó tí ó kọ nǹkan sí i sókè ní iwájú wọn,
Les bâtons sur lesquels vous écrivez seront dans votre main, sous leurs yeux. »
21 kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Israẹli jáde kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ. Èmi yóò ṣà wọ́n jọ pọ̀ láti gbogbo agbègbè, èmi yóò sì mú wọn padà sí ilẹ̀ ara wọn.
Dis-leur: « Le Seigneur Yahvé dit: « Voici que je vais prendre les enfants d'Israël du milieu des nations où ils sont allés, je les rassemblerai de tous côtés et je les ramènerai dans leur pays.
22 Èmi yóò ṣe wọ́n ní orílẹ̀-èdè kan ní ilẹ̀ náà, ní orí òkè Israẹli, ọba kan ni yóò wà lórí gbogbo wọn, wọn kì yóò sì jẹ́ orílẹ̀-èdè méjì mọ́, tàbí kí a pín wọn sí ìjọba méjì.
Je ferai d'eux une seule nation dans le pays, sur les montagnes d'Israël. Un seul roi sera leur roi à tous. Ils ne seront plus deux nations. Ils ne seront plus du tout divisés en deux royaumes.
23 Wọn kì yóò sì tún fi àwọn òrìṣà wọn ba ara wọn jẹ́ mọ́, tàbí ohun ìríra wọn, tàbí ohun ìrékọjá wọn: ṣùgbọ́n èmi yóò gbà wọn là kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àgàbàgebè wọn, èmi yóò sì wẹ̀ wọn mọ́. Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
Ils ne se souilleront plus par leurs idoles, ni par leurs abominations, ni par aucune de leurs transgressions; mais je les délivrerai de toutes les demeures où ils ont péché, et je les purifierai. Ils seront mon peuple, et je serai leur Dieu.
24 “‘Dafidi ìránṣẹ́ mi ni yóò jẹ ọba lórí wọn, gbogbo wọn yóò sì ní olùṣọ àgùntàn kan. Wọn yóò sì tẹ̀lé òfin mi, wọn yóò sì ṣe àníyàn láti pa àṣẹ mi mọ́.
"''Mon serviteur David sera leur roi. Ils auront tous un seul berger. Ils marcheront dans mes ordonnances, observeront mes lois et les mettront en pratique.
25 Wọn yóò gbé ní ilẹ̀ tí mo fún Jakọbu ìránṣẹ́ mi, ilẹ̀ tí àwọn baba yín ń gbé. Àwọn àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn ni yóò máa gbé ibẹ̀ láéláé, ìránṣẹ́ mi Dafidi ni yóò jẹ́ Ọmọ-aládé wọn láéláé.
Ils habiteront dans le pays que j'ai donné à mon serviteur Jacob et dans lequel vos pères ont vécu. Ils y habiteront, eux, leurs enfants et les enfants de leurs enfants, pour toujours. David, mon serviteur, sera leur prince pour toujours.
26 Èmi yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn, yóò sì jẹ́ májẹ̀mú títí ayérayé. Èmi yóò gbé wọn kalẹ̀, èmi yóò sì sọ wọ́n di púpọ̀ ní iye, èmi yóò sì gbé ilé mímọ́ mi kalẹ̀ ní àárín wọn títí láé.
Je conclurai avec eux une alliance de paix. Ce sera une alliance éternelle avec eux. Je les placerai, je les multiplierai, et je placerai mon sanctuaire au milieu d'eux pour toujours.
27 Ibùgbé mí yóò wà pẹ̀lú wọn, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run wọn, wọn yóò sì jẹ́ ènìyàn mi.
Ma tente sera aussi avec eux. Je serai leur Dieu, et ils seront mon peuple.
28 Nígbà náà ni àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa sọ Israẹli di mímọ́, nígbà tí ibi mímọ́ mi bá wà ní àárín wọn títí ayérayé.’”
Les nations sauront que je suis Yahvé qui sanctifie Israël, lorsque mon sanctuaire sera au milieu d'eux pour toujours. »''"

< Ezekiel 37 >