< Daniel 1 >

1 Ní ọdún kẹta tí Jehoiakimu jẹ ọba Juda, Nebukadnessari ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu, ó sì kọlù ú pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
La troisième année du règne de Jojakim, roi de Juda, Nebucadnetsar, roi de Babylone, vint à Jérusalem et l'assiégea.
2 Olúwa sì fa Jehoiakimu ọba Juda lé e lọ́wọ́, pẹ̀lú àwọn ohun èlò ilé Ọlọ́run. Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó kó lọ sí ilé òrìṣà ní Babeli, sí inú ilé ìṣúra òrìṣà rẹ̀.
L'Éternel livra entre ses mains Jehoïakim, roi de Juda, avec une partie des ustensiles de la maison de Dieu, et il les transporta au pays de Schinear, dans la maison de son dieu. Il apporta les ustensiles dans la maison du trésor de son dieu.
3 Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Aṣipenasi, olórí àwọn ìwẹ̀fà ààfin rẹ̀ pé, kí ó mú nínú àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n wá láti ìdílé ọba àti lára àwọn tí ó wá láti ilé ọlá.
Le roi parla à Ashpenaz, maître de ses eunuques, pour qu'il fasse venir quelques-uns des enfants d'Israël, de la descendance royale et des nobles:
4 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí kò ní àbùkù ara, tí wọ́n rẹwà, tí wọ́n sì fi ìfẹ́ sí ẹ̀kọ́ hàn, tí wọ́n sì ní ìmọ̀, tí òye tètè ń yé àti àwọn tí ó kún ojú òsùwọ̀n láti ṣiṣẹ́ ní ààfin ọba kí ó kọ́ wọ́n ní èdè àti onírúurú ẹ̀kọ́ ìwé ti àwọn Babeli.
des jeunes gens qui n'avaient pas de défaut, mais qui étaient de bonne constitution, habiles en toute sagesse, doués de savoir, comprenant la science, et qui étaient capables de se tenir dans le palais du roi; et qu'il leur enseignât le savoir et la langue des Chaldéens.
5 Ọba pèsè oúnjẹ ojoojúmọ́ àti wáìnì láti orí tábìlì i rẹ̀ fún wọn, ó sì kọ́ wọn fún ọdún mẹ́ta. Lẹ́yìn náà ni wọn yóò bẹ̀rẹ̀ sí í ṣiṣẹ́ fún ọba.
Le roi leur donna une portion quotidienne des mets du roi et du vin qu'il buvait, et leur imposa une nourriture de trois ans, à l'issue de laquelle ils se présenteraient devant le roi.
6 Lára àwọn wọ̀nyí ni àwọn tó wá láti Juda: Daniẹli, Hananiah, Miṣaeli àti Asariah.
Or, parmi ces enfants de Juda, il y avait Daniel, Hanania, Mishaël et Azaria.
7 Olórí àwọn ìwẹ̀fà fún wọn ní orúkọ tuntun: Ó fún Daniẹli ní Belteṣassari, ó fún Hananiah ní Ṣadraki, ó fún Miṣaeli ní Meṣaki àti Asariah ní Abednego.
Le prince des eunuques leur donna des noms: à Daniel, il donna le nom de Beltschatsar; à Hanania, celui de Shadrac; à Mishael, celui de Meshach; et à Azaria, celui d'Abednego.
8 Ṣùgbọ́n Daniẹli pinnu ní ọkàn ara rẹ̀ pé òun kò ní ba ara òun jẹ́ pẹ̀lú oúnjẹ àti wáìnì ọba, nígbà náà ni ó gba ààyè lọ́wọ́ olórí àwọn ìwẹ̀fà wí pé òun kò fẹ́ ba ara òun jẹ́ ní ọ̀nà yìí.
Mais Daniel résolut dans son cœur de ne pas se souiller avec les mets du roi et avec le vin qu'il buvait. Il demanda donc au prince des eunuques de ne pas se souiller.
9 Ọlọ́run mú kí Daniẹli rí ojúrere àti àánú gbà láti ọwọ́ olórí àwọn ìwẹ̀fà,
Dieu fit en sorte que Daniel trouve de la bonté et de la compassion aux yeux du prince des eunuques.
10 ṣùgbọ́n olórí àwọn ìwẹ̀fà sọ fún Daniẹli pé, “Mo bẹ̀rù olúwa mi, ẹni tí o ti pèsè oúnjẹ àti ohun mímu rẹ. Báwo ni ìrísí rẹ yóò ṣe burú jù ti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ẹlẹgbẹ́ ẹ̀ rẹ lọ? Nígbà náà ni èmi yóò fi orí mi wéwu lọ́dọ̀ ọba.”
Le prince des eunuques dit à Daniel: « Je crains mon seigneur le roi, qui a fixé votre nourriture et votre boisson. Car pourquoi verrait-il vos visages plus mauvais que ceux des jeunes gens de votre âge? Vous mettriez alors ma tête en danger auprès du roi. »
11 Nígbà náà ni Daniẹli sọ fún olùṣọ́ tí olórí àwọn ìwẹ̀fà yàn lórí i Daniẹli, Hananiah, Miṣaeli àti Asariah pé,
Alors Daniel dit à l'intendant que le prince des eunuques avait nommé sur Daniel, Hanania, Mischaël et Azaria:
12 “Jọ̀wọ́ dán àwa ìránṣẹ́ rẹ wò fún ọjọ́ mẹ́wàá. Má ṣe fún wa ní ohun kankan, àfi ewébẹ̀ láti jẹ àti omi láti mu.
« Mets tes serviteurs à l'épreuve, je t'en prie, pendant dix jours; qu'ils nous donnent des légumes à manger et de l'eau à boire.
13 Nígbà náà ni kí o fi ìrísí i wa wé ti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí wọ́n ń jẹ oúnjẹ ọba, kí o sì ṣe àwa ìránṣẹ́ rẹ ní ìbámu pẹ̀lú u bí o bá ṣe rí i sí.”
Puis, que l'on examine devant toi notre visage et celui des jeunes gens qui mangent les mets du roi; et selon ce que tu verras, traite tes serviteurs. »
14 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì gbà láti dán wọn wò fún ọjọ́ mẹ́wàá.
Il les écouta donc à ce sujet et les mit à l'épreuve pendant dix jours.
15 Lẹ́yìn ọjọ́ kẹwàá ara wọn le, wọ́n sì sanra ju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí wọ́n ń jẹ oúnjẹ ọba lọ.
Au bout de dix jours, leur visage était plus beau et ils étaient plus gras que tous les jeunes gens qui avaient mangé les mets du roi.
16 Bẹ́ẹ̀ ni olùṣọ́ mú oúnjẹ àdídùn àti wáìnì tí ó yẹ kí wọ́n mu kúrò, ó sì fún wọn ní ewébẹ̀ dípò rẹ̀.
L'intendant enleva leurs mets et le vin qu'on leur avait donné à boire, et leur donna des légumes.
17 Ọlọ́run fún àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọ̀nyí ní ìmọ̀ àti òye nínú gbogbo onírúurú ìwé àti ẹ̀kọ́ ọ wọn: Daniẹli sì ní òye ìran àti àlá ní oríṣìíríṣìí.
Quant à ces quatre jeunes gens, Dieu leur donna de la connaissance et de l'habileté dans toute l'instruction et la sagesse; et Daniel eut l'intelligence de toutes les visions et de tous les songes.
18 Ní òpin ìgbà tí ọba dá, pé kí a mú wọn wá sínú ààfin, olórí àwọn ìwẹ̀fà mú wọn wá síwájú ọba Nebukadnessari.
A la fin des jours que le roi avait fixés pour les faire venir, le prince des eunuques les fit venir devant Nebucadnetsar.
19 Ọba sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì rí i pé kò sí ẹni tí ó dàbí i Daniẹli, Hananiah, Miṣaeli àti Asariah; nítorí náà wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣe iṣẹ́ ọba.
Le roi s'entretint avec eux, et il ne se trouva parmi eux personne comme Daniel, Hanania, Mishaël et Azaria. Ils se tinrent donc devant le roi.
20 Nínú gbogbo ọ̀ràn ọgbọ́n àti òye tí ọba ń béèrè lọ́wọ́ wọn, ó rí i pé wọ́n sàn ní ìlọ́po mẹ́wàá ju gbogbo àwọn amòye àti ọlọ́gbọ́n tí ó wà ní gbogbo ìjọba rẹ̀.
Pour toutes les questions de sagesse et d'intelligence que le roi leur posa, il les trouva dix fois meilleurs que tous les magiciens et enchanteurs qui étaient dans tout son royaume.
21 Daniẹli sì wà níbẹ̀ títí di ọdún kìn-ín-ní ọba Kirusi.
Daniel a continué jusqu'à la première année du roi Cyrus.

< Daniel 1 >