< Ezekiel 36 >

1 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn òkè gíga Israẹli kí o sì wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè gíga Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Əmdi sǝn, i insan oƣli, Israil taƣliriƣa bexarǝt berip mundaⱪ degin: — Israil taƣliri, Pǝrwǝrdigarning sɵzini anglanglar: —
2 Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Àwọn ọ̀tá sọ nípa yín pé, “Háà! Àwọn ibi gíga ìgbàanì ti di ohun ìní wa.”’
Rǝb Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Düxmǝnning silǝrgǝ ⱪarap: «Waⱨ! Mǝnggü yuⱪiri jaylar bizgǝ tǝǝlluⱪ boldi!» degini tüpǝylidin,
3 Nítorí náà, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé wọn sọ ọ di ahoro, tí wọn sì ń dọdẹ rẹ ní gbogbo ọ̀nà kí ìwọ kí ó lè di ìní fún àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù, àti ohun ti àwọn ènìyàn ń sọ ọ̀rọ̀ ìríra àti ìdíbàjẹ́ sí,
xunga bexarǝt berip mundaⱪ degin: — Rǝb Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Bǝrⱨǝⱪ, qünki ular silǝrni wǝyranǝ ⱪilip, ǝllǝrdin ⱪalƣanliriƣa tǝwǝ ⱪilixⱪa ⱨǝryandin silǝrni ǝzgǝnliki tüpǝylidin, wǝ silǝr ǝllǝr arisida sɵz-qɵqǝk wǝ tɵⱨmǝt obyekti bolup ⱪalƣanliⱪinglardin,
4 nítorí náà, ẹ̀yin òkè gíga Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn òkè gíga àti àwọn òkè kéékèèké, fún àfonífojì ńlá àti àfonífojì kéékèèké, fún àwọn ibi ìsọdahoro ìparun àti fún àwọn ìlú tí a ti kọ̀sílẹ̀ tí a ti kó tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù ní àyíká sì fi ṣe ẹlẹ́yà,
ǝmdi xunga, i Israil taƣliri, Rǝb Pǝrwǝrdigarning sɵzini anglanglar: — Rǝb Pǝrwǝrdigar ǝllǝrdin ⱪalƣanliriƣa olja ⱨǝm mazaⱪ obyekti bolup ⱪalƣan taƣlar, egizliklǝr, jiralar wǝ jilƣilarƣa, wǝyran bolƣan harabilǝr wǝ taxliwetilgǝn xǝⱨǝrlǝrgǝ mundaⱪ dǝydu: —
5 èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ìgbóná ọkàn ní mo sọ̀rọ̀ sí àwọn kèfèrí yòókù, àti sí Edomu, nítorí pẹ̀lú ìbínú àti ìjowú ní ọkàn wọn ni wọ́n sọ ilé mi di ohun ìní wọn, kí wọn kí o lè kó pápá oko tútù rẹ̀.’
Xunga Rǝb Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Huxal boluxup ⱪǝlbidiki pütün ɵqmǝnliki bilǝn Mening zeminimni ɵzlirigǝ tǝǝlluⱪ boluxⱪa bekitip, uni bulang-talang ⱪiliwalayli degǝn ǝllǝrdin ⱪalƣanliriƣa wǝ Edomdikilǝrning ⱨǝmmisigǝ bǝrⱨǝⱪ, Mǝn [Ɵz hǝlⱪimgǝ] bolƣan ⱪizƣinliⱪimdin qiⱪⱪan aqqiⱪ otida sɵz ⱪildim: —
6 Nítorí náà, sọtẹ́lẹ̀ nípa ilẹ̀ Israẹli náà kí o sì sọ sí àwọn òkè gíga náà àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn àfonífojì ńlá àti sí àwọn àfonífojì kéékèèké, ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi sọ̀rọ̀ nínú ìrunú owú mi nítorí pé ìwọ ti jìyà ìfiṣẹ̀sín àwọn orílẹ̀-èdè.
Israil zemini toƣruluⱪ bexarǝt berip, taƣlar, egizliklǝr, jiralar wǝ jilƣilarƣa sɵz ⱪilip mundaⱪ degin: — Rǝb Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Mana, Mǝn Ɵz [hǝlⱪimgǝ bolƣan] ⱪizƣinliⱪimdin ⱪǝⱨrim bilǝn sɵz ⱪildim — qünki silǝr ǝllǝrning mazaⱪ-aⱨanǝtlirini yegǝnsilǝr.
7 Nítorí náà, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi ṣe ìbúra nípa nína ọwọ́ mi sókè pé; àwọn orílẹ̀-èdè àyíká rẹ náà yóò jìyà ìfiṣẹ̀sín.
— Xunga Rǝb Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Mǝn ⱪolumni kɵtürüp xundaⱪ ⱪǝsǝm iqkǝnki, bǝrⱨǝⱪ, ǝtrapinglardiki ǝllǝr ɵzining mazaⱪ-aⱨanǝtlirini ɵzi ixitidu.
8 “‘Ṣùgbọ́n ìwọ, òkè gíga Israẹli, yóò mú ẹ̀ka àti èso fún àwọn ènìyàn mi Israẹli, nítorí wọn yóò wá sílé ní àìpẹ́ yìí.
Lekin silǝr, i Israil taƣliri, xahlinisilǝr, hǝlⱪim Israilƣa mewǝ berisilǝr; qünki ular pat arida ⱪaytip kelidu.
9 Èmi ń ṣe àníyàn fún ọ, èmi yóò sì fi rere wọ̀ ọ́; àwa yóò tu ọ́, àwa yóò sì gbìn ọ́,
Qünki mana, Mǝn silǝr tǝripinglardidurmǝn; Mǝn silǝrgǝ ⱪaraymǝn, silǝr yumxitilisilǝr ⱨǝm terilisilǝr.
10 èmi yóò sì sọ iye àwọn ènìyàn di púpọ̀ nínú rẹ àti gbogbo ilé Israẹli. Àwọn ìlú yóò di ibùgbé, a yóò sì tún àwọn ibi ìparun kọ́.
Wǝ Mǝn üstünglǝrdǝ adǝmlǝrni, yǝni Israilning pütkül jǝmǝtini, ularning barliⱪini kɵpǝytimǝn; xǝⱨǝrlǝr aⱨalilik bolidu, harabilǝr ⱪaytidin ⱪurulidu.
11 Èmi yóò sọ iye ènìyàn àti ẹran dì púpọ̀ nínú yín, wọn yóò sì so èso, wọn yóò sì di púpọ̀ yanturu. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn máa gbé nínú rẹ bí ti àtẹ̀yìnwá, èmi yóò sì mú kí o ṣe rere ju ìgbà àtijọ́ lọ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ pé èmi ni Olúwa.
Mǝn üstünglǝrdǝ adǝm ⱨǝm ⱨaywanlarni kɵpǝytimǝn, ular awup nǝsil kɵridu; Mǝn ɵtkǝn zamanlardikidǝk silǝrni olturaⱪliⱪ ⱪilimǝn; bǝrⱨǝⱪ, ⱨalinglarni ǝslidikidin ǝwzǝl ⱪilimǝn; silǝr Mening Pǝrwǝrdigar ikǝnlikimni bilip yetisilǝr.
12 Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn, àní àwọn ènìyàn Israẹli, rìn lórí rẹ̀. Wọn yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì di ogún ìní wọn; ìwọ kì yóò sì gba àwọn ọmọ wọn lọ́wọ́ wọn mọ́.
Mǝn üstünglǝrgǝ adǝmlǝrni, yǝni hǝlⱪim Israilni mangdurimǝn; ular silǝrgǝ igidarqiliⱪ ⱪilidu, silǝr ularning mirasi bolisilǝr; silǝr yǝnǝ ularni baliliridin juda ⱪilmaysilǝr.
13 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé àwọn ènìyàn sọ fún ọ pé, “Ìwọ pa àwọn ènìyàn run, ìwọ sì gba àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè lọ́wọ́ wọn,”
Rǝb Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Qünki ularning silǝrgǝ: «Silǝr adǝmlǝrni yǝysilǝr, ɵz elinglarni balilardin juda ⱪilƣansilǝr!» degini tüpǝylidin,
14 nítorí náà ìwọ kì yóò pa àwọn ènìyàn run tàbí mú kì orílẹ̀-èdè di aláìlọ́mọ mọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.
ǝmdi silǝr yǝnǝ adǝmlǝrni yemǝysilǝr, ɵz elinglarni baliliridin yǝnǝ juda ⱪilmaysilǝr, dǝydu Rǝb Pǝrwǝrdigar.
15 Èmi kì yóò mú ki ó gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn láti ọ̀dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè mọ́, ìwọ kì yóò jìyà ọ̀rọ̀ ìfiṣẹ̀sín láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tàbí mú kí orílẹ̀-èdè rẹ ṣubú, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
— Mǝn silǝrgǝ yǝnǝ ǝllǝrning mazaⱪ-aⱨanǝtlirini anglatⱪuzmaymǝn; silǝr ǝllǝrning tapa-tǝnisini yǝnǝ kɵtürmǝysilǝr, silǝr ɵz elinglarni ⱪaytidin yiⱪitmaysilǝr, — dǝydu Rǝb Pǝrwǝrdigar.
16 Síwájú sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Pǝrwǝrdigarning sɵzi manga kelip xundaⱪ deyildi: —
17 “Ọmọ ènìyàn, nígbà tí àwọn ènìyàn Israẹli ń gbé ní ilẹ̀ wọn, wọ́n bà á jẹ́ nípa ìwà àti ìṣe wọn. Ìwà wọn dàbí nǹkan àkókò àwọn obìnrin ni ojú mi.
I insan oƣli, Israil jǝmǝti ɵz zeminida turƣan qaƣlarda, ular ɵz yoli ⱨǝm ⱪilmixliri bilǝn uni bulƣiƣan; Mening aldimda ularning yoli ay kɵrgǝn ayalning napakliⱪiƣa ohxax.
18 Nítorí náà mo tú ìbínú mi jáde sórí wọn nítorí wọn ti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ àti nítorí pé wọ́n ti fi ère wọn ba a jẹ́.
Xunga zeminƣa tɵkkǝn ⱪan üqün, zeminni mǝbudliri bilǝn bulƣiƣanliⱪi üqün, Mǝn ⱪǝⱨrimni ular üstigǝ tɵktum;
19 Mo tú wọn ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, a sì fọ́n wọn ká sí àwọn ìlú; mo ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà àti ìṣe wọn.
Mǝn ularni ǝllǝr arisiƣa tarⱪitiwǝttim, ular mǝmlikǝtlǝr iqigǝ tarilip kǝtti; Mǝn ularning yolliri ⱨǝm ⱪilmixliri boyiqǝ ularning üstigǝ ⱨɵküm qiⱪardim.
20 Gbogbo ibi tí wọ́n lọ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè ni wọn ti sọ orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́, nítorí tí a sọ nípa wọn pé, ‘Ìwọ̀nyí ni àwọn ènìyàn Olúwa, síbẹ̀ wọn ní láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀.’
Ular baridiƣan ⱨǝrⱪaysi ǝllǝrgǝ kǝlgǝndǝ, ular toƣrisida: «Bular Pǝrwǝrdigarning hǝlⱪi, biraⱪ ular Uning zeminidin qiⱪⱪan!» — deyilgǝndǝ, ular yǝnila Mening pak-muⱪǝddǝs namimni bulƣiƣan;
21 Orúkọ mímọ́ mi jẹ́ mi lógún, èyí tí ilé Israẹli sọ di aláìmọ́ ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ.
Biraⱪ Mǝn Israil jǝmǝti barƣan ⱨǝrⱪaysi ǝllǝr arisida bulƣanƣan pak-muⱪǝddǝs namim üqün kɵngül bɵldüm.
22 “Nítorí náà, sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Kì í ṣe nítorí rẹ, ìwọ ilé Israẹli, ni èmi yóò ṣe ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí, ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mímọ́ mi, èyí ti ìwọ ti sọ di aláìmọ́ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti lọ.
Xunga Israil jǝmǝtigǝ mundaⱪ degin: — Rǝb Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Mǝn bu ixni silǝrni dǝp ǝmǝs, i Israil jǝmǝti, bǝlki silǝr barƣan ⱨǝrⱪaysi ǝllǝr arisida silǝr bulƣiƣan ɵz pak-muⱪǝddǝs namim üqün ⱪilimǝn.
23 Èmi yóò fi jíjẹ́ mímọ́ orúkọ ńlá mi, èyí tí a ti sọ di aláìmọ́ hàn ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè, orúkọ tí ìwọ ti sọ di aláìmọ́ ni àárín wọn. Nígbà náà àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, ni Olúwa Olódùmarè wí, nígbà tí mo bá fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ yín ni iwájú wọn.
Mǝn ǝllǝr arisida bulƣanƣan, Ɵzümning büyük namimni pak-muⱪǝddǝs dǝp kɵrsitimǝn; namimni dǝl silǝr ular arisida bulƣiƣan; ularning kɵz aldida Mǝn Ɵzümni silǝrning aranglarda pak-muⱪǝddǝs kɵrsǝtkinimdǝ, ǝllǝr Mening Pǝrwǝrdigar ikǝnlikimni bilip yetidu, — dǝydu Rǝb Pǝrwǝrdigar.
24 “‘Nítorí èmi yóò mú yín jáde kúrò ni àwọn orílẹ̀-èdè náà; Èmi yóò ṣà yín jọ kúrò ní gbogbo àwọn ìlú náà; Èmi yóò sì mú yín padà sí ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín.
Mǝn silǝrni ǝllǝr arisidin elip, mǝmlikǝtlǝr iqidin yiƣip, silǝrni ɵz zemininglarƣa ⱪayturimǝn.
25 Èmi yóò wọ́n omi tó mọ́ sí yín lára ẹ̀yin yóò sì mọ́; Èmi yóò sì fọ̀ yín mọ́ kúrò nínú gbogbo ìwà èérí yin gbogbo àti kúrò nínú gbogbo òrìṣà yin.
— Mǝn süpsüzük suni üstünglarƣa qaqimǝn, buning bilǝn silǝr pak bolisilǝr. Silǝrni ⱨǝmmǝ paskiniliⱪinglardin wǝ butliringlardin paklaymǝn.
26 Èmi yóò fún yín ni ọkàn tuntun, èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú yín; Èmi yóò sì mú ọkàn òkúta kúrò nínú yín, èmi yóò sì fi ọkàn ẹran fún yín.
Mǝn silǝrgǝ yengi ⱪǝlb berimǝn, iqinglarƣa yengi bir roⱨ salimǝn; teninglardiki tax yürǝkni elip taxlap, meⱨrlik bir ⱪǝlbni ata ⱪilimǝn.
27 Èmi yóò fi ẹ̀mí mi sínú yín, èmi yóò sì mú ki ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ẹ sì fiyèsí àti pa òfin mi mọ́.
Mening Roⱨimni iqinglarƣa kirgüzüp, silǝrni ǝmr-pǝrmanlirim boyiqǝ mangƣuzimǝn, ⱨɵkümlirimni tutⱪuzimǝn, xuning bilǝn ularƣa ǝmǝl ⱪilisilǝr;
28 Ẹ̀yin yóò sì máa gbé ilẹ̀ náà tí mo ti fi fún àwọn baba ńlá yín; ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
silǝr Mǝn ata-bowiliringlarƣa tǝⱪdim ⱪilƣan zeminda yaxaysilǝr; Mening ⱪowmim bolisilǝr, Mǝn silǝrning Hudayinglar bolimǝn.
29 Èmi yóò sì gbà yín kúrò nínú gbogbo ìwà àìmọ́ yín. Èmi yóò pèsè ọkà, èmi yóò sì mú kí ó pọ̀ yanturu, èmi kì yóò sì mú ìyàn wá sí orí yín.
Mǝn silǝrni barliⱪ paskiniqiliktin ⱪutⱪuzimǝn; Mǝn buƣdayni awun boluxⱪa buyruymǝn; üstünglǝrgǝ ⱨeq aqarqiliⱪni ⱪoymaymǝn;
30 Èmi yóò sọ èso àwọn igi yín àti ohun ọ̀gbìn oko yín di púpọ̀, nítorí kí ẹ̀yin kí ó má ṣe jìyà ìdójútì mọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà nítorí ìyàn.
Mǝn dǝrǝhlǝrning mewisini wǝ etizdiki mǝⱨsulatlarni awutimǝnki, silǝr aqarqiliⱪ tüpǝyldin ǝllǝr arisida xǝrmǝndǝ bolmaysilǝr.
31 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò rántí àwọn ọ̀nà búburú àti àwọn ìwà ìkà yín, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ìwà tí kò bójúmu.
Silǝr rǝzil yolliringlar wǝ naqar ⱪilmixliringlarni ǝslǝp, ⱪǝbiⱨlikliringlar wǝ yirginqlik ⱪilƣanliringlar üqün ɵz-ɵzünglardin yirginisilǝr.
32 Mo fẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ń kò ṣe nǹkan wọ̀nyí nítorí yín, ni Olúwa Olódùmarè wí. Jẹ kí ojú kí ó tì yín, kí ẹ sì gba ẹ̀tẹ́ nítorí ìwà yín ẹ̀yin ilé Israẹli!
Silǝrgǝ mǝlum bolsunki, bu ixni ⱪilixim silǝr üqün ǝmǝs, — dǝydu Rǝb Pǝrwǝrdigar, — ɵz yolliringlar üqün hijil bolup xǝrmǝndǝ bolunglar, i Israil jǝmǝti.
33 “‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ tí mo wẹ̀ yín kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín gbogbo, èmi yóò ṣe àtúnṣe àwọn ìlú yín, wọn yóò sì ṣe àtúnkọ́ ìwólulẹ̀.
— Rǝb Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Mǝn ⱪǝbiⱨlikinglardin pakliƣan künidǝ, Mǝn xǝⱨǝrlǝrni aⱨalilik ⱪilimǝn, harabǝ ⱪalƣan jaylarmu ⱪaytidin ⱪurulidu.
34 Ilẹ̀ ahoro náà ní àwa yóò tún kọ́ ti kì yóò wà ní ahoro lójú àwọn tí ó ń gba ibẹ̀ kọjá mọ́.
Wǝyran ⱪilinƣan zemin ɵtüp ketiwatⱪan ⱨǝrbirining kɵz aldida wǝyranǝ kɵrünsimu, u ⱪaytidin terilidu.
35 Wọn yóò sọ wí pé, “Ilẹ̀ yìí tí ó ti wà ní ahoro tẹ́lẹ̀ ti dàbí ọgbà Edeni; àwọn ìlú tí ó wà ní wíwó lulẹ̀, ahoro tí a ti parun, ni àwa yóò mọdi sí tí yóò sì wà fún gbígbé ni ìsinsin yìí.”
Xuning bilǝn ular: «Bu wǝyran ⱪilinƣan zemin huddi Erǝm baƣqisidǝk boldi; harabǝ, wǝyran ⱪilinƣan xǝⱨǝrlǝr ⱨazir mustǝⱨkǝmlǝndi, aⱨalilik boldi» — dǝydu.
36 Nígbà náà àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà ní àyíká yín tí ó kù yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti tún àwọn ohun tí ó bàjẹ́ kọ́, mo sì ti tún ohun tí ó di ìṣòfo gbìn. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi yóò sì ṣe e?’
Wǝ ǝtrapida ⱪalƣan ǝllǝr Mǝnki Pǝrwǝrdigarning buzulƣan jaylarni ⱪurƣuqi ⱨǝm wǝyranǝ ⱪilinƣan yǝrlǝrni ⱪaytidin teriƣuqi ikǝnlikimni bilip yetidu; Mǝnki Pǝrwǝrdigar sɵz ⱪildim, buningƣa ǝmǝl ⱪilimǝn.
37 “Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò yí sí ilé Israẹli, èmi yóò sì ṣe èyí fún wọn. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn yín pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí àgùntàn,
Rǝb Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Mǝn yǝnila Israilning jǝmǝtining bu ixlarni tilǝydiƣan dua-tilawǝtlirigǝ ijabǝt ⱪilƣuqi bolimǝn; Mǝn ⱪoy padisidǝk ularning adǝmlirini awutimǝn;
38 kí ó pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí ọ̀wọ́ ẹran fún ìrúbọ ní Jerusalẹmu ní àsìkò àjọ̀dún tí a yàn. Ìlú ti a parun yóò wá kún fún agbo àwọn ènìyàn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.”
Muⱪǝddǝs dǝp ayrilƣan ⱪurbanliⱪ ⱪoy padisidǝk, bekitilgǝn ⱨeyt-bayramliriƣa beƣixlanƣan ⱪoy padisi Yerusalemƣa toldurulƣandǝk, harabǝ bolƣan xǝⱨǝrlǝr ⱪaytidin adǝm padiliri bilǝn toldurulidu; ular Mening Pǝrwǝrdigar ikǝnlikimni bilip yetidu.

< Ezekiel 36 >