< Ezekiel 25 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
La parole de l'Éternel me fut adressée, en ces mots:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
Fils d'homme, tourne ta face vers les fils d'Ammon, et prophétise contre eux.
3 Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
Dis aux enfants d'Ammon: « Écoute la parole du Seigneur Yahvé! Le Seigneur Yahvé dit: « Parce que vous avez dit: « Ah! » contre mon sanctuaire quand il a été profané, contre le pays d'Israël quand il a été dévasté, et contre la maison de Juda quand elle est allée en captivité,
4 kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
voici que je vous livre aux fils de l'Orient pour qu'ils vous possèdent. Ils établiront chez toi leurs campements et y feront leurs demeures. Ils mangeront tes fruits et boiront ton lait.
5 Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Je ferai de Rabba une étable pour les chameaux et des fils d'Ammon un lieu de repos pour les troupeaux. Alors vous saurez que je suis Yahvé ».
6 Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
Car le Seigneur Yahvé dit: « Parce que tu as battu des mains, tapé des pieds, et que tu t'es réjoui avec tout le mépris de ton âme contre le pays d'Israël,
7 nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
voici que j'étends ma main sur toi, et je te livre au pillage des nations. Je te retrancherai du milieu des peuples, et je te ferai périr hors des pays. Je te détruirai. Alors vous saurez que je suis Yahvé. »
8 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
« Le Seigneur Yahvé dit: « Parce que Moab et Séir disent: Voici la maison de Juda comme toutes les nations,
9 nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
voici, j'ouvrirai le côté de Moab, depuis ses villes, depuis les villes qui sont sur ses frontières, la gloire du pays, Beth Jeshimoth, Baal Meon et Kiriathaim,
10 Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
vers les fils de l'Orient, pour aller contre les fils d'Ammon; et je les donnerai en possession, afin qu'on ne se souvienne pas des fils d'Ammon parmi les nations.
11 Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
J'exécuterai des jugements sur Moab. Alors ils sauront que je suis Yahvé. »
12 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
"'Le Seigneur Yahvé dit: « Parce qu'Édom a traité la maison de Juda en se vengeant, parce qu'il l'a gravement offensée et s'est vengé d'elle, »
13 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
c'est pourquoi le Seigneur Yahvé dit: « J'étendrai ma main sur Édom, j'en exterminerai l'homme et le bétail, et je le réduirai en désert depuis Théman. Ils tomberont par l'épée jusqu'à Dedan.
14 Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
J'exercerai ma vengeance sur Édom par la main de mon peuple d'Israël. On fera à Édom selon ma colère et selon ma fureur. Alors ils connaîtront ma vengeance, dit le Seigneur Yahvé.
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
"'Le Seigneur Yahvé dit: « Parce que les Philistins se sont vengés, et qu'ils se sont vengés avec mépris de l'âme pour détruire avec une hostilité perpétuelle, »
16 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
c'est pourquoi le Seigneur Yahvé dit: « Voici, j'étendrai ma main sur les Philistins, j'exterminerai les Chéréthiens, et je détruirai le reste de la côte maritime.
17 Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”
J'exercerai sur eux une grande vengeance, avec des châtiments violents. Alors ils sauront que je suis Yahvé, quand j'exercerai sur eux ma vengeance. »''

< Ezekiel 25 >