< Ezekiel 24 >

1 Ní ọdún kẹsànán, oṣù kẹwàá, ọjọ́ kẹwàá, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
V devetem letu, v desetem mesecu, na deseti dan meseca je ponovno prišla k meni Gospodova beseda, rekoč:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ọjọ́ náà sílẹ̀, ọjọ́ náà gan an, nítorí ọba Babeli náà ti da ojú ti Jerusalẹmu ní ọjọ́ yìí gan an.
»Človeški sin, zapiši si ime dneva, celó tega istega dne. Babilonski kralj se je ta isti dan nameril zoper [prestolnico] Jeruzalem.
3 Sì pa òwe yìí fún ilé ọlọ́tẹ̀ náà, sọ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Gbé ìkòkò ìdáná náà ka iná, gbé e ka iná kí o sì da omi sí i nínú.
In izreci prispodobo uporni hiši ter jim reci: ›Tako govori Gospod Bog: ›Pristavi lonec, pristavi ga in prav tako vanj nalij vodo.
4 Kó àwọn ègé ẹran tí a gé náà sínú rẹ̀, gbogbo àwọn ègé ẹran tí ó tóbi, itan àti apá. Kó àwọn egungun tí ó dára jù sínú rẹ̀,
Zberi vanj kose, celó vsak dober kos, stegno in pleče; napolni ga z izbranimi kostmi.
5 mú àwọn tí ó jọjú nínú agbo ẹran. Kó àwọn egungun sí abẹ́ ẹ rẹ̀; sì jẹ́ kí ó hó dáradára sì jẹ́ kí àwọn egungun náà bọ̀ nínú rẹ̀.
Vzemi izbrano od tropa in pod njim prav tako sežgi kosti in naredi, da bo dobro vrelo in v njem naj prevrejo njegove kosti.‹
6 Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà, fún ìkòkò náà tí èérí rẹ̀ wà nínú rẹ̀, tí èérí kò dà kúrò lójú rẹ̀! Mú ẹran náà jáde ní ekìrí ekìrí má ṣe ṣà wọ́n mú.
Zato tako govori Gospod Bog: ›Gorje krvoločnemu mestu, loncu, čigar plast umazanije je v njem in katerega plast umazanije ni odšla od njega! Prinesi to ven, kos za kosom; naj noben žreb ne pade na to.
7 “‘Nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ó ta sílẹ̀ wà ní àárín rẹ̀; à á sí orí àpáta kan lásán kò dà á sí orí ilẹ̀, níbi ti erùpẹ̀ yóò ti bò ó.
Kajti njena kri je v njeni sredi; postavljala jo je na vrh skale; ni je izlivala na tla, da jo pokrije s prahom;
8 Láti bá à le jẹ́ kí ìbínú kí ó dé láti gbẹ̀san mo da ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sí orí àpáta kan lásán, kí o ma bà á wà ni bíbò.
da bi lahko povzročila razjarjenosti, da pride gor, da se maščuje; njeno kri sem postavil na vrh skale, da ne bi bila pokrita.‹
9 Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà! Èmi pàápàá yóò jẹ́ kí òkìtì iná náà tóbi.
Zato tako govori Gospod Bog: ›Gorje krvoločnemu mestu! Naredil bom celo grmado za velik ogenj.
10 Nítorí náà kó igi náà jọ sí i, kí o sì fi iná sí i. Ṣe ẹran náà dáradára, fi tùràrí dùn ún; kí o sì jẹ́ kí egungun náà jóná.
Nakopičite les, zanetite ogenj, použijte meso in ga dobro začinite in naj bodo kosti sežgane.
11 Lẹ́yìn náà gbé òfìfo ìkòkò náà lórí ẹyin iná kí idẹ rẹ̀ lè gbóná, kí ó lè pọ́n àti ki ìfófó rẹ̀ le di yíyọ́ nínú rẹ̀ kí èérí rẹ̀ le jó dànù.
Potem ga praznega postavite na ognjeno oglje, da njegov bron lahko razbeli in lahko zagori in da bo njegova umazanost lahko v njem stopljena, da bo plast umazanije v njem lahko použita.
12 Ó ti ba gbogbo akitiyan jẹ: èérí rẹ̀ kò sì jáde kúrò lára rẹ̀, èérí náà gan an yóò wà nínú iná.
Samo sebe je izmučila z lažmi in njena velika plast umazanije ni šla ven iz nje. Njena plast umazanije bo v ognju.
13 “‘Nísinsin yìí èérí rẹ̀ ni ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wà. Nítorí mo gbìyànjú láti wẹ̀ ọ́ mọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò sì mọ́ kúrò nínú ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, a kì yóò sì tún wẹ̀ ọ mọ́ kúrò nínú èérí rẹ, títí èmi yóò fi jẹ́ kí ìbínú mi balẹ̀ sórí rẹ̀.
V tvoji umazanosti je nespodobnost. Ker sem te očistil, ti pa nisi bila očiščena, ne boš več očiščena svoje umazanosti, dokler svoji razjarjenosti ne storim, da počiva na tebi.
14 “‘Èmi Olúwa ni ó sọ ọ́, yóò sì ṣe, èmi yóò sì ṣe é. Èmi kì yóò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá sí i, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọkàn mi padà; gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ, ni wọn yóò dá ọ lẹ́jọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Jaz, Gospod, sem to govoril. To se bo zgodilo in jaz bom to storil; ne bom šel nazaj niti ne bom prizanašal niti se ne bom kesal; glede na tvoje poti in glede na tvoja početja te bodo sodili, ‹ govori Gospod Bog.«
15 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá pé:
Prav tako je prišla k meni Gospodova beseda, rekoč:
16 “Ọmọ ènìyàn, kíyèsi i, mo mú ìfẹ́ ojú rẹ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, nípa lílù kan. Ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ gbààwẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sọkún, bẹ́ẹ̀ ni omijé ojú rẹ kò gbọdọ̀ kán sílẹ̀.
»Človeški sin, glej, z udarcem vzamem od tebe željo tvojih oči. Vendar ne boš žaloval niti jokal niti tvoje solze ne bodo tekle.
17 Má ṣe sọkún, má ṣe gbààwẹ̀ fún òkú. Wé ọ̀já sí orí rẹ, sì bọ bàtà sí ẹsẹ̀ rẹ, má ṣe bo ètè ìsàlẹ̀ rẹ, ma ṣe jẹ oúnjẹ tí àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.”
Zadrži se jokanja, nobenega žalovanja za mrtvimi ne opravljaj, nad svojo glavo si zaveži ruto in nadeni si svoje čevlje na svoja stopala in ne pokrivaj svojih ustnic in ne jej kruha od ljudi.«
18 Báyìí ni mo sọ̀rọ̀ fún àwọn ènìyàn ní òwúrọ̀, ní àṣálẹ́ ìyàwó mi sì kú. Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo ṣe bí a ti pàṣẹ fún mi.
Tako sem ljudstvu govoril zjutraj, zvečer pa je moja žena umrla; in zjutraj sem storil, kakor mi je bilo ukazano.
19 Lẹ́yìn náà àwọn ènìyàn bi mí léèrè pé, “Ṣe o kò ni sọ fún wa ohun ti nǹkan wọ̀nyí ní láti ṣe pẹ̀lú wa?”
In ljudstvo mi je reklo: »Ali nam ne boš povedal kaj so nam te stvari, da jih tako počneš?«
20 Mo sọ báyìí fún wọn pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Potem sem jim odgovoril: »K meni je prišla Gospodova beseda, rekoč:
21 Sọ fún ilé Israẹli, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, èmi yóò sọ ibi mímọ́ mi di ibi àìmọ́ tayọ agbára yín, ìfẹ́ ojú yín, ìkáàánú yín, àti ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin tí ẹ̀yin fi sílẹ̀ sẹ́yìn yóò ṣubú nípa idà.
›Govori Izraelovi hiši: ›Tako govori Gospod Bog: ›Glejte, oskrunil bom svoje svetišče, odličnost vaše moči, željo vaših oči in to, kar vaša duša pomiluje; in vaši sinovi in vaše hčere, ki ste jih pustili, bodo padli pod mečem.
22 Ẹyin yóò sì ṣe bí mo ti ṣe. Ẹ̀yin kì yóò bo ìsàlẹ̀ ojú yín tàbí jẹ oúnjẹ ti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.
In storili boste, kakor sem jaz storil: ne boste pokrili svojih ustnic niti jedli kruha od ljudi.
23 Ẹ̀yin yóò fi àwọn ọ̀já wé àwọn orí yín àti àwọn bàtà ni ẹsẹ̀ yín, ẹ̀yin kì yóò ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò ṣòfò dànù nítorí àwọn àìṣedéédéé yín, ẹ̀yin yóò sì máa kérora láàrín ara yín.
In vaše rute bodo na vaših glavah in vaši čevlji na vaših stopalih. Ne boste niti žalovali niti jokali; temveč boste hirali zaradi svojih krivičnosti in žalovali drug proti drugemu.
24 Esekiẹli yóò jẹ àmì fún un yín; ẹ̀yin yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe. Nígbà tí èyí bá ṣẹlẹ̀, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’
Tako vam je Ezekiel znamenje: glede na vse, kar je storil, boste vi storili. In ko to pride, boste spoznali, da jaz sem Gospod Bog.
25 “Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ, Ọmọ ènìyàn, kì yóò ha jẹ́ pé, ní ọjọ́ náà, nígbà ti mo bá gba agbára wọn, ayọ̀ wọn àti ògo wọn, ìfẹ́ ojú wọn, ohun tí wọn gbé ọkàn wọn lé, àti àwọn ọmọ ọkùnrin wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ obìnrin wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn,
Tudi ti, človeški sin, ali ne bo to na dan, ko jim odvzamem njihovo moč, radost njihove slave, željo njihovih oči in to, na kar so naravnali svoje ume, njihove sinove in njihove hčere,
26 ní ọjọ́ náà ẹni tí ó bá sálà yóò tọ̀ ọ́ wá láti sọ ìròyìn náà fún ọ.
da bo tisti, ki pobegne na ta dan, prišel k tebi, da ti povzroči, da to slišiš s svojimi lastnimi ušesi?
27 Ní ọjọ́ náà ẹnu rẹ yóò sì ṣí; ìwọ yóò sọ̀rọ̀, ìwọ kì yóò sì yadi mọ́. Báyìí ìwọ yóò jẹ́ àmì fún wọn; wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ní Olúwa.”
Na tisti dan se bodo tvoja usta odprla k tistemu, ki je pobegnil in govoril boš in ne boš več nem. Ti jim boš znamenje. In spoznali bodo, da jaz sem Gospod.‹«

< Ezekiel 24 >