< Ezekiel 20 >

1 Ní ọjọ́ kẹwàá, oṣù karùn-ún ọdún keje, ní díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá wádìí lọ́wọ́ Olúwa, wọn jókòó níwájú mi.
La septième année, le cinquième mois, le dixième jour du mois, quelques-uns des anciens d'Israël vinrent consulter l'Éternel et s'assirent devant moi.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
La parole de Yahvé me fut adressée en ces termes:
3 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún àwọn àgbàgbà Israẹli, kì ó sì wí fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ṣe ki ẹ lè wádìí lọ́dọ̀ mi ni ẹ ṣe wá? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi kì yóò gbà kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.’
« Fils d'homme, parle aux anciens d'Israël, et dis-leur: « Le Seigneur Yahvé dit: « Est-ce pour me consulter que vous êtes venus? Je suis vivant, dit le Seigneur Yahvé, et je ne me laisserai pas interroger par vous ».
4 “Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí? Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí ọmọ ènìyàn? Nítorí náà fi gbogbo ìwà ìríra baba wọn kò wọ́n lójú,
« Les jugeras-tu, fils de l'homme? Les jugeras-tu? Fais-leur connaître les abominations de leurs pères.
5 kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ní ọjọ́ tí mo yàn Israẹli, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ìbúra sí àwọn ọmọ ilé Jakọbu, mo sì fi ara mi hàn wọn ní Ejibiti, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ẹ̀jẹ́ wí pé, “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
Dis-leur: Le Seigneur Yahvé dit: « Le jour où j'ai choisi Israël, où j'ai juré aux descendants de la maison de Jacob, où je me suis fait connaître à eux au pays d'Égypte, où je leur ai juré: « Je suis Yahvé votre Dieu »,
6 Ní ọjọ́ náà mo lọ búra fún wọn pé, èmi yóò mú wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti lọ sí ilẹ̀ ti mo ti wá sílẹ̀ fún wọn, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
ce jour-là, je leur ai juré de les faire sortir du pays d'Égypte pour entrer dans un pays que je leur avais préparé, où coulent le lait et le miel, et qui est la gloire de tous les pays.
7 Mo sì wí fún wọn pé, “Kí olúkúlùkù nínú yín gbé ìríra ojú rẹ̀ kúrò, kí ẹ sì má bá sọ ara yín di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà Ejibiti, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
Je leur ai dit: « Que chacun de vous jette les abominations de ses yeux. Ne vous souillez pas avec les idoles d'Égypte. Je suis Yahvé, votre Dieu.
8 “‘Ṣùgbọ́n wọn ṣọ̀tẹ̀ sí mi wọn kò sì gbọ́rọ̀, wọn kò gbé àwòrán ìríra tí wọ́n dojúkọ kúrò níwájú wọn bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si kọ̀ àwọn òrìṣà Ejibiti sílẹ̀, torí náà mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí, èmi yóò sì jẹ́ kí ìbínú mi sẹ̀ lórí wọn ní ilẹ̀ Ejibiti.
"''Mais ils se sont rebellés contre moi et n'ont pas voulu m'écouter. Ils n'ont pas tous rejeté les abominations de leurs yeux. Ils n'ont pas non plus abandonné les idoles d'Égypte. Alors j'ai dit que je répandrais sur eux ma fureur, pour accomplir ma colère contre eux au milieu du pays d'Égypte.
9 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní jẹ́ kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí wọn ń gbé láàrín wọn, lójú àwọn ẹni tí mo ti fi ara hàn fún ara Israẹli nípa mímú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti.
Mais j'ai agi à cause de mon nom, afin qu'il ne soit pas profané aux yeux des nations parmi lesquelles ils se trouvaient, aux yeux desquelles je me suis fait connaître à eux en les faisant sortir du pays d'Égypte.
10 Nítorí náà, mo mú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti mo sì mú wọn wá sínú aginjù.
Je les fis sortir du pays d'Égypte et les conduisis dans le désert.
11 Mo sì fún wọn ni òfin mi, mo sì fi àwọn òfin mi hàn wọ́n; nítorí pé ẹni tó bá ṣe wọ́n yóò yè nípa wọn.
Je leur donnai mes lois et leur montrai mes ordonnances, que si un homme les met en pratique, il vivra en elles.
12 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún wọn ní ọjọ́ ìsinmi gẹ́gẹ́ bí àmì láàrín àwọn àti èmi, kí wọn lè mọ̀ pé èmi ni Olúwa tó sọ wọn di mímọ́.
Je leur ai aussi donné mes sabbats, comme un signe entre moi et eux, afin qu'ils sachent que je suis Yahvé qui les sanctifie.
13 “‘Síbẹ̀; ilé Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí mí nínú aginjù. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sì kọ àwọn òfin mi sílẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá pa á mọ́ yóò yè nínú rẹ̀. Wọn sì sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi sórí wọn, èmi yóò sì pa wọ́n run nínú aginjù.
"''Mais la maison d'Israël s'est rebellée contre moi dans le désert. Ils n'ont pas suivi mes lois et ils ont rejeté mes ordonnances, que si un homme les observe, il vivra en elles. Ils ont grandement profané mes sabbats. Alors j'ai dit que je répandrais ma colère sur eux dans le désert, pour les consumer.
14 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní mú kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí mo kó wọn jáde.
Mais j'ai agi pour l'honneur de mon nom, afin qu'il ne soit pas profané aux yeux des nations sous le regard desquelles je les ai fait sortir.
15 Nítorí náà, mo tún gbọ́wọ́ mi sókè ní ìbúra fún wọn nínú aginjù pé, èmi kì yóò mú wọn dé ilẹ̀ tí mo fi fún wọn—ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
Je leur ai aussi juré dans le désert de ne pas les faire entrer dans le pays que je leur avais donné, ruisselant de lait et de miel, qui est la gloire de tous les pays,
16 Nítorí pé, wọn kọ òfin mi sílẹ̀, wọn kò sì tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sọ ọjọ́ ìsinmi mi dí aláìmọ́. Nítorí pé tọkàntọkàn ni wọn ń tẹ̀lé òrìṣà wọn.
parce qu'ils ont rejeté mes ordonnances, qu'ils n'ont pas suivi mes lois, qu'ils ont profané mes sabbats, et que leur cœur est allé après leurs idoles.
17 Síbẹ̀síbẹ̀ mo wò wọ́n pẹ̀lú àánú, ń kò sì pa wọ́n run tàbí kí òpin dé bá wọn nínú aginjù.
Mais mon œil les a épargnés, et je ne les ai pas détruits. Je ne les ai pas fait périr dans le désert.
18 Ṣùgbọ́n mo sọ fún àwọn ọmọ wọn nínú aginjù pé, “Ẹ má ṣe rìn ní ìlànà àwọn baba yín, ẹ má ṣe pa òfin wọn mọ́, ẹ má ṣe bá ara yín jẹ́ pẹ̀lú òrìṣà wọn.
J'ai dit à leurs enfants dans le désert: « Ne suivez pas les lois de vos pères. N'observez pas leurs ordonnances et ne vous souillez pas avec leurs idoles.
19 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ó sì pa òfin mi mọ́.
Je suis Yahvé, votre Dieu. Marchez selon mes lois, observez mes ordonnances et mettez-les en pratique.
20 Ẹ ya ọjọ́ ìsinmi mi sí mímọ́ kí ó lè jẹ́ àmì láàrín wa, ki ẹ lè mọ̀ pé èmi ní Olúwa Ọlọ́run yín.”
Sanctifiez mes sabbats. Ils seront un signe entre moi et vous, afin que vous sachiez que je suis Yahvé votre Dieu ».
21 “‘Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ náà ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn kò sì pa òfin mi mọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá tẹ̀lé àwọn òfin yìí, yóò yè nínú rẹ̀, wọ́n sì tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú mi lórí wọn, Èmi yóò sì mú kí ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn ni aginjù.
"''Mais les enfants se sont rebellés contre moi. Ils n'ont pas suivi mes lois et n'ont pas gardé mes ordonnances pour les mettre en pratique, ce que l'homme fait, il y vivra. Ils ont profané mes sabbats. Alors j'ai dit que je répandrais sur eux ma fureur, pour accomplir ma colère contre eux dans le désert.
22 Síbẹ̀síbẹ̀ mo dáwọ́ dúró, nítorí orúkọ mi, mo sì ṣe ohun tí kò ní ba orúkọ mi jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè ti mo kó wọn jáde lójú wọn.
Mais je retirai ma main et je travaillai à cause de mon nom, afin qu'il ne fût pas profané aux yeux des nations sous le regard desquelles je les avais fait sortir.
23 Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú ọwọ́ ti mo gbé sókè sí wọn, mo búra fún wọn nínú aginjù pé èmi yóò tú wọn ka sì àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì fọ́n wọn káàkiri ilẹ̀ gbogbo,
Je leur jurai, dans le désert, de les disperser parmi les nations et de les répandre dans les pays,
24 nítorí pé wọn kò pa òfin mi mọ́, wọn sì tún kọ àṣẹ mi sílẹ̀, wọn tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Ojú wọn sì wà ní ara òrìṣà baba wọn.
parce qu'ils n'avaient pas exécuté mes ordonnances, mais qu'ils avaient rejeté mes lois et profané mes sabbats, et que leurs yeux étaient attachés aux idoles de leurs pères.
25 Èmi náà sì fi wọn fún ìlànà tí kò dára àti òfin tí wọn kò le e yè nípa rẹ̀;
De plus, je leur ai donné des lois qui n'étaient pas bonnes, et des ordonnances dans lesquelles ils ne pouvaient pas vivre.
26 mo jẹ́ kí ó sọ wọn di aláìmọ́ nípa ẹ̀bùn nípa fífi àkọ́bí ọmọ wọn rú ẹbọ sísun, àkọ́bí wọn la iná kọjá, kí èmi sọ wọ́n di ahoro, kí wọn le mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
Je les ai pollués par leurs propres dons, en faisant passer par le feu tout ce qui ouvre le ventre, afin de les réduire en désolation, pour qu'ils sachent que je suis Yahvé. »'.
27 “Nítorí náà, Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilé Israẹli kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Èyí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí, nínú èyí tí baba yín ti sọ̀rọ̀-òdì sí mi, nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀.
C'est pourquoi, fils de l'homme, parle à la maison d'Israël et dis-leur: « Le Seigneur Yahvé dit: « Vos pères m'ont blasphémé en ceci, qu'ils ont commis une infamie à mon égard.
28 Nítorí nígbà tí mo mú wọn dé ilẹ̀ náà, tí mo gbé ọwọ́ mi sókè láti fi í fún wọn, nígbà náà ni wọ́n rí olúkúlùkù òkè gíga, àti gbogbo igi bíbò, wọ́n sì rú ẹbọ wọn níbẹ̀, wọ́n sì gbé ìmúnibínú ọrẹ wọ́n kalẹ̀ níbẹ̀; níbẹ̀ pẹ̀lú ni wọ́n ṣe òórùn dídùn wọn, wọ́n sì ta ohun ọrẹ mímu sílẹ̀ níbẹ̀.
Car lorsque je les ai fait entrer dans le pays que j'avais juré de leur donner, ils ont vu toute colline élevée et tout arbre touffu, et ils y ont offert leurs sacrifices, et ils y ont présenté la provocation de leur offrande. C'est là qu'ils présentaient leurs sacrifices, et c'est là qu'ils présentaient leurs offrandes.
29 Nígbà náà ni mo wí fún wọn pé, kí ní ibi gíga tí ẹ̀yin lọ yìí?’” (Orúkọ rẹ̀ ni a sì ń pè ní Bama di òní yìí.)
Puis je leur ai dit: « Que signifie le haut lieu où vous allez? ". C'est ainsi que son nom est appelé Bamah jusqu'à ce jour. »''
30 “Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli pé, ‘Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, ṣé o fẹ́ ba ara rẹ jẹ́ bi àwọn baba rẹ ṣe ṣe, tiwọn ń ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé àwọn àwòrán ìríra?
« C'est pourquoi tu diras à la maison d'Israël: « Le Seigneur Yahvé dit: « Vous vous souillez selon la voie de vos pères? Vous vous prostituez après leurs abominations?
31 Nígbà tí ẹ̀yin bá san ọrẹ yìí, ìrúbọ ọmọkùnrin ọmọ yín, tí ẹ mú ọmọ yin la iná kọjá, ẹ̀yin ń tẹ̀síwájú láti ba ara yín jẹ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà yín títí di òní yìí, ẹ̀yin yóò ha jẹ wádìí lọ́dọ̀ mi, ìwọ ilé Israẹli? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi ki yóò jẹ́ kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.
Quand vous offrez vos présents, quand vous faites passer vos fils par le feu, vous vous souillez par toutes vos idoles jusqu'à ce jour? Est-ce que je dois être interrogé par vous, maison d'Israël? Je suis vivant, dit le Seigneur Yahvé, je ne me laisserai pas interroger par vous!
32 “‘Ẹ̀yin wí pé, “Àwa fẹ́ dàbí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù, bí àwọn ènìyàn ayé, tó ń bọ igi àti òkúta.” Ṣùgbọ́n ohun ti ẹ ni lọ́kàn kò ní ṣẹ rárá.
"« Ce qui vous vient à l'esprit ne sera pas du tout, puisque vous dites: « Nous serons comme les nations, comme les familles des pays, pour servir le bois et la pierre ».
33 Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò jẹ ọba lórí yín pẹ̀lú ọwọ́ agbára tí èmi yóò nà jáde pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná mi.
Je suis vivant, dit le Seigneur Yahvé, et c'est à main forte, à bras étendu, à colère déversée, que je serai roi sur vous.
34 Èmi yóò si mú yín jáde kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì ṣà yín jọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín sí pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà tí èmi yóò nà jáde àti pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná ni.
Je vous ferai sortir du milieu des peuples, je vous rassemblerai des pays où vous êtes dispersés, à main forte, à bras étendu et avec une colère déversée.
35 Èmi yóò si mú yín wá sí aginjù àwọn orílẹ̀-èdè, níbẹ̀ ni ojúkójú ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ lé e yín lórí.
Je vous conduirai dans le désert des peuples, et là j'entrerai en jugement avec vous, face à face.
36 Bí mo ṣe ṣe ìdájọ́ àwọn baba yín nínú aginjù nílẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní Olúwa Olódùmarè wí.
De même que j'ai jugé vos pères dans le désert du pays d'Égypte, de même je vous jugerai, dit le Seigneur Yahvé.
37 Èmi yóò kíyèsi i yín bí mo ti mú un yín kọjá lábẹ́ ọ̀pá, èmi yóò sì mú yín wá sí abẹ́ ìdè májẹ̀mú.
Je vous ferai passer sous la verge, et je vous ferai entrer dans le lien de l'alliance.
38 Èmi yóò si ṣa àwọn ọlọ̀tẹ̀ kúrò láàrín yín, àti àwọn o lù re òfin kọjá, èmi yóò mu wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ tiwọn gbé ṣe àtìpó, wọn ki yóò si wọ ilẹ̀ Israẹli. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ní Olúwa.
J'éliminerai du milieu de vous les rebelles et ceux qui me désobéissent. Je les ferai sortir du pays où ils habitent, mais ils n'entreront pas dans le pays d'Israël. Alors vous saurez que je suis Yahvé. »
39 “‘Ní tí ẹ̀yin, ilé Israẹli, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kí olúkúlùkù yín lọ máa sìn òrìṣà rẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí, ẹ̀yin yóò gbọ́ tèmi, ẹ̀yin kò sí ní i bá orúkọ mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú ọrẹ àti àwọn òrìṣà yín mọ́.
"'Quant à vous, maison d'Israël, le Seigneur Yahvé dit: « Allez, chacun sert ses idoles, et plus tard aussi, si vous ne m'écoutez pas; mais vous ne profanerez plus mon saint nom par vos dons et par vos idoles.
40 Nítorí lórí òkè mímọ́ mi, lórí òkè gíga Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí, níbẹ̀ ni ilẹ̀ náà ní gbogbo ilé Israẹli yóò sìn mí; èmi yóò sì tẹ́wọ́ gba wọ́n níbẹ̀. Níbẹ̀ èmi yóò béèrè ọrẹ àti ẹ̀bùn nínú àkọ́so yín pẹ̀lú gbogbo ẹbọ mímọ́ yín.
Car sur ma montagne sainte, sur la montagne de la hauteur d'Israël, dit le Seigneur Yahvé, là toute la maison d'Israël, tous, me serviront dans le pays. Là, je les accueillerai, et là, je demanderai vos offrandes et les prémices de vos offrandes, avec toutes vos choses saintes.
41 Èmi yóò tẹ́wọ́ gbà yín gẹ́gẹ́ bí tùràrí olóòórùn dídùn nígbà tí mo ba mú yín jáde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín ká sí, èmi yóò sì fi ìwà mímọ́ mi hàn láàrín yín lójú àwọn orílẹ̀-èdè.
Je vous accueillerai comme une odeur agréable, quand je vous ferai sortir du milieu des peuples et que je vous rassemblerai des pays où vous avez été dispersés. Je serai sanctifié en toi aux yeux des nations.
42 Nígbà náà ni ẹ o mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú yín wa sí ilẹ̀ Israẹli; sí ilẹ̀ tí mo gbọ́wọ́ mí sókè nínú ẹ̀jẹ́ láti fún àwọn baba yín.
Vous saurez que je suis Yahvé, quand je vous ferai entrer dans le pays d'Israël, dans le pays que j'ai juré de donner à vos pères.
43 Níbẹ̀ ni ẹ ó wa rántí ìwà àti gbogbo ìṣesí yín, èyí tí ẹ̀yin fi sọ ara yín di aláìmọ́, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún gbogbo ibi tí ẹ̀yin ti ṣe.
Là, vous vous souviendrez de vos voies et de toutes vos actions par lesquelles vous vous êtes souillés. Alors vous vous détesterez à vos propres yeux, à cause de tous les maux que vous avez commis.
44 Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá hùwà sí yín nítorí orúkọ mi ni, tí ń kò hùwà sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ibi àti ìwà ìríra yín. Ẹ̀yin ilé Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Vous saurez que je suis Yahvé, quand je vous aurai traités à cause de mon nom, non pas selon vos mauvaises voies, ni selon vos actions corrompues, maison d'Israël, dit le Seigneur Yahvé.'"
45 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
La parole de Yahvé me fut adressée, en ces termes:
46 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ ìhà gúúsù; wàásù lòdì sí gúúsù kí ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ sí igbó ilẹ̀ gúúsù.
« Fils d'homme, tourne ta face vers le midi, prêche vers le midi, et prophétise contre la forêt des champs du midi.
47 Sọ fún igbó ìhà gúúsù pé: ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi í, èmi yóò dá iná kan nínú rẹ̀, yóò sì jó olúkúlùkù igi tútù nínú rẹ̀, àti olúkúlùkù igi gbígbẹ. Jíjò ọwọ́ iná náà ní kí yóò ṣé é pa, àti gbogbo ojú láti gúúsù dé àríwá ni a ó sun nínú rẹ̀.
Dis à la forêt du midi: « Écoute la parole de Yahvé: Le Seigneur Yahvé dit: « Voici, je vais allumer chez toi un feu qui dévorera tout arbre vert et tout arbre sec. La flamme ardente ne s'éteindra pas, et tous les visages, du sud au nord, en seront brûlés.
48 Gbogbo ènìyàn yóò sì mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó dá a, a kì yóò sì le è pa á.’”
Toute chair verra que c'est moi, Yahvé, qui l'ai allumée. Elle ne s'éteindra pas. »'"
49 Nígbà náà ni mo wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Wọn ń wí fún mi pé, ‘Kì í wa ṣe pé òwe lo ń pa bí?’”
Alors je dis: « Ah, Seigneur Yahvé! On dit de moi: « N'est-il pas un orateur de paraboles? ».

< Ezekiel 20 >