< Ezekiel 19 >
1 “Kọ orin ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ-aládé Israẹli
« Prononcez une complainte sur les princes d'Israël,
2 wí pé: “‘Èwo nínú abo kìnnìún ni ìyá rẹ̀ ní àárín àwọn kìnnìún yòókù? Ó sùn ní àárín àwọn ọ̀dọ́ kìnnìún ó sì ń tọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.
et dites, Quelle était ta mère? Une lionne. Elle s'est couchée parmi les lions, au milieu des jeunes lions, elle a nourri ses petits.
3 Ó sì tọ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ dàgbà, ó sì di kìnnìún tó ní agbára, ó kọ́ ọ láti ṣọdẹ, ó sì ń pa àwọn ènìyàn jẹ.
Elle a élevé un de ses petits. Il est devenu un jeune lion. Il a appris à attraper la proie. Il a dévoré des hommes.
4 Àwọn orílẹ̀-èdè gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n sì fi ẹ̀wọ̀n mú un nínú iho wọn. Wọn fi ẹ̀wọ̀n mu nu lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
Les nations ont aussi entendu parler de lui. Il a été pris dans leur fosse; et ils l'ont emmené avec des crochets dans le pays d'Égypte.
5 “‘Nígbà tí abo kìnnìún yìí rí pé ìrètí rẹ̀ sì jásí asán, ó mú ọmọ rẹ̀ mìíràn ó sì tún tọ́ ọ dàgbà di kìnnìún tó ní agbára.
"'Or, quand elle vit qu'elle avait attendu, et son espoir était perdu, puis elle a pris un autre de ses petits, et en a fait un jeune lion.
6 Ó sì ń rìn káàkiri láàrín àwọn kìnnìún nítorí pé ó ti lágbára, o kọ ọdẹ ṣíṣe, ó sì pa àwọn ènìyàn.
Il montait et descendait parmi les lions. Il est devenu un jeune lion. Il a appris à attraper la proie. Il a dévoré des hommes.
7 Ó sì wó odi wọn palẹ̀ ó sì sọ àwọn ìlú wọn di ahoro. Ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé ibẹ̀ sì wà ní ìpayà nítorí bíbú ramúramù rẹ̀.
Il connaissait leurs palais, et ont dévasté leurs villes. La terre était désolée avec sa plénitude, à cause du bruit de ses rugissements.
8 Nígbà náà ni àwọn orílẹ̀-èdè dìde sí i, àwọn tó yìí ká láti ìgbèríko wá. Wọn dẹ àwọ̀n wọn fún un, wọn sì mú nínú ihò wọn.
Et les nations l'attaquèrent de tous côtés, depuis les provinces. Ils ont étendu leur filet sur lui. Il a été pris dans leur fosse.
9 Wọn fi ìwọ̀ gbé e sínú àgò, wọn mú un lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Babeli, wọn fi sínú ìhámọ́, a kò sì gbọ́ bíbú rẹ̀ mọ́ lórí òkè Israẹli.
Ils l'ont mis dans une cage avec des crochets, et l'ont amené au roi de Babylone. Ils l'ont amené dans des forteresses, afin que sa voix ne soit plus entendue sur les montagnes d'Israël.
10 “‘Ìyá rẹ dàbí àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ̀; tí á gbìn sí etí odò ó, kún fún èso, ó sì kún fún ẹ̀ka nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
"'Ta mère était comme une vigne dans ton sang, plantée près des eaux. Il était fécond et plein de branches à cause des nombreuses eaux.
11 Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ lágbára tó láti fi ṣe ọ̀pá àṣẹ ìjòyè, ó ga sókè láàrín ewé rẹ̀, gíga rẹ̀ hàn jáde láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ka rẹ̀.
Il avait des branches robustes pour les sceptres de ceux qui gouvernaient. Leur stature était exaltée parmi les épais branchages. Ils ont été vus dans leur taille avec la multitude de leurs branches.
12 Ṣùgbọ́n ó fà á tu ní ìrunú, á sì wọ́ ọ lulẹ̀, afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn sì gbé èso rẹ̀, ọ̀pá líle rẹ̀ ti ṣẹ́, ó sì rọ iná sì jó wọn run.
Mais il a été arraché avec fureur. Il a été jeté à terre, et le vent d'est a desséché ses fruits. Ses branches fortes ont été brisées et se sont desséchées. Le feu les a consumés.
13 Báyìí, a tún ún gbìn sínú aṣálẹ̀ ni ilẹ̀ gbígbẹ àti ilẹ̀ tó ń pòǹgbẹ omi.
Maintenant, elle est plantée dans le désert, dans une terre sèche et assoiffée.
14 Iná sì jáde láti ọ̀kan lára ẹ̀ka rẹ̀ ó sì pa ẹ̀ka àti èso rẹ̀ run, dé bi pé kò sí ẹ̀ka tó lágbára lórí rẹ̀ mọ́; èyí to ṣe fi ṣe ọ̀pá fún olórí mọ́.’ Èyí ni orin ọ̀fọ̀ a o sì máa lo bí orin ọ̀fọ̀.”
Le feu est sorti de ses branches. Il a dévoré ses fruits, de sorte qu'il n'y a pas en elle de branche forte pour être un sceptre pour gouverner. C'est une lamentation, et ce sera une lamentation. »