< Exodus 6 >

1 Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Ní ìsin yìí, ìwọ yóò rí ohun tí èmi yóò ṣe sí Farao pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi ni yóò fi jẹ́ kí wọn lọ; pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi, òun yóò lé wọn jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
Na LEUM GOD El fahk nu sel Moses, “Inge kom ac fah liye ma nga ac oru nu sel tokosra. Ke po ku luk, nga ac oru elan fuhlela mwet luk uh in som. Aok, nga ac oru elan luselosla liki facl sel uh.”
2 Ọlọ́run sì tún sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa.
God El kaskas nu sel Moses ac fahk, “Nga pa LEUM GOD.
3 Mo fi ara hàn Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu bí Ọlọ́run alágbára, ṣùgbọ́n nípa orúkọ mi Olúwa, Èmi kò fi ara mi hàn wọ́n.
Nga tuh sikyang nu sel Abraham, ac Isaac, ac Jacob, oana ke nga God Kulana, tusruktu nga tiana fahkyuyak nu selos ke Ine mutal luk: LEUM GOD.
4 Èmí sì tún fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú wọn láti fún wọn ní ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí wọn gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì.
Nga oayapa oakiya wuleang luk yorolos in sang nu selos facl Canaan, facl se su elos tuh mutangan mwetsac we.
5 Èmi sì ti tún gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli àwọn tí àwọn ará Ejibiti mú gẹ́gẹ́ bí ẹrú, àti pé èmi sì ti rántí májẹ̀mú mi.
Inge nga lohng sasao lun mwet Israel, su mwet Egypt akkohsye, ac nga esam na wuleang luk.
6 “Sọ fún àwọn ará ilé Israẹli, ‘Èmi ni Olúwa, Èmi yóò sọ yín di òmìnira kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti. Èmi yóò sì gbà yín sílẹ̀ kúrò ní oko ẹrú wọn. Èmi yóò dá a yín sílẹ̀ pẹ̀lú apá nínà (àwọn iṣẹ́ ìyanu) àti pẹ̀lú ìdájọ́ ńlá.
Ouinge fahk nu sin mwet Israel lah nga fahk mu, ‘Nga pa LEUM GOD. Nga fah tulekowosla ac aksukosokyekowos liki moul in kohs lowos yurin mwet Egypt. Nga fah asroela po kulana luk in use kaiyuk upa nu faclos, ac nga fah molikowosla.
7 Èmi yóò mú un yín bí ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó mú un yín jáde kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti.
Nga fah oru tuh komws in mwet luk sifacna, ac nga fah God lowos. Kowos fah etu lah nga pa LEUM GOD lowos ke pacl se nga ac aksukosokye kowos liki moul in kohs lowos in Egypt.
8 Èmi yóò mú un yín wá ilẹ̀ náà ti èmi ti búra pẹ̀lú ìgbọ́wọ́sókè láti fi fún Abrahamu. Isaaki àti Jakọbu. Èmi yóò fi fún un yín bí ohun ìní, Èmi ni Olúwa.’”
Nga ac fah us kowos nu in sie facl su nga orek wulela ku kac in sang nu sel Abraham, Isaac, ac Jacob. Ac nga ac sot nu suwos tuh in facl suwos. Nga LEUM GOD.’”
9 Mose sì sọ èyí fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n wọn kò fi etí sílẹ̀ sí Mose nítorí ọkàn wọn tó rẹ̀wẹ̀sì àti nítorí ìgbèkùn búburú bí ohun tí ó ti kọ́ sọ kó wọn sí ní oko ẹrú wọn.
Moses el fahk ma inge nu sin mwet Israel, tusruktu elos tiana porongel, mweyen wanginla finsrak lalos ke sripen upala akkohs orek nu selos.
10 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose.
Na LEUM GOD El fahk nu sel Moses,
11 “Lọ, sọ fún Farao ọba Ejibiti pé kí ó jẹ́ kí àwọn ará Israẹli lọ kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
“Som ac fahk nu sel tokosra lun Egypt elan fuhlela mwet Israel in som liki facl sel an.”
12 Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà ti àwọn ará Israẹli tó jẹ́ ènìyàn mi kó fetí sí ọ̀rọ̀ mi, báwo ni Farao yóò ṣe fetí sí ọ̀rọ̀ mi, nígbà ti mo jẹ́ akólòlò?”
Tuh Moses el topuk fahk, “Mwet Israel inge elos tiana lohngyu, na ac fuka tuh tokosra elan lohngyu? Nga mwet na supah in kas se.”
13 Olúwa bá ìran Mose àti Aaroni sọ̀rọ̀ nípa àwọn ará Israẹli àti Farao ọba Ejibiti, ó pàṣẹ fún wọn pé kí wọn kó àwọn Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
LEUM GOD El fahk nu sel Moses ac Aaron, “Fahkang nu sin mwet Israel ac Tokosra Egypt lah nga supwekomtal in kolla mwet Israel liki facl Egypt.”
14 Wọ̀nyí ni olórí ìran wọn: àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi. Àwọn wọ̀nyí ni ìdílé Reubeni.
Reuben, wen se emeet natul Jacob, oasr wen akosr natul: Hanoch, Pallu, Hezron, ac Carmi. Eltal pa mwet matu mutaweyen sou inge su ekin inelos.
15 Àwọn ọmọ Simeoni ni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu ọmọ obìnrin Kenaani. Àwọn wọ̀nyí ni ìran Simeoni.
Simeon, oasr wen onkosr natul: Jemuel, Jamin, Ohad, Jachin, Zohar, ac Shaul, wen nutin mutan Canaan se. Eltal pa mwet matu mutaweyen sou inge su ekin inelos.
16 Ìwọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn: Gerṣoni, Kohati àti Merari. Lefi lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
Levi, oasr wen tolu natul: Gershon, Kohath, ac Merari. Eltal pa mwet matu mutaweyen sou inge su ekin inelos. Levi el moul yac siofok tolngoul itkosr.
17 Àwọn ọmọ Gerṣoni ni ìran wọn ni: Libni àti Ṣimei.
Oasr wen luo natul Gershon: Libni ac Shimei, ac pukanten fwilin tulik natulos.
18 Àwọn ọmọ Kohati ni: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli. Kohati lo ẹ̀tàléláádóje ọdún láyé.
Oasr wen akosr natul Kohath: Amram, Izhar, Hebron, ac Uzziel. Kohath el moul yac siofok tolngoul tolu.
19 Àwọn ọmọ Merari ni: Mahili àti Muṣi. Ìwọ̀nyí ni ìran Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn.
Oasr wen luo natul Merari: Mahli ac Mushi. Pa inge sou nukewa lal Levi ac takinyen fwilin tulik natulos.
20 Amramu sì fẹ́ Jokebedi arábìnrin baba rẹ̀ ní ìyàwó. Jokebedi sì bí Aaroni àti Mose fún un. Amramu lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
Amram el payuk sin mutan se wien papa tumal ah, Jochebed, su oswella Aaron ac Moses. Amram el moul yac siofok tolngoul itkosr.
21 Àwọn ọmọ Isari ni: Kora, Nefegi àti Sikri.
Wen tolu natul Izhar: Korah, Nepheg, ac Zichri.
22 Àwọn ọmọ Usieli ni: Miṣaeli, Elsafani àti Sitiri.
Wen tolu pac natul Uzziel: Mishael, Elzaphan, ac Sithri.
23 Aaroni fẹ́ Eliṣeba ọmọbìnrin Amminadabu tí í ṣe arábìnrin Nahiṣoni, ó sì bí Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
Aaron el payuk sel Elisheba, acn natul Amminadab ac ma wial Nahshon. El oswella Nadab, Abihu, Eleazar, ac Ithamar.
24 Àwọn ọmọ Kora ni: Asiri, Elkana àti Abiasafu. Ìwọ̀nyí ni ìran Kora.
Wen tolu natul Korah: Assir, Elkanah, ac Abiasaph. Elos pa mwet matu mutaweyen sou nukewa natul Korah.
25 Eleasari ọmọ Aaroni fẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọbìnrin Putieli ní ìyàwó, ó sì bí Finehasi fún un. Ìwọ̀nyí ni olórí àwọn Lefi ni ìdílé ìdílé.
Elezar, wen natul Aaron, el payuk sin sie acn natul Putiel, su oswella Phinehas. Pa inge sifen sou nukewa ke sruf lun Levi.
26 Aaroni àti Mose yìí kan náà ni Olúwa sọ fún pé, “Ẹ kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí.”
Aaron ac Moses pa LEUM GOD El fahk nu se, “Kolla sruf nukewa lun Israel liki facl Egypt.”
27 Àwọn ni ó bá Farao ọba Ejibiti sọ̀rọ̀ nípa kíkó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni Ejibiti, àní Mose àti Aaroni yìí kan náà ni.
Eltal pa mwet ma fahkang nu sin tokosra Egypt in aksukosokyela mwet Israel.
28 Nígbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ni Ejibiti,
Ke LEUM GOD El kaskas nu sel Moses in acn Egypt,
29 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa. Sọ ohun gbogbo ti mo ti sọ fún ọ fún Farao ọba Ejibiti.”
El fahk, “Nga pa LEUM GOD. Fahk nu sin Tokosra Egypt ma nukewa nga fahk nu sum uh.”
30 Ṣùgbọ́n Mose sì wí ní iwájú Olúwa pé, “Níwọ́n ìgbà ti mo jẹ́ akólòlò, ọ̀nà dà ti Farao yóò ṣe fi etí sí mi?”
Tuh Moses el topuk, “Kom etu lah nga mwet na supah in kas se. Na ac fuka tuh tokosra elan lohngyu?”

< Exodus 6 >