< Exodus 5 >

1 Lẹ́yìn náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, wọ́n sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli sọ, ‘Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó lè ṣe àjọ mi ní ijù.’”
Na Moses ac Aaron som nu yurin tokosra Egypt ac fahk, “LEUM GOD lun Israel El fahk, ‘Fuhlela mwet luk in som, tuh elos fah ku in oru sie kufwa in akfulatyeyu yen mwesis.’”
2 Farao dáhùn wí pé, “Ta ni Olúwa, tí èmi yóò fi gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, tí èmi yóò fi jẹ́ kí Israẹli ó lọ? Èmi kò mọ Olúwa, èmi kò sì ní jẹ́ kí Israẹli ó lọ.”
Tokosra el kouyak ac fahk, “Su LEUM GOD? Efu ku ngan lohngol ac fuhlela mwet Israel in som? Nga tia etu ke LEUM GOD, ac nga fah tia lela mwet Israel in som.”
3 Lẹ́yìn náà ni wọ́n wí pé, “Ọlọ́run àwọn Heberu tí pàdé wa. Ní ìsinsin yìí, jẹ́ kí a lọ ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sínú aginjù láti rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run wa, kí Ó má ba á fi àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí idà bá wa jà.”
Moses ac Aaron topkol, “God lun mwet Hebrew El sikme nu sesr. Lela nu sesr kut in fahsr ke len tolu nu yen mwesis in oru mwe kisa lasr nu sin LEUM GOD lasr. Kut fin tia oru, El ac fah unikuti ke mas ku ke mweun.”
4 Ṣùgbọ́n ọba Ejibiti sọ wí pé, “Mose àti Aaroni, èéṣe ti ẹ̀yin fi mú àwọn ènìyàn kúrò lẹ́nu iṣẹ́ wọn? Ẹ padà sẹ́nu iṣẹ́ yín.”
Tokosra el fahk nu sel Moses ac Aaron, “Efu komtal ku nunku in tulokinya orekma lun mwet uh? Mwet kohs ingan in folokla orekma!
5 Nígbà náà ni Farao sọ pé, “Ẹ wò ó àwọn ènìyàn náà ti pọ̀ sí ì nílẹ̀ yìí ní ìsinsin yìí, ẹ̀yin sì ń dá wọn dúró láti máa bá iṣẹ́ lọ.”
Kowos arulana pus liki mwet Egypt uh, a inge kowos lungse mongla, tia orekma!”
6 Ní ọjọ́ yìí kan náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn akóniṣiṣẹ́ àti àwọn ti ń ṣe alábojútó iṣẹ́ lórí àwọn ènìyàn.
Ke len sacna, tokosra el sapkin mwet Egypt su liyaung mwet kohs, ac mwet Israel su mwet kol lalos
7 “Ẹ̀yin kò ní láti pèsè koríko gbígbẹ fún bíríkì sísun mọ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí; ẹ jẹ́ kí wọn máa wá koríko gbígbẹ fún ara wọn.
in tia sifil sang mah pao nu sin mwet Israel in orek brick kac, a elos in sifacna som suk.
8 Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn ó ṣe iye bíríkì kan náà bí ì ti àtẹ̀yìnwá, kí ẹ má ṣe dín iye rẹ̀ kú. Ọ̀lẹ ni wọ́n, ìwà ọ̀lẹ yìí náà ló mú wọn pariwo pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ, kí a sì rú ẹbọ sí Ọlọ́run wa.’
Tusruktu elos in oru na pisen brick ma elos muta oru meet ah — in tia pueni. El fahk, “Srikla orekma itukyang nu selos an, pa sis elos kwafe na sik nga in fuhlelosla in som orek kisa nu sin God lalos uh!
9 Ẹ mú iṣẹ́ náà le fún wọn, kí wọn bá a le è tẹramọ́ iṣẹ́ wọn, ẹ má fi ààyè gba irọ́ wọn.”
Sang orekma lalos an in upa liki meet ah, ac oru elos in kafofo, tuh in wangin pacl lalos in muta porongo kas kikiap inge.”
10 Ní ìgbà náà ni àwọn akóniṣiṣẹ́ àti àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ jáde tọ̀ wọ́n lọ láti sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Èyí ni ohun tí Farao sọ, ‘Èmi kò ní fún un yín ni koríko gbígbẹ mọ́.
Mwet liyaung mwet kohs ac mwet Israel su kol orekma lalos elos som ac fahk nu sin mwet Israel, “Tokosra el fahk mu el ac tia sifilpa supu mah pao nu suwos.
11 Ẹ lọ wá koríko gbígbẹ ni ibi tí ẹ bá ti lè rí i, ṣùgbọ́n iṣẹ́ yín kí yóò dínkù.’”
El mu kowos in sifacna som eis yen na kowos ku in konauk we, tusruk pisen brick kowos ac oru an in pisa se na meet ah.”
12 Gbogbo wọn sí fọ́n káàkiri ni ilẹ̀ Ejibiti láti sa ìdì koríko tí wọn yóò lò bí ì koríko gbígbẹ fún sísun bíríkì.
Ouinge mwet uh fahsrelik yen nukewa fin acn Egypt sukok mah pao nu ke brick.
13 Àwọn akóniṣiṣẹ́ sì ń ni wọ́n lára, wọ́n wí pé, “Ẹ parí iṣẹ́ tí ẹ ni láti ṣe fún ọjọ́ kan bí ìgbà ti a ń fún un yin ní koríko gbígbẹ.”
Mwet liyaung mwet kohs elos srike na in kalyaelos in oru na pisen brick sac, oana ke elos tuh orala ke pacl ma itukyang mah pao nu selos.
14 Àwọn alábojútó iṣẹ́ tí àwọn akóniṣiṣẹ́ Farao yàn lára ọmọ Israẹli ni wọn ń lù, tí wọn sì ń béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò ṣe iye bíríkì ti ẹ̀yin ń ṣe ní àná ní òní bí i tí àtẹ̀yìnwá?”
Mwet liyaung mwet kohs elos sringil mwet kol orekma lun mwet Israel, su elos srisrngiya in liyaung orekma uh. Elos kouyak ac siyuk, “Efu komtal ku tia oru na pisen brick se ma komtal oru meet ah?”
15 Nígbà náà ni àwọn alábojútó iṣẹ́ tí a yàn lára àwọn ọmọ Israẹli tọ Farao lọ láti lọ bẹ̀bẹ̀ pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ọwọ́ líle mú àwa ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ báyìí?
Na mwet kol orekma lun mwet Israel elos som nu yorol tokosra ac fahk, “Efu tokosra ku oru ange nu sesr?
16 Wọn kò fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni koríko gbígbẹ, síbẹ̀ wọn sọ fún wa pé, ‘Ẹ ṣe bíríkì!’ Wọ́n na àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ, ṣùgbọ́n ẹ̀bi náà wá láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.”
Tia ituku mah pao nu sesr, a srakna sapkinyuk kut in orek brick! Ac inge sringsring kut. Ma koluk inge ma lun mwet lom uh.”
17 Farao sí dáhùn wí pé, “Ọ̀lẹ ni yín, ọ̀lẹ! Èyí ni ó mú kí ẹ̀yin máa sọ ní ìgbà gbogbo pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ, kí a sì rú ẹbọ sí Olúwa.’
Tokosra el topuk, “Komtal alsrangesr ac tia lungse orekma, pa pwanang komtal siyuk ngan lela nu sumtal in som ac orek kisa nu sin LEUM GOD.
18 Nísinsin yìí ẹ padà lọ sí ẹnu iṣẹ́ yín, a kò ní fún un yín ni koríko gbígbẹ, síbẹ̀ ẹ gbọdọ̀ ṣe iye bíríkì tí ó yẹ kí ẹ ṣe.”
Folokla orekma! Wangin mah pao ac itukot nu sumtal, tuh kowos in oru na pisen brick sac.”
19 Àwọn ọmọ Israẹli tí ó jẹ́ alábojútó iṣẹ́ mọ̀ dájú wí pé àwọn ti wà nínú wàhálà ńlá ní ìgbà tí a sọ fún wọn pé, “Ẹ kò ní láti dín iye bíríkì tí ẹ ń ṣe ni ojoojúmọ́ kù.”
Mwet kol orekma lun mwet Israel akilenak lah ac arulana koluk nu selos, ke fwackyang tari elos in oru na pisen brick se ke len nukewa oana ke elos muta oru meet ah.
20 Ní ìgbà tí wọ́n kúrò ni ọ̀dọ̀ Farao wọ́n rí Mose àti Aaroni tí ó dúró láti pàdé wọn.
Ke elos illa, elos sonol Moses ac Aaron su tu soanelos.
21 Wọn sì wí pé, “Kí Olúwa kí ó wò yín, kí ó sì ṣe ìdájọ́! Ẹ̀yin ti mú wa dàbí òórùn búburú fún Farao àti àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀, ẹ sì ti fún wọn ni idà láti fi pa wá.”
Na elos fahk nu seltal, “LEUM GOD El liye ma komtal oru nu sesr inge ac El ac fah kai komtal mweyen ke sripomtal tokosra ac mwet fulat lal inge srungakut. Komtal sang in oasr sripe elos in unikuti.”
22 Mose padà tọ Olúwa lọ, ó sì wí pé, “Olúwa, èéṣe tí ìwọ fi mú ìyọnu wá sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí? Ṣe torí èyí ni ìwọ fi rán mi?
Na Moses el sifil kaskas nu sin LEUM GOD ac fahk, “O Leum, efu kom ku oru koluk mwet lom? Efu kom ku supweyume nu inge?
23 Láti ìgbà ti mo ti tọ Farao lọ láti bá a sọ̀rọ̀ ni orúkọ rẹ ni ó ti mú ìyọnu wá sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì gba àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀ rárá.”
Ke na pacl se nga mutawauk fahsr nu yorol tokosra in kaskas nu sel Inem, el oru arulana koluk nu selos. Ac wanginna ma kom oru in kasrelos!”

< Exodus 5 >