< Exodus 32 >

1 Nígbà tí àwọn ènìyàn rí i pé Mose pẹ́ kí ó tó sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè wá, wọn péjọ yí Aaroni ká, wọ́n sì wí pé, “Wá, dá òrìṣà tí yóò máa ṣáájú wa fún wa. Bí ó ṣe ti Mose tí ó mú wa jáde láti Ejibiti wá, àwa kò mọ́ ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí i.”
A widząc lud, iż omieszkiwał Mojżesz zejść z góry, tedy zebrał się lud przeciw Aaronowi, i mówili do niego: Wstań, uczyń nam bogi, którzy by szli przed nami; bo Mojżeszowi, mężowi temu, który nas wywiódł z ziemi Egipskiej, nie wiemy co się stało.
2 Aaroni dá wọn lóhùn pé, “Ẹ bọ́ òrùka wúrà tí ó wà ní etí àwọn ìyàwó yín, tí àwọn ọmọkùnrin yín, àti tí àwọn ọmọbìnrin yín, kí ẹ sì mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi.”
Tedy im rzekł Aaron: Odejmijcie nausznice złote, które są na uszach żon waszych, synów waszych, i córek waszych, a przynieście do mnie.
3 Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ènìyàn bọ́ òrùka etí wọn, wọn sì kó wọn wá fún Aaroni.
I poodrywał wszystek lud nausznice złote, które były na uszach ich, a przynieśli do Aarona.
4 Ó sì gbà wọ́n ní ọwọ́ wọn, ó sì fi ṣe ohun ọnà fínfín, ó sì dà á ní àwòrán ẹgbọrọ màlúù. Nígbà náà ni wọn wí pé, “Israẹli, wọ̀nyí ni òrìṣà, ti ó mú un yín jáde wá láti Ejibiti.”
Które gdy odebrał z ręku ich, wykształtował je rylcem i uczynił z nich cielca odlewanego. I rzekli: Ci są bogowie twoi, Izraelu, którzy cię wywiedli z ziemi Egipskiej.
5 Nígbà ti Aaroni rí èyí, ó kọ́ pẹpẹ kan níwájú ẹgbọrọ màlúù náà, ó sì kéde pé, “Lọ́la ni àjọyọ̀ sí Olúwa.”
Co ujrzawszy Aaron, zbudował ołtarz przed nim; a wołając Aaron mówił: Święto Pańskie jutro będzie.
6 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn dìde ní kùtùkùtù ọjọ́ kejì, wọ́n sì rú ẹbọ sísun, wọ́n sì mú ẹbọ àlàáfíà wá. Lẹ́yìn náà wọ́n jókòó láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì dìde láti ṣeré.
A wstawszy bardzo rano nazajutrz, ofiarowali całopalenia, i przywiedli ofiary spokojne; i siadł lud, aby jadł i pił, i wstali grać.
7 Olúwa sì wí fún Mose pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ, nítorí àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ mú gòkè wá láti Ejibiti, wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀.
Tedy rzekł Pan do Mojżesza: Idź zstąp; bo się popsował lud twój, któryś wywiódł z ziemi Egipskiej.
8 Wọ́n ti yí kánkán kúrò nípa ọ̀nà tí mo ti mo pàṣẹ fún wọn, wọ́n sì ti dá ère ẹgbọrọ màlúù fún ara wọn. Wọ́n ti foríbalẹ̀ fún un, wọ́n sì ti rú ẹbọ sí i, wọ́n sì ti sọ pé, ‘Israẹli wọ̀nyí ní òrìṣà tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá.’”
Ustąpili prędko z drogi, którąm im przykazał; uczynili sobie cielca odlewanego, i kłaniali się mu, i ofiarowali mu mówiąc: Ci są bogowie twoi, Izraelu, którzy cię wywiedli z ziemi Egipskiej.
9 Olúwa wí fún Mose pé, “Èmi ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, wọ́n sì jẹ́ ọlọ́rùn líle ènìyàn.
Rzekł zasię Pan do Mojżesza: Widziałem lud ten, a oto, jest lud twardego karku.
10 Ǹjẹ́ nísinsin yìí fi mí sílẹ̀, nítorí kí ìbínú mi lè gbóná sí wọn, kí Èmi sì lè pa wọ́n run. Nígbà náà ni Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá.”
Przetoż teraz puść mię, że się rozpali popędliwość moja na nie i wygładzę je; a ciebie uczynię w naród wielki.
11 Ṣùgbọ́n Mose kígbe fún ojúrere Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ó wí pé, “Olúwa, èéṣe tí ìbínú rẹ yóò ṣe gbóná sí àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ mú jáde láti Ejibiti wá pẹ̀lú agbára ńlá àti ọwọ́ agbára?
I modlił się Mojżesz Panu Bogu swemu, a rzekł: Przeczże o Panie, rozpala się popędliwość twoja przeciwko ludowi twemu, któryś wywiódł z ziemi Egipskiej mocą wielką i ręką możną?
12 Èéṣe tí àwọn ará Ejibiti yóò ṣe wí pé, ‘Nítorí ibi ni ó ṣe mọ̀ ọ́n mọ̀ mú wọn jáde, láti pa wọ́n ní orí òkè àti láti gbá wọn kúrò lórí ayé’? Yípadà kúrò nínú ìbínú rẹ tí ó múná, yí ọkàn padà, kí o má sì ṣe mú ìparun wá sórí àwọn ènìyàn rẹ.
A przeczżeby Egipczanie rzec mieli, mówiąc: Na ich złe wywiódł je, aby je pobił na górach, i aby je wygładził z wierzchu ziemi? Odwróć się od gniewu zapalczywości twojej, a ulituj się nad złem ludu twego.
13 Rántí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ Abrahamu, Isaaki àti Israẹli, ẹni tí ìwọ búra fún fúnra rẹ̀, ‘Tí o wí fún wọn pé, Èmi yóò mú irú-ọmọ rẹ pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, Èmi yóò sì fún irú-ọmọ rẹ ní gbogbo ilẹ̀ tí mo ti pinnu fún wọn, yóò sì jẹ́ ogún ìní wọn láéláé.’”
Wspomnij na Abrahama, Izaaka, i Izraela, sługi twoje, którymeś przysiągł sam przez się i mówiłeś do nich: Rozmnożę nasienie wasze jako gwiazdy niebieskie, i wszystkę tę ziemię, o którejm mówił. Dam ją nasieniu waszemu, i odziedziczą ją na wieki.
14 Nígbà náà ni Olúwa dáwọ́ ìbínú rẹ̀ dúró, kò sì mú ìparun náà tí ó sọ wá sórí àwọn ènìyàn rẹ̀ mọ́.
I użalił się Pan nad złem, które mówił, że uczynić miał ludowi swemu.
15 Mose sì yípadà, ó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà pẹ̀lú òkúta wàláà ẹ̀rí méjì ní ọwọ́ rẹ̀. Wọ́n kọ ìwé síhà méjèèjì, iwájú àti ẹ̀yin.
A obróciwszy się Mojżesz zstąpił z góry, dwie tablice świadectwa mając w ręku swych, tablice pisane po obu stronach; i na tej, i na owej stronie były pisane.
16 Iṣẹ́ Ọlọ́run sì ni wàláà náà; ìkọ̀wé náà jẹ́ ìkọ̀wé Ọlọ́run, a fín in sára àwọn òkúta wàláà náà.
A one tablice robotą Bożą były; pismo także pismo Boże było, wyryte na tablicach.
17 Nígbà tí Joṣua gbọ́ ariwo àwọn ènìyàn tí wọ́n ń kígbe, ó sọ fún Mose pé, “Ariwo ogun wà nínú àgọ́.”
A usłyszawszy Jozue głos ludu wołającego, rzekł do Mojżesza: Głos bitwy w obozie.
18 Mose dáhùn pé, “Kì í ṣe ariwo fún ìṣẹ́gun, kì í ṣe ariwo fún aṣẹ́gun; ohùn àwọn tí ń kọrin ni mo gbọ́.”
Który odpowiedział: Nie jest to głos zwyciężających, ani głos porażonych: głos śpiewających ja słyszę.
19 Nígbà tí Mose dé àgọ́, ó sì rí ẹgbọrọ màlúù náà àti ijó, ìbínú rẹ gbóná, ó sì sọ wàláà ọwọ́ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ ní ìsàlẹ̀ òkè náà.
I stało się, gdy się przybliżył do obozu, że ujrzał cielca i tańce; a rozgniewawszy się bardzo Mojżesz, porzucił z ręku swoich tablice, i stłukł je pod górą.
20 Ó sì gbé ẹgbọrọ màlúù tí wọ́n ṣe, ó sì fi iná jó wọn; ó sì lọ̀ wọ́n kúnná, ó dà á sínú omi, ó sì mú àwọn ọmọ Israẹli mu ún.
Wziął też cielca, którego byli uczynili, i spalił go w ogniu, i skruszył go aż na proch, a wysypawszy na wodę, dał pić synom Izraelskim.
21 Mose sọ fún Aaroni pé, “Kí ni àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe sí ọ, tí ìwọ ṣe mú wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ ńlá yìí?”
I rzekł Mojżesz do Aarona: Cóż ci ten lud uczynił, żeś wprowadził nań grzech wielki?
22 Aaroni dáhùn wí pé, “Má ṣe bínú olúwa mi. Ìwọ mọ bí àwọn ènìyàn yìí ṣe burú tó.
Odpowiedział Aaron: Niech się nie rozpala gniew pana mego; ty znasz ten lud, jako do złego skłonny jest.
23 Wọ́n sọ fún mi pé, ‘Ṣe òrìṣà fún wa, tí yóò máa ṣáájú wa. Bí ó ṣe ti Mose ẹni tí ó mú wa jáde láti Ejibiti wá àwa kò mọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí i.’
Bo mi mówili: Uczyń nam bogi, którzy by szli przed nami, gdyż Mojżeszowi, mężowi temu, który nas wywiódł z ziemi Egipskiej, nie wiemy, co się stało.
24 Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún wọn pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó ní òrùka wúrà, kí ó bọ́ ọ wá.’ Nígbà náà ni wọ́n fún mi ní wúrà, mo sì jù ú sínú iná, a sì fi ṣe ẹgbọrọ màlúù yìí!”
I odpowiedziałem im: Kto ma złoto, odrywajcie je z siebie. I dali mi, i wrzuciłem je w ogień, i ulał się ten cielec.
25 Mose rí pé àwọn ènìyàn náà kò ṣe ṣàkóso àti pé Aaroni ti sọ wọ́n di aláìlákóṣo láàrín àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wọn.
Widząc tedy Mojżesz lud obnażony, (bo go był złupił Aaron na zelżenie przed nieprzyjaciołmi ich).
26 Bẹ́ẹ̀ ni Mose dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, ó sì wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá wà fún Olúwa, kí ó wá sí ọ̀dọ̀ mi.” Gbogbo àwọn ará Lefi sì péjọ yí i ká.
Stanął Mojżesz w bramie obozu, i rzekł: Kto Pański, przystąp do mnie. I zebrali się do niego wszyscy synowie Lewiego.
27 Nígbà náà ni ó sọ fún wọn pé, “Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, wí pé, ‘Kí olúkúlùkù ọkùnrin kí ó kọ idà rẹ̀ sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Ẹ lọ padà, kí ẹ jà láti àgọ́ kan dé òmíràn, olúkúlùkù kí ó pa arákùnrin rẹ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ àti aládùúgbò rẹ.’”
I rzekł do nich: Tak mówi Pan, Bóg Izraelski: Przypasz każdy miecz swój do biodry swojej; przychodźcie a wracajcie się od bramy do bramy w obozie, a zabijajcie każdy brata swego, i każdy przyjaciela swego, i każdy bliźniego swego.
28 Àwọn ará Lefi ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ṣe pàṣẹ, àti ní ọjọ́ náà àwọn tí ó kú tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ènìyàn.
I uczynili synowie Lewiego według słowa Mojżeszowego; i poległo z ludu dnia onego około trzech tysięcy mężów.
29 Nígbà náà ni Mose wí pé, “Ẹ ti ya ara yín sọ́tọ̀ fún Olúwa lónìí, nítorí ìwọ ti dìde sí àwọn ọmọ rẹ àti arákùnrin rẹ, ó sì ti bùkún fún ọ lónìí.”
Bo był rzekł Mojżesz: Poświęćcie ręce swoje dziś Panu, każdy na synu swym, i na bratu swym, aby wam dane było dziś błogosławieństwo.
30 Ní ọjọ́ kejì Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ̀yin ti dá ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí èmi yóò gòkè lọ bá Olúwa; bóyá èmi lè ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yín.”
A gdy było nazajutrz, mówił Mojżesz do ludu: Wyście zgrzeszyli grzechem wielkim; przetoż teraz wstąpię do Pana, aza go ubłagam za grzech wasz.
31 Bẹ́ẹ̀ ni Mose padà tọ Olúwa lọ, ó sì wí pé, “Yé, kí ni ẹ̀ṣẹ̀ ńlá tí àwọn ènìyàn ti dá yìí! Wọ́n ti ṣe òrìṣà wúrà fún ara wọn.
Wróciwszy się tedy Mojżesz do Pana, mówił: Proszę, zgrzeszył ten lud grzechem wielkim; bo sobie uczynili bogi złote.
32 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, jọ̀wọ́ dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n ṣùgbọ́n tí kò bá sì ṣe bẹ́ẹ̀, pa orúkọ mi rẹ́ kúrò nínú ìwé tí ìwọ ti kọ.”
Teraz tedy, albo odpuść grzech ich, albo jeźli nie, wymaż mię proszę z ksiąg twoich, któreś napisał.
33 Olúwa dá Mose lóhùn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi, Èmi yóò pa á rẹ́ kúrò nínú ìwé mi.
I rzekł Pan do Mojżesza: Kto mi zgrzeszył, tego wymażę z ksiąg moich.
34 Ǹjẹ́ nísinsin yìí lọ, máa darí àwọn ènìyàn yìí lọ sí ibi ti mo sọ, angẹli mi yóò sì máa lọ ṣáájú yín. Ìgbà ń bọ̀ fún mi tì Èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò, Èmi yóò fi yà jẹ wọ́n fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
A teraz idź, prowadź ten lud, gdziem ci rozkazał. Oto, Anioł mój pójdzie przed tobą; ale w dzień nawiedzenia mego nawiedzę też i na nich ten grzech ich.
35 Olúwa sì yọ àwọn ènìyàn náà lẹ́nu, pẹ̀lú ààrùn nítorí ohun tí wọ́n ṣe ní ti ẹgbọrọ màlúù tí Aaroni ṣe.
Skarał tedy Pan lud, przeto, że uczynili byli cielca, którego był uczynił Aaron.

< Exodus 32 >