< Genesis 42 >

1 Nígbà tí Jakọbu mọ̀ pé ọkà wà ní Ejibiti, ó wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pé, “Èéṣe tí ẹ ń wo ara yín lásán?”
A widząc Jakób, że było zboże w Egipcie, rzekł do synów swoich: Czemuż się oglądacie jeden na drugiego?
2 “Mo tí gbọ́ pé ọkà wà ní ilẹ̀ Ejibiti. Ẹ sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibẹ̀ kí ẹ sì rà wá fún wa, kí a má ba à kú.”
I mówił im: Otom słyszał, że jest zboże w Egipcie. Jedźcież tam, a kupcie nam stamtąd, abyśmy żywi byli, a nie pomarli.
3 Nígbà náà ni mẹ́wàá nínú àwọn arákùnrin Josẹfu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ra ọkà.
Jechało tedy dziesięć braci Józefowych kupować zboże, do Egiptu;
4 Ṣùgbọ́n Jakọbu kò rán Benjamini àbúrò Josẹfu lọ pẹ̀lú wọn nítorí ẹ̀rù ń bà á kí aburú má ba à ṣẹlẹ̀ sí i.
Ale Benjamina, brata Józefowego nie posłał Jakób z bracią jego, bo mówił: By snać nie przypadło nań co złego.
5 Nítorí náà, àwọn ọmọ Israẹli wà lára àwọn tó lọ Ejibiti lọ ra oúnjẹ nítorí ìyàn náà mú ni ilẹ̀ Kenaani pẹ̀lú.
I szli synowie Izraelowi pospołu z innymi tamże idącymi kupować zboże; albowiem był głód w ziemi Chananejskiej.
6 Nísinsin yìí, Josẹfu ni alábojútó fún gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, òun sì ni ó ń bojútó ọkà títà fún gbogbo ènìyàn ìlú náà. Nítorí náà nígbà tí àwọn arákùnrin Josẹfu dé, wọ́n tẹríba, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún Josẹfu.
A Józef był przedniejszym rządcą w onej ziemi; onże sprzedawał zboża wszystkiemu ludowi ziemi. A gdy przyszli bracia Józefowi, kłaniali mu się twarzą do ziemi.
7 Lọ́gán tí Josẹfu ti rí àwọn arákùnrin rẹ̀ ni ó ti dá wọn mọ̀, ṣùgbọ́n ó ṣe bí i wí pé kò mọ̀ wọ́n, ó sì sọ̀rọ̀ líle sí wọn. Ó béèrè pé, “Níbo ni ẹ ti wá?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Láti ilẹ̀ Kenaani ni a ti wá ra oúnjẹ.”
A ujrzawszy Józef bracią swą, poznał je; lecz stawił się im jako obcy, i mówił do nich surowo, i rzekł do nich: Skądeście przyszli? I odpowiedzieli: Z ziemi Chananejskiej, abyśmy nakupili żywności.
8 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, Josẹfu mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, síbẹ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kò mọ̀ ọ́n.
Tedy poznał Józef bracią swą; ale go oni nie poznali.
9 Nígbà náà ni ó rántí àlá rẹ̀ tí ó lá sí wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Amí ni yín, ẹ wá láti wo àṣírí ilẹ̀ wa ni.”
I wspomniał Józef na sny, które mu się śniły o nich, i rzekł im: Szpiegowieście wy, a przyszliście, abyście przepatrzyli miejsca nieobronne tej ziemi.
10 Wọ́n dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ olúwa wa, àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá láti ra oúnjẹ ni.
A oni mu odpowiedzieli: Nie tak, panie mój; ale słudzy twoi przyszli, aby nakupili żywności.
11 Ọmọ baba ni wá, olóòtítọ́ ènìyàn sì ni wá pẹ̀lú, àwa kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò.”
Wszyscyśmy synowie jednego męża; ludzieśmy szczerzy, a nie są słudzy twoi szpiegami.
12 Ó wí fún wọn pé, “Rárá! Ẹ wá láti wo àṣírí ilẹ̀ wa ni.”
A on rzekł do nich: Nie tak, aleście nieobronne miejsca tej ziemi przyszli przepatrować.
13 Ṣùgbọ́n wọ́n tún dáhùn pé, “Arákùnrin méjìlá ni àwa ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ baba kan náà, tí ó ń gbé ní ilẹ̀ Kenaani. Èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn wa ń bẹ lọ́dọ̀ baba wa, ọ̀kan sì ti kú.”
I rzekli: Dwanaście nas braci było sług twoich, synów jednego męża w ziemi Chananejskiej; a oto, najmłodszy z ojcem naszym teraz jest w domu, a jednego już nie masz.
14 Josẹfu wí fún wọn pé, “Bí mo ti wí fún un yín náà ni, Ayọ́lẹ̀wò ni yín!
I rzekł im Józef: Toć jest com ja wam powiedział, mówiąc: Szpiegowieście wy.
15 Èyí sì ni a ó fi dán an yín wò, èmi búra pé, níwọ̀n ìgbà tí Farao bá wà láààyè, ẹ kì yóò kúrò níbí, àyàfi bí arákùnrin yín kan tókù bá wá sí ibí.
Przez to was doświadczę; żywie Farao, nie wynijdziecie stąd, aż mi tu przyjdzie brat wasz młodszy.
16 Ẹ rán ọ̀kan nínú yín lọ láti mú arákùnrin yín wá, àwa yóò fi ẹ̀yin tókù pamọ́ sínú túbú, kí àwa ba à lè mọ bóyá òtítọ́ ni ẹ̀yin ń wí. Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé irọ́ ni ẹ̀yin ń pa, ní òtítọ́ bí Farao ti ń bẹ láààyè ayọ́lẹ̀wò ni yín!”
Poślijcież jednego z was, aby przywiódł brata waszego, a wy w więzieniu będziecie, ażby były doświadczone słowa wasze, jestli prawda przy was; a jeźli nie, żywie Farao, żeście wy szpiegowie.
17 Ó sì fi gbogbo wọn sínú túbú fún ọjọ́ mẹ́ta.
Tedy je dał pod straż do trzech dni.
18 Ní ọjọ́ kẹta, Josẹfu wí fún wọn pé, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe kí ẹ̀yin ba à le yè nítorí mo bẹ̀rù Ọlọ́run.
I mówił do nich Józef dnia trzeciego: Uczyńcie tak, a żyć będziecie; boć się ja boję Boga.
19 Tí ó bá jẹ́ pé olóòtítọ́ ènìyàn ni yín, ẹ jẹ́ kí ọ̀kan nínú yín dúró ni túbú ní ìhín, nígbà tí àwọn yòókù yín yóò gbé ọkà lọ fún àwọn ará ilé e yín tí ebi ń pa.
Jeźliście szczerzy, brat wasz jeden niech będzie okowany w więzieniu, gdzieście wy byli; a wy jedźcie i odnieście zboże, abyście odjęli głodowi domy wasze.
20 Ṣùgbọ́n ẹ gbọdọ̀ mú arákùnrin tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn yín wá, kí n ba à le mọ òtítọ́ ohun ti ẹ ń wí, kí ẹ má ba à kú.” Wọn sì gbà láti ṣe èyí.
A brata waszego młodszego przywiedźcie do mnie, a sprawdzą się słowa wasze, i nie pomrzecie. I uczynili tak.
21 Wọ́n ń sọ ọ́ láàrín ara wọn wí pé, “Àwa jẹ̀bi nítòótọ́ nípa ti arákùnrin wa. A rí ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀ nígbà tí ó ń bẹ̀ wá nítorí ẹ̀mí rẹ̀, ṣùgbọ́n a kò gbẹ́bẹ̀, nítorí náà ni ìdààmú yìí fi dé bá wa.”
I mówili jeden do drugiego: Zaprawdęśmy zgrzeszyli przeciwko bratu naszemu; bo widząc utrapienie duszy jego, gdy się nam modlił, nie wysłuchaliśmy go; dla tegoż przyszedł na nas ten kłopot.
22 Reubeni dá wọn ní ohùn pé, “Èmi kò wí fún yín pé kí ẹ má se ṣẹ̀ sí ọmọdékùnrin náà? Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọ́! Ṣùgbọ́n nísinsin yìí a ń béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ wa.”
Odpowiedział im tedy Ruben, mówiąc: Izalim wam nie mówił temi słowy: Nie grzeszcie przeciw pacholęciu? a nie usłuchaliście; otóż teraz krwi jego z rąk naszych szukają.
23 Wọn kò sì mọ̀ pé, Josẹfu ń gbọ́ wọn ní àgbọ́yé nítorí ògbufọ̀ ni ó ń lò tẹ́lẹ̀.
A oni nie wiedzieli, żeby rozumiał Józef; bo tłumacz był między nimi.
24 Ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún. Ó sì tún yí padà sí wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀. Ó mú Simeoni kúrò láàrín wọn, ó sì dè é ní ojú wọn.
Odwróciwszy się tedy od nich Józef, płakał; a obróciwszy się do nich, mówił z nimi, i wziąwszy od nich Symeona, związał go przed oczyma ich.
25 Josẹfu pàṣẹ pé kí wọn bu ọkà kún inú àpò wọn, kí wọn sì mú owó ẹnìkọ̀ọ̀kan padà sínú àpò rẹ̀, kí wọn sì fún wọn ní ohun tí wọn yóò lò nírín-àjò wọn padà sílé. Lẹ́yìn ìgbà tí a ti ṣe èyí fún wọn,
I rozkazał Józef, aby napełniono wory ich zbożem, i wrócono pieniądze ich każdemu do woru jego, i żeby im dano żywności na drogę; i uczyniono tak.
26 wọn gbé ẹrù wọn lé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọn sì padà lọ sí ilé.
Tedy oni włożywszy zboża swoje na osły swe, odjechali stamtąd.
27 Níbi tí wọ́n ti dúró láti sùn lóru ọjọ́ náà, ọ̀kan nínú wọn tú àpò rẹ̀ láti mú oúnjẹ fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, ó sì rí owó rẹ̀ ní ẹnu àpò rẹ̀.
I rozwiązawszy jeden z nich wór swój, aby dał obrok osłowi swemu w gospodzie, ujrzał pieniądze swoje, które były na wierzchu w worze jego.
28 Ó sì wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “a ti dá owó mi padà, òun nìyí ní ẹnu àpò mi.” Ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì ń gbọ̀n, wọ́n sì wí pé, “Èwo nìyí tí Ọlọ́run ṣe sí wa yìí.”
I rzekł do braci swej: Wrócono mi pieniądze moje, a oto, są w worze moim. Tedy im upadło serce, i zdumieli się, jeden do drugiego mówiąc: Cóż nam to Bóg uczynił?
29 Nígbà tí wọ́n padà dé ọ̀dọ̀ Jakọbu baba wọn ní ilẹ̀ Kenaani, wọ́n ròyìn gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún un wí pé,
Zatem przyszli do Jakóba, ojca swego, do ziemi Chananejskiej, i powiedzieli mu wszystko, co się im przydało, mówiąc:
30 “Ọkùnrin náà tí í ṣe alábojútó ilẹ̀ náà, sọ̀rọ̀ líle sí wa, ó sì fi ẹ̀sùn kàn wá pé a wá yọ́ ilẹ̀ náà wò ni.
Mówił z nami on mąż, pan onej ziemi, surowo, i udał nas za szpiegi ziemi;
31 Ṣùgbọ́n, a wí fún un pé, ‘Rárá o, olóòtítọ́ ènìyàn ni wá, a kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò.
A myśmy mu rzekli: Szczerzyśmy, nie byliśmy szpiegami;
32 Arákùnrin méjìlá ni wá, ọmọ baba kan náà, ọ̀kan ti kú, èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn wà lọ́dọ̀ baba wa ni ilẹ̀ Kenaani.’
Dwanaście nas było braci synów ojca naszego; jednego już nie masz, a młodszy teraz jest z ojcem naszym w ziemi Chananejskiej.
33 “Nígbà náà ni ọkùnrin tí ó jẹ́ alábojútó ilẹ̀ náà wí fún wa pé, ‘Báyìí ni n ó ṣe mọ̀ bóyá olóòtítọ́ ènìyàn ni yín, ẹ fi ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ níbí, pẹ̀lú mi, ẹ sì mú oúnjẹ lọ fún àwọn ará ilé yín tí ebi ń pa kú lọ, lọ́wọ́ ìyàn.
I mówił do nas mąż on, pan onej ziemi: Po tem poznam, żeście szczerzy; brata waszego jednego zostawcie u mnie, a zboże dla odjęcia głodowi domów waszych weźmijcie a idźcie;
34 Ṣùgbọ́n ẹ mú arákùnrin yín tí ó kéré jùlọ wá fún mi kí n le mọ̀ pé dájúdájú ẹ kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò bí kò ṣe ènìyàn tòótọ́. Nígbà náà ni n ó mú arákùnrin yín padà fún un yín, lẹ́yìn náà ẹ le máa wá ṣe òwò bí ó ti wù yín ní ilẹ̀ yìí.’”
Potem przywiedźcie brata waszego młodszego do mnie, abym poznał, żeście wy nie szpiegowie, ale szczerzy; tedy wam wrócę brata waszego, a w tej ziemi handlować będziecie.
35 Bí wọ́n sì ti ń tú àpò ẹrù wọn, ẹnìkọ̀ọ̀kan bá owó tí ó san fún ọjà náà lẹ́nu àpò rẹ̀! Ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi, àwọn àti baba wọn.
I stało się, gdy wypróżniali wory swoje, a oto, każdy znalazł węzeł pieniędzy swych w worze swoim; a obaczywszy węzły z pieniędzmi swymi, oni i ojciec ich, polękali się.
36 Jakọbu baba wọn wí fún wọn pé, “Ẹ ti mú mi pàdánù àwọn ọmọ mi. N kò rí Josẹfu mọ́, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì rí Simeoni náà mọ. Ẹ sì tún fẹ́ mú Benjamini lọ. Èmi ni gbogbo ohun búburú yìí wá ń ṣẹlẹ̀ sí!”
I rzekł im Jakób, ojciec ich: Osierociliście mię, Józefa nie masz, i Symeona nie masz, a Benjamina weźmiecie; na mię się to wszystko złe zwaliło.
37 Nígbà náà ni Reubeni wí fún baba rẹ̀ pé, “Pa àwọn ọmọ mi méjèèjì bí n kò bá mú Benjamini padà wá fún ọ, èmi ni kí o fà á lé lọ́wọ́, n ó sì mu un padà wá.”
I rzekł Ruben do ojca swego, mówiąc: Dwóch synów moich zabij, jeźlić go zaś nie przywiodę; daj go do ręki mojej, a ja go tobie przywrócę.
38 Ṣùgbọ́n Jakọbu wí pé, “Ọmọ mi kì yóò bá a yín lọ, ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀. Bí ohunkóhun bá ṣẹlẹ̀ sí i, ìbànújẹ́ ni yóò sì pa mi kú ni ọjọ́ ogbó mi yìí.” (Sheol h7585)
Ale on rzekł: Nie pójdzie syn mój z wami, gdyż brat jego umarł, a on sam tylko został; a jeźliby nań przypadło co złego na drodze, którą pójdziecie, tedy doprowadzicie sędziwość moję z żałością do grobu. (Sheol h7585)

< Genesis 42 >