< Deuteronomy 32 >

1 Fetísílẹ̀, ẹ̀yin ọ̀run, èmi yóò sọ̀rọ̀; ẹ gbọ́, ìwọ ayé, ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
Deschideţi urechea voi, cerurilor, şi voi vorbi; şi ascultă, pământule, cuvintele gurii mele.
2 Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ ọ̀ mi máa rọ̀ bí òjò, kí àwọn ọ̀rọ̀ mi máa sọ̀kalẹ̀ bí ìrì, bí òjò wíníwíní sára ewéko tuntun, bí ọ̀wààrà òjò sára ohun ọ̀gbìn.
Doctrina mea să picure ca ploaia, vorbirea mea să cadă ca roua, ca ploaia măruntă peste verdeaţa proaspătă şi ca ploile peste iarbă,
3 Èmi yóò kókìkí orúkọ Olúwa. Ẹyin títóbi Ọlọ́run wa!
Pentru că voi vesti numele DOMNULUI, daţi măreţie Dumnezeului nostru.
4 Òun ni àpáta, iṣẹ́ ẹ rẹ̀ jẹ́ pípé, gbogbo ọ̀nà an rẹ̀ jẹ́ òdodo. Ọlọ́run olóòtítọ́ tí kò ṣe àṣìṣe kan, Ó dúró ṣinṣin, òdodo àti òtítọ́ ni òun.
El este Stânca, lucrarea sa este desăvârşită, pentru că toate căile lui sunt judecată, el este un Dumnezeu al adevărului şi fără nelegiuire, el este just şi drept.
5 Wọ́n ti ṣe iṣẹ́ ìbàjẹ́ sọ́dọ̀ ọ rẹ̀; fún ìtìjú u wọn, wọn kì í ṣe ọmọ rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n ìran tí ó yí sí apá kan tí ó sì dorí kodò.
Ei s-au corupt, pata lor nu este cea a copiilor lui, sunt o generaţie perversă şi strâmbă.
6 Ṣé báyìí ni ẹ̀yin yóò ṣe san an fún Olúwa, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìgbọ́n ènìyàn? Ǹjẹ́ òun kọ́ ni baba yín, Ẹlẹ́dàá yín, tí ó dá a yín tí ó sì mọ yín?
Astfel răsplătiţi voi DOMNULUI, popor prost şi neînţelept? Nu este el Tatăl tău care te-a cumpărat? Nu te-a făcut el şi te-a întemeiat?
7 Rántí ìgbà láéláé; wádìí àwọn ìran tí ó ti kọjá. Béèrè lọ́wọ́ baba à rẹ yóò sì sọ fún ọ, àwọn àgbàgbà rẹ, wọn yóò sì ṣàlàyé fún ọ.
Aminteşte-ţi de zilele din vechime, ia aminte la anii multor generaţii, întreabă pe tatăl tău şi îţi va arăta, pe bătrânii tăi şi îţi vor spune.
8 Nígbà tí Ọ̀gá-ògo fi ogún àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, nígbà tí ó pín onírúurú ènìyàn, ó sì gbé ààlà kalẹ̀ fún àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí iye ọmọkùnrin Israẹli.
Când cel Preaînalt a împărţit naţiunilor moştenirea lor, când a separat pe fiii lui Adam, a aşezat graniţele poporului conform cu numărul copiilor lui Israel;
9 Nítorí ìpín Olúwa ni àwọn ènìyàn an rẹ̀, Jakọbu ni ìpín ìní i rẹ̀.
Pentru că partea DOMNULUI este poporul său; Iacob este sorţul moştenirii sale.
10 Ní aginjù ni ó ti rí i, ní aginjù níbi tí ẹranko kò sí. Ó yíká, ó sì tọ́jú rẹ̀, ó pa á mọ́ bí ẹyin ojú u rẹ̀.
El l-a găsit într-un pământ, intr-un deşert; într-o risipire, pustiu al urletelor; l-a condus, l-a instruit, l-a păzit ca pe lumina ochiului său.
11 Bí idì ti í ru ìtẹ́ rẹ̀ ti ó sì ń rábàbà sórí ọmọ rẹ̀, tí ó na ìyẹ́ apá rẹ̀ láti gbé wọn ki ó sì gbé wọn sórí ìyẹ́ apá rẹ̀.
Precum îşi scutură acvila cuibul, pluteşte peste puii săi, îşi întinde aripile, îi ia, îi poartă pe aripile ei tari,
12 Olúwa ṣamọ̀nà; kò sì sí ọlọ́run àjèjì pẹ̀lú rẹ̀.
Astfel l-a condus DOMNUL, singur, şi nu a fost niciun dumnezeu străin cu el.
13 Ó mú gun ibi gíga ayé ó sì fi èso oko bọ́ ọ. Ó sì jẹ́ kí ó mú oyin láti inú àpáta wá, àti òróró láti inú akọ òkúta wá.
L-a făcut să călărească pe înălţimile pământului, ca să mănânce rodul câmpului; şi l-a făcut să sugă miere din stâncă şi untdelemn din stânca de cremene;
14 Pẹ̀lú u wàràǹkàṣì àti wàrà àgùntàn àti ti àgbò ẹran àti pẹ̀lú ọ̀rá ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́, pẹ̀lú àgbò irú u ti Baṣani tí ó sì mu ẹ̀jẹ̀ èso àjàrà, àní àti wáìnì.
Unt de la vaci şi lapte de la oi, cu grăsimea mieilor şi berbeci de rasă din Basan şi ţapi cu grăsimea rărunchilor grâului; şi ai băut sângele pur al strugurelui.
15 Jeṣuruni sanra tán ó sì tàpá; ìwọ sanra tán, ìwọ ki tan, ọ̀rá sì bò ọ́ tán. O kọ Ọlọ́run tí ó dá ọ o sì kọ àpáta ìgbàlà rẹ.
Dar Ieşurun s-a îngrăşat şi a azvârlit din picior, te-ai îngrăşat, te-ai îngroşat, te-ai acoperit cu grăsime; atunci l-a părăsit pe Dumnezeul care l-a făcut şi a dispreţuit Stânca salvării lui.
16 Wọ́n sì fi òrìṣà mú un jowú, ohun ìríra ni wọ́n fi mú un bínú.
L-au provocat la gelozie cu dumnezei străini, l-au provocat la mânie cu urâciuni.
17 Wọ́n rú ẹbọ sí iwin búburú, tí kì í ṣe Ọlọ́run, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀ rí, ọlọ́run tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ farahàn láìpẹ́, ọlọ́run tí àwọn baba yín kò bẹ̀rù.
Au sacrificat dracilor şi nu lui Dumnezeu, unor dumnezei pe care nu i-au cunoscut, unora noi, de curând veniţi, de care părinţii voştri nu s-au temut.
18 Ìwọ kò rántí àpáta, tí ó bí ọ; o sì gbàgbé Ọlọ́run tí ó dá ọ.
De Stânca, cea care te-a născut, tu ai uitat şi nu ţi-ai adus aminte de Dumnezeul, care te-a format.
19 Olúwa sì rí èyí ó sì kọ̀ wọ́n, nítorí tí ó ti bínú nítorí ìwà ìmúnibínú àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ.
Şi când DOMNUL a văzut, i-a detestat din cauza provocării fiilor săi şi a fiicelor sale.
20 Ó sì wí pé, “Èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò lára wọn, èmi yóò sì wò ó bí ìgbẹ̀yìn in wọn yóò ti rí; nítorí wọ́n jẹ́ ìran alágídí, àwọn ọmọ tí kò sí ìgbàgbọ́ nínú wọn.
Şi a spus: Îmi voi ascunde faţa de ei, voi vedea care va fi sfârşitul lor, pentru că ei sunt o generaţie foarte perversă, copii în care nu este credinţă.
21 Wọ́n fi mí jowú nípa ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run, wọ́n sì fi ohun asán an wọn mú mi bínú. Èmi yóò mú wọn kún fún ìlara láti ọ̀dọ̀ àwọn tí kì í ṣe ènìyàn; èmi yóò sì mú wọn bínú láti ọ̀dọ̀ aṣiwèrè orílẹ̀-èdè.
M-au întărâtat la gelozie prin ceea ce nu este Dumnezeu; m-au provocat la mânie cu deşertăciunile lor, şi eu îi voi întărâta la gelozie prin cei ce nu sunt un popor; îi voi provoca la mânie printr-o naţiune proastă.
22 Nítorí pé iná kan ràn nínú ìbínú mi, yóò sì jó dé ipò ikú ní ìsàlẹ̀. Yóò sì run ayé àti ìkórè e rẹ̀ yóò sì tiná bọ ìpìlẹ̀ àwọn òkè ńlá. (Sheol h7585)
Pentru că în mânia mea s-a aprins un foc şi va arde până la cel mai adânc iad şi va mistui pământul cu venitul lui şi va aprinde temeliile munţilor. (Sheol h7585)
23 “Èmi yóò kó àwọn ohun búburú lé wọn lórí èmi ó sì na ọfà mi tán sí wọn lára.
Voi îngrămădi ticăloşii asupra lor, îmi voi consuma săgeţile peste ei.
24 Èmi yóò mú wọn gbẹ, ooru gbígbóná àti ìparun kíkorò ni a ó fi run wọ́n. Pẹ̀lú oró ohun tí ń rákò nínú erùpẹ̀.
Vor fi arşi de foame şi mistuiți de arşiţă pârjolitoare şi de distrugere amară, de asemenea voi trimite dinţii fiarelor asupra lor, cu otrava şerpilor din ţărână.
25 Idà ní òde, àti ẹ̀rù nínú ìyẹ̀wù, ni yóò run ọmọkùnrin àti wúńdíá. Ọmọ ẹnu ọmú àti arúgbó eléwú irun pẹ̀lú.
Sabia în afară şi teroare înăuntru, amândouă vor nimici pe tânăr şi pe fecioară, pe sugar şi pe omul cu perii cărunţi.
26 Mo ní èmi yóò tú wọn ká èmi yóò sì mú ìrántí i wọn dà kúrò nínú àwọn ènìyàn,
Am spus: Îi voi risipi în colţuri, voi face ca amintirea lor să înceteze dintre oameni,
27 nítorí bí mo ti bẹ̀rù ìbínú ọ̀tá, kí àwọn ọ̀tá a wọn kí ó má ba à wí pé, ‘Ọwọ́ wa lékè ni; kì í sì í ṣe Olúwa ni ó ṣe gbogbo èyí.’”
Dacă nu m-aş teme de furia duşmanului, ca nu cumva potrivnicii lor să se comporte ciudat şi ca nu cumva să spună: Mâna noastră este înălţată şi nu DOMNUL a făcut toate acestea.
28 Wọ́n jẹ́ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí òye nínú wọn.
Pentru că ei sunt o naţiune lipsită de sfat şi nici nu este înţelegere în ei.
29 Bí ó ṣe pé wọ́n gbọ́n, kí òye yìí sì yé wọn kí wọn ro bí ìgbẹ̀yìn wọn yóò ti rí!
O, de ar fi înţelepţi şi de ar înţelege aceasta şi ar lua aminte la sfârşitul lor de pe urmă!
30 Báwo ni ẹnìkan ṣe lè lé ẹgbẹ̀rún, tàbí tí ẹni méjì sì lè lé ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sá, bí kò ṣe pé àpáta wọn ti tà wọ́n, bí kò ṣe pé Olúwa wọn ti fi wọ́n tọrẹ?
Cum ar urmări unul o mie şi doi ar pune pe fugă zece mii, dacă nu i-ar fi vândut Stânca lor şi nu i-ar fi închis DOMNUL?
31 Nítorí pé àpáta wọn kò dàbí àpáta wa, àní àwọn ọ̀tá wa tìkára wọn ń ṣe onídàájọ́.
Pentru că stânca lor nu este ca Stânca noastră, chiar duşmanii noştri sunt judecători.
32 Igi àjàrà a wọn wá láti igi àjàrà Sodomu àti ti ìgbẹ́ ẹ Gomorra. Èso àjàrà wọn kún fún oró, ìdì wọn korò.
Pentru că viţa lor este din viţa Sodomei şi din câmpiile Gomorei, strugurii lor sunt struguri de fiere, ciorchinii lor sunt amari,
33 Ọtí wáìnì wọn ìwọ ti dragoni ni, àti oró mímú ti ejò paramọ́lẹ̀.
Vinul lor este otrava dragonilor şi veninul crud al viperelor.
34 “Èmi kò to èyí jọ ní ìpamọ́ èmi kò sì fi èdìdì dì í ní ìṣúra mi?
Nu este lucrul acesta păstrat la mine şi sigilat printre tezaurele mele?
35 Ti èmi ni láti gbẹ̀san. Èmi yóò san án fún wọn ní àkókò tí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yóò yọ; ọjọ́ ìdààmú wọn súnmọ́ etílé ohun tí ó sì ń bọ̀ wá bá wọn yára bọ̀.”
Mie îmi aparţine răzbunarea şi recompensa; la timpul cuvenit le va aluneca piciorul, pentru că ziua nenorocirii lor este aproape şi lucrurile care vor veni peste ei se vor grăbi.
36 Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò sì ṣàánú fún àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ nígbà tí ó bá rí i pé agbára wọn lọ tán tí kò sì sí ẹnìkan tí ó kù, ẹrú tàbí ọmọ.
Pentru că DOMNUL va judeca pe poporul său şi se va pocăi pentru servitorii săi, când va vedea că puterea lor s-a dus şi nu va fi nimeni închis, sau lăsat.
37 Yóò wí pé, “Òrìṣà wọn dà báyìí, àpáta tí wọ́n fi ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé e wọn,
Şi va spune: Unde sunt dumnezeii lor, stânca în care s-au încrezut,
38 ọlọ́run tí ó jẹ ọ̀rá ẹran ẹbọ wọn tí ó ti mu ọtí i wáìnì ẹbọ ohun mímu wọn? Jẹ́ kí wọn dìde láti gbà wọ́n! Jẹ́ kí wọn ṣe ààbò fún un yín!
Ei care au mâncat grăsimea sacrificiilor lor şi au băut vinul darurilor lor de băutură? Să se ridice şi să vă ajute şi să fie protecţia voastră.
39 “Wò ó báyìí pé, Èmi fúnra à mi, Èmi ni! Kò sí ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi. Mo sọ di kíkú mo sì tún sọ di ààyè. Mo ti ṣá lọ́gbẹ́ Èmi yóò sì mu jiná, kò sí ẹni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ ọ̀ mi.
Vedeţi acum că eu, eu sunt el şi nu este alt dumnezeu împreună cu mine; eu ucid şi eu dau viaţă; eu rănesc şi eu vindec, şi nu este cineva care să vă scape din mâna mea.
40 Mo gbé ọwọ́ mi sókè ọ̀run mo sì wí pé, Èmi ti wà láààyè títí láé,
Pentru că îmi ridic mâna spre cer şi spun: Eu trăiesc pentru totdeauna.
41 nígbà tí mo bá pọ́n idà dídán mi àti tí mo bá sì fi ọwọ́ mi lé ìdájọ́, Èmi yóò san ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá mi Èmi ó sì san fún àwọn tí ó kórìíra à mi.
Dacă îmi ascut sabia strălucitoare şi mâna mea apucă judecata, voi întoarce răzbunare duşmanilor mei şi voi răsplăti celor care mă urăsc.
42 Èmi yóò mú ọfà mu ẹ̀jẹ̀, nígbà tí idà mi bá jẹ ẹran: ẹ̀jẹ̀ ẹni pípa àti ẹni ìgbèkùn, láti orí àwọn aṣáájú ọ̀tá.”
Îmi voi îmbăta săgeţile de sânge şi sabia mea va înghiți carne; şi le voi îmbăta de sângele celor ucişi şi al captivilor, de la începutul răzbunărilor peste duşman.
43 Ẹ yọ̀ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ nítorí òun yóò gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀; yóò sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá a rẹ̀ yóò sì ṣe ètùtù fún ilẹ̀ àti ènìyàn rẹ̀.
Bucuraţi-vă naţiunilor, cu poporul său, pentru că el va răzbuna sângele servitorilor săi şi va întoarce răzbunare potrivnicilor săi şi va fi milos cu ţara sa şi cu poporul său.
44 Mose sì wá ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí ní etí àwọn ènìyàn náà, òun, àti Hosea ọmọ Nuni.
Şi Moise a venit şi a rostit toate cuvintele cântării acesteia în auzul poporului, el şi Hoşea, fiul lui Nun.
45 Nígbà tí Mose parí i kíka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí Israẹli.
Şi Moise a terminat de vorbit toate cuvintele acestea înaintea întregului Israel,
46 Ó sọ fún un pé, “Ẹ gbé ọkàn an yín lé gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ láàrín yín lónìí, kí ẹ̀yin lè pàṣẹ fún àwọn ọmọ yín láti gbọ́rọ̀ àti láti ṣe gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
Şi le-a spus: Puneţi-vă la inimă toate cuvintele pe care le mărturisesc printre voi astăzi, ca să le porunciţi copiilor voştri să ia seama să le împlinească, toate cuvintele acestei legi.
47 Wọn kì í ṣe ọ̀rọ̀ asán fún ọ, ìyè e yín ni wọ́n. Nípa wọn ni ẹ̀yin yóò gbé pẹ́ lórí ilẹ̀ tí ẹ̀yin ń gòkè e Jordani lọ láti gbà.”
Pentru că nu este un lucru deşert pentru voi, pentru că este viaţa voastră, şi prin acest lucru vă veţi prelungi zilele în ţara în care treceţi Iordanul, ca să o stăpâniţi.
48 Ní ọjọ́ kan náà, Olúwa sọ fún Mose pé,
Şi DOMNUL a vorbit lui Moise în aceeaşi zi, spunând:
49 “Gòkè lọ sí Abarimu sí òkè Nebo ní Moabu, tí ó kọjú sí Jeriko, kí o sì wo ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí mo ń fi fún àwọn ọmọ Israẹli, bí ìní i wọn.
Urcă-te pe muntele acesta, Abarim, pe muntele Nebo, care este în ţara Moabului, care este în dreptul Ierihonului; şi priveşte ţara Canaanului, pe care o dau în stăpânire copiilor lui Israel,
50 Ní orí òkè tí ìwọ ń gùn lọ ìwọ yóò kùú níbẹ̀, kí a sì sin ọ́ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ, gẹ́gẹ́ bí arákùnrin in rẹ Aaroni ti kú ní orí òkè Hori tí a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn an rẹ̀.
Şi mori pe muntele pe care te vei urca şi adună-te la poporul tău; precum a murit Aaron, fratele tău, pe muntele Hor, şi a fost adunat la poporul său,
51 Ìdí ni pé ẹ̀yin méjèèjì ṣẹ̀ sí mi láàrín àwọn ọmọ Israẹli ní ibi omi Meriba Kadeṣi ní aginjù Sini àti nítorí ẹ̀yin kò yà mí sí mímọ́ láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
Pentru că aţi încălcat legea împotriva mea în mijlocul copiilor lui Israel, la apele Meriba-Cades, în pustiul Ţin, pentru că nu m-aţi sfinţit în mijlocul copiilor lui Israel.
52 Nítorí náà, ìwọ yóò rí ilẹ̀ náà ní ọ̀kánkán, o kì yóò wọ inú rẹ̀ ilẹ̀ ti mo ti fi fún àwọn ọmọ Israẹli.”
Totuşi tu vei vedea ţara înaintea ta dar nu vei intra acolo, în ţara pe care o dau copiilor lui Israel.

< Deuteronomy 32 >