< Deuteronomy 31 >

1 Nígbà náà ni Mose jáde tí ó sì sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí gbogbo Israẹli pé,
Şi Moise a mers şi a vorbit aceste cuvinte către tot Israelul.
2 “Mo jẹ́ ọmọ ọgọ́fà ọdún báyìí àti pé èmi kò ni lè darí i yín mọ́. Olúwa ti sọ fún mi pé, ‘Ìwọ kò ní kọjá Jordani.’
Şi le-a spus: Eu astăzi sunt în vârstă de o sută douăzeci de ani; nu mai pot ieşi şi intra, de asemenea DOMNUL mi-a spus: Tu nu vei trece Iordanul acesta.
3 Olúwa Ọlọ́run rẹ fúnra rẹ̀ ni yóò rékọjá fún ọ. Yóò pa àwọn orílẹ̀-èdè yìí run níwájú rẹ, ìwọ yóò sì mú ìní ilẹ̀ wọn, Joṣua náà yóò rékọjá fún ọ, bí Olúwa ti sọ.
DOMNUL Dumnezeul tău, el va trece înaintea ta şi va nimici naţiunile acestea dinaintea ta şi le vei stăpâni, şi Iosua, el va trece înaintea ta, precum a spus DOMNUL.
4 Olúwa yóò sì ṣe fún wọn ohun tí ó ti ṣe sí Sihoni àti sí Ogu ọba Amori, tí ó parun pẹ̀lú ilẹ̀ ẹ wọn.
Şi DOMNUL le va face precum a făcut lui Sihon şi lui Og, împăraţii amoriţilor şi ţării lor, pe care i-a nimicit.
5 Olúwa yóò fi wọ́n fún ọ, kí o sì ṣe sí wọn gbogbo èyí tí mo ti pàṣẹ fún ọ.
Şi DOMNUL îi va da înaintea voastră, să le faceţi conform cu toate poruncile pe care vi le-am poruncit.
6 Jẹ́ alágbára kí o sì ní ìgboyà. Má ṣe bẹ̀rù tàbí jáyà nítorí i wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń lọ pẹ̀lú rẹ, Òun kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
Fiţi tari şi curajoşi, nu vă temeţi, nici nu vă îngroziţi înaintea lor, pentru că DOMNUL Dumnezeul tău, el este cel care merge cu tine; el nu te va lăsa, nici nu te va părăsi.
7 Nígbà náà ni Mose pe Joṣua ó sì wí fún un níwájú gbogbo Israẹli pé, “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí o ní láti lọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fún wọn, kí o sì pín ilẹ̀ náà láàrín wọn bí ogún wọn.
Şi Moise l-a chemat pe Iosua şi i-a spus înaintea ochilor întregului Israel: Fii tare şi curajos, pentru că tu trebuie să intri cu poporul acesta în ţara pe care DOMNUL a jurat-o părinţilor lor că le-o dă; şi tu îi vei face să o moştenească.
8 Olúwa fúnra rẹ̀ ń lọ níwájú rẹ yóò sì wà pẹ̀lú rẹ; kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Má ṣe bẹ̀rù má sì ṣe fòyà.”
Şi DOMNUL, el este cel care merge înaintea ta; el va fi cu tine, el nu te va lăsa, nici nu te va părăsi, nu te teme, nici nu te descuraja.
9 Nígbà náà ni Mose kọ òfin yìí kalẹ̀ ó sì fi fún àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, tí ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti fún gbogbo àwọn àgbàgbà ní Israẹli.
Şi Moise a scris legea aceasta şi a dat-o preoţilor, fiii lui Levi, care purtau chivotul legământului DOMNULUI, şi tuturor bătrânilor lui Israel.
10 Nígbà náà ni Mose pàṣẹ fún wọn, “Ní òpin ọdún méje méje, ní àkókò ọdún ìdásílẹ̀, nígbà àjọ àwọn àgọ́.
Şi Moise le-a poruncit, spunând: La sfârşitul fiecăror şapte ani, în solemnitatea anului iertării, la sărbătoarea corturilor,
11 Nígbà tí gbogbo Israẹli bá wá láti fi ara hàn níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ibi tí yóò yàn, ìwọ yóò ka òfin yìí níwájú wọn sí etí ìgbọ́ wọn.
Când va veni tot Israelul să se arate înaintea DOMNULUI Dumnezeul tău în locul pe care îl va alege, să citeşti legea aceasta înaintea întregului Israel, în auzul lor.
12 Pe àwọn ènìyàn jọ àwọn ọkùnrin, àwọn obìnrin àti àwọn àjèjì tí ń gbé àwọn ìlú u yín kí wọn lè fetí sí i kí wọn sì lè kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ kí wọn sì rọra tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí.
Adună poporul împreună, pe bărbaţi şi pe femei şi pe copii şi pe străinul tău care este înăuntrul porţilor tale, ca să audă şi să înveţe şi să se teamă de DOMNUL Dumnezeul vostru şi să ia seama să împlinească toate cuvintele acestei legi,
13 Àwọn ọmọ wọn tí wọn kò mọ òfin yìí, gbọdọ̀ gbọ́ kí wọn sì kọ́ láti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ níwọ̀n ìgbà tí o tí ń gbé ní ilẹ̀ tí ò ń kọjá la Jordani lọ láti ni.”
Şi copiii lor, care nu au cunoscut nimic, să audă şi să înveţe să se teamă de DOMNUL Dumnezeul vostru, în toate zilele cât trăiţi în ţara în care treceţi Iordanul, ca să o stăpâniţi.
14 Olúwa sọ fún Mose pé, “Ọjọ́ ikú rẹ ti súnmọ́ etílé báyìí. Pe Joṣua kí ẹ sì fi ara yín hàn nínú àgọ́ àjọ, níbi tí èmi yóò ti fi àṣẹ fún un.” Nígbà náà ni Mose àti Joṣua wá, wọ́n sì fi ara wọn hàn níbi àgọ́ àjọ.
Şi DOMNUL i-a spus lui Moise: Iată, ţi se apropie zilele ca să mori; cheamă pe Iosua şi înfăţişaţi-vă, ca să îi dau poruncă. Şi Moise şi Iosua au mers şi s-au înfăţişat la tabernacolul întâlnirii.
15 Nígbà náà ni Olúwa farahàn níbi àgọ́ ní ọ̀wọ́ àwọsánmọ̀, àwọsánmọ̀ náà sì dúró sókè ẹnu-ọ̀nà àgọ́.
Şi DOMNUL s-a arătat în tabernacol, într-un stâlp de nor, şi stâlpul de nor stătea deasupra intrării tabernacolului.
16 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Ìwọ ń lọ sinmi pẹ̀lú àwọn baba à rẹ, àwọn wọ̀nyí yóò sì ṣe àgbèrè ara wọn sí ọlọ́run àjèjì ilẹ̀ tí wọn ń wọ̀ lọ láìpẹ́. Wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀ wọn yóò sì da májẹ̀mú tí mo bá wọn dá.
Şi DOMNUL i-a spus lui Moise: Iată, tu vei adormi cu părinţii tăi şi poporul acesta se va ridica şi va curvi cu dumnezeii străinilor ţării în care intră să fie cu ei şi mă va părăsi şi va rupe legământul meu pe care l-am făcut cu ei.
17 Ní ọjọ́ náà ni èmi yóò bínú sí wọn èmi yóò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀; èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò fún wọn, wọn yóò sì parun. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àjálù àti ìṣòro yóò wá sórí wọn, àti ní ọjọ́ náà ni wọn yóò béèrè pé, ‘Ǹjẹ́ ìpọ́njú wọ̀nyí kò wá sórí i wa nítorí Ọlọ́run wa kò sí pẹ̀lú u wa?’
Atunci furia mea se va aprinde împotriva lor în ziua aceea şi îi voi părăsi şi îmi voi ascunde faţa de ei şi ei vor fi mâncaţi şi li se vor întâmpla multe rele şi tulburări, astfel încât vor spune în ziua aceea: Nu au venit aceste rele peste noi pentru că Dumnezeul nostru nu este în mijlocul nostru?
18 Èmi yóò sì pa ojú mi mọ́ dájúdájú ní ọjọ́ náà nítorí i gbogbo ìwà búburú wọn ní yíyípadà sí ọlọ́run mìíràn.
Şi îmi voi ascunde într-adevăr faţa în ziua aceea, pentru toate relele pe care le-au lucrat, pentru că s-au întors spre alţi dumnezei.
19 “Ní báyìí kọ ọ́ kalẹ̀ fúnra à rẹ orin yìí kí o sì kọ ọ́ sí Israẹli kí o sì jẹ́ kí wọn kọ ọ́ kí ó lè jẹ́ ẹ̀rí ì mi sí wọn.
Şi acum scrieţi această cântare pentru voi, învaţă-i pe copiii lui Israel să o cânte, pune-o în gurile lor, ca această cântare să îmi servească de mărturie împotriva copiilor lui Israel.
20 Nígbà tí mo ti mú wọn wá sí ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin, ilẹ̀ tí mo ti ṣe ìlérí ní ìbúra fún àwọn baba ńlá wọn, àti nígbà tí wọ́n bá jẹ, tí ó sì tẹ́ wọn lọ́rùn, tí wọ́n sì gbilẹ̀, wọn yóò yí padà sí ọlọ́run mìíràn wọn yóò sì sìn wọ́n, wọn yóò kọ̀ mí sílẹ̀, wọn yóò sì da májẹ̀mú mi.
Pentru că îi voi duce în ţara pe care am jurat-o părinţilor lor, în care curge lapte şi miere şi vor mânca şi se vor sătura şi se vor îngrăşa; atunci se vor întoarce spre alţi dumnezei şi le vor servi şi mă vor provoca şi vor rupe legământul meu.
21 Àti nígbà tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpọ́njú àti ìṣòro bá wá sórí i wọn, orin yìí yóò jẹ́ ẹ̀rí sí wọn, nítorí kò ní di ìgbàgbé fún àwọn ọmọ wọn. Mo mọ̀ ohun tí wọ́n ní inú dídùn sí láti ṣe, pàápàá kí èmi tó mú wọn wá sí ilẹ̀ tí mo ṣe ìlérí fún wọn lórí ìbúra.”
Şi va fi, când li se vor întâmpla multe rele şi tulburări, că această cântare va mărturisi împotriva lor ca o mărturie, pentru că nu va fi uitată din gura seminţei lor, pentru că eu cunosc imaginaţia după care merg, chiar acum, înainte să îi fi adus în ţara pe care eu le-am jurat-o.
22 Nígbà náà ni Mose kọ orin yìí kalẹ̀ ní ọjọ́ náà ó sì kọ ọ́ sí Israẹli.
Şi Moise a scris această cântare în aceeaşi zi şi a învăţat pe copiii lui Israel să o cânte.
23 Olúwa sì fún Joṣua ọmọ Nuni ní àṣẹ yìí: “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí ìwọ yóò mú Israẹli wá sí ilẹ̀ tí mo ṣèlérí fún wọn lórí ìbúra, èmi fúnra à mi yóò sì wà pẹ̀lú rẹ.”
Şi i-a poruncit lui Iosua, fiul lui Nun, spunând: Fii tare şi curajos, pentru că tu vei duce pe copiii lui Israel în ţara pe care le-am jurat-o, iar eu voi fi cu tine.
24 Lẹ́yìn ìgbà tí Mose ti parí i kíkọ ọ̀rọ̀ òfin yìí sínú ìwé láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin,
Şi s-a întâmplat, după ce a terminat Moise de scris cuvintele legii acesteia într-o carte, până la sfârşitul lor,
25 ó sì fi àṣẹ yìí fún àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n ń gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa:
Că Moise a poruncit leviţilor care purtau chivotul legământului DOMNULUI, spunând:
26 “Gba ìwé òfin yìí kí o sì fi sí ẹ̀gbẹ́ àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Níbẹ̀ ni yóò wà bí ẹ̀rí sí ọ.
Luaţi cartea aceasta a legii şi puneţi-o alături de chivotul legământului DOMNULUI Dumnezeul vostru, ca să fie acolo ca mărturie împotriva ta.
27 Nítorí mo mọ irú ọlọ̀tẹ̀ àti ọlọ́rùn líle tí ẹ jẹ́. Bí o bá ṣe ọlọ̀tẹ̀ sí Olúwa nígbà tí mo pàpà wà láyé pẹ̀lú yín, báwo ní ẹ ó ti ṣe ọlọ̀tẹ̀ tó nígbà tí mo bá kú tán!
Pentru că eu cunosc răzvrătirea ta şi gâtul tău înţepenit, iată, încă fiind eu viu cu voi, astăzi, v-aţi răzvrătit împotriva DOMNULUI şi cu cât mai mult după moartea mea?
28 Ẹ péjọpọ̀ síwájú mi gbogbo àgbà ẹ̀yà yín àti àwọn aláṣẹ yín, kí èmi lè sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí etí ìgbọ́ ọ́ wọn.
Adunaţi la mine pe toţi bătrânii triburilor voastre şi pe administratorii voştri, ca să vorbesc în urechile lor cuvintele acestea şi să chem cerul şi pământul ca mărturie împotriva lor.
29 Nítorí tí mo mọ̀ pé lẹ́yìn ikú mi, ó dájú pé ìwọ yóò padà di ìbàjẹ́ pátápátá, ẹ ó sì yípadà kúrò ní ọ̀nà tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ní ọjọ́ tó ń bọ̀, ìpọ́njú yóò sọ̀kalẹ̀ sórí i yín nítorí ẹ̀yin yóò ṣe búburú níwájú Olúwa ẹ ó sì mú u bínú nípa ohun tí ọwọ́ yín ti ṣe.”
Pentru că ştiu că după moartea mea vă veţi corupe de tot şi vă veţi abate de la calea pe care v-am poruncit-o; şi vi se va întâmpla răul în zilele de pe urmă, pentru că veţi face ce este rău înaintea ochilor DOMNULUI, ca să îl provocaţi la furie prin lucrarea mâinilor voastre.
30 Mose sì ka ọ̀rọ̀ inú orin yìí láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin sí etí ìgbọ́ ọ gbogbo ìjọ Israẹli:
Şi Moise a vorbit în urechile întregii adunări a lui Israel cuvintele cântării acesteia, până la sfârşitul lor.

< Deuteronomy 31 >