< Deuteronomy 3 >

1 Lẹ́yìn èyí ní a yípadà tí a sì kọrí sí ọ̀nà tí ó lọ sí Baṣani, Ogu ọba Baṣani àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ ṣígun wá pàdé wa ní Edrei.
Megfordultunk és fölmentünk Boson felé; és kijött Óg, Boson királya elénk, ő és egész népe háborúra Edreibe.
2 Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀. Kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
És az Örökkévaló mondta nekem: Ne félj tőle, mert kezedbe adtam őt és egész népét, meg országát; tégy vele, amint tettél Szichónnal, az Emóri királyával, aki Chesbónban lakik.
3 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run wa fi Ogu ọba Baṣani àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lé wa lọ́wọ́. A kọlù wọ́n títí kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè.
És az Örökkévaló, a mi Istenünk kezünkbe adta Ógot is, Boson királyát és egész népét; mi megvertük őt úgy, hogy nem hagytunk belőle maradékot.
4 Ní ìgbà náà ní a gba gbogbo àwọn ìlú rẹ̀. Kò sí ọ̀kankan tí a kò gbà nínú àwọn ọgọta ìlú tí wọ́n ní, gbogbo agbègbè Argobu, lábẹ́ ìjọba Ogu ní Baṣani.
Meghódítottuk mind a városait az időben, nem volt város, melyet el nem vettünk tőlük; hatvan várost, Árgóv egész vidékét, Óg birodalmát Bosonban.
5 Gbogbo ìlú wọ̀nyí ní a mọ odi gíga yíká pẹ̀lú àwọn ìlẹ̀kùn àti irin. Ọ̀pọ̀ àwọn ìlú kéékèèké tí a kò mọ odi yíká sì tún wà pẹ̀lú.
Mindezek erősített városok voltak, magas fallal, kapukkal és tolózárral, kivéve az igen sok nyílt várost.
6 Gbogbo wọn ni a parun pátápátá gẹ́gẹ́ bí á ti ṣe sí Sihoni ọba Heṣboni, tí a pa gbogbo ìlú wọn run pátápátá: tọkùnrin tobìnrin àti àwọn ọmọ wọn.
És kiirtottuk azokat, amint tettünk Szichónnal, Chesbón királyával, kiirtva minden várost férfiakat, nőket és gyermekeket.
7 Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú wọn, fún ara wa.
Mind a barmot pedig és a városok zsákmányát magunknak vettük prédául.
8 Ní ìgbà náà ni a ti gba ilẹ̀ tí ó wà ní Jordani láti odò Arnoni, títí dé orí òkè Hermoni lọ́wọ́ àwọn ọba Amori méjèèjì wọ̀nyí.
Elvettük abban az időben az országot az Emóri két királyának kezéből, mely a Jordánon innen van, az Árnón patakjától a Chermón hegyéig;
9 (Àwọn ará Sidoni ń pe Hermoni ní Sirioni. Àwọn Amori sì ń pè é ní Seniri).
– a czidóniták nevezik a Chermónt Szirjónnak, az Emóri pedig Szenirnek nevezi;
10 Gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè olórí títẹ́ náà ni a gbà àti gbogbo Gileadi, àti gbogbo Baṣani, títí dé Saleka, àti Edrei, ìlú àwọn ọba Ogu ní ilẹ̀ Baṣani.
a síkság minden városát, az egész Gileádot, egész Bosont, Szálchóig és Edreig, Óg birodalmának városait Bosonban.
11 (Ogu tí í ṣe ọba Baṣani nìkan ni ó ṣẹ́kù nínú àwọn ará Refaimu. Ibùsùn rẹ̀ ni a fi irin ṣe, ó sì gùn ju ẹsẹ̀ bàtà mẹ́tàlá lọ ní gígùn àti ẹsẹ̀ bàtà mẹ́fà ní ìbú. Èyí sì wà ní Rabba ti àwọn Ammoni.)
Mert csak Óg, Boson királya maradt az óriások maradékából; íme ágya vaságy, nemde Rábbász-Bené-Ámmónban van, hosszúsága kilenc könyök és négy könyök a szélessége, a férfi könyöke szerint.
12 Nínú àwọn ilẹ̀ tí a gbà ní ìgbà náà, mo fún àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, ní ilẹ̀ tí ó wà ní àríwá Aroeri níbi odò Arnoni, pọ̀ mọ́ ìdajì ilẹ̀ òkè Gileadi pẹ̀lú gbogbo ìlú wọn.
És ezt az országot elfoglaltuk abban az időben, Áróértól, mely az Árnón patakja mellett van, meg Gileád hegységének felét és városait adtam a Rúbéninak és Gádinak.
13 Gbogbo ìyókù Gileadi àti gbogbo Baṣani, ní ilẹ̀ ọba Ogu ni mo fún ìdajì ẹ̀yà Manase. (Gbogbo agbègbè Argobu ni Baṣani tí a mọ̀ sí ilẹ̀ àwọn ará Refaimu.
Gileád többi részét pedig, meg az egész Bosom, Óg birodalmát adtam Menásse féltörzsének; az Árgóv egész vidékét, amaz egész Bosont nevezik az óriások országának.
14 Jairi ọ̀kan nínú àwọn ìran Manase gba gbogbo agbègbè Argobu títí dé ààlà àwọn ará Geṣuri àti àwọn ará Maakati; a sọ ibẹ̀ ní orúkọ rẹ̀ torí èyí ni Baṣani fi ń jẹ́ Hafoti-Jairi títí di òní.)
Joir, Menásse fia elvette Árgóv egész vidékét, a Gesúri és Maáchoszi határáig és elnevezte azokat az ő nevéről; Bosont Chávvósz-Joirnak mind e mai napig.
15 Mo sì fi Gileadi fún Makiri,
Mochirnak pedig adtam Gileádot.
16 ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Reubeni àti ọmọ Gadi ni mo fún ní ilẹ̀ láti Gileadi lọ dé odò Arnoni (àárín odò náà sì jẹ́ ààlà) títí ó fi dé odò Jabbok. Èyí tí i ṣe ààlà àwọn ará Ammoni.
A Rúbéninek és a Gádinak pedig adtam Gileádtól egész az Árnón patakjáig, a patak közepét határul, a Jábbók patakjáig, az Ámmón fiainak határán,
17 Pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah pẹ̀lú, àti Jordani gẹ́gẹ́ bí òpin ilẹ̀ rẹ̀, láti Kinnereti lọ títí dé Òkun pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah, àní Òkun Iyọ̀, ní ìsàlẹ̀ àwọn orísun Pisga ní ìhà ìlà-oòrùn.
és a síkságot, a Jordánt határul, Kinneresztől a síkság tengeréig, a Piszga lejtői alatt, keletre.
18 Mo pàṣẹ fún un yín ní ìgbà náà pé, “Olúwa Ọlọ́run yín ti fi ilẹ̀ yìí fún un yín láti ní i. Ṣùgbọ́n, gbogbo àwọn ọkùnrin yín tí ó lera tí wọ́n sì ti dira ogun, gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín: ará Israẹli.
És megparancsoltam nektek abban az időben, mondván: Az Örökkévaló, a ti Istenetek adta nektek ezt az országot, hogy elfoglaljátok azt; fölfegyverkezve vonuljatok testvéreitek, Izrael fiai előtt, mind a hadba valók.
19 Àwọn ẹ̀yà a yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ohun ọ̀sìn in yín (mo mọ̀ pé ẹ ti ní ohun ọ̀sìn púpọ̀) lè dúró ní àwọn ìlú tí mo fi fún un yín,
Csak nejeitek, gyermekeitek és nyájaitok – tudom, hogy sok nyájatok van – maradjanak városaitokban, melyeket nektek adtam,
20 títí di ìgbà tí Olúwa yóò fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi bí ó ti fún un yín, àti ìgbà tí àwọn náà yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún wọn ní ìhà kejì Jordani. Nígbà náà ni ọ̀kọ̀ọ̀kan yín tó lè padà lọ sí ìní rẹ̀ tí mo fún un.”
mindaddig, míg nyugalmat szerez az Örökkévaló testvéreiteknek, úgy mint nektek és elfoglalják ők is az országot, melyet az Örökkévaló, a ti Istenetek ad nekik a Jordánon túl, azután visszatérhettek, kiki az ő birtokához, melyet nektek adtam.
21 Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún Joṣua pé, “Ìwọ tí fi ojú rẹ rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ṣe sí àwọn ọba méjèèjì wọ̀nyí. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò ṣe sí àwọn ilẹ̀ ọba tí ẹ̀yin n lọ.
Józsuának pedig megparancsoltam abban az időben, mondván: Szemeid látták mindazt, amit tett az Örökkévaló, a ti Istenetek a két királlyal; így fog tenni az Örökkévaló mindama birodalmakkal, ahová te átvonulsz.
22 Ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, Olúwa Ọlọ́run yín tìkára rẹ̀ ni yóò jà fún un yín.”
Ne féljetek tőlük, mert az Örökkévaló, a ti Istenetek az, aki harcol értetek.
23 Nígbà náà ni mo bẹ Olúwa wí pé,
És könyörögtem az Örökkévalónak abban az időben, mondván:
24 “Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí bẹ̀rẹ̀ sí fi títóbi rẹ àti ọwọ́ agbára rẹ han ìránṣẹ́ rẹ. Ọlọ́run wo ló tó bẹ́ẹ̀ láyé àti lọ́run tí ó lè ṣe àwọn iṣẹ́ agbára ńlá tí o ti ṣe?
Uram, Istenem te elkezdted megmutatni szolgádnak nagyságodat és erős kezedet; hisz ki oly Isten az égben és a földön, aki cselekednék a te cselekedeteid és hatalmad szerint?
25 Jẹ́ kí n kọjá lọ wo ilẹ̀ rere ti ìkọjá Jordani, ilẹ̀ òkè dídára nì àti Lebanoni.”
Hadd vonuljak át, kérlek, hogy lássam azt a jó országot, mely a Jordánon túl van, azt a jó hegyet és a Libánónt.
26 Ṣùgbọ́n torí i tiyín, Olúwa Ọlọ́run bínú sí mi kò sì gbọ́ tèmi. Olúwa sọ wí pé, “Ó tó gẹ́ẹ́, ìwọ kò gbọdọ̀ sọ ohunkóhun lórí ọ̀rọ̀ yìí sí mi mọ́.
De fölgerjedt az Örökkévaló ellenem miattatok és nem hallgatott rám; azt mondta az Örökkévaló nekem: Elég! ne szólj hozzám többé ebben a dologban.
27 Gòkè lọ sí orí òkè Pisga, sì wò yíká ìwọ̀-oòrùn, ìlà-oòrùn, àríwá àti gúúsù. Fi ojú ara rẹ wo ilẹ̀ náà níwọ̀n bí ìwọ kò tí ní kọjá Jordani yìí.
Menj föl a Piszga csúcsára, vesd föl szemeidet nyugatra, északra, délre és keletre és nézd meg szemeiddel, mert nem fogsz átvonulni ezen a Jordánon.
28 Ṣùgbọ́n yan Joṣua, kí o sì gbà á níyànjú, mú un lọ́kàn le, torí pé òun ni yóò síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí kọjá, yóò sì jẹ́ kí wọn jogún ilẹ̀ náà tí ìwọ yóò rí.”
Adj parancsot Józsuának, erősítsd és bátorítsd őt, mert ő fog átvonulni a nép előtt és ő fogja birtokba adni nekik az országot, melyet látsz.
29 Báyìí ni a dúró ní àfonífojì ní ẹ̀bá Beti-Peori.
így maradtunk a völgyben, Bész-Peórral szemben.

< Deuteronomy 3 >