< Deuteronomy 1 >

1 Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mose sọ fún gbogbo Israẹli ní aginjù, aginjù ìlà-oòrùn Jordani, ni Arabah, ní òdìkejì Ṣufi, ní àárín Parani àti Tofeli, Labani, Haserotu àti Disahabu.
Ezek a szavak, amelyekkel szólott Mózes egész Izraelhez a Jordánon innen, a pusztában, a síkságon, a nádastengerrel szemben, Poron meg Tófel és Lovon meg Cháczérósz és Di-Zohov között.
2 (Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Horebu dé Kadeṣi-Barnea, bí a bá gba ọ̀nà òkè Seiri.)
Tizenegy napi út a Chórebtól, a Széir hegye felé Kádes-Bárneáig.
3 Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kọ́kànlá, Mose sọ ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ nípa àwọn ọmọ Israẹli fún wọn.
És volt a negyvenedik évben, a tizenegyedik hónapban, a hónap elsején, szólt Mózes Izrael fiaihoz mind aszerint, amint az Örökkévaló parancsolta neki az ő számukra;
4 Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani ni ó ṣẹ́gun ní Edrei, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu.
miután megverte Szichónt, az Emóri királyát; aki Chesbónban lakott és Ógot, Boson királyát, aki lakott Ástorószban, Edreiben,
5 Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani tí ó wà nínú ilẹ̀ Moabu ni Mose bẹ̀rẹ̀ sísọ àsọyé òfin wọ̀nyí wí pé:
A Jordánon innen; Móáb országában kezdte Mózes magyarázni ezt a tant, mondván:
6 Olúwa Ọlọ́run wa bá wa sọ̀rọ̀ ní Horebu pé, “Ẹ ti dúró ní orí òkè yìí pẹ́ tó.
Az Örökkévaló, a mi Istenünk szólt hozzánk a Chóreben, mondván: Eleget laktatok már a hegy alatt.
7 Ẹ yípadà kí ẹ sì tẹ̀síwájú ní ìrìnàjò yín lọ sí ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, ẹ tọ gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń gbé Arabah lọ ní aginjù, ní àwọn orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní gúúsù àti ní etí Òkun, lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani àti lọ sí Lebanoni, títí fi dé odò ńlá Eufurate.
Forduljatok meg és vonuljatok és menjetek az Emóri hegyéhez és minden szomszédjaihoz a síkságon, a hegyen, az alföldön, a déli vidéken és a tenger partján, a Kanaáni országába, a Libánónra, a nagy folyamig, a Perosz folyamig.
8 Wò ó, èmi tí fi ilẹ̀ yí fún un yín, ẹ wọ inú rẹ̀ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí Olúwa ti búra wí pé òun yóò fún àwọn baba yín: fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu, àti fún àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn.”
Lásd, elétek adtam az országot, menjetek be és foglaljátok el, az országot, melyről megesküdött őseiteknek: Ábrahámnak, Izsáknak és Jákobnak, hogy nekik adja és magzatuknak utánuk.
9 Mo wí fún un yín nígbà náà pé, “Èmi nìkan kò lè dá ẹrù u yín gbé.
És szóltam hozzátok abban az időben, mondván: Nem bírlak egymagam vinni benneteket.
10 Olúwa Ọlọ́run yín ti sọ yín di púpọ̀ lónìí, ẹ̀yin sì ti pọ̀ bí ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run.
Az Örökkévaló, a ti Istenetek megsokasított benneteket, és íme ti ma annyian vagytok, mint az ég csillagai sokaságra nézve.
11 Kí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín sọ yín di púpọ̀ ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún sí i, kí ó sì bùkún un yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
Az Örökkévaló; őseitek Istene tegyen hozzátok ezerszer annyit, mint vagytok és áldjon meg benneteket, amint szólt felőletek.
12 Báwo ni èmi nìkan ṣe lè máa ru àjàgà àti ìṣòro yín àti èdè-àìyedè yín?
Hogy vigyem egymagam fáradalmatokat, terheteket és pörlekedésteket?
13 Ẹ yan àwọn ọlọ́gbọ́n, olóye àti àwọn ẹni àpọ́nlé, láti inú ẹ̀yà yín kọ̀ọ̀kan, èmi yóò sì fi wọ́n ṣe olórí yín.”
Adjatok közületek bölcs férfiakat és értelmeseket és ismereteseket törzseitek szerint, és én teszem azokat fölétek.
14 Ẹ̀yin sì dá mi lóhùn wí pé, “Ohun tí ìwọ ti gbèrò láti ṣe nì dára.”
Ti feleltetek nekem és mondtátok: Jó a dolog, amiről szóltál, hogy megteszed.
15 Bẹ́ẹ̀ ni mo yan olórí àwọn ẹ̀yà yín, àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin, ẹni àpọ́nlé, mo sì fi jẹ olórí yín, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà yín.
Vettem tehát törzseitek fejeit, bölcs férfiakat és ismereteseket és tettem őket fejekké fölétek, ezrek tisztjeivé, százak tisztjeivé, ötvenek tisztjeivé és tizek tisztjeivé, meg felügyelőkké törzseitek szerint.
16 Mo sì kìlọ̀ fún àwọn onídàájọ́ yín nígbà náà pé, ẹ gbọ́ èdè-àìyedè tí ó wà láàrín àwọn ènìyàn an yín kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ òdodo, bóyá ẹjọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ láàrín Israẹli sí Israẹli ni tàbí láàrín Israẹli kan sí àlejò.
És megparancsoltam bíráitoknak abban az időben, mondván: Hallgassátok meg testvéreiteket és ítéljetek igazsággal ember és társa közt, meg az ő idegené közt.
17 Ẹ má sì ṣe ojúsàájú ní ìdájọ́. Ẹ ṣe ìdájọ́ ẹni ńlá àti kékeré bákan náà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹnikẹ́ni torí pé ti Ọlọ́run ni ìdájọ́. Ẹjọ́ tí ó bá le jù fún un yín ni kí ẹ mú wá fún mi. Èmi yóò sì gbọ́ ọ.
Ne ismerjetek tekintélyt az ítéletben, a kicsinyt, mint a nagyot hallgassátok meg, ne féljetek senkitől, mert az ítélet Istené; amely dolog pedig nehéz nektek; azt hozzátok elém, hogy meghallgassam.
18 Nígbà náà ni èmi yóò sọ ohun tí ẹ ó ṣe fún un yín.
És megparancsoltam nektek abban az időben mind a dolgokat, melyeket megtegyetek.
19 Nígbà náà ní a gbéra láti Horebu, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wá, a sì la àwọn ilẹ̀ lókè Amori kọjá lọ dé gbogbo aginjù ńlá tí ó ba ni lẹ́rù nì tí ẹ̀yin ti rí, bẹ́ẹ̀ ni a sì dé Kadeṣi-Barnea.
Mi elvonultunk a Chórebtől és végigmentünk eme egész, nagy és félelmetes pusztán, melyet láttatok, az Emóri hegye felé, amint parancsolta nekünk az Örökkévaló, a mi Istenünk és elérkeztünk Kádes-Barneáig.
20 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ ti dé ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, èyí tí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.
És mondtam nektek: Elérkeztetek az Emóri hegyéig, melyet az Örökkévaló, a mi Istenünk nekünk ad.
21 Ẹ kíyèsi i, Olúwa Ọlọ́run yín ló ni ilẹ̀ náà. Ẹ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín tí sọ fún un yín. Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà.”
Lásd, elédadta az Örökkévaló, a te Istened az országot, menj föl, foglald el, amint szólt az Örökkévaló, őseid Istene hozzád; ne félj és ne csüggedj!
22 Nígbà náà ni gbogbo yín tọ̀ mí wá wí pé, “Jẹ́ kí a yan àwọn ayọ́lẹ̀wò láti yọ́ ilẹ̀ náà wò fún wa, kí wọn sì fún wa ní ìròyìn àwọn ọ̀nà tí a ó gbà àti àwọn ìlú tí a ó bá pàdé.”
Akkor odaléptetek hozzám mindnyájan és mondtátok: Hadd küldjünk férfiakat magunk előtt, hogy kikémleljék nekünk az országot és hozzanak nekünk feleletet az út felől, amelyen fölmegyünk és a városok felől, amelyekhez elérkezünk.
23 Èrò náà sì dára lójú mi, torí èyí ni mo ṣe yan àwọn ènìyàn méjìlá nínú yín, ẹnìkan láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
Jónak tetszett szemeimben a dolog, vettem közületek tizenkét férfiút, egy férfiút törzsenként.
24 Wọ́n sì gòkè lọ sí ilẹ̀ òkè náà, wọ́n sì wá sí àfonífojì Eṣkolu, wọ́n sì yẹ̀ ẹ́ wò.
Ők megfordultak és fölmentek a hegyre, elérkeztek Eskól völgyéig és kikémlelték azt.
25 Wọ́n sì mú lára èso ilẹ̀ náà wá fún wa pé, “Ilẹ̀ tí ó dára ni Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
Vettek kezükbe az ország gyümölcséből és lehozták nekünk; és hoztak nekünk feleletet és mondták: Jó az ország, melyet az Örökkévaló, a mi Istenünk nekünk ad.
26 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́ gòkè lọ; ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín.
De ti nem akartatok fölmenni és ellenszegültetek az Örökkévaló, a ti Istenetek parancsának.
27 Ẹ kùn nínú àgọ́ ọ yín, ẹ sì wí pé, “Olúwa kórìíra wa, torí èyí ló fi mú wa jáde láti Ejibiti láti fi wá lé àwọn ará Amori lọ́wọ́ láti pa wá run.
Zúgolódtatok sátraitokban és mondtátok: Mert gyűlölt bennünket az Örökkévaló, azért vezetett ki bennünket Egyiptom országából, hogy adjon minket az Emóri kezébe, hogy elpusztítson bennünket.
28 Níbo la ó lọ? Àwọn arákùnrin wa ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa nípa sísọ pé, ‘Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga jù wá lọ; àwọn ìlú náà tóbi jọjọ bẹ́ẹ̀ ni odi wọn ga kan ọ̀run. A tilẹ̀ rí àwọn òmíràn (ìran Anaki) níbẹ̀.’”
Hová menjünk mi föl? Testvéreink elcsüggesztették szívünket, mondván: Nagyobb és hatalmasabb nép az nálunknál, a városok nagyok és az égig megerősítve, meg az ánokiták fiait is láttuk ott.
29 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ má ṣojo, ẹ kò sì gbọdọ̀ bẹ̀rù wọn.
És mondtam nektek: Ne ijedjetek meg és ne féljetek tőlük.
30 Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń ṣáájú yín yóò jà fún un yín; bí ó ti ṣe fún un yín ní Ejibiti lójú ẹ̀yin tìkára yín
Az Örökkévaló, a ti Istenetek, aki jár előttetek, ő harcol majd értetek, mind aszerint, mint cselekedett veletek Egyiptomban szemeitek láttára,
31 àti ní aginjù. Níbẹ̀ ni ẹ ti rí i bí Olúwa Ọlọ́run yín ti gbé yín, bí baba ti í gbé ọmọ rẹ̀, ní gbogbo ọ̀nà tí ẹ lọ títí ẹ fi padà dé ibí yìí.”
meg a pusztában, amelyet láttál, hogy vitt téged az Örökkévaló, a te Istened, amint viszi valaki az ő fiát, az egész úton, amelyen jártatok, míg elérkeztetek erre a helyre.
32 Pẹ̀lú gbogbo èyí tí mo wí, ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín,
De ebben a dologban nem hittetek az Örökkévalóban, a ti Istenetekben,
33 tí ń ṣáájú u yín lọ ní gbogbo ọ̀nà yín, nípa fífi iná ṣe amọ̀nà yín ní òru àti ìkùùkuu ní ọ̀sán, láti fi àwọn ibi tí ẹ lè tẹ̀dó sí hàn yín àti àwọn ọ̀nà tí ẹ ó rìn.
aki jár előttetek az úton, hogy kikémleljen nektek helyet, ahol táborozzatok, tűzben éjjel, hogy mutassa nektek az utat, amelyen menjetek, és felhőben nappal.
34 Nígbà tí Olúwa gbọ́ ohun tí ẹ sọ, inú bí i, ó sì búra wí pé,
És az Örökkévaló meghallotta szavaitok hangját, megharagudott és megesküdött, mondván:
35 “Kò sí ọ̀kan nínú ìran búburú yìí tí yóò dé ilẹ̀ rere tí mo ti búra láti fún àwọn baba ńlá a yín.
Nem fogja látni egy sem a férfiak közül, ez a gonosz nemzedék, a jó országot, melyről megesküdtem, hogy őseiteknek adom,
36 Bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne. Òun ni yóò wọ̀ ọ́. Èmi yóò sì fún òun àti àwọn ìran rẹ̀ ní ilẹ̀ náà tí ó ti fi ẹsẹ̀ rẹ̀ tẹ̀; torí pé ó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ tẹ̀lé Olúwa.”
kivéve Kálebet, Jefune fiát; ő fogja látni, neki adom a földet, ahol járt és fiának, mivelhogy teljesen járt az Örökkévaló után.
37 Torí i tiyín ni Olúwa fi bínú sí mi wí pé, “Ìwọ náà kì yóò wọ ibẹ̀ bákan náà,
Rám is megharagudott az Örökkévaló miattatok, mondván: Te sem fogsz oda, bemenni.
38 ṣùgbọ́n Joṣua ọmọ Nuni tí ń ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ ni yóò wọ ibẹ̀. Mú un, ní ọkàn le torí pé, òun yóò ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli láti gba ilẹ̀ náà.
Józsua, Nún fia, ki előtted áll, ő megy oda be, őt bátorítsd, mert ő fogja birtokba adni Izraelnek
39 Àwọn èwe yín tí ẹ sọ pé wọn yóò kó lẹ́rú. Àwọn ọmọ yín tí ko tí ì mọ rere yàtọ̀ sí búburú ni yóò wọ ilẹ̀ náà.
Gyermekeitek pedig, akikről mondtátok, martalékká lesznek és fiaitok, akik még nem ismerik ma a jót és a rosszat, ők mennek oda be; nekik adom és ők fogják azt elfoglalni.
40 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, ẹ yí padà sí aginjù tí ó wà ní ọ̀nà tí ó lọ sí Òkun Pupa.”
Ti pedig forduljatok meg és vonuljatok a pusztába a nádastenger felé.
41 Nígbà náà ni ẹ fèsì wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa. A ó sì gòkè lọ láti jà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wa.” Torí náà gbogbo yín ẹ mú ohun ìjà a yín, ẹ rò pé ó rọrùn láti gòkè lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè náà.
De ti feleltetek és mondtátok nekem Vétkeztünk az Örökkévaló ellen, mi föl akarunk menni, hagy harcoljunk mind aszerint, amint parancsolta nekünk az Örökkévaló, a mi Istenünk; felkötöttétek, kiki az ő harci eszközeit és készek voltatok fölmenni a hegyre.
42 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ fún wọn, ‘Ẹ má ṣe gòkè lọ láti jà torí pé èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín. Àwọn ọ̀tá a yín yóò sì ṣẹ́gun yín.’”
De az Örökkévaló mondta nekem: Mondd nekik: Ne menjetek föl és ne harcoljatok, mert én nem vagyok közepettetek, hogy vereséget ne szenvedjetek ellenségeitek előtt.
43 Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbọ́, ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa, pẹ̀lú ìgbéraga yín, ẹ gòkè lọ sí ìlú olókè náà.
És szóltam hozzátok, de ti nem hallgattatok rám és ellenszegültetek az Örökkévaló parancsának, dacoltatok és fölmentetek a hegyre.
44 Àwọn ará Amori tí ń gbé ní àwọn òkè náà, dojúkọ yín bí àgbájọpọ̀ oyin. Wọ́n sì lù yín bolẹ̀ láti Seiri títí dé Horma.
Akkor kijött az Emóri, aki azon a hegyen lakott, elétek és üldöztek benneteket, mint a méhek teszik, és szétvertek benneteket Széirben egész Chormoig.
45 Ẹ padà, ẹ sì sọkún níwájú Olúwa, òun kò sì fetí sí igbe ẹkún yín, Ó sì kọ etí dídi sí i yín.
És visszatértetek és sírtatok az Örökkévaló színe előtt, de az Örökkévaló nem hallgatta meg szavatokat és nem figyelt rátok.
46 Báyìí ni ẹ sì dúró ní Kadeṣi fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ṣe.
És maradtatok Kádesben sok ideig, amennyi ideig maradtatok.

< Deuteronomy 1 >