< Deuteronomy 24 >

1 Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ obìnrin kan, tí ó sì gbe ní ìyàwó, yóò sì ṣe, bí obìnrin náà kò bá rí ojúrere ní ojú ọkùnrin náà, nítorí ó rí ohun àìtọ́ kan lára rẹ̀, ǹjẹ́ kí ó kọ ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún obìnrin náà, kí ó sì fi lé e lọ́wọ́, kí ó sì ran jáde kúrò nínú ilé rẹ̀,
Când un bărbat şi-a luat o soţie şi s-a căsătorit cu ea şi se întâmplă că ea nu găseşte favoare înaintea ochilor lui, pentru că el a găsit în ea ceva necurăţie, să îi scrie o carte de divorţ şi să i-o dea în mână şi să o trimită afară din casa lui.
2 tí ó bá di ìyàwó ọkùnrin mìíràn lẹ́yìn ìgbà tí ó kúrò nílé rẹ,
Şi după ce ea a plecat din casa lui, poate să se ducă şi să fie soţia altui bărbat.
3 àti tí ọkọ rẹ̀ kejì kò bá fẹ́ràn rẹ̀ tí ó sì kọ ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ sí i, kí ó fi fún un kí ó sì lé e kúrò nílé e rẹ̀, tàbí tí ọkọ rẹ̀ kejì bá kú,
Şi dacă soţul de pe urmă o urăşte şi îi scrie o carte de divorţ şi i-o dă în mână şi o trimite afară din casa lui, sau dacă moare soţul de pe urmă, care şi-a luat-o de soţie,
4 nígbà náà ni ọkọ, tí ó ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀, kò gbọdọ̀ fẹ́ ẹ mọ́ lẹ́yìn tí ó ti di àìmọ́. Nítorí èyí ni ìríra níwájú Olúwa. Má ṣe mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sórí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ bí ogún.
Soţul ei cel dintâi, care a trimis-o, nu va mai putea să o ia ca să îi fie din nou soţie, după ce ea s-a pângărit, pentru că aceasta este o urâciune înaintea DOMNULUI; şi să nu faci să păcătuiască ţara, pe care DOMNUL Dumnezeul tău ţi-o dă ca moştenire.
5 Bí ọkùnrin kan bá ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó, o kò gbọdọ̀ ran lọ sí ogun tàbí kí ó ní iṣẹ́ kan láti ṣe. Ó ní láti ní òmìnira fún ọdún kan kí ó dúró sílé kí ó sì mú inú dídùn bá ìyàwó rẹ̀ tí ó fẹ́.
Când un bărbat a luat de curând o soţie, să nu meargă la război, nici să nu i se poruncească vreo sarcină, ci să fie liber acasă un an şi să îşi înveselească soţia pe care şi-a luat-o.
6 Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ gba ìyá ọlọ tàbí ọmọ ọlọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìdúró fún gbèsè, nítorí pé ẹ̀mí ènìyàn ni ó gbà ní pàṣípàrọ̀ n nì.
Niciun om să nu ia garanţie piatra de moară inferioară sau superioară, pentru că el ar lua garanţie viaţa.
7 Bí a bá mú ọkùnrin kan tí ó jí ọ̀kan nínú arákùnrin rẹ̀ ní Israẹli gbé àti tí ó jí ọ̀kan nínú ẹrú tàbí kí ó tà á, ẹni tí ó jí ènìyàn gbé ní láti kú. Ẹ ní láti wẹ búburú kúrò láàrín yín.
Dacă un om este găsit furând pe vreunul dintre fraţii săi dintre copiii lui Israel şi face comerţ cu el, sau îl vinde, atunci hoţul acela să moară; şi să îndepărtezi răul din mijlocul tău.
8 Ní ti ààrùn ẹ̀tẹ̀ kíyèsára láti máa ṣe gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ti pàṣẹ fún ọ. O ní láti máa fi ìṣọ́ra tẹ̀lé ohun tí mo ti pàṣẹ fún wọn.
Ia aminte la rana leprei, să iei seama şi să faci tot ce te învaţă preoţii, leviţii, precum le-am poruncit, astfel să ţineţi şi să faceţi.
9 Rántí ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe sí Miriamu lójú ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí o jáde kúrò ní Ejibiti.
Aminteşte-ţi ce a făcut DOMNUL Dumnezeul tău lui Miriam pe cale, după ce aţi ieşit din Egipt.
10 Nígbà tí o bá wín arákùnrin rẹ ní ohunkóhun, má ṣe lọ sí ilé rẹ̀ láti gba ohun tí ó bá mú wá bí ẹ̀rí.
Când împrumuţi ceva fratelui tău, să nu intri în casa lui să îi iei garanţia.
11 Dúró síta gbangba kí o sì jẹ́ kí ọkùnrin tí o wín mú ògo rẹ jáde wá fún ọ.
Să stai afară şi omul căruia i-ai împrumutat să îţi aducă garanţia afară.
12 Bí ọkùnrin náà bá jẹ́ tálákà má ṣe lọ sùn ti ìwọ ti ògo rẹ.
Şi dacă omul este sărac, să nu te culci cu garanţia lui.
13 Dá aṣọ ìlekè rẹ padà ní àṣálẹ́ kí ó bá à le sùn lórí i rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, ó sì máa jásí ìwà òdodo níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
În orice caz să îi înapoiezi garanţia la apusul soarelui, ca să doarmă în haina lui şi să te binecuvânteze şi aceasta îţi va fi dreptate înaintea DOMNULUI Dumnezeul tău.
14 Má ṣe ni alágbàṣe kan lára tí ó jẹ́ tálákà àti aláìní, bóyá ó jẹ́ arákùnrin Israẹli tàbí àlejò tí ó ń gbé ní ọ̀kan nínú àwọn ìlú rẹ.
Să nu oprimi un servitor angajat, sărac şi nevoiaş, dintre fraţii tăi sau dintre străinii tăi, care sunt în ţara ta, înăuntrul porţilor tale.
15 San owó iṣẹ́ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà kí ó tó di àṣálẹ́, nítorí ó jẹ́ tálákà, ó sì gbẹ́kẹ̀lé e bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ó lè ké pe Olúwa sí ọ, o sì máa gba ìdálẹ́bi ẹ̀ṣẹ̀.
La ziua lui să îi dai plata şi să nu apună soarele peste ea, pentru că este sărac şi îşi pune inima lui în aceasta, ca nu cumva să strige împotriva ta către DOMNUL şi să îţi fie păcat.
16 Baba kò gbọdọ̀ kú fún àwọn ọmọ wọn tàbí kí àwọn ọmọ kú fún baba wọ́n; olúkúlùkù ní láti kú fún ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀.
Părinţii să nu fie ucişi pentru copii, nici copiii să nu fie ucişi pentru părinţi, fiecare om să fie dat morţii pentru propriul său păcat.
17 Má ṣe yí ìdájọ́ po fún àlejò tàbí aláìní baba, tàbí gba aṣọ ìlekè opó bí ẹ̀rí.
Să nu pervertești judecata străinului, nici a celui fără tată; nici să nu iei o haină a văduvei ca garanţie,
18 Rántí pé o jẹ́ ẹrú ní Ejibiti tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì gbà ọ́ níbẹ̀. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
Ci să îţi aminteşti că ai fost rob în Egipt şi DOMNUL Dumnezeul tău te-a răscumpărat de acolo; de aceea îţi poruncesc să faci acest lucru.
19 Nígbà tí o bá ń kórè oko rẹ tí o sì fojú fo ìtí kan, má ṣe padà lọ mú u. Fi í kalẹ̀ fún àwọn àlejò, aláìní baba àti opó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ lè bùkún fún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ.
Când îţi seceri recolta în câmpul tău şi vei fi uitat un snop în câmp, să nu te întorci să îl iei, să fie pentru străin, pentru cel fără tată şi pentru văduvă, pentru ca DOMNUL Dumnezeul tău să te binecuvânteze în toată lucrarea mâinilor tale.
20 Nígbà tí o bá ń gun igi olifi lára àwọn igi i rẹ, má ṣe padà lọ sí ẹ̀ka náà ní ìgbà kejì. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
Când îţi baţi măslinul, să nu treci peste ramuri din nou, să fie pentru străin, pentru cel fără tată şi pentru văduvă.
21 Nígbà tí ìwọ bá kórè èso àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ, má ṣe lọ sí ọgbà náà mọ́. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
Când aduni strugurii viei tale, să nu culegi ce rămâne în urma ta, să fie pentru străin, pentru cel fără tată şi pentru văduvă.
22 Rántí pé ìwọ ti jẹ́ àlejò ní Ejibiti. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
Şi să îţi aminteşti că ai fost rob în ţara Egiptului, de aceea îţi poruncesc să faci acest lucru.

< Deuteronomy 24 >