< Joshua 1 >

1 Lẹ́yìn ikú u Mose ìránṣẹ́ Olúwa, Olúwa sọ fún Joṣua ọmọ Nuni, olùrànlọ́wọ́ ọ Mose,
Și s-a întâmplat, după moartea lui Moise, servitorul DOMNULUI, că DOMNUL i-a vorbit lui Iosua, fiul lui Nun, servitorul lui Moise, spunând:
2 “Mose ìránṣẹ́ mi ti kú. Nísinsin yìí, ìwọ àti gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹ múra láti kọjá odò Jordani lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ó fi fún wọn fún àwọn ará Israẹli.
Moise, servitorul meu, a murit; de aceea ridică-te acum și treci Iordanul acesta, tu și tot acest popor, până în țara pe care le-o dau copiilor lui Israel.
3 Èmi yóò fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe ìlérí fún Mose.
Orice loc, pe care îl va călca talpa piciorului vostru, vi l-am dat; așa cum i-am spus lui Moise.
4 Ilẹ̀ ẹ yín yóò fẹ̀ láti aginjù Lebanoni, àti láti odò ńlá, ti Eufurate—gbogbo orílẹ̀-èdè Hiti títí ó fi dé Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
De la pustie și Libanul acesta până la râul cel mare, râul Eufrat, tot pământul hitiților și până la marea cea mare spre apusul soarelui, va fi ținutul vostru.
5 Kì yóò sí ẹnikẹ́ni tí yóò le è dúró níwájú rẹ ní ọjọ́ ayé è rẹ gbogbo. Bí mo ti wà pẹ̀lú u Mose, bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, Èmi kì yóò fi ọ́ sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Èmi kì yóò kọ̀ ọ́.
Niciun om nu va fi în stare să stea în picioare înaintea ta toate zilele vieții tale; precum am fost cu Moise, astfel voi fi cu tine; nu te voi lăsa, nici nu te voi părăsi.
6 “Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le, nítorí ìwọ ni yóò ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, láti lè jogún ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fi fún wọn.
Fii tare și curajos; fiindcă acestui popor tu îi vei împărți ca moștenire țara, pe care am jurat-o părinților lor că le-o voi da.
7 Jẹ́ alágbára, kí o sì mú àyà le gidigidi. Kí o sì ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin tí Mose ìránṣẹ́ mi fún ọ mọ́, má ṣe yà kúrò nínú u rẹ̀ sí ọ̀tún tàbí sí òsì, kí ìwọ kí ó lè ṣe rere níbikíbi tí ìwọ bá ń lọ.
Numai fii tare și foarte curajos, ca să iei seama să faci conform cu toată legea pe care ți-a poruncit-o servitorul meu, Moise; nu te abate de la ea nici la dreapta, nici la stânga, ca să prosperi oriunde vei merge.
8 Má ṣe jẹ́ kí ìwé òfin yìí kúrò ní ẹnu rẹ, máa ṣe àṣàrò nínú u rẹ̀ ní ọ̀sán àti ní òru, kí ìwọ kí ó lè ṣọ́ra láti ṣe gbogbo nǹkan tí a kọ sí inú u rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dára fún ọ, ìwọ yóò sì ní àṣeyọrí.
Această carte a legii să nu se depărteze de gura ta, ci cugetă asupra ei zi și noapte, ca să iei seama să faci conform cu tot ce este scris în ea; fiindcă atunci vei face calea ta prosperă și atunci vei avea mult succes.
9 Èmi kò ha ti pàṣẹ fún ọ bí? Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le. Má ṣe bẹ̀rù, má sì ṣe rẹ̀wẹ̀sì, nítorí pé Olúwa à rẹ yóò wà pẹ̀lú rẹ ní ibikíbi tí ìwọ bá ń lọ.”
Nu ți-am poruncit eu? Fii tare și curajos; nu te teme, nici nu te descuraja, fiindcă DOMNUL Dumnezeul tău este cu tine oriunde mergi.
10 Báyìí ni Joṣua pàṣẹ fún olórí àwọn ènìyàn rẹ̀,
Atunci Iosua le-a poruncit ofițerilor poporului, spunând:
11 “Ẹ la ibùdó já, kí ẹ sì sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Ẹ pèsè oúnjẹ yín sílẹ̀. Ní ìwòyí ọ̀túnla, ẹ̀yin yóò la Jordani yìí kọjá, láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín láti ní.’”
Treceți prin oștire și porunciți poporului, spunând: Pregătiți-vă merinde, fiindcă în trei zile veți trece Iordanul acesta, ca să intrați să stăpâniți țara, pe care DOMNUL Dumnezeul vostru v-o dă ca să o stăpâniți.
12 Ṣùgbọ́n Joṣua sọ fún àwọn ará a Reubeni, àwọn ará Gadi àti fún ìdajì ẹ̀yà Manase pé,
Și Iosua le-a vorbit rubeniților și gadiților și jumătății tribului lui Manase, spunând:
13 “Rántí àṣẹ tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pa fún yín: ‘Olúwa Ọlọ́run yín á fún yin ní ìsinmi, òun yóò sì fún un yín ní ilẹ̀ yìí.’
Amintiți-vă de cuvântul pe care vi l-a poruncit Moise, servitorul DOMNULUI, spunând: DOMNUL Dumnezeul vostru v-a dat odihnă și v-a dat această țară.
14 Àwọn ìyàwó yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ẹran ọ̀sìn yín lè dúró ní ilẹ̀ tí Mose fún un yin ní ìlà-oòrùn Jordani; ṣùgbọ́n gbogbo àwọn jagunjagun un yín, pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín. Ẹ̀yin yóò sì rán àwọn arákùnrin yín lọ́wọ́
Soțiile voastre, micuții voștri și vitele voastre, să rămână în țara pe care v-a dat-o Moise de această parte a Iordanului; dar voi să treceți înarmați înaintea fraților voștri, toți bărbații puternici de valoare și să îi ajutați,
15 títí Olúwa yóò fi fún wọn ní ìsinmi, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún un yín, àti títí tí àwọn pẹ̀lú yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún wọn. Lẹ́yìn náà, ẹ̀yin lè padà sí ilẹ̀ ìní in yín, tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún un yin ní agbègbè ìlà-oòrùn ti Jordani.”
Până când DOMNUL va da odihnă fraților voștri, precum v-a dat și vouă și ei de asemenea vor fi luat în stăpânire țara pe care le-o dă DOMNUL Dumnezeul vostru; atunci vă veți întoarce în țara stăpânirii voastre și vă veți bucura de ea, de partea aceasta a Iordanului spre răsăritul soarelui, pe care v-a dat-o Moise, servitorul DOMNULUI.
16 Nígbà náà ni wọ́n dá Joṣua lóhùn pé, “Ohunkóhun tí ìwọ pàṣẹ fún wa ni àwa yóò ṣe, ibikíbi tí ìwọ bá rán wa ni àwa yóò lọ.
Și i-au răspuns lui Iosua, spunând: Vom face tot ce ne poruncești și vom merge oriunde ne trimiți.
17 Gẹ́gẹ́ bí àwa ti gbọ́rọ̀ sí Mose nínú ohun gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò máa gbọ́ tìrẹ. Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà pẹ̀lú u Mose.
Precum am dat ascultare lui Moise în toate, astfel îți vom da ascultare ție; numai DOMNUL Dumnezeul tău să fie cu tine, precum a fost cu Moise.
18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tàpá sí ọ̀rọ̀ rẹ, tí kò sì ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ nínú ohun gbogbo tí ìwọ yóò pàṣẹ fún wọn, pípa ni a ó pa á. Kí ìwọ sá à ṣe gírí, kí ó sì mú àyà le!”
Oricine se va răzvrăti împotriva poruncii tale și nu va da ascultare cuvintelor tale în tot ce îi poruncești, să fie dat morții; numai fii tare și curajos!

< Joshua 1 >