< Deuteronomy 21 >

1 Tí a bá rí ọkùnrin tí a pa, ní ìdùbúlẹ̀ ní pápá nínú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ láti jogún, tí a kò sì mọ ẹni tí ó pa á,
Dacă în ţara, pe care ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău să o stăpâneşti, se va găsi un om ucis, zăcând în câmp, şi nu se ştie cine l-a ucis,
2 àwọn àgbàgbà yín yóò jáde lọ láti wọn jíjìnnà ibi òkú sí ìlú tí ó wà nítòsí.
Atunci bătrânii tăi şi judecătorii tăi să iasă şi să măsoare până la cetăţile care sunt împrejurul celui ucis,
3 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí òkú yóò mú ẹgbọrọ abo màlúù tí kò ì ṣiṣẹ́ rí àti tí kò sì fà nínú àjàgà rí,
Şi va fi astfel, din cetatea care este lângă cel ucis, bătrânii cetăţii aceleia să ia o viţea, cu care nu s-a lucrat şi care nu a tras la jug;
4 kí àwọn àgbàgbà ìlú náà kí wọn mú ẹgbọrọ abo màlúù náà sọ̀kalẹ̀ wá sí àfonífojì tí ó ní omi ṣíṣàn kan, tí a kò ro, tí a kò sì gbìn, kí wọn kí ó sì ṣẹ́ ọrùn ẹgbọrọ màlúù náà níbẹ̀ ní àfonífojì náà.
Şi bătrânii cetăţii aceleia să coboare viţeaua într-o vale nelucrată, în care nici nu s-a recoltat nici nu s-a semănat, şi să frângă gâtul viţelei acolo în vale,
5 Àwọn àlùfáà, ọmọ Lefi yóò wá síwájú, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti yàn wọ́n láti ṣe ìránṣẹ́ fún un àti láti bùkún ní orúkọ Olúwa àti láti parí gbogbo ẹjọ́ àríyànjiyàn àti ọ̀rọ̀ ìlú.
Şi preoţii, fiii lui Levi, să se apropie, pentru că pe ei i-a ales DOMNUL Dumnezeul tău să îi servească şi să binecuvânteze în numele DOMNULUI; şi prin cuvântul lor să fie încercată orice ceartă şi orice lovitură,
6 Nígbà náà ni gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí yóò wẹ ọwọ́ wọn lórí ẹgbọrọ abo màlúù tí a ti kan ọrùn rẹ̀ ní àfonífojì,
Şi toţi bătrânii cetăţii aceleia, care este lângă cel ucis, să îşi spele mâinile deasupra viţelei decapitate în vale,
7 wọn yóò sì sọ pé, “Ọwọ́ wa kò ta ẹ̀jẹ̀ yìí sílẹ̀, tàbí kí ojú wa rí i ní títa sílẹ̀.”
Şi să răspundă şi să zică: Mâinile noastre nu au vărsat acest sânge, nici ochii noştri nu au văzut.
8 Dáríjì, Olúwa, àwọn ènìyàn rẹ ni Israẹli, tí ìwọ ti dá sílẹ̀, àti kí ìwọ má ṣe gba ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ ní àárín àwọn ènìyàn rẹ ní Israẹli. Ṣùgbọ́n kí a dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ yìí jì.
Fii milostiv, Doamne, faţă de poporul tău Israel, pe care l-ai răscumpărat, şi nu pune sânge nevinovat în contul poporului tău Israel. Şi sângele li se va ierta.
9 Nígbà náà ni ìwọ wẹ̀ kúrò láàrín rẹ ẹ̀bi títa ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí o ti ṣe èyí tí ó tọ́ níwájú Olúwa.
Astfel să îndepărtezi sângele nevinovat din mijlocul tău, când vei face ce este drept înaintea ochilor DOMNULUI.
10 Nígbà tí o bá lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá rẹ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ tí o sì mú àwọn ìgbèkùn,
Când vei ieşi la război împotriva duşmanilor tăi şi DOMNUL Dumnezeul tău îi va da în mâinile tale şi îi vei lua captivi,
11 tí o sì rí obìnrin tí ó dára lára àwọn ìgbèkùn, tí o sì ní ìfẹ́ sí i, o lè mu u gẹ́gẹ́ bí aya à rẹ.
Şi între cei captivi vei vedea o femeie frumoasă şi vei avea dorinţă spre ea şi vei voi să ţi-o iei de soţie,
12 Mú u wá sí ilé e rẹ kí o sì jẹ́ kí ó fá irun orí rẹ̀, gé èékánná an rẹ̀,
Atunci să o aduci la tine în casa ta şi să îşi radă capul şi să îşi taie unghiile;
13 kí o sì mú aṣọ tí ó wọ̀ nígbà tí ó di ìgbèkùn sí ẹ̀gbẹ́ kan. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ń gbé ilé rẹ tí ó sì ti ṣọ̀fọ̀ baba àti ìyá rẹ̀ fún odidi oṣù kan, nígbà náà ni o lè tọ̀ ọ́ lọ kí o sì ṣe ọkọ rẹ̀ kí ó jẹ́ aya rẹ.
Şi să îşi lepede hainele captivităţii ei de pe ea şi să rămână în casa ta şi să plângă pe tatăl ei şi pe mama ei o lună întreagă, şi după aceea să intri la ea şi să fii soţul ei şi ea să fie soţia ta.
14 Bí inú rẹ̀ kò bá sì dùn sí i, jẹ́ kí ó lọ sí ibikíbi tí ó bá fẹ́. O kò gbọdọ̀ tà á tàbí lò ó bí ẹrú, lẹ́yìn ìgbà tí o ti dójútì í.
Şi va fi astfel, dacă nu găseşti plăcere în ea, să îi dai drumul să meargă încotro voieşte; dar să nu o vinzi deloc pe bani; să nu faci comerţ cu ea, pentru că ai înjosit-o.
15 Bí ọkùnrin kan bá ní ìyàwó méjì, tí ó sì fẹ́ ọ̀kan ṣùgbọ́n tí kò fẹ́ èkejì, tí àwọn méjèèjì sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un ṣùgbọ́n tí àkọ́bí jẹ́ ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn.
Dacă un bărbat are două soţii, una iubită şi alta neiubită, şi i-au născut copii, atât cea iubită cât şi cea neiubită, şi dacă fiul întâi-născut este al celei ce nu era iubită,
16 Nígbà tí ó bá ń pín ohun ìní rẹ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, kò gbọdọ̀ fi ẹ̀tọ́ àkọ́bí fún ọmọ ìyàwó tí kò fẹ́ràn.
Atunci va fi astfel: în ziua când va da moştenire fiilor săi ceea ce are, nu va putea face întâi-născut pe fiul celei iubite înaintea fiului celei ce nu era iubită, care este cel întâi-născut;
17 Ó ní láti fi ipò ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn fun un gẹ́gẹ́ bí àkọ́bí i rẹ̀ nípa fífún un ní ìlọ́po ìpín gbogbo ohun tí ó ní. Ọmọ yẹn ni àmì àkọ́kọ́ agbára baba rẹ̀. Ẹ̀tọ́ àkọ́bí jẹ́ tirẹ̀.
Ci să recunoască de întâi-născut pe fiul celei ce nu era iubită, dându-i o parte dublă din tot ce are, pentru că el este începutul puterii sale; dreptul de întâi-născut este al lui.
18 Bí ọkùnrin kan bá ní aláìgbọ́ràn tàbí ọlọ̀tẹ̀ ọmọ tí kò gbọ́rọ̀ sí baba àti ìyá rẹ̀ tí kò sì ní í gbà tí wọ́n bá ń bá a wí,
Dacă un om are un fiu încăpățânat şi răzvrătit, care nu va asculta de vocea tatălui său, sau vocea mamei sale, şi când ei îl ceartă, nu le dă ascultare,
19 baba àti ìyá rẹ̀ yóò gbá a mú, wọn yóò mu wá fún àwọn àgbàgbà ní ẹnu-bodè ìlú u rẹ̀.
Atunci tatăl său şi mama sa să îl apuce şi să îl scoată la bătrânii cetăţii sale şi la poarta locului său.
20 Wọn yóò sì wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Ọmọ wa yìí jẹ́ aláìgbọ́ràn àti ọlọ̀tẹ̀. Kò ní gbọ́rọ̀ sí wa lẹ́nu. Ọ̀jẹun àti ọ̀mùtípara ni.”
Şi să spună bătrânilor cetăţii sale: Acest fiu al nostru este încăpățânat şi răzvrătit, nu ascultă de vocea noastră; este un lacom şi un beţiv.
21 Nígbà náà ni gbogbo ọkùnrin ìlú rẹ̀ yóò sọ ọ́ ní òkúta pa. Ìwọ yóò sì mú ìwà ibi kúrò láàrín yín, gbogbo Israẹli yóò gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n.
Şi toţi oamenii cetăţii sale să îl ucidă cu pietre, ca să moară, astfel să îndepărtezi răul din mijlocul vostru şi tot Israelul să audă şi să se teamă.
22 Bí ọkùnrin kan tí ó jẹ̀bi ẹ̀sùn bá ní láti kú tí ó sì kú, tí a sì gbé òkú rẹ̀ kọ́ sára igi,
Şi dacă un om a făcut un păcat demn de moarte, şi este ucis, şi îl spânzuri de lemn,
23 o kò gbọdọ̀ fi òkú rẹ̀ sílẹ̀ sára igi ní gbogbo òru. Gbìyànjú láti sin ín ní ọjọ́ náà gan an, nítorí ẹni tí a bá gbé kọ́ sórí igi wà lábẹ́ ègún Ọlọ́run. Ìwọ kò gbọdọ̀ ba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún jẹ́.
Trupul lui să nu rămână toată noaptea pe lemn, ci să îl înmormântezi chiar în acea zi; (pentru că cel spânzurat este blestemat de Dumnezeu) ca să nu fie pângărită ţara ta, pe care ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău ca moştenire.

< Deuteronomy 21 >