< Deuteronomy 2 >

1 Nígbà náà ni a yípadà, tí a sì mú ọ̀nà wa pọ̀n lọ sí aginjù, a gba ọ̀nà Òkun Pupa, bí Olúwa ti darí mi. Ìgbà pípẹ́ ni a fi ń rìn kiri yíká agbègbè àwọn ìlú olókè Seiri.
Annakutána megfordulánk, és indulánk a pusztába a Veres tenger felé, a miképen szólott vala nékem az Úr, és kerülgettük a Szeir hegyét sok ideig.
2 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé,
De szóla az Úr nékem, mondván:
3 “Ẹ ti rìn yí agbègbè ilẹ̀ olókè yìí pẹ́ tó, nísinsin yìí, ẹ yípadà sí ìhà àríwá.
Elég már e hegyet kerülgetnetek, forduljatok észak felé.
4 Fún àwọn ènìyàn náà ní àwọn òfin wọ̀nyí: ‘Ẹ ti fẹ́ la ilẹ̀ àwọn arákùnrin yín kọjá, àwọn ọmọ Esau; àwọn ará Edomu tí ń gbé ní Seiri. Ẹ̀rù yín yóò bà wọ́n, ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi.
Parancsolj azért a népnek, mondván: Mikor általmentek a ti atyátokfiainak, az Ézsaú fiainak határán, a kik Szeirben lakoznak: jóllehet félnek tőletek, mindazáltal igen vigyázzatok!
5 Ẹ má ṣe wá wọn níjà torí pé èmi kò ní fún un yín ní èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn. Bí ó ti wù kí ó kéré mọ èmi kò ní fún un yín. Mo ti fi ilẹ̀ òkè Seiri fún Esau gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀.
Ne ingereljétek őket, mert nem adok az ő földjükből néktek egy talpalatnyit sem; mert Ézsaúnak adtam a Szeir hegyét örökségül.
6 Ẹ san owó oúnjẹ tí ẹ bá jẹ fún wọn àti omi tí ẹ bá mu.’”
Pénzen vásároljatok tőlük enni valót, hogy egyetek, és vizet is pénzen vegyetek tőlük, hogy igyatok,
7 Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín. Ó ti mójútó ìrìnàjò yín nínú aginjù ńlá yìí. Olúwa Ọlọ́run yín wà pẹ̀lú u yín ní ogójì ọdún wọ̀nyí, dé bi pé ẹ̀yin kò ṣaláìní ohunkóhun.
Mert az Úr, a te Istened megáldott téged a te kezednek minden munkájában; tudja, hogy e nagy pusztaságon jársz; immár negyven esztendeje veled van az Úr, a te Istened; nem szűkölködtél semmiben.
8 Bẹ́ẹ̀ ni a kọjá ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wa, àwọn ọmọ Esau tí ń gbé ní Seiri. A yà kúrò ní ọ̀nà Arabah èyí tí ó wá láti Elati àti Esioni-Geberi, a sì rìn gba ọ̀nà aginjù Moabu.
És általmenénk a mi atyánkfiai között, az Ézsaú fiai között, a kik lakoznak vala Szeirben, a síkság útján Eláthtól és Éczjon-Gebertől fogva. Azután megfordulánk és általmenénk a Moáb pusztájának útjára.
9 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ẹ má ṣe dẹ́rùba àwọn ará Moabu bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe bá wọn jagun torí pé n kò ní fi èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn fún un yín. Mo ti fi Ari fún àwọn ọmọ Lọti bí i ìní.”
És monda az Úr nékem: Ne hadakozzál Moáb ellen, és ne ingereld azt hadra, mert nem adok az ő földéből néked semmi örökséget; mert a Lót fiainak adtam Art örökségül.
10 (Àwọn Emimu ti gbé ibẹ̀ rí, àwọn ènìyàn tó síngbọnlẹ̀ tó sì pọ̀, wọ́n ga bí àwọn Anaki.
(Az Emeusok laktak abban annak előtte, nagy nép, sok és szálas, mint az Anákok.
11 Gẹ́gẹ́ bí Anaki àwọn ènìyàn náà pè wọ́n ní ará Refaimu ṣùgbọ́n àwọn ará Moabu pè wọ́n ní Emimu.
Óriásoknak állíttatnak vala azok is, mint az Anákok, és a Moábiták Emeknek hívták őket.
12 Àwọn ará Hori gbé ní Seiri, kí àwọn ọmọ Esau tó lé wọn kúrò níwájú wọn. Wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn, wọ́n tẹ̀dó sí ààyè wọn gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli tí ṣe ní ilẹ̀ tí Olúwa yóò fún wọn ní ìní wọn.)
Szeirben pedig Horeusok laktak az előtt, a kiket az Ézsaú fiai kiűztek, és kiirtottak színök elől, és azoknak helyén laktak, a miképen cselekedék Izráel is az ő örökségének földén, a melyet adott néki az Úr.)
13 Olúwa sì wí pé, “Ẹ dìde, kí ẹ sì la àfonífojì Seredi kọjá.” Bẹ́ẹ̀ ni a la àfonífojì náà kọjá.
Most keljetek fel, és menjetek át a Záred patakán; és átkelénk a Záred patakán.
14 Ó gbà wá ní ọdún méjìdínlógójì kí ó tó di wí pé a la àfonífojì Seredi kọjá láti ìgbà tí a ti kúrò ní Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà gbogbo ìran àwọn tí ó jẹ́ jagunjagun láàrín àwọn ènìyàn náà ti ṣègbé kúrò láàrín àwọn ènìyàn náà ní àsìkò yìí bí Olúwa ti búra fún wọn.
Az idő pedig, a melyet eljáránk Kádes-Barneától, míg általmenénk a Záred patakán, harmincznyolcz esztendő, a mely alatt kiveszett a hadra való férfiak egész nemzetsége a táborból, a mint megesküdt vala az Úr nékik.
15 Ọwọ́ Olúwa sì wà lòdì sí wọn nítòótọ́, láti run wọn kúrò nínú ibùdó, títí gbogbo wọn fi run tan.
E felett az Úrnak keze is vala ő rajtok, hogy elveszítse őket a táborból az ő kipusztulásukig.
16 Lẹ́yìn tí ẹni tí ó gbẹ̀yìn pátápátá nínú àwọn jagunjagun àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti kú,
És lőn, hogy a mint a hadakozó férfiak mind elpusztulának, kihalván a nép közül.
17 Olúwa sọ fún mi pé,
Így szóla az Úr nékem, mondván:
18 “Lónìí ni ẹ̀yin yóò la agbègbè Moabu kọjá ní Ari.
Ma te általmégy a Moáb határán Ar felé,
19 Bí ẹ bá dé ọ̀dọ̀ àwọn ará Ammoni, ẹ má ṣe halẹ̀ mọ́ wọn, ẹ kò sì gbọdọ̀ bá wọn jagun, torí pé èmi kì yóò fi àwọn ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ará Ammoni fún un yín ní ìní. Mo ti fi fún àwọn ọmọ Lọti ní ìní.”
És mikor közel jutsz az Ammon fiaihoz, ne háborgasd őket, ne is ingereld őket, mert nem adok néked az Ammon fiainak földjéből örökséget, mert a Lót fiainak adtam azt örökségül.
20 (A ka ilẹ̀ yìí sí ilẹ̀ àwọn Refaimu, tí wọ́n ti gbé níbẹ̀ rí, ṣùgbọ́n àwọn ará Ammoni ń pè wọ́n ní ará Samsummimu.
(Óriások földének tartották azt is; óriások laktak azon régenten, a kiket az Ammoniták Zanzummoknak hívtak.
21 Wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tó lágbára, wọ́n sì pọ̀, wọ́n sì ga gogoro bí àwọn ará Anaki. Olúwa run wọn kúrò níwájú àwọn ará Ammoni, tí wọ́n lé wọn jáde tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.
Ez a nép nagy, sok és szálas volt, valamint az Anákok, de kivesztette őket az Úr azok színe elől, hogy bírják azoknak örökségét, és lakjanak azoknak helyén;
22 Bákan náà ni Olúwa ṣe fún àwọn ọmọ Esau, tí wọ́n ń gbé ní Seiri, nígbà tí ó pa àwọn ará Hori run níwájú wọn. Wọ́n lé wọn jáde wọ́n sì ń gbé ní ilẹ̀ wọn títí di òní.
A miképen cselekedett az Ézsaú fiaival is, a kik Szeir hegyén laknak, a mikor kiveszté előlök a Horeusokat, hogy bírják azoknak örökségét, és lakjanak azoknak helyén mind e mai napig.
23 Nípa ti àwọn ará Affimu, tí wọ́n ń gbé ní àwọn ìlú kéékèèké dé Gasa, àwọn ará Kaftorimu, tí wọ́n jáde láti Krete wá ni ó pa wọ́n run, wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.)
Az Avveusokat is, a kik falvakban laknak vala Gázáig, kiirtották a Káftoreusok a kik kijöttek volt Káftorból, és lakának azoknak helyén.)
24 “Ẹ gbáradì, kí ẹ sì kọjá odò Arnoni. Kíyèsi, Mo ti fi Sihoni ará Amori, ọba Heṣboni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́. Ẹ bá ilẹ̀ náà jagun kí ẹ sì gbà á.
Keljetek fel azért, induljatok, menjetek át az Arnon patakán; lásd: kezedbe adtam Szihont, Hesbonnak királyát: az Emoreust, és annak földét; kezdj hozzá, foglald el azt, és hadakozzál ő ellene.
25 Èmi bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ìbẹ̀rù àti ìfòyà yín sára gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run láti òní lọ. Wọn yóò gbọ́ ìròyìn in yín, wọn yóò sì wárìrì, wọn yóò sì wà nínú ìdààmú ọkàn torí i tiyín.”
E napon kezdem rábocsátani a népekre, hogy féljenek és rettegjenek tőled az egész ég alatt, és a kik híredet hallják, rendüljenek meg és reszkessenek te előtted.
26 Mo rán àwọn ìránṣẹ́ láti aginjù Kedemoti lọ́ sọ́dọ̀ Sihoni ọba Heṣboni pẹ̀lú ọ̀rọ̀ àlàáfíà wí pé,
És követeket küldék a Kedemót pusztából Szihonhoz, Hesbon királyához békességes beszéddel ezt izenvén:
27 “Jẹ́ kí a la ilẹ̀ ẹ yín kọjá. Àwa yóò gba ti òpópónà nìkan. A kò ní yà sọ́tùn tàbí sósì.
Hadd menjek át a te földeden! Útról-útra megyek, nem térek le se jobbra, se balra.
28 Ẹ ta oúnjẹ tí a ó jẹ àti omi tí a ó mu fún wa ní iye owó wọn. Kìkì kí ẹ sá à jẹ́ kí a rìn kọjá:
Eleséget pénzen adj nékem, hogy egyem; vizet is pénzen adj nékem, hogy igyam; csak gyalog hadd megyek át:
29 gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Esau tí ó ń gbé ní Seiri àti àwọn ará Moabu tí ó ń gbé ní Ari, ti gbà wá láààyè títí a fi la Jordani já dé ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò fún wa.”
A miképen cselekedtek én velem az Ézsaú fiai, a kik Szeirben laknak; és a Moábiták, a kik Arban laknak; míglen átmegyek a Jordánon arra a földre, a melyet az Úr, a mi Istenünk ád nékünk!
30 Ṣùgbọ́n Sihoni ọba Heṣboni kò gbà fún wa láti kọjá. Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti mú ọkàn rẹ̀ yigbì, àyà rẹ̀ sì kún fún agídí kí ó ba à le fi lé e yín lọ́wọ́, bí ó ti ṣe báyìí.
De nem akarta Szihon, Hesbon királya, hogy átmenjünk ő rajta, mert megkeményítette volt az Úr, a te Istened az ő lelkét, és engedetlenné tette az Ő szívét, hogy a te kezedbe adja őt, a mint nyilván van e mai napon.
31 Olúwa sì bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kíyèsi i, mo ti bẹ̀rẹ̀ sí ní fi Sihoni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé e yín lọ́wọ́. Báyìí, ẹ máa ṣẹ́gun rẹ̀, kí ẹ sì gba ilẹ̀ rẹ̀.”
Monda pedig az Úr nékem: Lásd: elkezdem átadni néked Szihont és az ő földét; kezdj hozzá, foglald el azt, hogy az ő földe örököd legyen.
32 Nígbà tí Sihoni àti gbogbo àwọn jagunjagun rẹ̀ jáde wá láti bá wa jagun ní Jahasi,
És kijöve Szihon mi előnkbe minden népével, hogy megvívjon velünk Jahácznál.
33 Olúwa Ọlọ́run wa fi lé wa lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ ni a ṣẹ́gun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo ológun rẹ̀.
De az Úr, a mi Istenünk kezünkbe adá őt, és levertük őt és az ő fiait és minden ő népét.
34 Nígbà náà, gbogbo ìlú wọn ni a kó tí a sì pa wọ́n run pátápátá tọkùnrin, tobìnrin àti gbogbo ọmọ wọn. A kò sì dá ẹnikẹ́ni sí.
És elfoglaltuk minden ő városát abban az időben, és fegyverre hánytuk az egész várost: férfiakat, asszonyokat, és kisdedeket; nem hagytunk menekülni senkit.
35 Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú tí a ṣẹ́gun fún ara wa.
De a barmokat prédára vetettük közöttünk, és a városokból való ragadományokat, a melyeket elfoglaltunk volt.
36 Láti Aroeri, létí odò Arnoni àti láti àwọn ìlú tí ó wà lẹ́bàá odò náà títí ó fi dé Gileadi, kò sí ìlú tí ó lágbára jù fún wa, Olúwa Ọlọ́run wa fi gbogbo wọn fún wa.
Aróertől fogva, a mely van az Arnon patakának partján, és a völgyben lévő várostól fogva Gileádig, egy város sem volt, a melylyel ne bírtunk volna. Mind azokat az Úr, a mi Istenünk adta a mi kezünkbe.
37 Ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa Ọlọ́run wa, ẹ kò súnmọ́ ọ̀kan nínú ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò dé ilẹ̀ tí ó lọ sí Jabbok, tàbí ilẹ̀ tí ó yí àwọn ìlú òkè e nì ká.
De az Ammon fiainak földéhez nem közeledtél, sem a Jabbók patak egész oldalához, sem a hegyen lévő városokhoz, sem semmi olyanhoz, a melyektől eltiltott téged az Úr, a mi Istenünk.

< Deuteronomy 2 >