< Deuteronomy 1 >

1 Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mose sọ fún gbogbo Israẹli ní aginjù, aginjù ìlà-oòrùn Jordani, ni Arabah, ní òdìkejì Ṣufi, ní àárín Parani àti Tofeli, Labani, Haserotu àti Disahabu.
Ezek az igék, a melyeket szólott Mózes az egész Izráelnek, a Jordánon túl a pusztában, a mezőségen, a Veres tenger ellenében, Párán és Tófel, és Lábán és Haczéróth, és Dizaháb között.
2 (Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Horebu dé Kadeṣi-Barnea, bí a bá gba ọ̀nà òkè Seiri.)
Tizenegy napi járóföldön Hórebtől fogva, a Szeir hegyének menve, Kádes-Barneáig.
3 Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kọ́kànlá, Mose sọ ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ nípa àwọn ọmọ Israẹli fún wọn.
Lőn pedig a negyvenedik esztendőben, a tizenegyedik hónapban, a hónapnak első napján, szóla Mózes az Izráel fiainak mind a szerint, a mint parancsolt vala az Úr néki azok felől.
4 Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani ni ó ṣẹ́gun ní Edrei, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu.
Minekutána megverte vala Szihont az Emoreusok királyát, a ki lakik vala Hesbonban, és Ógot, Básánnak királyát Edreiben, a ki lakik vala Asthárótban:
5 Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani tí ó wà nínú ilẹ̀ Moabu ni Mose bẹ̀rẹ̀ sísọ àsọyé òfin wọ̀nyí wí pé:
A Jordánon túl, a Moáb földén, kezdé Mózes magyarázni ezt a törvényt, mondván:
6 Olúwa Ọlọ́run wa bá wa sọ̀rọ̀ ní Horebu pé, “Ẹ ti dúró ní orí òkè yìí pẹ́ tó.
Az Úr, a mi Istenünk szólott nékünk a Hóreben, ezt mondván: Elég ideig laktatok e hegy alatt;
7 Ẹ yípadà kí ẹ sì tẹ̀síwájú ní ìrìnàjò yín lọ sí ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, ẹ tọ gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń gbé Arabah lọ ní aginjù, ní àwọn orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní gúúsù àti ní etí Òkun, lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani àti lọ sí Lebanoni, títí fi dé odò ńlá Eufurate.
Forduljatok meg, és induljatok, és menjetek az Emoreusok hegyére, és annak minden szomszéd vidékére, a mezőségen, és a hegyes-völgyes földön, és dél felé, és a tengernek partján, a Kananeusok földére és a Libánusra, a nagy folyóvízig, az Eufrates folyóig.
8 Wò ó, èmi tí fi ilẹ̀ yí fún un yín, ẹ wọ inú rẹ̀ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí Olúwa ti búra wí pé òun yóò fún àwọn baba yín: fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu, àti fún àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn.”
Ímé előtökbe adtam a földet; menjetek be, és bírjátok azt a földet, a mely felől megesküdt az Úr a ti atyáitoknak, Ábrahámnak, Izsáknak és Jákóbnak, hogy nékik adja, és ő utánok az ő magvoknak.
9 Mo wí fún un yín nígbà náà pé, “Èmi nìkan kò lè dá ẹrù u yín gbé.
És szólottam vala néktek abban az időben, ezt mondván: Nem viselhetlek egymagam titeket;
10 Olúwa Ọlọ́run yín ti sọ yín di púpọ̀ lónìí, ẹ̀yin sì ti pọ̀ bí ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run.
Az Úr, a ti Istenetek megsokasított titeket elannyira, hogy oly sokan vagytok ti most, mint az égnek csillagai.
11 Kí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín sọ yín di púpọ̀ ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún sí i, kí ó sì bùkún un yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
Az Úr, a ti atyáitoknak Istene szaporítson meg titeket ezerszerte is inkább mint most vagytok, és áldjon meg titeket, a miképen igérte néktek!
12 Báwo ni èmi nìkan ṣe lè máa ru àjàgà àti ìṣòro yín àti èdè-àìyedè yín?
Miképen viselhetném én egymagam a terheiteket és a ti bajaitokat és a ti pereiteket?
13 Ẹ yan àwọn ọlọ́gbọ́n, olóye àti àwọn ẹni àpọ́nlé, láti inú ẹ̀yà yín kọ̀ọ̀kan, èmi yóò sì fi wọ́n ṣe olórí yín.”
Válaszszatok magatoknak bölcs, értelmes és a ti törzseitekben ismeretes férfiakat, és én azokat előljáróitokká teszem.
14 Ẹ̀yin sì dá mi lóhùn wí pé, “Ohun tí ìwọ ti gbèrò láti ṣe nì dára.”
És felelétek nékem, és mondátok: Jó dolog, a mit mondál, hogy míveled azt.
15 Bẹ́ẹ̀ ni mo yan olórí àwọn ẹ̀yà yín, àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin, ẹni àpọ́nlé, mo sì fi jẹ olórí yín, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà yín.
Vevém azért a ti törzseiteknek főbbjeit, a bölcs és ismeretes férfiakat, és tevém őket előljáróitokká: ezredesekké, századosokká, ötvenedesekké, tizedesekké és tiszttartókká, a ti törzseitek szerint.
16 Mo sì kìlọ̀ fún àwọn onídàájọ́ yín nígbà náà pé, ẹ gbọ́ èdè-àìyedè tí ó wà láàrín àwọn ènìyàn an yín kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ òdodo, bóyá ẹjọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ láàrín Israẹli sí Israẹli ni tàbí láàrín Israẹli kan sí àlejò.
És megparancsolám abban az időben a ti biráitoknak, mondván: Hallgassátok ki atyátokfiait, és ítéljetek igazságosan mindenkit, az ő atyjafiaival és jövevényeivel egyben.
17 Ẹ má sì ṣe ojúsàájú ní ìdájọ́. Ẹ ṣe ìdájọ́ ẹni ńlá àti kékeré bákan náà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹnikẹ́ni torí pé ti Ọlọ́run ni ìdájọ́. Ẹjọ́ tí ó bá le jù fún un yín ni kí ẹ mú wá fún mi. Èmi yóò sì gbọ́ ọ.
Ne legyetek személyválogatók az ítéletben: kicsinyt úgy, mint nagyot hallgassatok ki; ne féljetek senkitől, mert az ítélet az Istené; a mi pedig nehéznek tetszik néktek, én előmbe hozzátok, és én meghallgatom azt.
18 Nígbà náà ni èmi yóò sọ ohun tí ẹ ó ṣe fún un yín.
És megparancsoltam néktek abban az időben mindent, a mit cselekedjetek.
19 Nígbà náà ní a gbéra láti Horebu, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wá, a sì la àwọn ilẹ̀ lókè Amori kọjá lọ dé gbogbo aginjù ńlá tí ó ba ni lẹ́rù nì tí ẹ̀yin ti rí, bẹ́ẹ̀ ni a sì dé Kadeṣi-Barnea.
Azután elindulánk a Hórebtől, és bejártuk ama nagy és rettenetes pusztát, a melyet láttatok, az Emoreusok hegyének menve, a miképen parancsolta volt az Úr, a mi Istenünk nékünk; és eljutánk Kádes-Barneához.
20 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ ti dé ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, èyí tí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.
És mondám néktek: Eljutottatok az Emoreusok hegyéig, a melyet az Úr, a mi Istenünk ád nékünk.
21 Ẹ kíyèsi i, Olúwa Ọlọ́run yín ló ni ilẹ̀ náà. Ẹ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín tí sọ fún un yín. Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà.”
Ímé elődbe adta az Úr, a te Istened ezt a földet: menj fel, bírjad azt, a miképen megmondotta az Úr, a te atyáidnak Istene néked; ne félj, és meg ne rettenj!
22 Nígbà náà ni gbogbo yín tọ̀ mí wá wí pé, “Jẹ́ kí a yan àwọn ayọ́lẹ̀wò láti yọ́ ilẹ̀ náà wò fún wa, kí wọn sì fún wa ní ìròyìn àwọn ọ̀nà tí a ó gbà àti àwọn ìlú tí a ó bá pàdé.”
Ti pedig mindnyájan hozzám járulátok és mondátok: Küldjünk embereket előre, hogy kémleljék meg nékünk azt a földet, és hozzanak nékünk hírt az út felől, a melyen felmenjünk, és a városok felől, a melyekbe bevonuljunk.
23 Èrò náà sì dára lójú mi, torí èyí ni mo ṣe yan àwọn ènìyàn méjìlá nínú yín, ẹnìkan láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
És tetszék nékem ez a beszéd, és vevék közületek tizenkét férfiút, minden törzsből egyet-egyet.
24 Wọ́n sì gòkè lọ sí ilẹ̀ òkè náà, wọ́n sì wá sí àfonífojì Eṣkolu, wọ́n sì yẹ̀ ẹ́ wò.
És fordulának és felmenének a hegyre, és eljutának az Eskól völgyéig, és kikémlelék azt.
25 Wọ́n sì mú lára èso ilẹ̀ náà wá fún wa pé, “Ilẹ̀ tí ó dára ni Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
És vőnek kezeikbe annak a földnek gyümölcséből, és alá hozák hozzánk, és hírt hozának nékünk és mondának: Jó az a föld, a melyet az Úr, a mi Istenünk ád nékünk.
26 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́ gòkè lọ; ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín.
De ti nem akartatok felmenni; hanem pártot ütétek az Úrnak, a ti Isteneteknek parancsa ellen.
27 Ẹ kùn nínú àgọ́ ọ yín, ẹ sì wí pé, “Olúwa kórìíra wa, torí èyí ló fi mú wa jáde láti Ejibiti láti fi wá lé àwọn ará Amori lọ́wọ́ láti pa wá run.
És zúgolódátok a ti sátoraitokban, és mondátok: mivelhogy gyűlöl minket az Úr, azért hozott ki minket Égyiptom földéből, hogy adjon minket az Emoreus kezébe, és elpusztítson minket.
28 Níbo la ó lọ? Àwọn arákùnrin wa ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa nípa sísọ pé, ‘Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga jù wá lọ; àwọn ìlú náà tóbi jọjọ bẹ́ẹ̀ ni odi wọn ga kan ọ̀run. A tilẹ̀ rí àwọn òmíràn (ìran Anaki) níbẹ̀.’”
Hová mennénk fel mi? A mi atyánkfiai megrettenték a mi szíveinket, mondván: Az a nép nagyobb és szálasabb nálunknál; a városok nagyok és megerősíttettek az égig; még Anák fiakat is láttunk ott!
29 Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ má ṣojo, ẹ kò sì gbọdọ̀ bẹ̀rù wọn.
Akkor mondám néktek: Ne rettegjetek és ne féljetek azoktól;
30 Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń ṣáájú yín yóò jà fún un yín; bí ó ti ṣe fún un yín ní Ejibiti lójú ẹ̀yin tìkára yín
Az Úr, a ti Istenetek, a ki előttetek megy, ő hadakozik ti érettetek mind a szerint, a mint cselekedett vala veletek Égyiptomban a ti szemeitek előtt;
31 àti ní aginjù. Níbẹ̀ ni ẹ ti rí i bí Olúwa Ọlọ́run yín ti gbé yín, bí baba ti í gbé ọmọ rẹ̀, ní gbogbo ọ̀nà tí ẹ lọ títí ẹ fi padà dé ibí yìí.”
És a pusztában, a hol láttad, hogy úgy hordozott téged az Úr, a te Istened, a miképen hordozza az ember az ő fiát, mind az egész úton, a melyen jártatok, míg jutátok e helyre.
32 Pẹ̀lú gbogbo èyí tí mo wí, ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín,
Mindazáltal nem hivétek az Úrnak, a ti Isteneteknek.
33 tí ń ṣáájú u yín lọ ní gbogbo ọ̀nà yín, nípa fífi iná ṣe amọ̀nà yín ní òru àti ìkùùkuu ní ọ̀sán, láti fi àwọn ibi tí ẹ lè tẹ̀dó sí hàn yín àti àwọn ọ̀nà tí ẹ ó rìn.
A ki előttetek jár vala az úton, hogy helyet szemeljen ki néktek, a hol táborozzatok, éjjel tűzben, hogy megmutassa néktek az útat, a melyen járjatok, és felhőben nappal.
34 Nígbà tí Olúwa gbọ́ ohun tí ẹ sọ, inú bí i, ó sì búra wí pé,
Meghallá pedig az Úr beszédetek szavát, és megharaguvék, és megesküvék, mondván:
35 “Kò sí ọ̀kan nínú ìran búburú yìí tí yóò dé ilẹ̀ rere tí mo ti búra láti fún àwọn baba ńlá a yín.
E gonosz nemzetségből való emberek közül egy sem látja meg azt a jó földet, a mely felől megesküdtem, hogy a ti atyáitoknak adom;
36 Bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne. Òun ni yóò wọ̀ ọ́. Èmi yóò sì fún òun àti àwọn ìran rẹ̀ ní ilẹ̀ náà tí ó ti fi ẹsẹ̀ rẹ̀ tẹ̀; torí pé ó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ tẹ̀lé Olúwa.”
Kivéve Kálebet, a Jefunné fiát; ő meglátja azt, és ő néki adom azt a földet, a melyet tapodott, és az ő fiainak, mert tökéletességgel követte az Urat.
37 Torí i tiyín ni Olúwa fi bínú sí mi wí pé, “Ìwọ náà kì yóò wọ ibẹ̀ bákan náà,
Még én reám is megharaguvék az Úr miattatok, mondván: Te sem mégy oda be!
38 ṣùgbọ́n Joṣua ọmọ Nuni tí ń ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ ni yóò wọ ibẹ̀. Mú un, ní ọkàn le torí pé, òun yóò ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli láti gba ilẹ̀ náà.
Józsué, a Nún fia, a ki áll te előtted, ő megy be oda; azért biztassad őt, mert ő osztja el az örökséget Izráelnek.
39 Àwọn èwe yín tí ẹ sọ pé wọn yóò kó lẹ́rú. Àwọn ọmọ yín tí ko tí ì mọ rere yàtọ̀ sí búburú ni yóò wọ ilẹ̀ náà.
És a ti kicsinyeitek, a kikről szólátok hogy prédául lesznek, és a ti fiaitok, a kik nem tudnak most sem jót, sem gonoszt, azok mennek be oda, mert nékik adom azt, és ők bírják azt.
40 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, ẹ yí padà sí aginjù tí ó wà ní ọ̀nà tí ó lọ sí Òkun Pupa.”
Ti pedig forduljatok vissza, és induljatok a pusztába, a Veres tenger felé.
41 Nígbà náà ni ẹ fèsì wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa. A ó sì gòkè lọ láti jà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wa.” Torí náà gbogbo yín ẹ mú ohun ìjà a yín, ẹ rò pé ó rọrùn láti gòkè lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè náà.
És azt felelétek, és azt mondátok nékem: Vétkeztünk az Úr ellen, mi felmegyünk és hadakozunk mind a szerint, a mint parancsolta nékünk az Úr, a mi Istenünk! És felövezétek magatokat, kiki az ő harczi eszközeivel, és készek valátok felmenni a hegyre.
42 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ fún wọn, ‘Ẹ má ṣe gòkè lọ láti jà torí pé èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín. Àwọn ọ̀tá a yín yóò sì ṣẹ́gun yín.’”
Monda pedig az Úr nékem: Mondd meg nékik: Ne menjetek fel, és ne harczoljatok, mert nem vagyok közöttetek: hogy meg ne verettessetek a ti ellenségeitektől.
43 Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbọ́, ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa, pẹ̀lú ìgbéraga yín, ẹ gòkè lọ sí ìlú olókè náà.
És megmondám néktek, de nem hallgattatok rám, hanem pártot ütöttetek az Úr parancsolata ellen, és vakmerősködétek, és felmenétek a hegyre.
44 Àwọn ará Amori tí ń gbé ní àwọn òkè náà, dojúkọ yín bí àgbájọpọ̀ oyin. Wọ́n sì lù yín bolẹ̀ láti Seiri títí dé Horma.
De kijöve az Emoreus, a ki lakik vala azon a hegyen, ti ellenetek, és megkergetének titeket, mint a méhek szokták cselekedni, és vagdaltak vala titeket Szeirtől Hormáig.
45 Ẹ padà, ẹ sì sọkún níwájú Olúwa, òun kò sì fetí sí igbe ẹkún yín, Ó sì kọ etí dídi sí i yín.
És visszatérétek onnét, és sírátok az Úr előtt, de nem hallgatá meg az Úr a ti szavatokat, és nem figyele rátok.
46 Báyìí ni ẹ sì dúró ní Kadeṣi fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ṣe.
És sok időn át lakozátok Kádesben, a meddig ott lakozátok.

< Deuteronomy 1 >