< Deuteronomy 17 >

1 Ẹ má ṣe fi màlúù tàbí àgùntàn tí ó ní àbùkù, tàbí àbàwọ́n rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí ìríra ni èyí yóò jẹ́ fún un.
Să nu sacrifici DOMNULUI Dumnezeul tău vreun taur sau vreo oaie, în care să fie vreun cusur, sau vreun lucru rău, pentru că este o urâciune înaintea DOMNULUI Dumnezeul tău.
2 Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan tó ń gbé láàrín yín ní èyíkéyìí ìlú wọ̀n-ọn-nì, tí Olúwa fún un yín bá ń ṣe ibi ní ojú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ríré májẹ̀mú rẹ̀ kọjá,
Dacă se găseşte printre voi, în vreuna din porţile tale, pe care DOMNUL Dumnezeul tău ţi le dă, un bărbat sau o femeie care a lucrat stricăciuni înaintea ochilor DOMNULUI Dumnezeul tău, încălcând legământul lui,
3 èyí tí ó lòdì sí òfin mi, ó ń sin ọlọ́run mìíràn, ó ń foríbalẹ̀ fún wọn: àní sí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run,
Şi care a mers şi a servit altor dumnezei şi li s-a închinat, fie soarelui sau lunii sau vreunuia din oştirea cerului, ceea ce nu am poruncit;
4 tí èyí sì dé etí ìgbọ́ ọ yín, kí ẹ wádìí ọ̀rọ̀ náà dájúdájú. Bí ó bá jẹ́ òtítọ́ tí ó sì hàn gbangba pé ó ti ṣe ohun ìríra yìí, ní Israẹli.
Şi ţi se va spune şi vei fi auzit, să cercetezi cu atenţie; şi, iată, dacă este adevărat şi dacă lucrul este sigur, că s-a făcut această urâciune în Israel,
5 Ẹ mú ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ti ṣe ibi yìí wá sí ẹnu-ọ̀nà ibodè ìlú u yín, kí ẹ sọ ọ́ ní òkúta pa.
Atunci să scoţi afară la porţile tale pe acel bărbat sau pe acea femeie care a făcut acest lucru stricat, adică pe acel bărbat sau pe acea femeie, şi să îi ucizi cu pietre până când mor.
6 Lénu ẹlẹ́rìí méjì tàbí mẹ́ta ni a ó pa ọkùnrin náà tí ó yẹ láti kú, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe pànìyàn nípasẹ̀ ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo.
Din gura a doi martori, sau a trei martori, să fie ucis cel care va fi demn de moarte, dar să nu fie ucis din gura unui singur martor.
7 Àwọn ẹlẹ́rìí ni kí ó kọ́kọ́ gbọ́wọ́ lé e láti pa á. Lẹ́yìn èyí ni kí gbogbo ènìyàn dáwọ́jọ láti pa á. Nípa báyìí, ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní àárín yín.
Mâinile martorilor să fie primele asupra lui ca să îl ucidă şi după aceea mâinile întregului popor. Astfel să îndepărtezi răul din mijlocul vostru.
8 Bí ẹjọ́ bá wá sí ilé ẹjọ́ èyí tí ó nira jù láti dá, yálà ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni, ọ̀ràn dídá tàbí ìkanni-lábùkù, ẹ mú wọn lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn.
Şi dacă se va ridica un lucru prea greu de judecat pentru tine, între sânge şi sânge, între ceartă şi ceartă şi între lovitură şi lovitură, fiind cazuri de neînţelegere înăuntrul porţilor tale, atunci să te ridici şi să te urci la locul pe care îl va alege DOMNUL Dumnezeul tău.
9 Ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn àlùfáà tí í ṣe Lefi, àní sí ọ̀dọ̀ adájọ́ tí ó wà fún ìgbẹ́jọ́ ní ìgbà náà. Ẹ béèrè lọ́wọ́ wọn, wọn yóò sì ṣe ìdájọ́.
Şi să vii la preoţi, la leviţi şi la judecătorul care va fi în acele zile şi să întrebi; şi ei îţi vor arăta hotărârea de judecată,
10 Kí ìwọ kí ó sì ṣe bí ọ̀rọ̀ ìdájọ́, ti àwọn ará ibi tí Olúwa yóò yàn náà yóò fihàn ọ, kí ìwọ kí ó sì máa kíyèsí àti máa ṣe gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí wọn kọ́ ọ.
Şi să faci conform hotărârii, pe care ţi-o vor arăta cei din locul pe care îl va alege DOMNUL; şi să iei seama să faci toate cele ce te vor instrui ei,
11 Ẹ ṣe bí òfin tí wọ́n kọ́ ọ yín, àti ìpinnu tí wọ́n fún un yín. Ẹ má ṣe yípadà sọ́tùn tàbí sósì, kúrò nínú ohun tí wọ́n sọ fún un yín.
Să faci conform hotărârii legii care te vor învăţa ei şi conform judecăţii pe care ţi-o vor spune ei; să nu te abaţi nici la dreapta, nici la stânga de la hotărârea pe care ţi-o vor spune ei.
12 Ọkùnrin náà tí ó bá ṣe àìbọ̀wọ̀ fún adájọ́ tàbí àlùfáà tí ó ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, níbẹ̀ ni kí ẹ pa á. Nípa báyìí ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní Israẹli.
Şi bărbatul care se va purta cu îngâmfare şi nu va da ascultare preotului care stă să servească acolo înaintea DOMNULUI Dumnezeul tău, sau judecătorului, chiar bărbatul acela să moară; şi să îndepărtezi răul din Israel.
13 Gbogbo ènìyàn ni yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, wọn kò sì ní ṣe àìgbọ́ràn mọ́.
Şi tot poporul să audă şi să se teamă şi să nu se mai poarte cu mândrie.
14 Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín, tí ẹ sì ti gba ilẹ̀ náà, tí ẹ sì ń gbé inú rẹ̀, tí ẹ sì wá sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a yan ọba tí yóò jẹ lé wa lórí bí i ti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká.”
După ce vei fi intrat în ţara pe care ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău şi o vei stăpâni şi vei locui în ea şi vei spune: Voi pune un împărat peste mine, asemenea tuturor naţiunilor care sunt împrejurul meu;
15 Ẹ rí i dájú pé ọba tí Olúwa Ọlọ́run yín yàn fún un yín ní ẹ yàn. Ó gbọdọ̀ jẹ́ láàrín àwọn arákùnrin yín. Ẹ má ṣe fi àjèjì jẹ ọba lórí i yín: àní ẹni tí kì í ṣe arákùnrin ní Israẹli.
Să pui împărat peste tine pe acela pe care îl va alege DOMNUL Dumnezeul tău, să pui împărat peste tine pe unul dintre fraţii tăi; nu poţi să pui peste tine pe un străin, care nu este fratele tău.
16 Síwájú sí i, ọba náà kò gbọdọ̀ kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹṣin jọ fún ara rẹ̀, tàbí kí ó rán àwọn ènìyàn náà padà sí Ejibiti láti wá àwọn ẹṣin sí i, nítorí pé Olúwa ti sọ fún un yín pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ tún padà lọ ní ọ̀nà náà mọ́.”
Numai să nu aibă mulţi cai şi să nu facă pe popor să se întoarcă în Egipt, pentru a-şi înmulţi caii, văzând că DOMNUL v-a spus: Să nu vă mai întoarceţi pe acea cale.
17 Kò gbọdọ̀ kó aya jọ, kí ọkàn rẹ̀ má bá a yapa kúrò. Kò gbọdọ̀ kó fàdákà àti wúrà jọ fún ara rẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Nici să nu aibă multe soţii, ca să nu i se abată inima; nici să nu îşi înmulţească mult argint şi aur.
18 Nígbà tí ó bá jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀, kí ó ṣe àdàkọ àwọn òfin wọ̀nyí sí inú ìwé fún ara rẹ̀, láti inú ti àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi.
Şi va fi astfel: când şade pe tronul împărăţiei sale, să îşi scrie o copie a acestei legi într-o carte, după cea care este înaintea preoţilor, a leviţilor.
19 Èyí yóò sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun ó sì máa kà nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀, kí ó lè máa kọ́ àti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, láti máa tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí àti àwọn ìlànà rẹ̀ tọkàntọkàn.
Şi ea să fie cu el şi să citească din ea în toate zilele vieţii sale, ca să înveţe să se teamă de DOMNUL Dumnezeul său, ca să păzească toate cuvintele legii acesteia şi statutele acestea, ca să le facă,
20 Kí ó má ba à lérò pé òun sàn ju àwọn arákùnrin rẹ̀ yòókù lọ, kí ó sì ti ipa bẹ́ẹ̀ yípadà kúrò nínú òfin wọ̀nyí sí ọ̀tún tàbí sí òsì. Bẹ́ẹ̀ ni òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò jẹ ọba pẹ́ títí ní Israẹli.
Ca să nu i se înalţe inima deasupra fraţilor săi şi să nu se abată de la poruncă nici la dreapta, nici la stânga, pentru ca să îşi prelungească zilele în împărăţia sa, el şi copiii lui, în mijlocul lui Israel.

< Deuteronomy 17 >