< Daniel 8 >

1 Nígbà tí ó di ọdún kẹta ìjọba Belṣassari ọba, èmi Daniẹli rí ìran kan èyí tí mo ti rí tẹ́lẹ̀.
La troisième année du règne du roi Belschatsar, une vision m'apparut, à moi, Daniel, après celle qui m'était apparue la première fois.
2 Nínú ìran náà, mo rí ara mi nínú ilé ìṣọ́ ní Susa ní agbègbè ìjọba Elamu: nínú ìran náà mo wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ odò Ulai.
Je vis la vision. Or, lorsque j'ai eu la vision, j'étais dans la citadelle de Suse, qui est dans la province d'Élam. Je vis dans la vision, et je me trouvais près du fleuve d'Ulai.
3 Mo wo òkè mo sì rí àgbò kan tí ó ní ìwo méjì níwájú mi, ó dúró sí ẹ̀gbẹ́ odò Ulai, àwọn ìwo náà sì gùn. Ṣùgbọ́n ọ̀kan gùn ju èkejì lọ, èyí tí ó gùn jù ni ó yọ jáde kẹ́yìn.
Alors je levai les yeux et je regardai, et voici, un bélier qui avait deux cornes se tenait devant le fleuve. Les deux cornes étaient hautes, mais l'une était plus haute que l'autre, et la plus haute montait la dernière.
4 Mo rí àgbò náà ó ń kàn sí ìhà ìwọ̀-oòrùn, sí àríwá, àti sí gúúsù, kò sí ẹranko kankan tí ó le è dojúkọ ọ́, kò sí ẹnìkan tí ó le è yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ agbára rẹ̀, ó ń ṣe bí ó ti wù ú, ó sì di alágbára.
Je vis le bélier qui poussait vers l'ouest, vers le nord et vers le sud. Aucun animal ne pouvait se dresser devant lui. Il n'y avait personne qui pût délivrer de sa main, mais il faisait ce qu'il voulait, et il se glorifiait.
5 Bí mo ṣe ń ronú nípa èyí, lójijì ni òbúkọ kan tí ó ní ìwo láàrín ojú u rẹ̀ méjèèjì jáde láti ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó la gbogbo ayé kọjá láìfi ara kan ilẹ̀.
Comme je considérais, voici qu'un bouc vint de l'ouest sur la surface de toute la terre, et ne toucha pas le sol. Le bouc avait une corne remarquable entre les yeux.
6 Ó tọ àgbò tí ó ni ìwo méjì náà wá, èyí tí mo rí tó dúró sí ẹ̀gbẹ́ odò Ulai, ó sì dojúkọ ọ́ pẹ̀lú ìrunú tí ó lágbára.
Il s'approcha du bélier aux deux cornes, que je voyais debout devant le fleuve, et se précipita sur lui dans la fureur de sa puissance.
7 Mo rí i tí ó fi ìtara kọlu àgbò náà, ó lu àgbò náà bolẹ̀, ó sì ṣẹ́ ìwo rẹ̀ méjèèjì. Àgbò náà kò sì ní agbára láti dojúkọ ọ́, Òbúkọ náà kàn án mọ́lẹ̀, ó sì fi ẹsẹ̀ tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀, kò sì ṣí ẹni tí ó lè gba àgbò náà là kúrò lọ́wọ́ agbára rẹ̀.
Je l'ai vu s'approcher du bélier, et il s'est mis en colère contre lui; il a frappé le bélier et lui a brisé les deux cornes. Le bélier n'avait pas la force de se tenir devant lui, mais il le jeta à terre et le piétina. Il n'y avait personne qui pût délivrer le bélier de sa main.
8 Òbúkọ náà sì di alágbára púpọ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí ó dé góńgó, agbára rẹ̀ ru sókè, ìwo ńlá a rẹ̀ sì ṣẹ́ dànù, ní ipò o rẹ̀, ìwo mẹ́rin mìíràn hù, ó sì yọrí sí ìhà igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ọ̀run.
Le bouc s'éleva à un haut degré d'orgueil. Quand il fut fort, la grande corne se brisa, et à sa place s'élevèrent quatre grandes cornes vers les quatre vents du ciel.
9 Lára ọ̀kan nínú wọn, ìwo mìíràn yọ jáde, ó kékeré, ṣùgbọ́n ó dàgbà nínú agbára sí ìhà gúúsù, àti sí ìhà ìlà-oòrùn àti sí ilẹ̀ dídára.
De l'une d'elles sortit une petite corne, qui devint extrêmement grande, vers le midi, vers l'orient, et vers le pays glorieux.
10 Ó sì dàgbà títí ó fi kan ẹgbẹ́ ogun ọ̀run, ó sì jù lára àwọn ẹgbẹ́ ogun ọ̀run sí ayé ó sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀,
Elle s'éleva jusqu'à l'armée du ciel; elle jeta à terre une partie de l'armée et des étoiles, et les foula aux pieds.
11 ó sì gbé ara rẹ̀ ga gẹ́gẹ́ bí ọmọ-aládé ẹgbẹ́ ogun ọ̀run; ó sì mú ẹbọ ojoojúmọ́ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì gba ààyè ibi mímọ́ rẹ̀.
Elle s'éleva jusqu'au chef de l'armée; elle lui enleva l'holocauste perpétuel, et le lieu de son sanctuaire fut renversé.
12 A fún un ní ẹgbẹ́ ogun ọ̀run àti ẹbọ ojoojúmọ́ nítorí ìwà ọlọ̀tẹ̀ ẹ rẹ̀, ó sọ òtítọ́ nù nínú gbogbo ohun tó ṣe.
L'armée lui fut livrée, ainsi que l'holocauste perpétuel, par la désobéissance. Il a jeté la vérité par terre, et il a fait sa volonté et a prospéré.
13 Nígbà náà, ni mo gbọ́ tí ẹni mímọ́ ń sọ̀rọ̀, àti ẹni mímọ́ mìíràn sọ̀rọ̀ fún un pé, “Yóò ti pẹ́ tó tí ìran yìí yóò fi wá sí ìmúṣẹ—ìran nípa ẹbọ ojoojúmọ́, ìṣọ̀tẹ̀ tí ó mú ìsọdahoro wa, àní láti fi ibi mímọ́ àti ogun ọ̀run fún ni ní ìtẹ̀mọ́lẹ̀?”
Alors j'entendis un saint qui parlait; et un autre saint dit à celui qui parlait: « Jusqu'à quand durera la vision concernant l'holocauste perpétuel, et la désobéissance qui désole, pour que le sanctuaire et l'armée soient foulés aux pieds? »
14 Ó sọ fún mi pé, “Yóò gbà tó ẹgbọ̀kànlá lé lọ́gọ́rùn-ún alẹ́ àti òwúrọ̀; lẹ́yìn náà ni a ó tún ibi mímọ́ yà sí mímọ́.”
Il me dit: « Jusqu'à deux mille trois cents soirs et matins. Alors le sanctuaire sera purifié. »
15 Nígbà tí èmi Daniẹli, ń wo ìran náà, mo sì ń fẹ́ kí ó yé mi, ẹnìkan tí ó sì dúró níwájú mi.
Lorsque moi, Daniel, j'eus vu la vision, je cherchai à la comprendre. Et voici que se tenait devant moi quelqu'un qui avait l'apparence d'un homme.
16 Mo gbọ́ ohùn ènìyàn ní ẹ̀gbẹ́ Ulai, tí ó ń ké pé “Gabrieli, sọ ìtumọ̀ ìran náà fún ọkùnrin yìí.”
Entre les rives de l'Oulaï, j'entendis la voix d'un homme qui appelait et disait: « Gabriel, fais comprendre la vision à cet homme. »
17 Bí ó ṣe súnmọ́ ibi tí mo dúró sí, ẹ̀rù bà mí, mo sì dọ̀bálẹ̀. Ó ń sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ́ kí ó yé ọ pé ìran náà ń sọ nípa ìgbà ìkẹyìn ni.”
Il s'approcha donc de l'endroit où je me tenais; quand il arriva, j'eus peur et je tombai sur ma face; mais il me dit: « Comprends, fils d'homme, car la vision appartient au temps de la fin. »
18 Bí ó ṣe ń bá mi sọ̀rọ̀, mo ti sùn lọ fọnfọn, bí mo ṣe da ojú bolẹ̀. Nígbà náà ni ó fi ọwọ́ kàn mí, ó sì gbé mi dúró lórí ẹsẹ̀ mi.
Comme il me parlait, je tombai dans un profond sommeil, le visage contre terre, mais il me toucha et me redressa.
19 Ó sọ wí pé, “Èmi yóò sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ìkẹyìn ní ìgbà ìbínú, nítorí ìran náà jẹ mọ́ àkókò ohun tí a yàn nígbà ìkẹyìn.
Il dit: « Voici, je vais te faire connaître ce qui arrivera au dernier moment de la colère, car cela appartient au temps fixé de la fin.
20 Àgbò oníwo méjì tí o rí, òun ni ó dúró gẹ́gẹ́ bí àwọn ọba Media àti Persia.
Le bélier que tu as vu, qui avait deux cornes, ce sont les rois de Médie et de Perse.
21 Òbúkọ onírun náà ni ọba Giriki, ìwo ńlá ti ó wà láàrín ojú u rẹ̀ ni ọba àkọ́kọ́.
Le bouc rude, c'est le roi de Grèce. La grande corne qui est entre ses yeux, c'est le premier roi.
22 Ìwo mẹ́rin mìíràn sì dìde dúró dípò ọ̀kan tí ó ṣẹ́, èyí dúró gẹ́gẹ́ bí ìjọba mẹ́rin tí yóò dìde nínú orílẹ̀-èdè náà, ṣùgbọ́n wọn kì yóò ní ní irú agbára kan náà.
Quant à ce qui a été brisé, à la place où quatre se sont levés, quatre royaumes se lèveront de la nation, mais non avec sa puissance.
23 “Ní ìgbà ìkẹyìn ìjọba wọn, nígbà tí àwọn oníwà búburú bá dé ní kíkún, ni ọba kan yóò dìde, tí ojú rẹ̀ le koko, tí ó sì mòye ọ̀rọ̀ àrékérekè.
« Au dernier temps de leur règne, quand les transgresseurs seront au comble, se lèvera un roi à la face farouche, et qui comprendra des énigmes.
24 Yóò di alágbára, ṣùgbọ́n tí kì í ṣe nípa agbára rẹ̀. Yóò sì máa ṣe ìparun tí yóò ya ni lẹ́nu, yóò sì máa ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tó ń ṣe. Yóò sì run àwọn alágbára àti àwọn ènìyàn mímọ́.
Sa puissance sera grande, mais non par sa propre force. Il fera des ravages et prospérera dans ce qu'il fera. Il détruira les puissants et le peuple saint.
25 Nípa àrékérekè rẹ̀, yóò mú kí ẹ̀tàn gbèrú, yóò gbé ara rẹ̀ ga nínú ọkàn rẹ̀, nígbà tí wọ́n rò wí pé àlàáfíà dé, yóò sì pa àwọn ènìyàn run, nígbà tí wọn kò rò tẹ́lẹ̀, yóò sì lòdì sí olórí àwọn ọmọ-aládé, síbẹ̀, a ó pa á run ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa agbára ènìyàn.
Par sa politique, il fera prospérer la tromperie dans sa main. Il se glorifiera dans son cœur, et il détruira beaucoup de gens dans leur sécurité. Il se dressera aussi contre le prince des princes, mais il sera brisé sans mains humaines.
26 “Ìran alẹ́ àti ti òwúrọ̀, tí a fihàn ọ́ jẹ́ òtítọ́, ṣùgbọ́n pa ìran náà mọ́, nítorí pé, ó jẹ mọ́ ti ọjọ́ iwájú.”
« La vision des soirs et des matins qui a été racontée est vraie; mais scellez la vision, car elle concerne de nombreux jours à venir. »
27 Èmi Daniẹli sì ṣe àárẹ̀ fún ọjọ́ mélòó kan. Nígbà náà, mo dìde, mo sì ń bá iṣẹ́ ọba lọ. Ìran náà sì bà mí lẹ́rù, kò sì yé mi.
Moi, Daniel, je me suis évanoui et j'ai été malade pendant quelques jours. Puis je me suis levé et j'ai fait les affaires du roi. Je m'interrogeais sur la vision, mais personne ne la comprenait.

< Daniel 8 >