< Daniel 7 >

1 Ní ọdún àkọ́kọ́ Belṣassari ọba Babeli, Daniẹli lá àlá kan, ìran náà sì wá sí ọkàn an rẹ̀ bí ó ṣe sùn sórí ibùsùn un rẹ̀, ó sì kọ àlá náà sílẹ̀.
La première année de Belschatsar, roi de Babylone, Daniel eut, sur son lit, un rêve et des visions de sa tête. Puis il écrivit le rêve et raconta la somme des faits.
2 Daniẹli sọ pé, “Nínú ìran mi lóru mo wò ó, mo sì rí afẹ́fẹ́ ọ̀run mẹ́rin tí ó ń ru omi Òkun ńlá sókè.
Daniel prit la parole et dit: J'ai eu une vision pendant la nuit. Et voici, les quatre vents du ciel se déchaînèrent sur la grande mer.
3 Ẹranko ńlá mẹ́rin tí ó yàtọ̀ sí ara wọn, jáde láti inú Òkun náà.
Quatre grands animaux, différents les uns des autres, sortirent de la mer.
4 “Ẹranko kìn-ín-ní dàbí i kìnnìún, ó sì ní ìyẹ́ apá a idì, mo sì wò títí a fi fa ìyẹ́ apá rẹ̀ náà tu, a sì gbé e sókè kúrò ní ilẹ̀, a mú kí ó fi ẹsẹ̀ dúró bí ènìyàn, a sì fi àyà ènìyàn fún un.
« Le premier était semblable à un lion, et avait des ailes d'aigle. J'ai veillé jusqu'à ce qu'on lui arrache les ailes, qu'on le soulève de terre et qu'on le fasse tenir sur ses deux pieds comme un homme. On lui donna un cœur d'homme.
5 “Mo sì tún rí ẹranko kejì, ó rí bí irú ẹranko ńlá beari kan tí ó ń gbé ilẹ̀ òtútù; o gbé ara sókè ní apá kan, ó sì ní egungun ìhà mẹ́ta láàrín ẹ̀yìn in rẹ̀, wọ́n sì sọ fún un pé, ‘Dìde kí o sì jẹ ẹran tó pọ̀!’
« Voici, il y avait un autre animal, un second, semblable à un ours. Il était dressé d'un côté, et trois côtes étaient dans sa gueule entre ses dents. Ils lui dirent ceci: « Lève-toi! Dévore beaucoup de chair.
6 “Lẹ́yìn ìgbà náà, mo tún rí ẹranko kẹta ó rí bí àmọ̀tẹ́kùn. Ẹranko náà ní ìyẹ́ bí i ti ẹyẹ ní ẹ̀yìn, ó sì ní orí mẹ́rin, a sì fún un ní agbára láti ṣe ìjọba.
« Après cela, je regardai, et voici, il y en avait un autre, semblable à un léopard, qui avait sur son dos quatre ailes d'oiseau. Cet animal avait aussi quatre têtes, et la domination lui fut donnée.
7 “Lẹ́yìn èyí, nínú ìran mi ní òru mo tún rí ẹranko kẹrin, ó dẹ́rùbà ni, ó dáyà fo ni, ó sì lágbára gidigidi. Ó ní eyín irin ńlá; ó ń jẹ, ó sì ń fọ́ túútúú, ó sì fi ẹsẹ̀ tẹ èyí tókù mọ́lẹ̀. Ó yàtọ̀ sí gbogbo àwọn ẹranko ti ìṣáájú, ó sì ní ìwo mẹ́wàá.
« Après cela, j'eus des visions nocturnes. Et voici, il y avait un quatrième animal, impressionnant, puissant et extrêmement fort. Il avait de grandes dents de fer. Il dévorait et mettait en pièces, et il foulait le reste avec ses pieds. Il était différent de tous les animaux qui l'avaient précédé. Il avait dix cornes.
8 “Bí mo ṣe ń ronú nípa ìwo náà, nígbà náà ni mo rí ìwo mìíràn, tí ó kéré tí ó jáde wá ní àárín wọn; mẹ́ta lára àwọn ìwo ti àkọ́kọ́ sì fàtu níwájú u rẹ̀. Ìwo yìí ní ojú bí i ojú ènìyàn àti ẹnu tí ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga.
« Je considérais les cornes, et voici qu'au milieu d'elles montait une autre corne, une petite corne, devant laquelle trois des premières cornes avaient été arrachées par les racines; et voici qu'il y avait dans cette corne des yeux comme les yeux d'un homme, et une bouche qui parlait avec arrogance.
9 “Bí mo ṣe ń wò, “a gbé ìtẹ́ ọba kan kalẹ̀, ẹni ìgbàanì jókòó sórí ìtẹ́ rẹ̀. Aṣọ rẹ̀ funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú; irun orí rẹ̀ funfun bí òwú, ìtẹ́ ọba rẹ̀ rí bí ọwọ́ iná. Àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ ń jó bí i iná.
« J'ai veillé jusqu'à ce que les trônes soient placés, et celui qui est vieux de plusieurs jours s'est assis. Ses vêtements étaient blancs comme la neige, et les cheveux de sa tête comme de la laine pure. Son trône était fait de flammes ardentes, et ses roues brûlent le feu.
10 Odò iná ń sàn, ó ń jáde ní iwájú rẹ̀ wá. Àwọn ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún ń ṣe ìránṣẹ́ fún un; ọ̀nà ẹgbẹẹgbàárùn-ún nígbà ẹgbàárùn-ún dúró níwájú rẹ̀. Àwọn onídàájọ́ jókòó, a sì ṣí ìwé wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀.
Un torrent de feu sortit et s'échappa de devant lui. Des milliers de milliers de personnes l'ont servi. Dix mille fois dix mille se tenaient devant lui. Le jugement a été fixé. Les livres ont été ouverts.
11 “Nígbà náà ni mo bẹ̀rẹ̀ sí ní wò, nítorí àwọn ọ̀rọ̀ ìgbéraga tí ìwo náà ń sọ, mo wò títí a fi pa ẹranko náà, a sì pa á run, a sì jù ú sínú iná tí ń jó.
« Je veillais en ce temps-là, à cause de la voix des paroles arrogantes que prononçait la corne. J'ai veillé jusqu'à ce que l'animal soit tué, que son corps soit détruit et qu'il soit livré au feu.
12 A sì gba ìjọba lọ́wọ́ àwọn ẹranko yòókù, ṣùgbọ́n a fún wọn láààyè láti wà fún ìgbà díẹ̀.
Quant au reste des animaux, leur domination a été supprimée, mais leur vie s'est prolongée pendant une saison et un temps.
13 “Nínú ìran mi ní òru mo wò, mo rí ẹnìkan tí ó dúró sí iwájú u mi, ó rí bí ọmọ ènìyàn, ó ń bọ̀ wá nínú àwọsánmọ̀ ọ̀run, ó ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ ẹni ìgbàanì, a sì mú u wá sí iwájú rẹ̀.
J'ai eu des visions pendant la nuit. Et voici, sur les nuées du ciel arriva quelqu'un de semblable à un fils d'homme; il s'approcha de l'Ancien des Jours, et on le fit approcher de lui.
14 A sì fi ìjọba, ògo àti agbára ilẹ̀ ọba fún un; gbogbo ènìyàn, orílẹ̀-èdè àti èdè gbogbo wọn wólẹ̀ fún un. Ìjọba rẹ̀, ìjọba ayérayé ni, èyí tí kò le è kọjá, ìjọba rẹ̀ kò sì le è díbàjẹ́ láéláé.
Il lui fut donné la domination, la gloire et le règne, afin que tous les peuples, nations et langues le servent. Sa domination est une domination éternelle, qui ne passera pas, et son royaume un royaume qui ne sera pas détruit.
15 “Ọkàn èmi Daniẹli, dàrú, ìran tí ó wá sọ́kàn mi dẹ́rùbà mí.
« Quant à moi, Daniel, mon esprit était affligé dans mon corps, et les visions de ma tête me troublaient.
16 Mo lọ bá ọ̀kan nínú àwọn tí ó dúró níbẹ̀, mo sì bi í léèrè òtítọ́ ìtumọ̀ nǹkan wọ̀nyí. “Ó sọ fún mi, ó sì túmọ̀ àwọn nǹkan wọ̀nyí fún mi:
Je m'approchai de l'un de ceux qui étaient là, et je lui demandai la vérité sur tout cela. « Il me raconta donc, et me fit connaître l'interprétation des choses.
17 ‘Àwọn ẹranko ńlá mẹ́rin yìí, ni ìjọba mẹ́rin tí yóò dìde ní ayé.
Ces grands animaux, qui sont au nombre de quatre, sont quatre rois qui s'élèveront de la terre.
18 Ṣùgbọ́n, ẹni mímọ́ ti Ọ̀gá-ògo ni yóò gba ìjọba náà, yóò sì jogún un rẹ títí láé àti títí láéláé.’
Mais les saints du Très-Haut recevront le royaume, et posséderont le royaume pour toujours, dans les siècles des siècles.
19 “Nígbà náà, ni mo fẹ́ mọ ìtumọ̀ òtítọ́ ẹranko kẹrin, tí ó yàtọ̀ sí àwọn yòókù, èyí tí ó dẹ́rùba ni gidigidi, tí ó ní eyín irin àti èékánná idẹ, ẹranko tí ó ń run tí ó sì ń pajẹ, tí ó sì ń fi ẹsẹ̀ tẹ èyí tókù mọ́lẹ̀.
Je voulus savoir la vérité sur le quatrième animal, qui était différent de tous les autres, extrêmement redoutable, avec des dents de fer et des ongles d'airain, qui dévorait, déchirait et foulait aux pieds ce qui restait.
20 Bẹ́ẹ̀ ni mo sì fẹ́ mọ̀ nípa ìwo mẹ́wàá orí rẹ̀ àti nípa ìwo yòókù tí ó jáde, nínú èyí tí mẹ́ta lára wọn ṣubú, ìwo tí ó ní ojú, tí ẹnu rẹ̀ ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga.
Je voulus aussi savoir ce qu'il en était des dix cornes qui étaient sur sa tête et de l'autre corne qui était sortie et devant laquelle trois étaient tombées, de cette corne qui avait des yeux et une bouche parlant avec arrogance, et dont l'aspect était plus robuste que celui de ses semblables.
21 Bí mo ṣe ń wò, ìwo yìí ń bá àwọn ènìyàn mímọ́ jagun, ó sì borí i wọn,
Je regardai, et cette corne fit la guerre aux saints et l'emporta sur eux,
22 títí ẹni ìgbàanì fi dé, ó sì ṣe ìdájọ́ ìdáláre fún àwọn ẹni mímọ́ Ọ̀gá-ògo, àsìkò náà sì dé nígbà tí àwọn ẹni mímọ́ náà jogún ìjọba.
jusqu'à ce que vint l'Ancien des Jours, et que le jugement fut donné aux saints du Très-Haut, et que vint le temps où les saints possédèrent le royaume.
23 “Ó ṣe àlàyé yìí fún mi pé, ‘Ẹranko kẹrin ni ìjọba kẹrin tí yóò wà ní ayé. Yóò yàtọ̀ sí gbogbo àwọn ìjọba yòókù yóò sì pa gbogbo ayé run, yóò tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀, yóò sì fọ́ ọ́ sí wẹ́wẹ́.
« Il dit encore: Le quatrième animal sera un quatrième royaume sur la terre, qui sera différent de tous les royaumes, et qui dévorera toute la terre, la foulera et la brisera.
24 Ìwo mẹ́wàá ni ọba mẹ́wàá tí yóò wá láti inú ìjọba yìí. Lẹ́yìn tí wọn ní ọba mìíràn yóò dìde, ti yóò yàtọ̀ sí tí àwọn ti ìṣáájú, yóò sì borí ọba mẹ́ta.
Quant aux dix cornes, dix rois s'élèveront de ce royaume. Un autre s'élèvera après eux, et il sera différent des premiers, et il renversera trois rois.
25 Yóò sọ̀rọ̀ odi sí Ọ̀gá-ògo, yóò sì pọ́n ẹni mímọ́ lójú, yóò sì gbèrò láti yí ìgbà àti òfin padà. A ó fi àwọn ẹni mímọ́ lé e lọ́wọ́ fún ìgbà díẹ̀, ní ọdún méjì àti ààbọ̀.
Il prononcera des paroles contre le Très-Haut, et il épuisera les saints du Très-Haut. Il projettera de changer les temps et la loi, et ils seront livrés entre ses mains jusqu'à un temps, des temps et la moitié d'un temps.
26 “‘Ṣùgbọ́n àwọn onídàájọ́ yóò jókòó, nígbà náà ni a ó gba agbára rẹ̀, a ó sì pa á rùn pátápátá títí ayé.
"'Mais le jugement sera établi, et l'on enlèvera sa domination, pour la consumer et la détruire jusqu'à la fin.
27 Nígbà náà, ni a ó gba ìjọba, agbára àti títóbi ìjọba rẹ̀ ní abẹ́ gbogbo ọ̀run, a ó sì fi fún àwọn ẹni mímọ́, àwọn ènìyàn Ọ̀gá-ògo. Ìjọba rẹ̀ yóò jẹ́ ìjọba títí ayé, gbogbo aláṣẹ ni yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí i, wọn yóò sì máa sìn ín.’
Le royaume et la domination, et la grandeur des royaumes qui sont sous tout le ciel, seront donnés au peuple des saints du Très-Haut. Son royaume est un royaume éternel, et toutes les dominations le serviront et lui obéiront.''
28 “Báyìí ni àlá náà ṣe parí, ọkàn èmi Daniẹli sì dàrú gidigidi, nítorí èrò ọkàn mi yìí, ojú mi sì yípadà ṣùgbọ́n mo pa ọ̀ràn náà mọ́ ní ọkàn mi.”
« Voicila fin de l'affaire. Quant à moi, Daniel, mes pensées m'ont beaucoup troublé, et mon visage a changé en moi; mais j'ai gardé l'affaire dans mon cœur. »

< Daniel 7 >