< Daniel 2 >

1 Ní ọdún kejì ìjọba Nebukadnessari, ó lá àlá, èyí tí ó mú kí ọkàn an rẹ̀ dàrú, kò sì le è sùn.
La deuxième année du règne de Nebucadnetsar, Nebucadnetsar eut des songes; son esprit fut troublé, et le sommeil le quitta.
2 Nígbà náà ni ọba yára pe àwọn onídán, àwọn aláfọ̀ṣẹ, àwọn oṣó àti àwọn awòràwọ̀; àwọn tó ní ìmọ̀ àti àṣírí i títúmọ̀ ìràwọ̀, ọba pè wọ́n kí wọn wá sọ àlá tí ó lá. Nígbà tí wọ́n dé, tí wọ́n dúró níwájú ọba,
Alors le roi ordonna que l'on appelle les magiciens, les enchanteurs, les sorciers et les Chaldéens pour qu'ils racontent au roi ses rêves. Ils entrèrent donc et se tinrent devant le roi.
3 ọba sì wí fún wọn pé, “Mo ti lá àlá kan èyí tí ó mú kí ọkàn mi dàrú, mo sì fẹ́ mọ ìtumọ̀ àlá náà.”
Le roi leur dit: « J'ai fait un rêve, et mon esprit est troublé de connaître ce rêve. »
4 Nígbà náà ni àwọn awòràwọ̀ dá ọba lóhùn ní èdè Aramaiki pé, “Kí ọba kí ó pẹ́! Sọ àlá yìí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ àwa yóò sì sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún ọ.”
Alors les Chaldéens s'adressèrent au roi en langue syrienne: « O roi, vis éternellement! Raconte le rêve à tes serviteurs, et nous t'en donnerons l'interprétation. »
5 Ọba dá àwọn awòràwọ̀ lóhùn pé, “Ohun náà ti kúrò lórí mi, tí ẹ̀yin kò bá sọ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi, èmi yóò gé e yín sí wẹ́wẹ́, ilé e yín yóò sì di ààtàn.
Le roi répondit aux Chaldéens: « La chose s'est éloignée de moi. Si vous ne me faites pas connaître le rêve et son interprétation, vous serez taillés en pièces, et vos maisons seront transformées en tas de fumier.
6 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá sọ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi, èmi yóò fún un yín ní ẹ̀bùn, ọrẹ àti ọláńlá tí ó pọ̀. Nítorí náà, ẹ sọ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi.”
Mais si tu me fais connaître le rêve et son interprétation, tu recevras de moi des dons, des récompenses et de grands honneurs. Montre-moi donc le rêve et son interprétation. »
7 Lẹ́ẹ̀kan sí i, “Wọ́n tún dáhùn pé, jẹ́ kí ọba sọ àlá náà fún ìránṣẹ́ rẹ̀, àwa yóò sì túmọ̀ rẹ̀.”
Ils prirent la parole une seconde fois et dirent: « Que le roi raconte le songe à ses serviteurs, et nous en montrerons l'interprétation. »
8 Nígbà náà ni ọba sọ pé, “Èmi mọ̀ dájú wí pé ẹ̀yin fẹ́ fi àkókò ṣòfò nítorí pé ẹ̀yin ti mọ̀ pé nǹkan ti lọ ní orí mi.
Le roi répondit: « Je sais avec certitude que tu cherches à gagner du temps, car tu vois que la chose s'est éloignée de moi.
9 Tí ẹ̀yin kò bá lè sọ àlá mi, ìjìyà kan ṣoṣo ló wà fún un yín. Ẹ̀yin ti gbèrò láti pa irọ́ àti láti sọ àwọn ọ̀rọ̀ ti ó lè si ni lọ́nà fún mi, títí tí nǹkan yóò fi yí wọ́. Nítorí náà ẹ rọ́ àlá náà fún mi, èmi yóò sì mọ̀ pé ẹ lè túmọ̀ rẹ̀ fún mi.”
Mais si tu ne me fais pas connaître le rêve, il n'y a qu'une seule loi pour toi, car tu as préparé des paroles mensongères et corrompues pour parler devant moi, jusqu'à ce que la situation change. C'est pourquoi, dis-moi le rêve, et je saurai que tu peux me montrer son interprétation. »
10 Àwọn awòràwọ̀ sì dá ọba lóhùn pé, “Kò sí ènìyàn kan ní ayé tí ó lè sọ nǹkan tí ọba béèrè! Kò sí ọba náà bí ó ti wù kí ó tóbi àti kí ó lágbára tó, tí í béèrè irú nǹkan bẹ́ẹ̀ lọ́wọ́ àwọn onídán tàbí aláfọ̀ṣẹ tàbí awòràwọ̀.
Les Chaldéens répondirent au roi et dirent: « Il n'y a pas un homme sur la terre qui puisse montrer l'affaire du roi, car aucun roi, aucun seigneur, aucun chef n'a demandé une telle chose à aucun magicien, aucun enchanteur, aucun Chaldéen.
11 Nǹkan tí ọba béèrè yìí ṣòro púpọ̀. Kò sí ẹni tí ó lè fihan ọba àfi àwọn òrìṣà, tí wọn kì í gbé láàrín ènìyàn.”
C'est une chose rare que le roi demande, et il n'y a personne qui puisse la montrer devant le roi, si ce n'est les dieux, dont la demeure n'est pas avec la chair. »
12 Èyí mú kí ọba bínú, ó sì kanra, nítorí náà ó pàṣẹ kí a pa gbogbo àwọn amòye Babeli run.
A cause de cela, le roi était en colère et très furieux, et il ordonna que tous les sages de Babylone soient détruits.
13 Nítorí náà àṣẹ yìí jáde lọ wí pé kí a pa àwọn amòye, wọ́n ránṣẹ́ pe Daniẹli pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ láti pa wọ́n.
Le décret fut donc publié, et les sages devaient être tués. On chercha à faire tuer Daniel et ses compagnons.
14 Nígbà tí Arioku, olórí àwọn olùṣọ́ ọba, jáde láti lọ pa àwọn amòye Babeli, Daniẹli sọ̀rọ̀ fún un pẹ̀lú ọgbọ́n àti òye.
Alors Daniel répondit avec conseil et prudence à Arioch, chef des gardes du roi, qui était sorti pour tuer les sages de Babylone.
15 Ó béèrè lọ́wọ́ olórí àwọn olùṣọ́ ọba wí pé, “Èéṣe tí àṣẹ ọba fi yá kánkán bẹ́ẹ̀?” Arioku sì ṣe àlàyé ọ̀rọ̀ náà fún Daniẹli.
Il répondit à Arioch, le chef des gardes du roi: « Pourquoi le décret du roi est-il si urgent? » Et Arioch fit connaître la chose à Daniel.
16 Nígbà náà ni Daniẹli wọlé tọ ọba lọ, ó sì tọrọ kí ọba fún òun ní ààyè, òun yóò fi ìtumọ̀ àlá náà hàn fún ọba.
Daniel entra, et demanda au roi de lui fixer un moment, et de lui montrer l'interprétation.
17 Nígbà náà ni Daniẹli padà lọ sí ilé e rẹ̀, ó sì sọ fún àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ Hananiah, Miṣaeli àti Asariah.
Alors Daniel alla dans sa maison et fit connaître la chose à Hanania, à Mischaël et à Azaria, ses compagnons:
18 Ó sọ fún wọn pé kí wọn béèrè fún àánú Ọlọ́run, Olúwa ọ̀run, nítorí àṣírí yìí, kí Daniẹli pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ má ba ṣègbé pẹ̀lú àwọn ọlọ́gbọ́n Babeli yòókù, tí ó wà ní Babeli.
afin qu'ils demandent au Dieu des cieux la grâce de ce secret, pour que Daniel et ses compagnons ne périssent pas avec le reste des sages de Babylone.
19 Ní òru, àṣírí náà hàn sí Daniẹli ní ojú ìran. Nígbà náà ni Daniẹli fi ògo fún Ọlọ́run ọ̀run
Alors le secret fut révélé à Daniel dans une vision pendant la nuit. Alors Daniel bénit le Dieu des cieux.
20 Daniẹli wí pé: “Ọpẹ́ ni fún orúkọ Ọlọ́run láé àti láéláé; tirẹ̀ ni ọgbọ́n àti agbára.
Daniel répondit, « Béni soit le nom de Dieu pour les siècles des siècles; car la sagesse et la puissance lui appartiennent.
21 Ó yí ìgbà àti àkókò padà; ó mú ọba jẹ, ó ń mú wọn kúrò. Ó fún àwọn amòye ní ọgbọ́n àti ìmọ̀ fún àwọn tí ó ní òye.
Il change les temps et les saisons. Il destitue les rois et établit les rois. Il donne la sagesse aux sages, et la connaissance à ceux qui ont de l'intelligence.
22 Ó fi ohun ìjìnlẹ̀ àti àṣírí hàn; ó mọ ohun tí ó pamọ́ nínú òkùnkùn àti ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìmọ́lẹ̀ wà.
Il révèle les choses profondes et secrètes. Il sait ce qu'il y a dans les ténèbres, et la lumière habite avec lui.
23 Mo dúpẹ́, mo sì fi ìyìn fún ọ, ìwọ Ọlọ́run àwọn baba mi: ó ti fún mi ní ọgbọ́n àti agbára ó ti fi àwọn nǹkan tí a béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ hàn fún mi nítorí tí ìwọ ti fi àlá ọba hàn wá.”
Je te remercie et je te loue, O Dieu de mes pères, qui m'ont donné la sagesse et la puissance, et m'ont maintenant fait connaître ce que nous désirions de vous; car vous nous avez fait part de l'affaire du roi. »
24 Nígbà náà ni Daniẹli tọ́ Arioku lọ, ẹni tí ọba yàn láti pa àwọn amòye Babeli run, Daniẹli wí fún un pé, “Má ṣe pa àwọn amòye Babeli run. Mú mi lọ sí ọ̀dọ̀ ọba, èmi yóò sísọ ìtumọ̀ àlá rẹ̀ fún un.”
Daniel alla donc trouver Arioch, que le roi avait chargé de détruire les sages de Babylone. Il alla lui dire ceci: « Ne détruis pas les sages de Babylone. Fais-moi entrer devant le roi, et je montrerai au roi l'interprétation. »
25 Lẹ́sẹ̀kan náà, Arioku yára mú Daniẹli lọ sí iwájú ọba, ó sọ fún ọba pé, “Èmi ti rí ọkùnrin kan lára àwọn àjèjì tí ó wá láti Juda, ẹni tí ó lè sọ ìtumọ̀ àlá náà fún ọba.”
Alors Arioch fit venir Daniel en hâte devant le roi, et lui dit ceci: « J'ai trouvé un homme parmi les enfants de la captivité de Juda qui fera connaître au roi l'interprétation. »
26 Ọba béèrè lọ́wọ́ Daniẹli ẹni tí a tún ń pè ní Belṣassari pé, “Ṣé ìwọ lè sọ ohun tí mo rí nínú àlá mi àti ìtumọ̀ ọ rẹ̀ fún mi?”
Le roi prit la parole et dit à Daniel, qui s'appelait Belteshazzar: « Peux-tu me faire connaître le rêve que j'ai vu et son interprétation? »
27 Daniẹli dá ọba lóhùn pé, “Kò sí awòràwọ̀ kan, apògèdè, onídán tàbí aláfọ̀ṣẹ tí ó lè ṣe àlàyé àṣírí tí ọba béèrè fún
Daniel prit la parole devant le roi et dit: « Le secret que le roi a demandé ne peut être révélé au roi par des sages, des enchanteurs, des magiciens ou des devins;
28 ṣùgbọ́n, Ọlọ́run kan ń bẹ ní ọ̀run tí ó ń fi àṣírí hàn. Ó ti fihan ọba Nebukadnessari, ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ìkẹyìn ọjọ́. Àlá àti ìran tí o rí nígbà tí o dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ ni ìwọ̀nyí:
mais il y a dans les cieux un Dieu qui révèle les secrets, et il a fait connaître au roi Nebucadnetsar ce qui arrivera dans la suite des temps. Voici ton rêve et les visions de ta tête sur ton lit:
29 “Ọba, bí ìwọ ṣe sùn sórí ibùsùn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn rẹ ń ro àwọn ohun tó ń bọ̀, olùfihàn àṣírí ń fi ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ fún ọ.
« Quant à toi, ô roi, tes pensées sont venues sur ta couche, ce qui doit arriver après; et celui qui révèle les secrets t'a fait connaître ce qui arrivera.
30 Ṣùgbọ́n fún èmi, a fi àṣírí yìí hàn mí, kì í ṣe pé mo ní ọgbọ́n tí ó pọ̀ ju ti alààyè kankan lọ, ṣùgbọ́n nítorí kí ọba lè mọ ìtumọ̀ àlá àti kí ó lè mọ ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ̀.
Quant à moi, ce secret ne m'est pas révélé à cause d'une sagesse que j'aurais plus qu'aucun vivant, mais dans le but que l'interprétation soit connue du roi, et que tu puisses connaître les pensées de ton cœur.
31 “Ìwọ ọba ń wo, ère ńlá kan tí ó dúró níwájú rẹ, ère náà ga, ó sì dára láti wò, ìrísí i rẹ̀ ba ni lẹ́rù jọjọ.
« Toi, ô roi, tu as vu, et voici, une grande image. Cette image, qui était puissante et dont l'éclat était excellent, se tenait devant toi, et son aspect était terrifiant.
32 Orí ère náà jẹ́ kìkì wúrà, àyà rẹ̀ àti ọwọ́ rẹ̀ jẹ́ fàdákà, inú àti ẹ̀gbẹ́ itan rẹ̀ jẹ́ idẹ,
Cette statue avait une tête d'or fin, une poitrine et des bras d'argent, un ventre et des cuisses d'airain,
33 àwọn ẹsẹ̀ rẹ̀ jẹ́ irin, àwọn àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀ jẹ́ apá kan irin àti apá kan amọ̀.
des jambes de fer, des pieds en partie de fer et en partie d'argile.
34 Bí ó ṣe ń wò, òkúta kan wá, tí kò wá láti ọwọ́ ẹnìkankan. Ó kọlu ère náà ní àtẹ́lẹsẹ̀ irin àti amọ̀, ó sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́.
Tu as vu jusqu'à ce qu'une pierre taillée sans main frappe la statue sur ses pieds de fer et d'argile, et les mette en pièces.
35 Nígbà náà ni irin, amọ̀, idẹ, fàdákà àti wúrà fọ́ sí wẹ́wẹ́ lẹ́sẹ̀kan náà, ó sì dàbí ìyàngbò tí a fẹ́ kúrò lórí ọkà ní àsìkò ẹ̀ẹ̀rùn. Afẹ́fẹ́ gbé gbogbo rẹ̀ lọ láìṣẹ́ku ọ̀kan mọ́, òkúta tí ó fọ́ ère náà sì di òkè ńlá, ó sì gba gbogbo ayé.
Alors le fer, l'argile, l'airain, l'argent et l'or se brisèrent ensemble, et devinrent comme la balle des aires de battage d'été. Le vent les emporta, et il n'y eut plus de place pour eux. La pierre qui avait frappé la statue devint une grande montagne et remplit toute la terre.
36 “Èyí ni àlá náà, nígbà yìí ni a ó wá sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún ọba.
Voici le songe, et nous allons en donner l'interprétation devant le roi.
37 Ìwọ ọba jẹ́ ọba àwọn ọba. Ọlọ́run ọ̀run ti fi ìjọba agbára, títóbi àti ògo fún ọ;
Toi, ô roi, tu es le roi des rois, celui à qui le Dieu des cieux a donné le règne, la puissance, la force et la gloire.
38 ní ọwọ́ rẹ ló fi gbogbo ènìyàn, àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run sí. Ní ibi gbogbo tí wọ́n ń gbé, ó ti fi ọ́ ṣe olórí i wọn. Ìwọ ni orí wúrà náà.
Partout où habitent les enfants des hommes, il a remis entre tes mains les animaux des champs et les oiseaux du ciel, et il t'a fait dominer sur eux tous. Tu es la tête d'or.
39 “Lẹ́yìn èyí ni ìjọba mìíràn yóò dìde, tí kò ní lágbára tó tìrẹ, lẹ́yìn in rẹ̀, ìjọba kẹta tí yóò dàbí idẹ, èyí tí yóò jẹ ọba lórí i gbogbo ayé.
Après toi, il s'élèvera un autre royaume qui te sera inférieur, et un troisième royaume d'airain, qui dominera sur toute la terre.
40 Ju gbogbo rẹ̀ lọ, ìjọba kẹrin yóò wà, ìjọba náà yóò lágbára bí irin, gẹ́gẹ́ bí irin ti í fọ́, tó sì ń lọ gbogbo nǹkan àti bí irin ti í fọ́ nǹkan sí wẹ́wẹ́, bẹ́ẹ̀ ni yóò fọ́ tí yóò sì lọ gbogbo àwọn tókù.
Le quatrième royaume sera fort comme le fer, car le fer met tout en pièces et soumet tout; et comme le fer qui écrase tout cela, il mettra tout en pièces et écrasera.
41 Bí o ṣe rí i tí àtẹ́lẹsẹ̀ àti ọmọ ìka ẹsẹ̀ jẹ́ apá kan amọ̀ àti apá kan irin, bẹ́ẹ̀ ni ìjọba yóò ṣe pín; ṣùgbọ́n yóò sì ní agbára irin díẹ̀ nínú rẹ̀, bí ó ṣe rí i tí irin dàpọ̀ mọ́ amọ̀.
Comme tu as vu les pieds et les orteils, en partie d'argile et en partie de fer, ce sera un royaume divisé; mais il y aura en lui de la force du fer, parce que tu as vu le fer mêlé à l'argile.
42 Bí ọmọ ìka ẹsẹ̀ ṣe jẹ́ apá kan irin àti apá kan amọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìjọba yìí yóò lágbára lápákan tí kò sì ní lágbára lápákan.
Comme les orteils des pieds étaient en partie de fer et en partie d'argile, ainsi le royaume sera en partie fort et en partie fragile.
43 Gẹ́gẹ́ bí o ti rí i tí irin dàpọ̀ mọ́ amọ̀, báyìí ni àwọn ènìyàn yóò ṣe dàpọ̀ mọ́ ara wọn ní ti ìgbéyàwó, ṣùgbọ́n wọn kò ní wà ní ìṣọ̀kan, bí irin kò ṣe dàpọ̀ mọ́ amọ̀.
Comme tu as vu le fer mêlé à l'argile, ils se mêleront à la race des hommes, mais ils ne s'attacheront pas les uns aux autres, comme le fer ne se mêle pas à l'argile.
44 “Ní àsìkò àwọn ọba náà, Ọlọ́run ọ̀run yóò gbé ìjọba èyí tí kò le è bàjẹ́ kalẹ̀, èyí tí a kò ní fi lé ẹlòmíràn lọ́wọ́. Yóò sì run gbogbo ìjọba, yóò sì mú wọn wá sí òpin, ṣùgbọ́n ìjọba yìí yóò dúró láéláé.”
« Dans les jours de ces rois, le Dieu des cieux établira un royaume qui ne sera jamais détruit, et dont la souveraineté ne sera jamais confiée à un autre peuple; mais il brisera et consumera tous ces royaumes, et il subsistera à jamais.
45 Gẹ́gẹ́ bí o ṣe rí i pé a gé òkúta láti ara òkè, láì ti ọwọ́ ẹnikẹ́ni wá, òkúta èyí tí ó fọ́ irin, idẹ, amọ̀, fàdákà àti wúrà sí wẹ́wẹ́. “Ọlọ́run tí ó tóbi ti fihan ọba, ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú. Òtítọ́ ni àlá náà, bẹ́ẹ̀ ni ìtumọ̀ rẹ̀ ṣe é gbẹ́kẹ̀lé.”
Parce que tu as vu qu'une pierre s'est détachée sans main de la montagne et qu'elle a brisé le fer, le bronze, l'argile, l'argent et l'or, le grand Dieu a fait connaître au roi ce qui arrivera dans la suite. Le rêve est certain, et son interprétation est sûre. »
46 Nígbà náà, ni Nebukadnessari ọba dojúbolẹ̀ níwájú u Daniẹli ó sì fi orí balẹ̀ fún un, ó sì pàṣẹ pé kí wọn kí ó mu ọrẹ àti òórùn tùràrí fún Daniẹli.
Alors le roi Nebucadnetsar tomba sur sa face, se prosterna devant Daniel, et ordonna qu'on lui présente une offrande et des parfums doux.
47 Ọba wí fún Daniẹli pé, “Dájúdájú Ọlọ́run rẹ ni Ọlọ́run àwọn ọlọ́run àti Olúwa àwọn ọba gbogbo àti olùfihàn àwọn àṣírí, nítorí tí ìwọ lè fi àṣírí yìí hàn.”
Le roi prit la parole et dit à Daniel: « En vérité, ton Dieu est le Dieu des dieux, le Seigneur des rois et le révélateur des secrets, puisque tu as pu révéler ce secret. »
48 Nígbà náà ni ọba gbé Daniẹli ga, ó sì fún un ní ẹ̀bùn ńlá tí ó pọ̀. Ó sì fi ṣe olórí i gbogbo agbègbè ìjọba Babeli àti olórí gbogbo àwọn amòye Babeli.
Alors le roi fit de Daniel un grand homme et lui fit beaucoup de dons importants, et il le fit gouverner toute la province de Babylone et être le principal gouverneur de tous les sages de Babylone.
49 Daniẹli béèrè lọ́wọ́ ọba, ó sì yan Ṣadraki, Meṣaki, àti Abednego gẹ́gẹ́ bí alábojútó ìgbèríko Babeli ṣùgbọ́n Daniẹli fúnra rẹ̀ wà ní ààfin ọba.
Daniel demanda au roi de nommer Schadrac, Méschac et Abed-Nego pour diriger les affaires de la province de Babylone, mais Daniel était à la porte du roi.

< Daniel 2 >