< Colossians 3 >
1 Níwọ́n ìgbà tí a ti jí yín dìde pẹ̀lú Kristi ẹ máa ṣàfẹ́rí àwọn nǹkan tí ń bẹ lókè, níbi tí Kristi gbé wà tí ó jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.
ⲁ̅ⲓⲥϫⲉ ⲟⲩⲛ ⲁⲧⲉⲧⲉⲛⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲛⲉⲙ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲁ ⲛⲁ ⳿ⲡϣⲱⲓ ⲡⲓⲙⲁ ⲉⲧⲁ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲉϥϩⲉⲙⲥⲓ ⲥⲁⲟⲩ⳿ⲓⲛⲁⲙ ⳿ⲙⲫϯ.
2 Ẹ máa ronú àwọn ohun tí ń bẹ lókè kì í ṣe àwọn nǹkan tí ń bẹ ní ayé.
ⲃ̅ⲙⲉⲩⲓ ⳿ⲉⲛⲁ ⳿ⲡϣⲱⲓ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲧϩⲓϫⲉⲛ ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ ⲁⲛ.
3 Nítorí ẹ̀yin ti kú, a sì fi ìyè yín pamọ́ pẹ̀lú Kristi nínú Ọlọ́run.
ⲅ̅ⲁⲧⲉⲧⲉⲛⲙⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉⲧⲉⲛⲱⲛϧ ϩⲏⲡ ⲛⲉⲙ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ϧⲉⲛ ⲫϯ.
4 Nígbà tí Kristi, ẹni tí í ṣe ìyè yín yóò farahàn, nígbà náà ni ẹ̀yin pẹ̀lú yóò farahàn pẹ̀lú rẹ̀ nínú ògo.
ⲇ̅ⲉϣⲱⲡ ⲁϥϣⲁⲛⲟⲩⲟⲛϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϫⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲡⲉⲧⲉⲛⲱⲛϧ ⲧⲟⲧⲉ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ϩⲱⲧⲉⲛ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲟⲩⲟⲛϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲛⲉⲙⲁϥ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲱⲟⲩ.
5 Ẹ máa pa ẹ̀yà ara yín tí ń bẹ ní ayé run: àgbèrè, panṣágà, ìwà àìmọ́, ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti ìwọra, nítorí pé ìwọ̀nyí jásí ìbọ̀rìṣà.
ⲉ̅ⲱⲧⲉⲃ ⳿ⲛⲛⲉⲧⲉⲛⲙⲉⲗⲟⲥ ⲉⲧϩⲓϫⲉⲛ ⲡⲓⲕⲁϩⲓ ϯⲡⲟⲣⲛⲓⲁ ⲡⲓϭⲱϧⲉⲙ ⲡⲓⲡⲁⲑⲟⲥ ϯⲉⲡⲓⲑⲩⲙⲓⲁ ⲉⲧϩⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙ ϯⲙⲉⲧⲣⲉϥϭⲓ⳿ⲛϫⲟⲛⲥ ⲉⲧⲉ ϯⲙⲉⲧϣⲁⲙϣⲉ ⳿ⲓⲇⲱⲗⲟⲛ ⲧⲉ.
6 Lórí àwọn wọ̀nyí ni ìbínú Ọlọ́run ń bọ̀ wá.
ⲋ̅ⲛⲏⲉⲧⲉϥⲛⲏⲟⲩ ⲉⲑⲃⲏⲧⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓϫⲱⲛⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲓϣⲏⲣⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲙⲉⲧⲁⲧⲑⲱⲧ ⳿ⲛϩⲏⲧ.
7 Ẹ máa ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí tẹ́lẹ̀ nígbà tí ìgbé ayé yín sì jẹ́ apá kan ayé yìí.
ⲍ̅ⲛⲁⲓ ⲉⲧⲉ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ϩⲱⲧⲉⲛ ⲛⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲙⲟϣⲓ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲟⲩⲥⲏⲟⲩ ϩⲟⲧⲉ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲱⲛϧ ϧⲉⲛ ⲛⲁⲓ.
8 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ gbọdọ̀ fi àwọn wọ̀nyí sílẹ̀: ìbínú, ìrunú, àrankàn, fífi ọ̀rọ̀-kẹ́lẹ́-ba-tẹni-jẹ́ àti ọ̀rọ̀ èérí kúrò ní ètè yín.
ⲏ̅ϯⲛⲟⲩ ⲇⲉ ⲭⲱ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ϩⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲡⲓϫⲱⲛⲧ ⲡⲓ⳿ⲙⲃⲟⲛ ϯⲕⲁⲕⲓⲁ ⲡⲓϫⲉⲟⲩ⳿ⲁ ⲛⲓⲥⲁϫⲓ ⲉⲧϣⲟⲩⲓⲧ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲣⲱⲧⲉⲛ.
9 Ẹ má ṣe purọ́ fún ara yín, níwọ̀n ìgbà tí ẹ ti bọ́ ògbólógbòó ara yín pẹ̀lú ìṣe rẹ̀ sílẹ̀,
ⲑ̅⳿ⲙⲡⲉⲣϫⲉⲙⲉⲑⲛⲟⲩϫ ⳿ⲉⲛⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲁⲧⲉⲧⲉⲛⲃⲁϣ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲛⲁⲡⲁⲥ ⲛⲉⲙ ⲡⲉϥ⳿ⲡⲣⲁⲝⲓⲥ.
10 tí ẹ sì ti gbé ìgbé ayé tuntun wọ̀, èyí tí a sọ di tuntun nínú ìmọ̀ ní ìbámu pẹ̀lú àwòrán ẹni tí ó dá a.
ⲓ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲧⲉⲧⲉⲛϯ ϩⲓ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲙⲃⲉⲣⲓ ⲫⲏⲉⲑⲛⲁⲉⲣⲃⲉⲣⲓ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲥⲱⲟⲩⲛ ⲕⲁⲧⲁ ⳿ⲧϩⲓⲕⲱⲛ ⳿ⲙⲫⲏⲉⲧⲁϥⲥⲟⲛⲧϥ.
11 Níbi tí kò gbé sí Giriki tàbí Júù, ìkọlà tàbí aláìkọlà, aláìgbédè, ara Skitia, ẹrú tàbí òmìnira, ṣùgbọ́n Kristi ni ohun gbogbo nínú ohun gbogbo.
ⲓ̅ⲁ̅ⲡⲓⲙⲁ ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⲟⲩⲉⲓⲛⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⲥⲉⲃⲓ ⲛⲉⲙ ⲙⲉⲧⲁⲧⲥⲉⲃⲓ ⲃⲁⲣⲃⲁⲣⲟⲥ ⳿ⲥⲕⲩⲑⲟⲥ ⲃⲱⲕ ⲟⲩⲟϩ ⲣⲉⲙϩⲉ ⲁⲗⲗⲁ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ Ⲡⲭ̅ⲥ̅.
12 Nítorí náà, bí àyànfẹ́ Ọlọ́run, ẹni mímọ́ àti olùfẹ́, ẹ gbé ọkàn ìyọ́nú wọ̀, ìṣoore, ìrẹ̀lẹ̀, inú tútù àti sùúrù.
ⲓ̅ⲃ̅ⲙⲟⲓ ⲟⲩⲛ ϩⲓ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛϩⲁⲛⲥⲱⲧⲡ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲉⲩⲟⲩⲁⲃ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲙⲉⲛⲣⲓⲧ ⳿ⲛϩⲁⲛⲙⲉⲧϣⲁⲛ⳿ⲑⲙⲁϧⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩⲙⲉⲧⲣⲉϥϣⲉⲛϩⲏ ⲧ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲉⲧϩⲉⲗϫⲉ ⳿ⲛⲟⲩⲑⲉⲃⲓⲟ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲉⲧⲣⲉⲙⲣⲁⲩϣ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲉⲧⲣⲉϥⲱⲟⲩ ⳿ⲛϩⲏⲧ.
13 Ẹ máa fi ara dà á fún ara yín, ẹ sì máa dáríjì ara yín bí ẹnikẹ́ni bá ní ẹ̀sùn sí ẹnìkan: bí Kristi ti dáríjì yín, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin kí ó máa ṣe pẹ̀lú.
ⲓ̅ⲅ̅ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲁⲛⲉⲭⲉⲥⲑⲉ ⳿ⲛⲛⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲏⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲭⲱ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲛⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲏⲟⲩ ⲉϣⲱⲡ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲁⲣⲓⲕⲓ ⲟⲩⲧⲉ ⲟⲩⲁⲓ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲁⲓ ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧⲁ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲭⲱ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ϩⲱⲧⲉⲛ.
14 Àti borí gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ẹ gbé ìfẹ́ wọ̀, tí í ṣe àmùrè ìwà pípé.
ⲓ̅ⲇ̅⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⲇⲉ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲁⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ϯ ⲁⲅⲁⲡⲏ ⲉⲧⲉ ⲡⲓⲙⲟⲩⲣ ⲡⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓϫⲱⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
15 Ẹ sì jẹ́ kí àlàáfíà Ọlọ́run kí ó máa ṣe àkóso ọkàn yín, sínú èyí tí a pè yín pẹ̀lú nínú ara kan; kí ẹ sì máa dúpẹ́.
ⲓ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ϯϩⲓⲣⲏⲛⲏ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲙⲁⲣⲉⲥⲧⲁϫⲣⲟ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲉⲧⲉⲛϩⲏⲧ ⲑⲁⲓ ⲉⲧⲁⲩⲑⲁϩⲉⲙ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲣⲟⲥ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲥⲱⲙⲁ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ ⲟⲩⲟϩ ϣⲱⲡⲓ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲟⲓ ⳿ⲛⲣⲉϥϣⲉⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ.
16 Ẹ jẹ́ kí ọ̀rọ̀ Kristi máa gbé inú yín ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú ọgbọ́n gbogbo; kí ẹ máa kọ́ ọ, kí ẹ sì máa gba ara yín níyànjú nínú Saamu, àti orin ìyìn, àti orin ẹ̀mí, ẹ máa kọrin sí Ọlọ́run ní ọkàn ọpẹ́.
ⲓ̅ⲋ̅ⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡ⳪ ⲙⲁⲣⲉϥϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲧⲣⲁⲙⲁ⳿ⲟ ϧⲉⲛ ⳿ⲥⲃⲱ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛϯ⳿ⲥⲃⲱ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲧⲥⲁⲃⲟ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛⲯⲁⲗⲙⲟⲥ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛ⳿ⲥⲙⲟⲩ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛϩⲱⲇⲏ ⳿ⲙⲡ͞ⲛⲁ̅ⲧⲓⲕⲟⲛ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛϩⲱⲥ ⳿ⲉⲫϯ ϧⲉⲛ ⲛⲉⲧⲉⲛϩⲏⲧ ϧⲉⲛ ⲟⲩϣⲉⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ.
17 Ohunkóhun tí ẹ̀yin bá sì ń ṣe ní ọ̀rọ̀ tàbí ní ìṣe, ẹ máa ṣe gbogbo wọn ní orúkọ Jesu Olúwa, ẹ máa fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run Baba nípasẹ̀ rẹ̀.
ⲓ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲁⲓⲧⲟⲩ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲥⲁϫⲓ ⲓⲉ ϧⲉⲛ ⳿ⲡϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲣⲁⲛ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳪ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛϣⲉⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉⲛ ⲫϯ ⳿ⲫⲓⲱⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲧϥ.
18 Ẹ̀yin aya, ẹ máa tẹríba fún àwọn ọkọ yín, gẹ́gẹ́ bí ó ti yẹ nínú Olúwa.
ⲓ̅ⲏ̅ⲛⲓϩⲓ⳿ⲟⲙⲓ ⲙⲁϭⲛⲉϫⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛⲛⲉⲧⲉⲛϩⲁⲓ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧⲥⲉⲙ⳿ⲡϣⲁ ϧⲉⲛ Ⲡ⳪.
19 Ẹ̀yin ọkọ, ẹ máa fẹ́ràn àwọn aya yín, ẹ má sì ṣe korò sí wọn.
ⲓ̅ⲑ̅ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲁⲣⲓⲁⲅⲁⲡⲁⲛ ⳿ⲛⲛⲉⲧⲉⲛϩⲓ⳿ⲟⲙⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲉⲣϫⲱⲛⲧ ⲟⲩⲃⲏⲟⲩ.
20 Ẹ̀yin ọmọ ẹ máa gbọ́ ti àwọn òbí yín ní ohun gbogbo, nítorí èyí dára gidigidi nínú Olúwa.
ⲕ̅ⲛⲓϣⲏⲣⲓ ⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲛⲥⲁ ⲛⲉⲧⲉⲛⲓⲟϯ ϧⲉⲛ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲫⲁⲓ ⲅⲁⲣ ⲡⲉⲑⲣⲁⲛⲁϥ ⳿ⲙⲠ⳪.
21 Ẹ̀yin baba, ẹ má ṣe mú àwọn ọmọ yín bínú, kí wọn má bà á rẹ̀wẹ̀sì.
ⲕ̅ⲁ̅ⲛⲓⲓⲟϯ ⳿ⲙⲡⲉⲣϯϫⲱⲛⲧ ⳿ⲛⲛⲉⲧⲉⲛϣⲏⲣⲓ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲥⲉ⳿ϣⲧⲉⲙⲉⲣ⳿ⲙⲕⲁϩ ⳿ⲛϩⲏⲧ.
22 Ẹ̀yin ẹrú, ẹ gbọ́ ti àwọn olówó yín nípa ti ara ní ohun gbogbo; kì í ṣe ní àrọ́júṣe, bí àwọn aláṣehàn ènìyàn; ṣùgbọ́n ní òtítọ́ inú, ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
ⲕ̅ⲃ̅ⲛⲓⲉⲃⲓⲁⲓⲕ ⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲛⲥⲁ ⲛⲉⲧⲉⲛϭⲓⲥⲉⲩ ⲕⲁⲧⲁ ⲥⲁⲣⲝ ϧⲉⲛ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲧⲃⲁⲗ ⳿ⲙⲃⲱⲕ ⲁⲛ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛϩⲁⲛⲣⲉϥⲣⲁⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲁⲗⲗⲁ ϧⲉⲛ ⲟⲩϩⲁⲡⲗⲟⲩⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛϩⲏⲧ ϩⲱⲥ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲉⲣϩⲟϯ ϧⲁ⳿ⲧϩⲏ ⳿ⲙⲡϭ̅ ⲥ̅.
23 Ohunkóhun tí ẹ̀yin bá ń ṣe, ẹ máa fi tọkàntọkàn ṣe é fún Olúwa, kí í ṣe fún ènìyàn;
ⲕ̅ⲅ̅ⲡⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲁⲓϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛ ⲯⲩⲭⲏ ⲁⲣⲓϩⲱⲃ ϩⲱⲥ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲠ⳪ ⲟⲩⲟϩ ⲣⲱⲙⲓ ⲁⲛ.
24 kí ẹ mọ̀ pé lọ́wọ́ Olúwa ni ẹ̀yin ó gba èrè, nítorí ẹ̀yin ń sìn Olúwa Kristi.
ⲕ̅ⲇ̅ⲉⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ϫⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁϭⲓ ⳿ⲛ⳿ⲧϣⲉⲃⲓⲱ ⳿ⲛϯ⳿ⲕⲗⲏⲣⲟⲛⲟⲙⲓⲁ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ Ⲡ⳪ ⲁⲣⲓⲃⲱⲕ ⳿ⲙⲠⲭ̅ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲡⲉⲛ⳪.
25 Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe àìṣòdodo, yóò gbà á padà nítorí àìṣòdodo náà tí ó ti ṣe: kò sì ṣí ojúsàájú.
ⲕ̅ⲉ̅ⲫⲏ ⲅⲁⲣ ⲉⲧϭⲓ⳿ⲛϫⲟⲛⲥ ⳿ϥⲛⲁϭⲓ ⳿ⲙⲡⲉϥϭⲓ⳿ⲛϫⲟⲛⲥ ⲉⲧⲁϥⲁⲓϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ϫⲟⲩϣⲧ ⳿ⲉϩⲟ ⲛⲁϩⲣⲁϥ