< Colossians 2 >
1 Mo fẹ́ kí ẹ mọ bí mo ti ń jìjàkadì fún un yín àti fún àwọn ará Laodikea àti fún ọ̀pọ̀ ènìyàn mìíràn tí wọn kò ì tí ì rí mi sójú rí.
ⲁ̅ϯⲟⲩⲱϣ ⲅⲁⲣ ⲉⲑⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ϫⲉ ⲟⲩⲁⲅⲱⲛ ⳿ⲛⲁϣ ⳿ⲙⲙⲁⲓⲏ ⲉⲧⲉⲛⲧⲏⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲛⲏⲉⲧϧⲉⲛ ⲗⲁⲟⲇⲓⲕⲓⲁ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧⲉ ⳿ⲙⲡⲟⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲡⲁϩⲟ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲥⲁⲣⲝ.
2 Ohun tí mo ń béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run fún un yín nínú àdúrà mi ni pé, kí a lè mú yín lọ́kàn le, kí a sì lè so yín pọ̀ pẹ̀lú ìfẹ́ to lágbára, kí ẹ le ní àṣírí ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run lẹ́kùnrẹ́rẹ́. Àṣírí ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run náà ni Kristi fúnra rẹ̀.
ⲃ̅ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲥⲉϫⲉⲙⲛⲟⲙϯ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲟⲩϩⲏⲧ ⲉⲩ⳿ⲧⲥⲁⲃⲏ ⲟⲩⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲟⲩϩⲓⲟⲓ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲁⲅⲁⲡⲏ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲙⲉⲧⲣⲁⲙⲁ⳿ⲟ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲫⲙⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉϥⲕⲁϯ ⳿ⲉ⳿ⲡⲥⲟⲩⲉⲛ ⲡⲓⲙⲩⲥⲧⲏⲣⲓⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⳿ⲫⲓⲱⲧ ⳿ⲙⲠⲭ̅ⲥ̅.
3 Nínú ẹni tí a fi gbogbo ìṣúra ìjìnlẹ̀ ọgbọ́n àti ìmọ̀ pamọ́ sí.
ⲅ̅ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲉ ⲛⲓⲁϩⲱⲣ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ ϯ ⲥⲟⲫⲓⲁ ⲛⲉⲙ ⲡⲓ⳿ⲉⲙⲓ ⲉⲧϩⲏⲡ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ.
4 Mo sọ èyí fún un yín kí ẹnikẹ́ni ma ba à fi ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn mú yín ṣìnà.
ⲇ̅ⲫⲁⲓ ⲇⲉ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉ⳿ϣⲧⲉⲙ ⳿ϩⲗⲓ ⲉⲣϩⲁⲗ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲉⲥⲱⲟⲩ.
5 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò sí i lọ́dọ̀ yín nínú ara, ṣùgbọ́n mo wà lọ́dọ̀ yín nínú ẹ̀mí, bẹ́ẹ̀ ni mo sì ń yọ̀ láti kíyèsi ètò yín àti bí ìdúró ṣinṣin yín nínú Kristi ti rí.
ⲉ̅ⲓⲥϫⲉ ⲅⲁⲣ ϯ ⲛⲉⲙⲱⲧⲉⲛ ⲁⲛ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲥⲁⲣⲝ ⲁⲗⲗⲁ ϯ ⲛⲉⲙⲱⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲉⲓⲣⲁϣⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲓⲛⲁⲩ ⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲧⲁⲝⲓⲥ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲧⲁϫⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛⲛⲁϩϯ ⲉⲧϧⲉⲛ Ⲡⲭ̅ⲥ̅.
6 Nítorí náà, bí ẹ̀yin ti gba Jesu Kristi gẹ́gẹ́ bí Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin máa gbé nínú rẹ̀.
ⲋ̅⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲟⲩⲛ ⲉⲧⲁⲣⲉⲧⲉⲛϭⲓ ⳿ⲙⲠⲭ̅ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲙⲟϣⲓ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ.
7 Ẹ fi gbòǹgbò múlẹ̀, kí a sì gbé yín ró nínú rẹ̀, kí ẹ sì fi ẹsẹ̀ múlẹ̀ nínú ìgbàgbọ́ yín, bí a ti kọ́ yín, àti kí ẹ sì máa pọ̀ nínú rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́.
ⲍ̅ⲉⲣⲉⲧⲉⲛϭⲉ ⲛⲟⲩⲛⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲕⲱⲧ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲧⲁϫⲣⲏ ⲟⲩⲧ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲛⲁϩϯ ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲧⲥⲁⲃⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲟⲓ ⳿ⲛϩⲟⲩ⳿ⲟ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ϧⲉⲛ ⲟⲩϣⲉⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ.
8 Ẹ rí dájú pé ẹnikẹ́ni kò mú yin ní ìgbèkùn pẹ̀lú ẹ̀kọ́ àròsọ àti ìmọ̀ ẹ̀tàn, èyí tí ó gbára lé ìlànà ti ènìyàn àti àgbékalẹ̀ àwọn ẹ̀mí ayé yìí tí ó yàtọ̀ sí ti Kristi.
ⲏ̅⳿ⲁⲛⲁⲩ ⲟⲩⲛ ⲙⲏⲡⲱⲥ ⲟⲩⲟⲛ ⲡⲉⲧⲕⲱⲗⲡ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲧⲫⲓⲗⲟⲥⲟⲫⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲁⲡⲁⲧⲏ ⲉⲥϣⲟⲩⲓⲧ ⲕⲁⲧⲁ ⲛⲓⲡⲁⲣⲁⲇⲟⲥⲓⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲕⲁⲧⲁ ⲛⲓ⳿ⲥⲧⲟⲓⲭⲓⲱⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲕⲁⲧⲁ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲁⲛ.
9 Nítorí nínú Kristi ni ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìwàláàyè Ọlọ́run gbé ní ara,
ⲑ̅ϫⲉ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⳿ϥϣⲟⲡ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲙⲟϩ ⲧⲏⲣϥ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲙⲉⲑⲛⲟⲩϯ ⲥⲱⲙⲁⲧⲓⲕⲱⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲉⲧⲉⲛⲙⲉϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ.
10 ẹ̀yin sì ní ohun gbogbo ní kíkún nínú Kristi, ẹni tí i ṣe orí fún gbogbo agbára àti àṣẹ.
ⲓ̅ⲉⲧⲉ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲡⲉ ⳿ⲧⲁⲫⲉ ⳿ⲛⲁⲣⲭⲏ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲛⲉⲙ ⲉⲝⲟⲩⲥⲓⲁ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
11 Nínú ẹni tí a kò fi ìkọlà tí a fi ọwọ́ kọ kọ yín ní ilà, ni bíbọ ara ẹ̀ṣẹ̀ sílẹ̀, nínú ìkọlà Kristi.
ⲓ̅ⲁ̅ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲁⲩⲥⲟⲩⲃⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲥⲉⲃⲓ ⳿ⲛⲑⲁⲙⲓⲟ ⳿ⲛϫⲓϫ ⲁⲛ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲃⲱϣ ⳿ⲙ⳿ⲡⲥⲱⲙⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲥⲁⲣⲝ ⳿ⲛ⳿ϩⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲥⲉⲃⲓ ⳿ⲙⲠⲭ̅ⲥ̅.
12 Bí a ti sin yín pọ̀ pẹ̀lú rẹ̀ nínú ìtẹ̀bọmi, tí a sì ti jí yín dìde pẹ̀lú rẹ̀ nípasẹ̀ ìgbàgbọ́ yín nínú agbára Ọlọ́run, ẹni tí ó jí dìde kúrò nínú òkú.
ⲓ̅ⲃ̅⳿ⲉⲁⲩⲕⲉⲥ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲛⲉⲙⲁϥ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲱⲙⲥ ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲉ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⲁⲧⲉⲧⲉⲛⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲛⲉⲙⲁϥ ⲟⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲡⲓⲛⲁϩϯ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲉⲣϩⲱⲃ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲁϥⲧⲟⲩⲛⲟⲥϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲏⲉⲑⲙⲱⲟⲩⲧ.
13 Àti ẹ̀yin, ẹni tí ó ti kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ yín àti àìkọlà ará yín, mo ní, ẹ̀yin ni ó sì ti sọ di ààyè pọ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì ti dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín;
ⲓ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ϩⲱⲧⲉⲛ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲙⲱⲟⲩⲧ ϧⲉⲛ ⲛⲉⲧⲉⲛⲡⲁⲣⲁⲡⲧⲱⲙⲁ ⲛⲉⲙ ϯ ⲙⲉⲧⲁⲧⲥⲉⲃⲓ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛⲥⲁⲣⲝ ⲁϥⲧⲁⲛϧⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲛⲉⲙⲁϥ ⳿ⲉⲁϥⲭⲱ ⲛⲁⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲛⲉⲛⲡⲁⲣⲁ⳿ⲡⲧⲱⲙⲁ ⲧⲏⲣⲟⲩ.
14 Ó sì ti pa ìwé májẹ̀mú nì rẹ́, tí ó lòdì sí wa, tí a kọ nínú òfin, èyí tí o lòdì sí wa: òun ni ó sì ti mú kúrò lójú ọ̀nà, ó sì kàn án mọ àgbélébùú.
ⲓ̅ⲇ̅⳿ⲉⲁϥⲥⲱⲗϫ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲥϧⲓ ⳿ⲛϫⲓϫ ⲫⲁⲓ ⳿ⲉⲛⲁϥⲧⲟⲓ ϧⲁⲣⲟⲛ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲇⲟⲅⲙⲁ ⲫⲏ ⳿ⲉⲛⲁϥϯ ⲟⲩⲃⲏⲛ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲁϥⲟⲗϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲑⲙⲏϯ ⳿ⲉⲁϥϯⲓϥⲧ ⲛⲁϥ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲡⲓ.̇
15 Ó sì ti gba agbára kúrò lọ́wọ́ àwọn ìjọba ẹ̀mí búburú àti àwọn alágbára gbogbo, ó sì ti dójútì wọn ní gbangba, bí ó ti ń yọ̀ fún ìṣẹ́gun lórí wọn.
ⲓ̅ⲉ̅⳿ⲉⲁϥⲃⲁϣϥ ⳿ⲛⲛⲓⲁⲣⲭⲏ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲉⲝⲟⲩⲥⲓⲁ ⳿ⲉⲁϥϯ ⳿ⲙⲡⲟⲩⲥⲱⲓⲧ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲟⲩⲟⲛϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲉⲁϥⲁⲓⲧⲟⲩ ⳿ⲛ⳿ⲥⲣⲁϩ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ.
16 Nítorí náà ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ṣe ìdájọ́ yín ní ti jíjẹ, tàbí ní ti mímu, tàbí ní ti ọjọ́ àsè, tàbí oṣù tuntun, àti ọjọ́ ìsinmi.
ⲓ̅ⲋ̅⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉ ⳿ϩⲗⲓ ⲟⲩⲛ ϯϩⲁⲡ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲟⲩⲱⲙ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲥⲱ ⲓⲉ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲧⲟⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩϣⲁⲓ ⲓⲉ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲥⲟⲩⲁⲓ ⲓⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ϩⲁⲛⲥⲁⲃⲃⲁⲧⲟⲛ.
17 Àwọn tí í ṣe òjìji ohun tí ń bọ̀; ṣùgbọ́n ní ti òtítọ́, nínú Kristi ni àti mu wọn ṣẹ.
ⲓ̅ⲍ̅ⲉⲧⲉ ⳿ⲧϧⲏⲓⲃⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲉⲑⲏⲛⲟⲩ ⲧⲉ ⲡⲓⲥⲱⲙⲁ ⲇⲉ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅.
18 Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni tí ó ní inú dídùn nínú ìrẹ̀lẹ̀ èké àti bíbọ àwọn angẹli lọ́ èrè yín gbà lọ́wọ́ yín, ẹni tí ń dúró lórí nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí ó ti rí, tí ó ń ṣe féfé asán nípa èrò ti ọkàn ara rẹ̀.
ⲓ̅ⲏ̅⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉ ⳿ϩⲗⲓ ϭⲣⲟ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⲉϥⲟⲩⲱϣ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲑⲉⲃⲓⲟ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲛⲉⲙ ⲟⲩϣⲉⲙϣⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⲛⲏⲉⲧⲁϥⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲁϥϩⲱⲙⲓ ⳿ⲉϫⲱⲟⲩ ⲉϥϭⲟⲥⲓ ⳿ⲛϩⲏⲧ ϩⲓⲕⲏ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⳿ⲡϩⲏⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⲧⲉϥⲥⲁⲣⲝ.
19 Wọn ti sọ ìdàpọ̀ wọn pẹ̀lú ẹni tí i ṣe orí nu, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí a ń ti ipa oríkèé àti iṣan pèsè fún gbogbo ara, ti a sì ń so ó ṣọ̀kan pọ̀, tí ó sì ń dàgbà nípa ìmísí Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ϥ⳿ⲁⲙⲟⲛⲓ ⲁⲛ ⳿ⲛϯⲁⲫⲉ ⲫⲏⲉⲧⲉ ⲡⲓⲥⲱⲙⲁ ⲧⲏⲣϥ ⲟⲩ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲡⲉ ⲉⲩⲥⲁϩⲛⲓ ⳿ⲛⲥⲱϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲛⲓⲙⲟϯ ⲛⲉⲙ ⲛⲓ⳿ⲥⲛⲁⲩϩ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲩ⳿ϫⲫⲟ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ϥⲛⲁⲁⲓⲁⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲁⲓⲁⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
20 Bí ẹ̀yin bá ti kú pẹ̀lú Kristi si àwọn agbára ìlànà ayé yìí, kín ló dé tí ẹ̀yin ń tẹríba fún òfin bí ẹni pé ẹ̀yin wà nínú ayé.
ⲕ̅ⲓⲥϫⲉ ⲁⲧⲉⲧⲉⲛⲙⲟⲩ ⲛⲉⲙ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁ ⲛⲓ⳿ⲥⲧⲟⲓⲭⲓⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⳿ⲁϧⲱⲧⲉⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛⲱⲡ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ ⲉⲩⲱⲛϧ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ.
21 Má ṣe dìímú, má ṣe tọ́ ọ wò, má ṣe fi ọwọ́ bà á.
ⲕ̅ⲁ̅⳿ⲙⲡⲉⲣϭⲓ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲉⲣϭⲓϯⲡⲓ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲉⲣϧⲱⲛⲧ.
22 Gbogbo èyí tí yóò ti ipa lílo run, gẹ́gẹ́ bí òfin àti ẹ̀kọ́ ènìyàn?
ⲕ̅ⲃ̅⳿ⲉϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧⲭⲏ ⳿ⲉ⳿ⲡⲧⲁⲕⲟ ⳿ⲉ⳿ϣⲧⲉⲙⲉⲣ⳿ⲭ ⲣⲁⲥⲑⲉ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲕⲁⲧⲁ ⲛⲓϩⲟⲛϩⲉⲛ ⲛⲉⲙ ϯⲙⲉⲧⲣⲉϥϯ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ.
23 Àwọn nǹkan tí ó ní àfarawé ọgbọ́n nítòótọ́, nípasẹ̀ àdábọwọ́ ìsìn, àti ìrẹ̀lẹ̀, àti ìpọ́nra-ẹni-lójú, ṣùgbọ́n tí kò ni èrè láti di ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara ku.
ⲕ̅ⲅ̅ⲉⲧⲉ ⲛⲉ ⲛⲏⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲥⲁϫⲓ ⲙⲉⲛ ⳿ⲛϧⲏⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩ⳿ⲥⲃⲱ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲟⲩⲱϣ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩϣⲉⲙϣⲓ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲑⲉⲃⲓⲟ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲙⲉⲧⲁⲧϯ ⲁⲥⲟ ⳿ⲉⲡⲓⲥⲱⲙⲁ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲧⲁⲓⲟ ⲁⲛ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲥⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲧⲥⲁⲣⲝ