< Acts 23 >

1 Paulu tẹjúmọ́ ìgbìmọ̀, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin arákùnrin mi, èmi tí ń fi gbogbo ẹ̀rí ọkàn rere lo ayé mi níwájú Ọlọ́run títí fi di òní yìí.”
ⲁ̅ⲈⲦⲀϤⲤⲞⲘⲤ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲈⲠⲒⲘⲀ ⲚϮϨⲀⲠ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲒⲢⲰⲘⲒ ⲚⲈⲚⲤⲚⲎⲞⲨ ⲀⲚⲞⲔ ⲚϦⲢⲎⲒ ϦⲈⲚⲤⲨⲚⲎⲆⲈⲤⲒⲤ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲐⲚⲀⲚⲈⲨ ⲀⲒⲈⲢⲠⲞⲖⲒⲦⲈⲨⲈⲤⲐⲈ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ϢⲀ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲠⲀⲒⲈϨⲞⲞⲨ.
2 Nígbà yìí ni Anania olórí àlùfáà pàṣẹ fún àwọn tí ó dúró tí Paulu pé, kí wọn ó gbá a lẹ́nu.
ⲃ̅ⲠⲒⲀⲢⲬⲒⲈⲢⲈⲨⲤ ⲆⲈ ⲀⲚⲀⲚⲒⲀⲤ ⲀϤⲞⲨⲀϨⲤⲀϨⲚⲒ ⲚⲚⲎ ⲈⲦⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦⲞⲨ ⲚⲀϨⲢⲀϤ ⲈⲐⲢⲞⲨϨⲒⲞⲨⲒ ϦⲈⲚⲢⲰϤ.
3 Nígbà náà ni Paulu wí fún un pé, “Ọlọ́run yóò lù ọ́, ìwọ ògiri tí a kùn lẹ́fun: ìwọ jókòó láti dá mi lẹ́jọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin, ṣùgbọ́n ìwọ gan an rú òfin nípa pípàṣẹ pé kí a lù mí!”
ⲅ̅ⲦⲞⲦⲈ ⲠⲈϪⲈ ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲚⲀϨⲒⲞⲨⲒ ⲈⲢⲞⲔ ⲘⲠⲀⲒⲢⲎϮ ϮϪⲞⲒ ⲈⲦⲞϢϪ ⲚⲔⲞⲚⲒⲀ ⲔⲈⲢⲠⲔⲈϨⲈⲘⲤⲒ ⲈⲔϮϨⲀⲠ ⲈⲢⲞⲒ ⲔⲀⲦⲀ ⲠⲒⲚⲞⲘⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲔⲈⲢⲔⲈⲖⲈⲨⲒⲚ ⲈⲐⲢⲞⲨϨⲒⲞⲨⲒ ⲈⲢⲞⲒ ⲤⲀⲂⲞⲖ ⲘⲠⲒⲚⲞⲘⲞⲤ.
4 Àwọn tí ó dúró tì Paulu sì wí pé, “Ìwọ́ ń gan olórí àlùfáà Ọlọ́run?”
ⲇ̅ⲚⲎ ⲆⲈ ⲈⲦⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦⲞⲨ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲀⲔϨⲰⲞⲨϢ ⲈⲠⲒⲀⲢⲬⲎⲈⲢⲈⲨⲤ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
5 Paulu sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin arákùnrin mi, èmi kò mọ̀ pé olórí àlùfáà ni: nítorí a tí kọ ọ́ pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ sọ̀rọ̀ olórí àwọn ènìyàn rẹ̀ ní búburú.’”
ⲉ̅ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲚⲀⲒⲤⲰⲞⲨⲚ ⲠⲈ ⲚⲀⲤⲚⲎⲞⲨ ϪⲈ ⲞⲨⲀⲢⲬⲒⲈⲢⲈⲨⲤ ⲠⲈ ⲤⲤϦⲎⲞⲨⲦ ⲄⲀⲢ ϪⲈ ⲞⲨⲀⲢⲬⲰⲚ ⲚⲦⲈⲠⲈⲔⲖⲀⲞⲤ ⲚⲚⲈⲔϪⲈ ⲠⲈⲦϨⲰⲞⲨ ϦⲀⲢⲞϤ.
6 Ṣùgbọ́n nígbà tí Paulu ṣàkíyèsí pé, apá kan wọn jẹ́ Sadusi, apá kan sì jẹ́ Farisi, ó kígbe ní ìgbìmọ̀ pé, “Ẹ̀yin arákùnrin mi, èmi jẹ́ Farisi, ọmọ Farisi sì ni èmi. Mo dúró ní ìdájọ́ nítorí ìrètí mi nínú àjíǹde òkú.”
ⲋ̅ⲈⲦⲀϤⲈⲘⲒ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ϪⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲘⲈⲢⲞⲤ ⲘⲈⲚ ⲈⲪⲀ ⲚⲒⲤⲀⲆⲆⲞⲨⲔⲈⲞⲤ ⲠⲈ ⲠⲒⲔⲈⲘⲈⲢⲞⲤ ⲆⲈ ⲈⲪⲀ ⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲠⲈ ⲀϤⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲒⲘⲀ ⲚϮϨⲀⲠ ⲚⲒⲢⲰⲘⲒ ⲚⲈⲚⲤⲚⲎⲞⲨ ⲀⲚⲞⲔ ⲞⲨⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲈⲐⲂⲈ ⲞⲨϨⲈⲖⲠⲒⲤ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲀⲚⲀⲤⲦⲀⲤⲒⲤ ⲚⲦⲈⲚⲒⲢⲈϤⲘⲰⲞⲨⲦ ⲀⲚⲞⲔ ⲤⲈϮϨⲀⲠ ⲈⲢⲞⲒ.
7 Nígbà tí ó sì tí wí èyí, ìyapa dé láàrín àwọn Farisi àti àwọn Sadusi: àjọ sì pín sì méjì.
ⲍ̅ⲪⲀⲒ ⲆⲈ ⲈⲦⲀϤϪⲞϤ ⲀϤϢⲰⲠⲒ ⲚϪⲈⲞⲨϢⲐⲞⲢⲦⲈⲢ ⲞⲨⲦⲈ ⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲤⲀⲆⲆⲞⲨⲔⲈⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲪⲰⲢϪ ⲚϪⲈⲠⲒⲘⲎϢ.
8 Nítorí tí àwọn Sadusi wí pé, kò sì àjíǹde, tàbí angẹli, tàbí ẹ̀mí: ṣùgbọ́n àwọn Farisi jẹ́wọ́ méjèèjì.
ⲏ̅ⲚⲒⲤⲀⲆⲆⲞⲨⲔⲈⲞⲤ ⲘⲈⲚ ⲄⲀⲢ ⲤⲈϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲘⲘⲞⲚ ⲀⲚⲀⲤⲦⲀⲤⲒⲤ ⲞⲨⲆⲈ ⲀⲄⲄⲈⲖⲞⲤ ⲞⲨⲆⲈ ⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲆⲈ ⲤⲈⲞⲨⲰⲚϨ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲈⲨⲤⲞⲠ.
9 Ó sì di ariwo ńlá, nínú àwọn olùkọ́ òfin tí ó wà ni apá tí àwọn Farisi dìde, wọ́n ń jà, wí pé, “Àwa kò rí ohun búburú kan lára ọkùnrin yìí,” wọ́n wí “àwa kò sì mọ̀ nítòótọ́ bí angẹli kan tàbí ẹ̀mí kan ń ba à sọ̀rọ̀?”
ⲑ̅ⲀϤϢⲰⲠⲒ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚϦⲢⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲦⲰⲞⲨⲚ ⲚϪⲈϨⲀⲚⲞⲨⲞⲚ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲒⲪⲀⲢⲒⲤⲈⲞⲤ ⲀⲨⲘⲖⲀϦ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲦⲈⲚϪⲈⲘ ϨⲖⲒ ⲘⲠⲈⲦϨⲰⲞⲨ ⲀⲚ ϦⲈⲚⲠⲀⲒⲢⲰⲘⲒ ⲒⲤϪⲈ ⲞⲨⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲀϤⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲒⲈ ⲞⲨⲀⲄⲄⲈⲖⲞⲤ.
10 Nígbà tí ìyapa sì di ńlá, tí olórí ogun bẹ̀rù kí Paulu má ba à di fífàya lọ́wọ́ wọn, ó pàṣẹ pé ki àwọn ọmọ-ogun sọ̀kalẹ̀ lọ láti fi ipá mú un kúrò láàrín wọn, kí wọn sì mú un wá sínú àgọ́ àwọn ológun.
ⲓ̅ⲈⲦⲀϤϢⲰⲠⲒ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚϢⲐⲞⲢⲦⲈⲢ ⲀϤⲈⲢϨⲞϮ ⲚϪⲈⲠⲒⲬⲒⲖⲒⲀⲢⲬⲞⲤ ⲘⲎⲠⲰⲤ ⲚⲤⲈϤⲒ ⲘⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦⲞⲨ ⲀϤⲈⲢⲔⲈⲖⲈⲨⲒⲚ ⲘⲠⲒⲤⲦⲢⲀⲦⲈⲨⲘⲀ ⲚⲦⲞⲨϢⲈ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲚⲦⲞⲨϨⲰⲖⲈⲘ ⲘⲘⲞϤ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲦⲞⲨⲘⲎϮ ⲚⲦⲞⲨⲈⲚϤ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϮⲠⲀⲢⲈⲘⲂⲞⲖⲎ.
11 Ní òru ọjọ́ náà Olúwa dúró tì Paulu, ó wí pé, “Mú ọkàn le! Bí ìwọ ti jẹ́rìí fún mi ní Jerusalẹmu, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò lè ṣàìjẹ́rìí ni Romu pẹ̀lú.”
ⲓ̅ⲁ̅ⲚϨⲢⲎⲒ ⲆⲈ ϦⲈⲚⲠⲒⲈϪⲰⲢϨ ⲈⲐⲚⲎⲞⲨ ⲀⲠϬⲞⲒⲤ ⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦϤ ⲚⲀϨⲢⲀϤ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ϪⲈⲘⲚⲞⲘϮ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲀⲔⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ⲈⲐⲂⲎⲦ ϦⲈⲚⲒⲈⲢⲞⲤⲀⲖⲎⲘ ⲠⲀⲒⲢⲎϮ ϨⲰϮ ⲈⲢⲞⲔ ⲞⲚ ⲚⲦⲈⲔⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ⲈⲐⲂⲎⲦ ϦⲈⲚⲦⲔⲈⲢⲰⲘⲎ.
12 Nígbà tí ilẹ̀ mọ́, àwọn Júù kan dìtẹ̀, wọ́n fi ara wọn bú pé, àwọn kì yóò jẹ, bẹ́ẹ̀ ní àwọn kì yóò mú títí àwọn ó fi pa Paulu.
ⲓ̅ⲃ̅ⲈⲦⲀ ⲠⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲆⲈ ϢⲰⲠⲒ ⲀⲨⲐⲰⲞⲨϮ ⲚϪⲈⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲀⲨⲦⲀⲢⲔⲰⲞⲨ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲈϢⲦⲈⲘⲞⲨⲰⲘ ⲞⲨⲆⲈ ⲈϢⲦⲈⲘⲤⲰ ϢⲀⲦⲞⲨϦⲰⲦⲈⲂ ⲘⲠⲀⲨⲖⲞⲤ.
13 Àwọn tí ó dìtẹ̀ yìí sì ju ogójì ènìyàn lọ.
ⲓ̅ⲅ̅ⲚⲀⲨⲈⲢϨⲞⲨⲞ ⲆⲈ ⲈⲘ ⲚⲢⲰⲘⲒ ⲚϪⲈⲚⲎ ⲈⲦⲀⲨⲒⲢⲒ ⲘⲠⲀⲒⲀⲚⲀϢ.
14 Wọ́n sì tọ olórí àwọn àlùfáà àti àwọn alàgbà lọ, wọn sì wí pé, “Àwa tí fi ara wa sínú ìdè ìbúra pé, a kì yóò tọ́ oúnjẹ kan wò títí àwa ó fi pa Paulu.
ⲓ̅ⲇ̅ⲚⲀⲒ ⲀⲨⲒ ϢⲀ ⲚⲒⲀⲢⲬⲒⲈⲢⲈⲨⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲠⲢⲈⲤⲂⲨⲦⲈⲢⲞⲤ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ϪⲈ ϦⲈⲚⲞⲨⲀⲚⲀⲐⲈⲘⲀ ⲀⲚⲦⲀⲢⲔⲞⲚ ⲈϢⲦⲈⲘϪⲈⲘϮⲠⲒ ⲚϨⲖⲒ ϢⲀⲦⲈⲚϦⲰⲦⲈⲂ ⲘⲠⲀⲨⲖⲞⲤ.
15 Ǹjẹ́ nísinsin yìí kí ẹ̀yin pẹ̀lú àjọ ìgbìmọ̀ wí fún olórí ogun, kí ó mú un sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá, bí ẹni pé ẹ̀yin ń fẹ́ wádìí ọ̀ràn rẹ̀ dájúdájú. Kí ó tó súnmọ́ tòsí, àwa ó ti múra láti pa á.”
ⲓ̅ⲉ̅ϮⲚⲞⲨ ⲞⲨⲚ ⲞⲨⲞⲚϨ ⲈⲠⲒⲬⲒⲖⲒⲀⲢⲬⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲠⲒⲘⲀⲚϮϨⲀⲠ ϨⲞⲠⲰⲤ ⲚⲦⲈϤⲈⲚϤ ϢⲀⲢⲰⲦⲈⲚ ϨⲰⲤ ϪⲈ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲈⲘⲒ ϦⲈⲚⲞⲨⲦⲀϪⲢⲞ ⲈⲐⲂⲎⲦϤ ⲀⲚⲞⲚ ⲆⲈ ⲘⲠⲀⲦⲈϤϦⲰⲚⲦ ⲈⲢⲰⲦⲈⲚ ⲦⲈⲚⲤⲈⲂⲦⲰⲦ ⲈϦⲞⲐⲂⲈϤ.
16 Nígbà tí ọmọ arábìnrin Paulu sí gbúròó ìdìtẹ̀ wọn, ó lọ, ó sì wọ inú àgọ́ àwọn ológun lọ, ó sì sọ fún Paulu.
ⲓ̅ⲋ̅ⲈⲦⲀϤⲤⲰⲦⲈⲘ ⲆⲈ ⲈϮϪⲞⲢϪⲤ ⲚϪⲈⲠϢⲎⲢⲒ ⲚⲦⲤⲰⲚⲒ ⲘⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲀϤⲒ ⲀϤϢⲈ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈϮⲠⲀⲢⲈⲘⲂⲞⲖⲎ ⲀϤⲦⲀⲘⲈ ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ.
17 Paulu sì pé ọ̀kan nínú àwọn balógun ọ̀run sọ́dọ̀ rẹ̀, ó ní, “Mú ọmọkùnrin yìí tọ olórí ogun lọ, nítorí ó ní nǹkan láti sọ fún un.”
ⲓ̅ⲍ̅ⲀϤⲘⲞⲨϮ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲈⲞⲨⲀⲒ ⲚⲚⲒⲈⲔⲀⲦⲞⲚⲦⲀⲢⲬⲞⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ϬⲒ ⲘⲠⲀⲒϦⲈⲖϢⲒⲢⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ϢⲀ ⲠⲒⲬⲒⲖⲒⲀⲢⲬⲞⲤ ⲞⲨⲞⲚⲦⲈϤ ⲞⲨϨⲰⲂ ⲄⲀⲢ ⲈϪⲞϤ ⲚⲀϤ.
18 Ó mú un, ó sì sìn ín lọ sọ́dọ̀ olórí ogun. Balógun ọ̀rún náà wí pé, “Paulu òǹdè pè mi sọ́dọ̀ rẹ̀, ó síbẹ̀ mí pé ki èmi mú ọmọkùnrin yìí tọ̀ ọ́ wá, ẹni tí ó ní nǹkan láti sọ fún ọ.”
ⲓ̅ⲏ̅ⲚⲐⲞϤ ⲘⲈⲚ ⲞⲨⲚ ⲀϤϬⲒⲦϤ ⲀϤⲈⲚϤ ϢⲀ ⲠⲒⲬⲒⲖⲒⲀⲢⲬⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲠⲈⲦⲤⲞⲚϨ ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲀϤⲘⲞⲨϮ ⲈⲢⲞⲒ ⲀϤϪⲞⲤ ⲚⲎⲒ ⲈⲒⲚⲒ ⲘⲠⲀⲒϦⲈⲖϢⲒⲢⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ϢⲀⲢⲞⲔ ⲈⲞⲨⲞⲚⲦⲈϤ ⲞⲨϨⲰⲂ ⲈϪⲞϤ ⲚⲀⲔ.
19 Alábojútó-ogun fà á lọ́wọ́, ó sì lọ si apá kan, ó sì bi í léèrè níkọ̀kọ̀ pé, “Kín ni ohun tí ìwọ ní sọ fún mi?”
ⲓ̅ⲑ̅ⲀϤⲀⲘⲀϨⲒ ⲆⲈ ⲚⲦⲈϤϪⲒϪ ⲚϪⲈⲠⲒⲬⲒⲖⲒⲀⲢⲬ ⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲈⲢⲀⲚⲀⲬⲰⲢⲒⲚ ⲤⲀⲞⲨⲤⲀ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦϤ ⲚⲀϤϢⲒⲚⲒ ⲘⲘⲞϤ ϪⲈ ⲞⲨ ⲠⲈⲦⲈⲔⲞⲨⲰϢ ⲈϪⲞϤ ⲚⲎⲒ.
20 Ó sì wí pé, “Àwọn Júù fi ìmọ̀ ṣọ̀kan láti wá bẹ̀ ọ́, kí o mú Paulu sọ̀kalẹ̀ wá sí àjọ ìgbìmọ̀ ní ọ̀la, bí ẹni pé àwọn ń fẹ́ béèrè nǹkan dájúdájú nípa rẹ̀.
ⲕ̅ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲀⲨⲤⲈⲘⲚⲎⲦⲤ ⲈⲦⲞⲂϨⲔ ⲚⲢⲀⲤϮ ϨⲞⲠⲰⲤ ⲚⲦⲈⲔⲒⲚⲒ ⲘⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲈⲠⲒⲘⲀⲚϮϨⲀⲠ ϨⲰⲤ ⲈⲔⲚⲀⲈⲘⲒ ⲈⲐⲂⲎⲦϤ ϦⲈⲚⲞⲨⲦⲀϪⲢⲞ.
21 Nítorí náà má ṣe gbọ́ tiwọn, nítorí àwọn tí ó dènà dè é nínú wọn ju ogójì ọkùnrin lọ, tí wọ́n fi ara wọn bú pé, àwọn kì yóò jẹ, bẹ́ẹ̀ ni àwọn kì yóò mu títí àwọn o fi pa á. Wọ́n sì ti múra tan nísinsin yìí, wọ́n ń retí ìdáhùn lọ́dọ̀ rẹ.”
ⲕ̅ⲁ̅ⲚⲐⲞⲔ ⲞⲨⲚ ⲘⲠⲈⲚⲐⲢⲈ ⲠⲈⲔϨⲎⲦ ⲐⲰⲦ ⲚⲈⲘⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞⲚ ϨⲞⲨⲞ ⲄⲀⲢ ⲈⲘ ⲚⲢⲰⲘⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϦⲎⲦⲞⲨ ⲈⲨϪⲰⲢϪ ⲈⲢⲞϤ ⲚⲀⲒ ⲈⲦⲀⲨⲦⲀⲢⲔⲈ ⲚⲞⲨⲈⲢⲎⲞⲨ ⲈϢⲦⲈⲘⲞⲨⲰⲘ ⲞⲨⲆⲈ ⲈϢⲦⲈⲘⲤⲰ ϢⲀⲦⲞⲨϦⲰⲦⲈⲂ ⲘⲘⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ϮⲚⲞⲨ ⲤⲈⲤⲈⲂⲦⲰⲦ ⲈⲨϪⲞⲨϢⲦ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲀⲦϨⲎ ⲘⲠⲒⲰϢ ⲈⲐⲚⲀϢⲰⲠⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦⲔ.
22 Nígbà náà ni olórí ogun fi ọmọ náà sílẹ̀ láti lọ, ó sí kìlọ̀ fún un pé, “Má ṣe wí fún ẹnìkan pé, ìwọ fi nǹkan wọ̀nyí hàn mi.”
ⲕ̅ⲃ̅ⲠⲒⲬⲒⲖⲒⲀⲢⲬⲞⲤ ⲞⲨⲚ ⲀϤⲬⲀ ⲠⲒϦⲈⲖϢⲒⲢⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲈⲀϤϨⲞⲚϨⲈⲚ ⲚⲀϤ ⲈϢⲦⲈⲘϪⲞⲤ ⲚϨⲖⲒ ϪⲈ ⲀⲔⲦⲀⲘⲞⲒ ⲈⲚⲀⲒ.
23 Ó sì pe méjì nínú àwọn balógun ọ̀run sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ múra igba ọmọ-ogun sílẹ̀, láti lọ sí Kesarea, àti àádọ́rin ẹlẹ́ṣin, àti igba ọlọ́kọ̀, ní wákàtí kẹta òru.
ⲕ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲘⲞⲨϮ ⲈⲂ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲒⲈⲔⲀⲦⲞⲚⲦⲀⲢⲬⲞⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲤⲈⲂⲦⲈ ⲤⲘⲘⲀⲦⲞⲒ ϨⲞⲠⲰⲤ ⲚⲤⲈϢⲈ ϢⲀ ⲔⲈⲤⲀⲢⲒⲀ ⲚⲈⲘ ⲞⲚϨⲒⲠⲈⲨⲤ ⲚⲈⲘ ⲤⲚⲢⲈϤϨⲒⲖⲞⲄⲬⲎ ⲒⲤϪⲈⲚ ⲪⲚⲀⲨ ⲚⲀϪⲠⲄ ⲘⲠⲒⲈϪⲰⲢϨ.
24 Ó sì wí pé, kí wọn pèsè ẹṣin, kí wọ́n gbé Paulu gùn ún; kí wọ́n sì lè mú un dé ọ̀dọ̀ Feliksi baálẹ̀ ní àlàáfíà.”
ⲕ̅ⲇ̅ⲚⲤⲈϬⲒ ⲚϨⲀⲚⲔⲈⲦⲈⲂⲚⲰⲞⲨⲒ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲞⲨⲦⲀⲖⲈ ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲚⲦⲞⲨⲚⲀϨⲘⲈϤ ϢⲀ ⲪⲨⲖⲒⲜ ⲠⲒϨⲎⲄⲈⲘⲰⲚ.
25 Ó sì kọ ìwé kan báyìí pé,
ⲕ̅ⲉ̅ⲀϤⲤϦⲀⲒ ⲆⲈ ⲚⲞⲨⲈⲠⲒⲤⲦⲞⲖⲎ ⲈⲞⲨⲞⲚ ⲚⲦⲀⲤ ⲘⲘⲀⲨ ⲚⲞⲨⲦⲨⲠⲞⲤ ⲘⲠⲀⲒⲢⲎϮ.
26 Kilaudiu Lisia, sí Feliksi baálẹ̀ ọlọ́lá jùlọ, àlàáfíà.
ⲕ̅ⲋ̅ⲔⲖⲀⲨⲆⲒⲞⲤ ⲖⲨⲤⲒⲀ ⲘⲠⲒⲔⲢⲀⲦⲒⲤⲦⲞⲤ ⲚϨⲎⲄⲈⲘⲰⲚ ⲪⲨⲖⲒⲜ ⲬⲈⲢⲈ.
27 Àwọn Júù mú ọkùnrin yìí, wọ́n sì ń pète láti pa á, nígbà náà ni mo dé pẹ̀lú ogun, mo sì gbà á lọ́wọ́ wọn nígbà tí mo gbọ́ pé ará Romu ni í ṣe.
ⲕ̅ⲍ̅ⲠⲀⲒⲢⲰⲘⲒ ⲀⲨⲦⲀϨⲞϤ ⲚϪⲈⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲨⲘⲈⲨⲒ ⲈϦⲞⲐⲂⲈϤ ⲀⲒϢⲈ ⲚⲈⲘ ⲠⲒⲤⲦⲢⲀⲦⲈⲨⲘⲀ ⲀⲒⲚⲀϨⲘⲈϤ ⲈⲦⲀⲒⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲞⲨⲢⲰⲘⲈⲞⲤ ⲠⲈ
28 Nígbà tí mo sì ń fẹ́ mọ ìdí ọ̀ràn tí wọn fi ẹ̀sùn kàn án sí, mo mú un sọ̀kalẹ̀ lọ sí àjọ ìgbìmọ̀ wọn.
ⲕ̅ⲏ̅ⲈⲒⲞⲨⲰϢ ⲆⲈ ⲈⲈⲘⲒ ⲈϮⲖⲰⲒϪⲒ ⲈⲦⲞⲨϪⲈⲘ ⲀⲢⲒⲔⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲈⲐⲂⲎⲦⲤ ⲀⲒⲈⲚϤ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲞⲨⲘⲀⲚϮϨⲀⲠ.
29 Ẹni tí mo rí pé, wọ́n fi sùn nítorí ọ̀ràn òfin wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò dá ọ̀ràn ohun kan tí ó tọ́ sí ikú àti sí ẹ̀wọ̀n.
ⲕ̅ⲑ̅ⲪⲀⲒ ⲈⲦⲀⲒϪⲈⲘϤ ⲈⲨϪⲈⲘ ⲀⲢⲒⲔⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲈⲐⲂⲈ ϨⲀⲚⲌⲎⲦⲎⲘⲀ ⲚⲦⲈⲠⲞⲨⲚⲞⲘⲞⲤ ⲘⲠⲒϪⲈⲘ ⲚⲞⲂⲒ ⲆⲈ ⲚϦⲎⲦϤ ⲈϤⲘⲠϢⲀ ⲘⲪⲘⲞⲨ ⲒⲈ ϨⲀⲚⲤⲚⲀⲨϨ ⲚⲦⲈⲞⲨⲈⲄⲔⲖⲎⲘⲀ.
30 Nígbà tí a sì tí jí i sọ fún mi pé, wọn yóò dènà de ọkùnrin náà, mo rán an sí ọ lọ́gán, mo sì pàṣẹ fún àwọn olùfisùn rẹ̀ pẹ̀lú, láti sọ ohun tí wọ́n bá rí wí sí i níwájú rẹ̀.
ⲗ̅ⲈⲦⲀⲨⲦⲀⲘⲞⲒ ⲆⲈ ⲈⲐⲂⲈ ⲞⲨⲤⲞϬⲚⲒ ⲈϤϨⲰⲞⲨ ⲈϤⲚⲀϢⲰⲠⲒ ϦⲀ ⲠⲀⲒⲢⲰⲘⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦⲞⲨ ⲤⲀⲦⲞⲦ ⲀⲒⲞⲨⲞⲢⲠϤ ϨⲀⲢⲞⲔ ⲈⲀⲒϨⲞⲚϨⲈⲚ ⲈⲦⲞⲦⲞⲨ ⲚⲚⲈϤⲔⲀⲦⲎⲄⲞⲢⲞⲤ ⲈⲐⲢⲞⲨⲤⲀϪⲒ ⲚⲀϨⲢⲀⲔ.
31 Nígbà náà ni àwọn ọmọ-ogun gbe Paulu, wọ́n sì mú un lóru lọ si Antipatrisi, gẹ́gẹ́ bí a tí pàṣẹ fún wọn.
ⲗ̅ⲁ̅ⲚⲒⲘⲀⲦⲞⲒ ⲘⲈⲚ ⲞⲨⲚ ⲔⲀⲦⲀ ⲠⲈⲦⲀⲨⲐⲀϢ ⲚⲰⲞⲨ ⲀⲨⲰⲖⲒ ⲘⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲚϪⲰⲢϨ ⲈⲀⲨⲈⲚϤ ⲈⲀⲚⲦⲒⲠⲀⲦⲢⲒⲤ.
32 Ní ọjọ́ kejì wọ́n sì fi àwọn ẹlẹ́ṣin sílẹ̀ láti máa bá a lọ, àwọn sì padà wá sínú àgọ́ àwọn ológun.
ⲗ̅ⲃ̅ⲠⲈϤⲢⲀⲤϮ ⲆⲈ ⲀⲨⲬⲰ ⲚⲚⲒϨⲒⲠⲈⲨⲤ ⲈⲐⲢⲞⲨϢⲈ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲀⲨⲔⲞⲦⲞⲨ ⲈϮⲠⲀⲢⲈⲘⲂⲞⲖⲎ.
33 Nígbà tí wọ́n dé Kesarea, tí wọ́n sí fi ìwé fún baálẹ̀, wọ́n mú Paulu pẹ̀lú wá síwájú rẹ̀.
ⲗ̅ⲅ̅ⲚⲀⲒ ⲆⲈ ⲈⲦⲀⲨⲒ ⲈⲔⲈⲤⲀⲢⲒⲀ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨϮ ⲚϮⲈⲠⲒⲤⲦⲞⲖⲎ ⲘⲠⲒϨⲎⲄⲈⲘⲰⲚ ⲀⲨⲦⲀϨⲞ ⲘⲠⲔⲈⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲚⲀϨⲢⲀϤ.
34 Nígbà tí ó sì ti ka ìwé náà, ó béèrè pé agbègbè ìlú wo ni tirẹ̀. Nígbà tí ó sì gbọ́ pé ará Kilikia ni;
ⲗ̅ⲇ̅ⲈⲦⲀϤⲰϢ ⲆⲈ ⲚϮⲈⲠⲒⲤⲦⲞⲖⲎ ⲀϤϢⲒⲚⲒ ϪⲈ ⲞⲨⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲀϢ ⲚⲈⲠⲀⲢⲬⲒⲀ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲞⲨⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚϮⲔⲨⲖⲒⲔⲒⲀ ⲠⲈ.
35 Ó wí pé, “Èmi yóò gbọ́ ẹjọ́ rẹ, nígbà tí àwọn olùfisùn rẹ pẹ̀lú bá dé.” Ó sì pàṣẹ pé kí wọn pa Paulu mọ́ ní abẹ́ àbojútó àwọn olùṣọ́ ní gbọ̀ngàn ìdájọ́ ààfin Herodu.
ⲗ̅ⲉ̅ⲈⲒⲈⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲢⲞⲔ ⲠⲈϪⲀϤ ϨⲞⲦⲀⲚ ⲀⲨϢⲀⲚⲒ ⲚϪⲈⲚⲈⲔⲔⲀⲦⲎⲄⲞⲢⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲞⲨⲀϨⲤⲀϨⲚⲒ ⲈⲐⲢⲞⲨⲀⲢⲈϨ ⲈⲢⲞϤ ϦⲈⲚⲠⲒⲠⲢⲈⲦⲰⲢⲒⲞⲚ ⲚⲦⲈⲎⲢⲰⲆⲎⲤ.

< Acts 23 >