< Acts 22 >

1 “Ẹ̀yin ará àti baba, ẹ gbọ́ tí ẹnu mi nísinsin yìí.”
ⲁ̅ⲚⲒⲢⲰⲘⲒ ⲚⲒⲤⲚⲎⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲒⲒⲞϮ ⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲦⲀⲀⲠⲞⲖⲞⲄⲒⲀ ⲈⲦⲈ ⲚⲦⲎⲒ ϢⲀⲢⲰⲦⲈⲚ ϮⲚⲞⲨ.
2 Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ pé ó ń bá wọn sọ̀rọ̀ ni èdè Aramaiki, wọ́n túbọ̀ dákẹ́ jẹ́ẹ́. Nígbà náà ni ó wí pé,
ⲃ̅ⲈⲦⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲆⲈ ϪⲈ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚⲰⲞⲨ ϦⲈⲚϮⲀⲤⲠⲒ ⲘⲘⲈⲦϨⲈⲂⲢⲈⲞⲤ ⲘⲀⲖⲖⲞⲚ ⲆⲈ ⲀⲨⲬⲀⲢⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ
3 “Júù ni èmi í ṣe, a bí mi ni Tarsu ìlú kan ní Kilikia, ṣùgbọ́n tí a tọ́ mi dàgbà ni ìlú yìí. Ní abẹ́ ẹsẹ̀ Gamalieli ni a sì gbé kọ́ mi ní òfin àwọn baba wa, tí mo sì ní ìtara fún Ọlọ́run àní gẹ́gẹ́ bí gbogbo yin tí rí ni òní.
ⲅ̅ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲘⲈⲚ ⲀⲚⲞⲔ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲚⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲀⲨⲘⲀⲤⲦ ϦⲈⲚⲦⲀⲢⲤⲞⲤ ⲚⲦⲈϮⲔⲨⲖⲒⲔⲒⲀ ⲈⲀⲨϢⲀⲚⲞⲨϢⲦ ϦⲈⲚⲦⲀⲒⲠⲞⲖⲒⲤ ϦⲀⲦⲈⲚ ⲚⲈⲚϬⲀⲖⲀⲨϪ ⲚⲄⲀⲘⲀⲖⲒⲎⲖ ⲪⲀⲒ ⲈⲦⲀϤⲦⲤⲀⲂⲞⲒ ⲈⲠⲦⲀϪⲢⲞ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲘⲞⲤ ⲚⲦⲈⲚⲈⲚⲒⲞϮ ⲈⲒⲞⲒ ⲚⲢⲈϤⲬⲞϨ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ϨⲰⲦⲈⲚ ⲈⲦⲈⲦⲈⲚⲞⲒ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲘⲪⲞⲞⲨ.
4 Mo sì ṣe inúnibíni sí àwọn ènìyàn tí ń tọ ọ̀nà yìí dé ojú ikú wọn, mo dè tọkùnrin tobìnrin wọ́n, mo sì fi wọ́n sínú túbú,
ⲇ̅ⲈⲀⲒϬⲞϪⲒ ⲚⲤⲀⲠⲀⲒⲘⲰⲒⲦ ϢⲀ ⲈϦⲢⲎⲒ ⲈⲪⲘⲞⲨ ⲈⲒⲤⲰⲚϨ ⲚϨⲀⲚⲢⲰⲘⲒ ⲚⲈⲘ ϨⲀⲚϨⲒⲞⲘⲒ ⲈⲒϨⲒⲞⲨⲒ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲈⲠϢⲦⲈⲔⲞ.
5 àní bí olórí àlùfáà pẹ̀lú gbogbo àjọ àwọn alàgbà tí lè jẹ́ mi ní ẹ̀rí. Mo tilẹ̀ gba ìwé àṣẹ lọ́wọ́ wọn lọ sọ́dọ̀ àwọn arákùnrin wọn ní Damasku láti mú àwọn tí ó wà níbẹ̀ ní dídè wá sí Jerusalẹmu, láti jẹ wọ́n ní yà.
ⲉ̅ⲘⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲈ ⲠⲒⲀⲢⲬⲒⲈⲢⲈⲨⲤ ⲞⲒ ⲘⲘⲈⲐⲢⲈ ⲚⲎⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲠⲢⲈⲤⲂⲨⲦⲈⲢⲞⲤ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲚⲎ ⲈⲦⲀⲒϬⲒ ⲈⲠⲒⲤⲦⲞⲖⲎ ⲚⲦⲞⲦⲞⲨ ϢⲀ ⲚⲒⲤⲚⲎⲞⲨ ⲚⲀⲒⲚⲀ ⲆⲈ ⲈⲆⲀⲘⲀⲤⲔⲞⲤ ⲈⲒⲚⲒ ⲚⲚⲒⲔⲈⲬⲰⲞⲨⲚⲒ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲈⲨⲤⲞⲚϨ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲒⲈⲢⲞⲤⲀⲖⲎⲘ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲤⲈϮⲘⲔⲀϨ ⲚⲰⲞⲨ.
6 “Bí èmi tí súnmọ́ etí Damasku níwọ̀n ọjọ́-kanrí, lójijì ìmọ́lẹ̀ ńlá láti ọ̀run wá mọ́lẹ̀ yí mi ká.
ⲋ̅ⲀⲤϢⲰⲠⲒ ⲆⲈ ⲘⲘⲞⲒ ⲈⲒⲘⲞϢⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲒϦⲰⲚⲦ ⲈⲆⲀⲘⲀⲤⲔⲞⲤ ⲘⲠⲔⲰϮ ⲘⲘⲈⲢⲒ ⲚⲞⲨϨⲞϮ ϦⲈⲚⲞⲨϨⲞϮ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰⲒⲚⲒ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲰⲒ ⲚϪⲈⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚⲞⲨⲰⲒⲚⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲦⲪⲈ.
7 Mo sì ṣubú lulẹ̀, mo sì gbọ́ ohùn kan tí ó wí fún mi pé, ‘Saulu, Saulu èéṣe tí ìwọ fi ń ṣe inúnibíni sí mi?’
ⲍ̅ⲀⲒϨⲈⲒ ⲆⲈ ⲈⲠⲈⲤⲎⲦ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲒⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲞⲨⲤⲘⲎ ⲈⲤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲎⲒ ϪⲈ ⲤⲀⲞⲨⲖ ⲤⲀⲞⲨⲖ ⲀϦⲞⲔ ⲔϬⲞϪⲒ ⲚⲤⲰⲒ.
8 “Mo sì béèrè pé, ‘Ta ni ìwọ, Olúwa?’ “Ó sì dá mi lóhùn pé, ‘Èmi ni Jesu tí Nasareti, ẹni tí ìwọ ń ṣe inúnibíni sí.’
ⲏ̅ⲀⲚⲞⲔ ⲆⲈ ⲀⲒⲈⲢⲞⲨⲰ ϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲚⲒⲘ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲆⲈ ⲚⲎⲒ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲠⲈ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲒⲚⲀⲌⲰⲢⲈⲞⲤ ⲪⲎ ⲚⲐⲞⲔ ⲈⲦⲈⲔϬⲞϪⲒ ⲚⲤⲰϤ.
9 Àwọn tí ó sì wà pẹ̀lú mi rí ìmọ́lẹ̀ náà nítòótọ́, ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ ohùn ẹni tí ń bá mi sọ̀rọ̀.
ⲑ̅ⲚⲎ ⲆⲈ ⲈⲚⲀⲨⲚⲈⲘⲎⲒ ⲚⲀⲨⲚⲀⲨ ⲘⲈⲚ ⲈⲠⲒⲞⲨⲰⲒⲚⲒ ⲘⲠⲞⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲆⲈ ⲈⲦⲤⲘⲎ ⲘⲠⲈⲦⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘⲎⲒ.
10 “Mo sí béèrè pé, ‘Kín ni kí èmí kí ó ṣe, Olúwa?’ “Olúwa sì wí fún mi pé, ‘Dìde, kí o sì lọ sí Damasku; níbẹ̀ ni a ó sì ti sọ ohun gbogbo fún ọ tí a yàn fún ọ láti ṣe.’
ⲓ̅ⲠⲈϪⲎⲒ ⲆⲈ ϪⲈ ⲞⲨ ⲠⲈϮⲚⲀⲀⲒϤ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲎⲒ ϪⲈ ⲦⲰⲚⲔ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲀⲔ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲆⲀⲘⲀⲤⲔⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲤⲈⲚⲀⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘⲀⲔ ⲘⲘⲀⲨ ⲈⲐⲂⲈ ϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦⲀⲨⲐⲀϢⲞⲨ ⲚⲀⲔ ⲈⲐⲢⲈⲔⲀⲒⲦⲞⲨ.
11 Àwọn tí ó sì wà pẹ̀lú mi fà mí lọ́wọ́ wọ Damasku lọ nítorí tí èmi kò lè ríran nítorí ìtànṣán ìmọ́lẹ̀ náà ti fọ́ mi ní ojú.
ⲓ̅ⲁ̅ⲀⲤϢⲰⲠⲒ ⲆⲈ ⲚϮⲚⲀⲨ ⲘⲂⲞⲖ ⲀⲚ ⲚⲦⲈⲚ ⲠⲰⲞⲨ ⲘⲠⲒⲞⲨⲰⲒⲚⲒ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲀⲨⲀⲘⲞⲚⲒ ⲆⲈ ⲚⲦⲀϪⲒϪ ⲚϪⲈⲚⲎ ⲈⲐⲚⲈⲘⲎⲒ ⲀⲒⲒ ⲈⲆⲀⲘⲀⲤⲔⲞⲤ.
12 “Ọkùnrin kan tí a ń pè ní Anania tọ̀ mí wá, ẹni tó jẹ́ olùfọkànsìn ti òfin, tí ó sì lórúkọ rere lọ́dọ̀ gbogbo àwọn Júù tí ó ń gbé ibẹ̀.
ⲓ̅ⲃ̅ⲞⲨⲀⲒ ⲆⲈ ϪⲈ ⲀⲚⲀⲚⲒⲀⲤ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲈϤⲈⲢϨⲞϮ ⲔⲀⲦⲀ ⲠⲒⲚⲞⲘⲞⲤ ⲈⲨⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ϦⲀⲢⲞϤ ⲚϪⲈⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲈⲦϢⲞⲠ ⲘⲘⲀⲨ.
13 Ó sì dúró tì mí, ó sì wí fún mi pé, ‘Arákùnrin Saulu, gba ìríran!’ Ní ẹsẹ̀ kan náà, mo sì ṣí ojú sí òkè mo sì lè rí i.
ⲓ̅ⲅ̅ⲈⲦⲀϤⲒ ⲆⲈ ϢⲀⲢⲞⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦϤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲎⲒ ϪⲈ ⲤⲀⲞⲨⲖ ⲠⲀⲤⲞⲚ ⲀⲚⲀⲨ ⲘⲂⲞⲖ ⲀⲚⲞⲔ ⲆⲈ ϨⲰ ϦⲈⲚϮⲞⲨⲚⲞⲨ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲀⲒⲤⲞⲘⲤ ⲈⲢⲞϤ.
14 “Nígbà náà ni ó wí pé: ‘Ọlọ́run àwọn baba wa ti yàn ọ́ láti mọ ìfẹ́ rẹ̀, àti láti ri Ẹni òdodo náà, àti láti gbọ́ ọ̀rọ̀ láti ẹnu rẹ̀.
ⲓ̅ⲇ̅ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲚⲦⲈⲚⲈⲚⲒⲞϮ ⲀϤⲈⲢϢⲞⲢⲠ ⲚⲤⲰⲦⲠⲔ ⲈⲈⲘⲒ ⲈⲠⲈⲦⲈϨⲚⲀϤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲚⲀⲨ ⲈⲠⲒⲐⲘⲎⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲞⲨⲤⲘⲎ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲢⲰϤ.
15 Ìwọ yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí rẹ̀ fún gbogbo ènìyàn, nínú ohun tí ìwọ tí rí tí ìwọ sì ti gbọ́.
ⲓ̅ⲉ̅ϪⲈ ⲬⲚⲀϢⲰⲠⲒ ⲚⲀϤ ⲘⲘⲈⲐⲢⲈ ϦⲀⲦⲈⲚ ⲢⲰⲘⲒ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲐⲂⲈ ⲚⲎ ⲈⲦⲀⲔⲚⲀⲨ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲔⲤⲞⲐⲘⲞⲨ.
16 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, kín ni ìwọ ń dúró dè? Dìde, kí a sì bamitiisi rẹ̀, kí ó sì wẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nù, kí ó sì máa pe orúkọ rẹ̀.’
ⲓ̅ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ϮⲚⲞⲨ ⲞⲨ ⲠⲈⲦⲈⲔⲚⲀⲀⲒϤ ⲦⲰⲚⲔ ϬⲒⲰⲘⲤ ⲞⲨⲞϨ ϪⲞⲔⲘⲈⲔ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲈⲔⲚⲞⲂⲒ ⲈⲔⲦⲰⲂϨ ⲘⲠⲈϤⲢⲀⲚ.
17 “Nígbà tí mo padà wá sí Jerusalẹmu tí mo ǹ gbàdúrà ní tẹmpili, mo bọ́ sí ojúran,
ⲓ̅ⲍ̅ⲀⲤϢⲰⲠⲒ ⲆⲈ ⲈⲦⲀⲒⲔⲞⲦⲦ ⲈⲒⲈⲢⲞⲤⲀⲖⲎⲘ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲒⲈⲢⲠⲢⲞⲤⲈⲨⲬⲈⲤⲐⲈ ϦⲈⲚⲠⲒⲈⲢⲪⲈⲒ ⲀⲒϢⲰⲠⲒ ϦⲈⲚⲞⲨⲦⲰⲘⲦ.
18 mo sì rí Olúwa, ó ń sọ̀rọ̀ fún mi pé, ‘Kíá! Jáde kúrò ní Jerusalẹmu kánkán, nítorí wọn kì yóò gba ẹ̀rí rẹ nípa mi gbọ́.’
ⲓ̅ⲏ̅ⲀⲒⲚⲀⲨ ⲈⲢⲞϤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲎⲒ ϪⲈ ⲀⲘⲞⲨ ⲚⲬⲰⲖⲈⲘ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲒⲈⲢⲞⲤⲀⲖⲎⲘ ϪⲈ ⲞⲨⲎⲒ ⲤⲈⲚⲀϬⲒ ⲘⲈⲦⲘⲈⲐⲢⲈ ⲚⲦⲞⲦⲔ ⲀⲚ ⲈⲐⲂⲎⲦ.
19 “Èmi sì wí pé, ‘Olúwa, àwọn ènìyàn wọ̀nyí pàápàá mọ̀ pé èmi ti lọ láti inú Sinagọgu kan sí èkejì láti máa sọ wọ́n sínú túbú àti láti máa lu àwọn tí ó gbà ọ́ gbọ́.
ⲓ̅ⲑ̅ⲀⲚⲞⲔ ϨⲰ ⲠⲈϪⲎⲒ ϪⲈ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲚⲐⲰⲞⲨ ⲤⲈⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲚⲀⲒϨⲒⲞⲨⲒ ⲈⲠϢⲦⲈⲔⲞ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲒϨⲒⲞⲨⲒ ⲔⲀⲦⲀ ⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲎ ⲚⲚⲎ ⲈⲐⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞⲔ.
20 Nígbà tí a sì ta ẹ̀jẹ̀ Stefanu ẹlẹ́rìí rẹ sílẹ̀, èmi náà pẹ̀lú dúró níbẹ̀, mo sì ní ohùn sí ikú rẹ̀, mo sì ń ṣe ìtọ́jú aṣọ àwọn ẹni tí ó pa á.’
ⲕ̅ⲞⲨⲞϨ ϨⲞⲦⲈ ⲈⲨⲚⲀⲪⲰⲚ ⲈⲂⲞⲖ ⲘⲠⲤⲚⲞϤ ⲚⲤⲦⲈⲪⲀⲚⲞⲤ ⲠⲈⲔⲘⲀⲢⲦⲨⲢⲞⲤ ⲀⲚⲞⲔ ϨⲰ ⲚⲀⲒⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦ ⲈⲒϮⲘⲀϮ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲒⲀⲢⲈϨ ⲈⲚⲒϨⲂⲰⲤ ⲚⲦⲈⲚⲎ ⲈⲚⲀⲨϦⲰⲦⲈⲂ ⲘⲘⲞϤ.
21 “Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, ‘Máa lọ; nítorí èmi ó rán ọ sí àwọn aláìkọlà lókèèrè réré.’”
ⲕ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲎⲒ ϪⲈ ⲘⲞϢⲒ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ϮⲚⲀⲞⲨⲞⲢⲠⲔ ⲈϨⲀⲚⲈⲐⲚⲞⲤ ⲈⲨⲞⲨⲎⲞⲨ.
22 Wọ́n sì fi etí sí ọ̀rọ̀ Paulu títí tí ó fi sọ ọ̀rọ̀ yìí. Nígbà yìí ni wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì kígbe wí pé, “Ẹ mu ẹni yìí kúrò láyé! Kò yẹ kí ó wà láààyè!”
ⲕ̅ⲃ̅ⲚⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲆⲈ ⲈⲢⲞϤ ϢⲀ ⲠⲀⲒⲤⲀϪⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϬⲒⲤⲒ ⲚⲦⲞⲨⲤⲘⲎ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲀⲖⲒ ⲪⲀⲒ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒϪⲈⲚ ⲠⲔⲀϨⲒ ⲞⲨ ⲄⲀⲢ ϤⲈⲘⲠϢⲀ ⲚⲰⲚϦ ⲀⲚ.
23 Bí wọ́n sì ti ń kígbe, tí wọ́n sì ń jú aṣọ wọn káàkiri, tí wọ́n ń ku eruku sí ojú ọ̀run,
ⲕ̅ⲅ̅ⲈⲨⲰϢ ⲆⲈ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲨⲤⲒϮ ⲚⲚⲞⲨϨⲂⲰⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲨⲤⲈⲦ ϢⲰⲒϢ ⲈⲠⲒⲀⲎⲢ.
24 olórí ogun pàṣẹ pé kí a mú Paulu wá sínú àgọ́ àwọn ológun. Ó sì pàṣẹ kí wọ́n ó lù ú, kí wọn fi ọ̀rọ̀ wa lẹ́nu wò, kí òun ba à lè mọ ìdí tí wọ́n fi ń kígbe lé e lórí bẹ́ẹ̀.
ⲕ̅ⲇ̅ⲀϤⲈⲢⲔⲈⲖⲈⲨⲒⲚ ⲚϪⲈⲠⲒⲬⲒⲖⲒⲀⲢⲬⲞⲤ ⲈⲐⲢⲞⲨϬⲒⲦϤ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈϮⲠⲀⲢⲈⲘⲂⲞⲖⲎ ⲈⲀϤϪⲞⲤ ⲈⲐⲢⲞⲨϮⲘⲔⲀϨ ⲚⲀϤ ϦⲈⲚϨⲀⲚⲘⲀⲤⲦⲒⲄⲜ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϤⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲚⲖⲰⲒϪⲒ ⲤⲈⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ ⲘⲠⲀⲒⲢⲎϮ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲰϤ.
25 Bí wọ́n sí tí fi ọṣán dè é, Paulu bí balógun ọ̀rún tí ó dúró tì í pé, “Ó ha tọ́ fún yín láti na ẹni tí i ṣe ará Romu ni àìdálẹ́bi bí?”
ⲕ̅ⲉ̅ϨⲞⲦⲈ ⲆⲈ ⲈⲦⲀⲨϬⲞⲖⲔϤ ϦⲈⲚⲚⲒϦⲰⲔ ⲠⲈϪⲈ ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲘⲠⲒⲈⲔⲀⲦⲞⲚⲦⲀⲢⲬⲞⲤ ⲈⲚⲀϤⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦϤ ϪⲈ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲚⲢⲰⲘⲈⲞⲤ ⲚϤⲈⲢ ⲠⲔⲈϨⲰⲞⲨⲒ ⲘⲠϨⲀⲠ ⲀⲚ ⲠⲈⲦⲤϢⲈ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲠⲈ ⲈⲈⲢⲘⲀⲤⲦⲒⲄⲄⲞⲒⲚ ⲘⲘⲞϤ.
26 Nígbà tí balógun ọ̀rún sì gbọ́ èyí, ó lọ wí fún olórí ogun pé, “Kín ni ó fẹ́ ṣe yìí: nítorí ọkùnrin yìí ará Romu ní i ṣe?”
ⲕ̅ⲋ̅ⲈⲦⲀϤⲤⲰⲦⲈⲘ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲠⲒⲈⲔⲀⲦⲞⲚⲦⲀⲢⲬ ⲞⲤ ⲀϤϢⲈ ϢⲀ ⲠⲒⲬⲒⲖⲒⲀⲢⲬⲞⲤ ⲀϤⲦⲀⲘⲞϤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲞⲨ ⲠⲈⲦⲈⲔⲚⲀⲀⲒϤ ⲠⲒⲢⲰⲘⲒ ⲄⲀⲢ ⲞⲨⲢⲰⲘⲈⲞⲤ ⲠⲈ.
27 Alábojútó-ogun sì dé, ó sì bí Paulu pé, “Sọ fún mi, ará Romu ni ìwọ jẹ́ bí?” Ó sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni.”
ⲕ̅ⲍ̅ⲀϤⲒ ⲆⲈ ϢⲀⲢⲞϤ ⲚϪⲈⲠⲒⲬⲒⲖⲒⲀⲢⲬⲞⲤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲀϪⲞⲤ ⲚⲎⲒ ϪⲈ ⲚⲐⲞⲔ ⲞⲨⲢⲰⲘⲈⲞⲤ ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲀϨⲀ.
28 Alábojútó-ogun sì dáhùn wí pé, “Owó púpọ̀ ni mo fi ra ọlá ìbílẹ̀ yìí.” Paulu wí pé, “Ṣùgbọ́n a bí mi sínú rẹ̀ ni.”
ⲕ̅ⲏ̅ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲚϪⲈⲠⲒⲬⲒⲖⲒⲀⲢⲬⲞⲤ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲀⲒϢⲰⲠ ⲚⲦⲀⲒⲠⲞⲖⲎⲦⲒⲀ ⲚⲎⲒ ϦⲀ ⲞⲨⲘⲎ ϢⲚⲔⲈⲪⲀⲖⲈⲞⲚ ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲈⲦⲀⲨⲘⲀⲤⲦ ⲚϦⲎⲦⲤ.
29 Nítorí náà àwọn tí ó múra láti fi ọ̀rọ̀ wa lẹ́nu wò fàsẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀: lójúkan náà. Olórí ogun pẹ̀lú sì bẹ̀rù nígbà tí ó mọ̀ pé ọmọ ìbílẹ̀ Romu ní Paulu i ṣe, àti nítorí ó tí dè é.
ⲕ̅ⲑ̅ⲤⲀⲦⲞⲦⲞⲨ ⲞⲨⲚ ⲀⲨϨⲈⲚⲞⲨ ⲤⲀⲂⲞⲖ ⲘⲘⲞϤ ⲚϪⲈⲚⲎ ⲈⲦϮⲘⲔⲀϨ ⲚⲀϤ ⲞⲨⲞϨ Ⲁ- ⲠⲒⲬⲒⲖⲒⲀⲢⲬⲞⲤ ⲈⲢϨⲞϮ ⲈⲦⲀϤⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲞⲨⲢⲰⲘⲈⲞⲤ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ϪⲈ ⲀϤⲤⲞⲚϨϤ.
30 Ní ọjọ́ kejì, nítorí tí olórí ogun fẹ́ mọ̀ dájúdájú ohun tí àwọn Júù ń fi Paulu sùn sí, ó tú u sílẹ̀, ó pàṣẹ kí àwọn olórí àlùfáà àti gbogbo ìgbìmọ̀ péjọ, nígbà náà ni ó mú Paulu sọ̀kalẹ̀, ó sì mú un dúró níwájú wọn.
ⲗ̅ⲠⲈϤⲢⲀⲤϮ ⲆⲈ ⲈϤⲞⲨⲰϢ ⲈⲈⲘⲒ ⲈⲠⲒⲦⲀϪⲢⲞ ϪⲈ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲀⲨⲈⲢⲔⲀⲦⲎⲄⲞⲢⲒⲚ ⲈⲢⲞϤ ⲚϪⲈⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲀϤⲂⲞⲖϤ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲞⲨⲀϨⲤⲀϨⲚⲒ ⲈⲐⲢⲞⲨⲒ ⲚϪⲈⲚⲒⲀⲢⲬⲒⲈⲢⲈⲨⲤ ⲚⲈⲘ ⲠⲒⲘⲀ ⲚϮϨⲀⲠ ⲦⲎⲢϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲈⲚ ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲈⲠⲈⲤⲎⲦ ⲀϤⲦⲀϨⲞϤ ⲈⲢⲀⲦϤ ⲚϦⲎⲦⲞⲨ.

< Acts 22 >