< 2 Timothy 3 >
1 Ṣùgbọ́n èyí ni kí o mọ̀ pé, ní ìkẹyìn ọjọ́ ìgbà ewu yóò dé.
ⲁ̅ⲫⲁⲓ ⲇⲉ ⲁⲣⲓ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϫⲉ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲛϧⲁ⳿ⲉ ⲉⲩ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛⲥⲏⲟⲩ ⳿ⲛϩⲱⲟⲩ.
2 Nítorí àwọn ènìyàn yóò jẹ́ olùfẹ́ ti ara wọn, olùfẹ́ owó, afọ́nnu, agbéraga, asọ̀rọ̀ búburú, aṣàìgbọràn sí òbí, aláìlọ́pẹ́, aláìmọ́.
ⲃ̅ⲉⲩ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲉⲩⲙⲉⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲁⲩⲁⲧⲟⲩ ⲉⲩⲟⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲓϩⲁⲧ ⳿ⲛⲉⲥⲓⲉ ⳿ⲛϭⲁⲥⲓϧⲏⲧ ⳿ⲛⲣⲉϥϫⲉⲟⲩ⳿ⲁ ⳿ⲛⲁⲧⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲛⲥⲁ ⲛⲟⲩⲓⲟϯ ⳿ⲛⲁⲧ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲁⲧⲧⲟⲩⲃⲟ.
3 Aláìnífẹ̀ẹ́, aláìlèdáríjì, abanijẹ́, aláìlè-kó-aràwọn-níjánu, òǹrorò, aláìnífẹ̀ẹ́ ohun rere,
ⲅ̅⳿ⲛⲁⲧϣⲉⲛϩⲏⲧ ⳿ⲛⲁⲧⲥⲉⲙⲛⲓ ⳿ⲛⲇⲓ⳿ⲁⲃⲟⲗⲟⲥ ⳿ⲛⲁⲧ⳿ϣ⳿ⲁⲙⲟⲛⲓ ⳿ⲛⲧⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲥⲉϣⲉⲡ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲁⲛ ⳿ⲛⲥⲉⲙⲉⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲡⲉⲑⲛⲁⲛⲉϥ ⲁⲛ.
4 oníkúpani, alágídí, ọlọ́kàn gíga, olùfẹ́ fàájì ju olùfẹ́ Ọlọ́run lọ.
ⲇ̅ⲉⲩⲟⲓ ⳿ⲙ⳿ⲡⲣⲟⲇⲟⲧⲏⲥ ⲉⲩⲁⲥⲓⲱⲟⲩ ⳿ⲛϭⲁⲥⲓⲛⲁϩⲃⲓ ⲉⲩⲟⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲓϩⲩⲇⲟⲛⲏ ⲙⲁⲗⲗⲟⲛ ⳿ⲉϩⲟⲧⲉ ⲙⲁⲓⲛⲟⲩϯ.
5 Àwọn tí wọn ní àfarawé ìwà-bí-Ọlọ́run, ṣùgbọ́n tí wọn sẹ́ agbára rẹ̀; yẹra kúrò lọ́dọ̀ àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú.
ⲉ̅ⲉⲣⲉ ⳿ⲡ⳿ⲥⲙⲟⲧ ⳿ⲛϯⲙⲉⲧⲉⲩⲥⲉⲃⲏⲥ ⳿ⲛⲧⲟⲧⲟⲩ ⲧⲉⲥϫⲟⲙ ⲇⲉ ⲉⲩϫⲱⲗ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲛⲁⲓⲕⲉ ⲭⲱⲟⲩⲛⲓ ⲇⲉ ϩⲉⲛⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ.
6 Nítorí nínú irú èyí ni àwọn ti ń rákò wọ inú ilé, tí wọ́n sì ń di àwọn obìnrin aláìlọ́gbọ́n tí a di ẹ̀ṣẹ̀ rù ní ìgbèkùn, tí a sì ń fi onírúurú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ fà kiri.
ⲋ̅⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲇⲉ ϧⲉⲛ ⲛⲁⲓ ⲛⲉ ⲛⲏ ⳿ⲉϣⲁⲩⲟⲙⲥⲟⲩ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲛⲓⲏⲓ ⲉⲩⲉⲣⲉⲭⲙⲁⲗⲱⲧⲉⲩⲓⲛ ⳿ⲛϩⲁⲛϩⲓ⳿ⲟⲙⲓ ⲉⲩⲙⲉϩ ⳿ⲛⲛⲟⲃⲓ ⲉⲩ⳿ⲓⲛⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛ⳿ⲉⲡⲓⲑⲩⲙⲓⲁ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛⲣⲏϯ.
7 Wọ́n ń fi ìgbà gbogbo kẹ́kọ̀ọ́, wọ́n kò sì lè dé ojú ìmọ̀ òtítọ́.
ⲍ̅ⲉⲩϭⲓ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲛⲥⲏⲟⲩ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲥⲉ⳿ϣϫⲉⲙϫⲟⲙ ⲁⲛ ⲉⲛⲉϩ ⳿ⲉ⳿ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉ⳿ⲡⲥⲟⲩⲉⲛ ϯⲙⲉⲑⲙⲏⲓ.
8 Ǹjẹ́ gẹ́gẹ́ bí Janesi àti Jamberi ti kọ ojú ìjà sí Mose náà ni wọ́n kọjú ìjà sí òtítọ́: àwọn ènìyàn tí inú wọn díbàjẹ́, àwọn ẹni ìtanù ní ti ọ̀ràn ìgbàgbọ́.
ⲏ̅⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲇⲉ ⳿ⲛⲓⲁⲛⲛⲏⲥ ⲛⲉⲙ ⲓⲁⲙⲃⲣⲏⲥ ⲉⲧⲁⲩϯ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲉⲛ ⲙⲱ⳿ⲩⲥⲏⲥ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ϩⲱⲟⲩ ⲛⲁⲓⲕⲉⲭⲱⲟⲩⲛⲓ ⲥⲉϯ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲉⲛ ϯⲙⲉⲑⲙⲏⲓ ϩⲁⲛⲣⲱⲙⲓ ⲉⲣⲉ ⲡⲟⲩϩⲏⲧ ⲧⲁⲕⲏⲟⲩⲧ ⲉⲩⲟⲓ ⳿ⲛⲁⲇⲟⲕⲓⲙⲟⲥ ⳿ⲙ⳿ⲡⲕⲱϯ ⳿ⲙⲡⲓⲛⲁϩϯ.
9 Ṣùgbọ́n wọn kì yóò lọ síwájú ju bẹ́ẹ̀ lọ, nítorí òmùgọ̀ wọn yóò farahàn fún gbogbo ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ti àwọn méjì yìí náà, ti yọrí si.
ⲑ̅ⲁⲗⲗⲁ ⲥⲉⲛⲁⲉⲣ⳿ⲡⲣⲟⲕⲟⲡⲧⲓⲛ ⲁⲛ ⲉⲩⲙⲉⲧϩⲟⲩ⳿ⲟ ⲧⲟⲩⲙⲉⲧⲁⲧ⳿ⲉⲙⲓ ⲅⲁⲣ ⳿ⲥⲛⲁϣⲱⲡⲓ ⲉⲥⲟⲩⲟⲛϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛⲑⲁ ⲛⲓⲕⲉⲭⲱⲟⲩⲛⲓ ⲉⲧⲁⲥϣⲱⲡⲓ.
10 Ṣùgbọ́n ìwọ ti mọ ẹ̀kọ́ mi, ìgbésí ayé mi, ìpinnu, ìgbàgbọ́, ìpamọ́ra, ìfẹ́ sùúrù.
ⲓ̅⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲇⲉ ⲁⲕⲙⲟϣⲓ ⳿ⲛⲥⲁ ⲧⲁⲙⲉⲧⲣⲉϥ ϯ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲛⲥⲁ ⲡⲁ⳿ⲥⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲥⲁ ⲡⲁϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛⲑⲱϣ ⲡⲁⲛⲁϩϯ ⲧⲁⲙⲉⲧⲣⲉϥⲱⲟⲩ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲧⲁⲁⲅⲁⲡⲏ ⲧⲁϩⲩⲡⲟⲙⲟⲛⲏ.
11 Inúnibíni, ìyà; àwọn ohun tí ó dé bá mi ní Antioku, ní Ikoniomu ní Lysra; àwọn inúnibíni tí mo faradà: Olúwa sì gbà mi kúrò nínú gbogbo wọn.
ⲓ̅ⲁ̅ⲛⲓⲇⲓⲱⲅⲙⲟⲥ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲛⲁⲓ⳿ⲙⲕⲁⲩϩ ⲛⲏⲉⲧⲁⲩϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲓ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲁⲛϯⲟⲭⲓⲁ ϧⲉⲛ ⲓⲕⲟⲛⲓⲟⲛ ϧⲉⲛ ⲗⲩⲥⲧⲣⲟⲓⲥ ⲛⲓⲇⲓⲱⲅⲙⲟⲥ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲉⲧⲁⲓϣⲟⲡⲟⲩ ⳿ⲉⲣⲟⲓ ⲁϥⲛⲁϩⲙⲉⲧ ⳿ⲛϫⲉ Ⲡ⳪ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϧⲏⲧⲟⲩ ⲧⲏⲣⲟⲩ.
12 Nítòótọ́, gbogbo àwọn tí ó fẹ́ máa gbé ìgbé ayé ìwà-bí-Ọlọ́run nínú Kristi Jesu yóò faradà inúnibíni.
ⲓ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟⲛ ⲇⲉ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲑⲟⲩⲱϣ ⳿ⲉⲱⲛϧ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲧⲉⲩⲥⲉⲃⲏⲥ ϧⲉⲛ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲥⲉⲛⲁ ϭⲟϫⲓ ⳿ⲛⲥⲱⲟⲩ.
13 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú, àti àwọn ẹlẹ́tàn yóò máa burú síwájú sí i, wọn ó máa tannijẹ, a ó sì máa tàn wọ́n jẹ.
ⲓ̅ⲅ̅ϩⲁⲛⲣⲱⲙⲓ ⲇⲉ ⲉⲩϩⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲣⲉϥⲥⲟⲡⲥⲉⲡ ⲉⲩ⳿ⲉ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ⲧϩⲏ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲡⲉⲧϩⲱⲟⲩ ⳿ⲛϩⲟⲩ⳿ⲟ ⲉⲩⲥⲱⲣⲉⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲩⲥⲟⲣⲉⲙ.
14 Ṣùgbọ́n ìwọ dúró nínú nǹkan wọ̀nyí tí ìwọ ti kọ́, tí a sì ti jẹ́ kí ojú rẹ dá ṣáṣá sí, kí ìwọ sì mọ̀ ọ̀dọ̀ ẹni tí ìwọ gbé kọ́ wọn.
ⲓ̅ⲇ̅⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲇⲉ ϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲏⲉⲧⲁⲕ⳿ⲧⲥⲁⲃⲟ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲕⲉⲣⲡⲓⲥⲧⲟⲥ ⳿ⲛϧⲏⲧⲟⲩ ⲉⲕ⳿ⲉⲙⲓ ϫⲉ ⲉⲧⲁⲕ⳿ⲧⲥⲁⲃⲟ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲛⲓⲙ.
15 Àti pé láti ìgbà ọmọdé ni ìwọ ti mọ Ìwé Mímọ́, tí ó lè sọ ọ́ di ọlọ́gbọ́n sí ìgbàlà nípasẹ̀ ìgbàgbọ́ nínú Kristi Jesu.
ⲓ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲓⲥϫⲉⲛ ⲉⲕⲟⲓ ⳿ⲛ⳿ⲁⲗⲟⲩ ϩⲁⲛ⳿ⲥϧⲁⲓ ⲉⲩⲟⲩⲁⲃ ⲉⲧⲉⲕⲥⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲛⲁⲓ ⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲉϯ⳿ⲥⲃⲱ ⲛⲁⲕ ⳿ⲉⲡⲓⲟⲩϫⲁⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲡⲓⲛⲁϩϯ ⲉⲧϧⲉⲛ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅.
16 Gbogbo ìwé mímọ́ ni ó ní ìmísí Ọlọ́run tí ó sì ní èrè fún ẹ̀kọ́, fún ìbániwí, fún ìtọ́ni, fún ìkọ́ni tí ó wà nínú òdodo.
ⲓ̅ⲋ̅⳿ⲅⲣⲁⲫⲏ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲛⲛⲓϥⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲥⲉⲟⲓ ⳿ⲛϩⲏⲟⲩ ⲉⲩ⳿ⲥⲃⲱ ⲉⲩⲥⲟϩⲓ ⲉⲩⲧⲁϩⲟ ⳿ⲉⲣⲁⲧϥ ⲉⲩ⳿ⲥⲃⲱ ⲑⲏ ⲉⲧϧⲉⲛ ϯⲇⲓⲕⲉⲟⲥⲩⲛⲏ.
17 Kí ènìyàn Ọlọ́run lè pé, tí a ti múra sílẹ̀ pátápátá fun iṣẹ́ rere gbogbo.
ⲓ̅ⲍ̅ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⳿ⲫⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲙⲫϯ ⲉϥⲥⲉⲃⲧⲱⲧ ⲟⲩⲟϩ ⲉϥⲧⲁϫⲣⲏⲟⲩⲧ ϧⲉⲛ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲑⲛⲁⲛⲉⲩ