< 2 Kings 7 >

1 Eliṣa wí pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ‘Ní àsìkò yìí ní ọ̀la, a ó ta òsùwọ̀n ìyẹ̀fun barle kíkúnná kan ní ṣékélì kan àti méjì òsùwọ̀n ọkà barle fún ṣékélì kan ní ẹnu-bodè Samaria.’”
És monda Elizeus: Halljátok meg az Úr beszédét. Ezt mondja az Úr: Holnap ilyenkor egy köböl zsemlyelisztet egy sikluson, és két köböl árpát egy sikluson vesznek Samaria kapujában.
2 Ìjòyè kan ẹni tí ọwọ́ ọba ń fi ara tì dáhùn wí fún ènìyàn Ọlọ́run pé, “Ẹ wò ó, tí Olúwa bá tilẹ̀ ṣí fèrèsé ọ̀run sílẹ̀, ṣé èyí lè rí bẹ́ẹ̀?” Eliṣa dáhùn pé, “Ìwọ yóò rí i pẹ̀lú ojú rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní jẹ nǹkan kan lára rẹ̀!”
És felelvén egy főember, a kinek kezére támaszkodott a király, az Isten emberének, monda: Hacsak az Úr ablakokat nem csinál az égen; akkor meglehet? És monda Elizeus: Ímé, te szemeiddel meg fogod látni, de nem eszel belőle.
3 Nísinsin yìí àwọn ọkùnrin mẹ́rin kan wà pẹ̀lú ẹ̀tẹ̀ ní ẹnu àbáwọlé ibodè ìlú. Wọ́n wí fún olúkúlùkù pé, “Kí ni ó dé tí àwa yóò fi jókòó síbí títí àwa yóò fi kú?
A kapu előtt pedig volt négy bélpoklos férfi, a kik mondák egymásnak: Miért maradunk itt, hogy meghaljunk éhen?
4 Tí àwa bá wí pé, ‘Àwa lọ sí ìlú, ìyàn wà níbẹ̀,’ àwa yóò sì kú. Tí àwa bá dúró níbí, a máa kú, ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ jẹ́ kí a lọ sí ibùdó ti àwọn ará Siria kí àwa kí ó sì tẹríba. Bí wọ́n bá dá wa sí, àwa yóò yè, tí wọ́n bá sì pa wá, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò kú.”
Ha azt határozzuk is, hogy bemegyünk a városba, ott is inség van, és akkor ott halunk meg; ha pedig itt maradunk, akkor itt halunk meg; jertek el azért, szökjünk el a Siriabeliek táborába, ha meghagyják életünket, élünk, ha megölnek, meghalunk.
5 Ní àfẹ̀mọ́júmọ́ wọ́n dìde wọ́n sì lọ sí ibùdó àwọn ará Siria. Nígbà tí wọ́n dé ẹ̀gbẹ́ ibùdó náà, kò sí ọkùnrin kan níbẹ̀,
És felkeltek alkonyatkor, hogy a Siriabeliek táborába menjenek; és mikor odaértek a Siriabeliek táborának széléhez, ímé már nem volt ott senki.
6 nítorí tí Olúwa jẹ́ kí àwọn ará Siria gbọ́ ìró kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin àti ogun ńlá, wọ́n sì wí fún ara wọn pé, “Ẹ wò ó, ọba Israẹli ti bẹ ogun àwọn Hiti àti àwọn ọba Ejibiti láti dojúkọ wá!”
Mert az Úr azt cselekedte volt, hogy a Siriabeliek tábora szekerek zörgését és lovak dobogását, és nagy sereg robogását hallotta, és mondának egymásnak: Ímé az Izráel királya bérbe fogadta meg ellenünk a Hitteusok királyit és az Égyiptombeliek királyit, hogy ellenünk jőjjenek.
7 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì dìde wọ́n sì sálọ ní àfẹ̀mọ́júmọ́ wọ́n sì fi àgọ́ wọn sílẹ̀ àti ẹṣin wọn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n sì fi ibùdó sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti wà, wọ́n sì sálọ fún ẹ̀mí wọn.
És felkelvén elfutának alkonyatkor, és elhagyák mind sátoraikat, mind lovaikat, mind szamaraikat, a mint a tábor volt, és elfutának, csakhogy életöket megmenthessék.
8 Nígbà tí àwọn ọkùnrin tí ó ní ààrùn ẹ̀tẹ̀ dé ẹ̀gbẹ́ ibùdó wọ́n sì wọ inú ọ̀kan nínú àgọ́ náà. Wọ́n jẹ wọ́n sì mu, wọ́n sì kó fàdákà, wúrà àti ẹ̀wù, wọ́n sì lọ. Wọ́n sì wọ àgọ́ mìíràn lọ, wọ́n kó àwọn nǹkan láti ibẹ̀ wọ́n sì kó wọn pamọ́ pẹ̀lú.
Mikor azért e bélpoklosok a tábor széléhez értek, bemenvén egy sátorba, evének és ivának, és elvivének onnét ezüstöt, aranyat és ruhákat, és elmenvén elrejték azokat; és megtérvén más sátorba menének be, és abból is hozának és elmenvén, elrejték.
9 Nígbà náà wọ́n wí fún ara wọn pé, “Àwa kò ṣe ohun rere. Òní yìí jẹ́ ọjọ́ ìròyìn rere àwa sì pa á mọ́ ara wa. Tí àwa bá dúró títí di àfẹ̀mọ́júmọ́, ìjìyà yóò jẹ́ ti wa. Ẹ jẹ́ kí a lọ ní ẹ̀ẹ̀kan kí a lọ ròyìn èyí fún àwọn ilé ọba.”
És monda egyik a másiknak: Nem igazán cselekszünk: ez a mai nap örömmondás napja, ha mi hallgatunk, és a virradatot megvárjuk, büntetés ér bennünket; most azért jertek és menjünk el, és mondjuk meg a király házának.
10 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì lọ wọ́n sì pe àwọn asọ́bodè ìlú, wọ́n sì wí fún wọn pé, “Àwa lọ sí ibùdó àwọn ará Siria kò sì sí ọkùnrin kankan níbẹ̀ tàbí ohùn ènìyàn kan àyàfi ẹṣin tí a so àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn àgọ́ náà sì wà gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti wà.”
És elmenének, és kiáltának a város kapuján állónak, és elbeszélék nékik, mondván: Odamentünk volt a Siriabeliek táborába, és ímé már nem volt ott senki; emberek szava nem hallatszott, csak a lovak és szamarak vannak kikötve, és a sátorok úgy, a mint voltak.
11 Àwọn aṣọ́bodè náà pariwo ìròyìn náà, wọ́n sì sọ nínú ààfin ọba.
Kiáltának azért a kapunállók, és hírré tevék ott benn a király házában.
12 Ọba sì dìde ní òru ó sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Èmi yóò sọ fún yín ohun tí àwọn ará Siria tí ṣe fún wa. Wọ́n mọ̀ wí pé ebi ń pa wá; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ti kúrò ni ibùdó láti sá pamọ́ sí ẹ̀gbẹ́ ilé, wọ́n rò wí pé, ‘Wọn yóò jáde lóòtítọ́, nígbà náà àwa yóò mú wọn ní ààyè, àwa yóò sì wọ inú ìlú lọ.’”
És felkele éjszaka a király, és monda az ő szolgáinak: Megmondom néktek, mit csinálnak velünk a Siriabeliek. Tudják, hogy éhen vagyunk, és csak azért mentek ki a táborból, hogy elrejtőzzenek a mezőn, mondván: Mikor kijönnek a városból, megfogjuk őket elevenen, és bemegyünk a városba.
13 Ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ dáhùn pé, “Èmí o bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí àwa kí ó mú márùn-ún nínú àwọn ẹṣin tí ó kù, nínú àwọn tí ó kù ní ìlú—kíyèsí i, wọ́n sá dàbí gbogbo àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ Israẹli tí ó kù nínú rẹ̀, kíyèsí i, àní bí gbogbo ènìyàn Israẹli tí a run, sí jẹ́ kí a rán wọn lọ láti lọ wo ohun tí ó ṣẹlẹ̀.”
Akkor felele egy az ő szolgái közül, és monda: Ki kell választani a megmaradt lovak közül, a melyek a városban megmaradtak, ötöt, – ímé épen olyanok ezek, mint Izráelnek egész sokasága, a mely megmaradt; ímé épen olyanok ezek, mint Izráel egész sokasága, a mely elpusztult, – és küldjük ki, hadd lássuk meg.
14 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yan kẹ̀kẹ́ méjì pẹ̀lú ẹṣin wọn, ọba sì ránṣẹ́ tọ ogun àwọn ará Siria lẹ́yìn ó pàṣẹ fún àwọn awakọ̀ pé, “Ẹ lọ kí ẹ lọ wo ohun tí ó ṣẹlẹ̀.”
És vevének két szekeret lovakkal, és kiküldé a király a siriaiak táborába, mondván: Menjetek el és nézzétek meg.
15 Wọ́n sì tẹ̀lé wọn títí dé Jordani, wọ́n sì rí gbogbo ọ̀nà kún fún agbádá pẹ̀lú ohun èlò tí ará àwọn Siria gbé sọnù ní yàrá wọn. Ìránṣẹ́ náà padà ó sì wá sọ fún ọba.
És mikor utánuk mentek egész a Jordánig, ímé az egész út rakva volt ruhákkal és edényekkel, a melyeket a siriaiak a sietségben elhánytak. És mikor visszajöttek a követek, és elmondák ezt a királynak:
16 Nígbà náà àwọn ènìyàn jáde lọ ìkógun ní ibùdó àwọn ará Siria. Bẹ́ẹ̀ ni òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kan ni wọ́n tà fún ṣékélì kan, àti òsùwọ̀n barle méjì ní ṣékélì kan, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
Kiment a nép, és kirabolta a Siriabeliek táborát, és egy köböl zsemlyelisztet egy sikluson, és két köböl árpát egy sikluson vettek, az Úrnak beszéde szerint.
17 Nísinsin yìí ọba sì mú ìjòyè náà lórí ẹni tí ó fi ọwọ́ ara rẹ̀ tì ní ìkáwọ́ ẹnu ibodè, àwọn ènìyàn sì tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ẹnu ibodè. Ó sì kú, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọtẹ́lẹ̀ nígbà tí ọba sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
A király pedig azt a főembert, a kinek kezére szokott támaszkodni, oda rendelte a kapuhoz. És a nép eltapodá őt a kapuban, és meghala, a mint az Isten embere megmondotta, a ki megjövendölte ezt, mikor a király lement hozzá.
18 Ó sì ti ṣẹlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọ fún ọba: “Ní àsìkò yìí ní ọ̀la, òsùwọ̀n ìyẹ̀fun ni a ó ta nì ṣékélì kan àti òsùwọ̀n méjì barle ní ṣékélì kan ní ẹnu-ọ̀nà ibodè Samaria.”
Úgy történt, a mint az Isten embere a királynak jövendölte: Két köböl árpát egy sikluson és egy köböl zsemlyelisztet egy sikluson adnak holnap ilyenkor Samaria kapujában.
19 Ìjòyè náà ti wí fún ènìyàn Ọlọ́run pé, “Wò ó, kódà ti Olúwa bá ṣí fèrèsé ní ọ̀run, ṣé èyí lè ṣẹlẹ̀?” Ènìyàn Ọlọ́run sì ti dáhùn pé, “Kìkì ojú rẹ ni ìwọ yóò fi rí i, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní jẹ ọ̀kankan lára rẹ̀.”
És ezt felelte volt a főember az Isten emberének, mondván: Hacsak az Úr ablakokat nem csinál az égen; akkor meglehet? és ő azt mondotta rá: Ímé te szemeiddel meg fogod látni; de nem eszel belőle.
20 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí fún un gẹ́lẹ́, nítorí tí àwọn ènìyàn tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ẹnu ibodè, ó sì kú.
És teljesen így történt vele, mert eltapodá őt a nép a kapuban és meghalt.

< 2 Kings 7 >