< 2 Kings 6 >

1 Àwọn ọmọ wòlíì sọ fún Eliṣa pé, “Wò ó, ní ibi tí a ti pàdé pẹ̀lú rẹ, ó kéré fún wa.
És mondának a próféták fiai Elizeusnak: Ímé ez a hely, a hol nálad lakunk, igen szoros nékünk;
2 Jẹ́ kí àwa kí ó lọ sí Jordani, ní ibi tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ti le rí ọ̀pá kan, jẹ́ kí àwa kí ó kọ́lé síbẹ̀ fún wa láti gbé.” Ó sì wí pé, “Lọ.”
Hadd menjünk el, kérlek, a Jordán mellé, hogy mindenikünk egy-egy fát hozzon onnét, hogy ott valami hajlékot építsünk magunknak, a melyben lakjunk. És monda: Menjetek el!
3 Nígbà náà ni ọ̀kan lára wọn wí pé, “Kí ó wù ọ́, èmí bẹ̀ ọ́, láti bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ?” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ,”
És monda egy közülök: Nyugodj meg rajta, és jőjj el a te szolgáiddal. És monda: Én is elmegyek.
4 Ó sì lọ pẹ̀lú wọn. Wọ́n sì lọ sí Jordani wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gé igi.
És elméne velök. És menének a Jordán mellé, és ott fákat vágtak.
5 Bí ọ̀kan ṣe gé igi náà, àáké irin náà bọ́ sínú omi, ó kígbe sókè pé, “O! Olúwa mi, mo yá a ni!”
És történt, hogy mikor egy közülök egy fát levágna, a fejsze beesék a vízbe. Akkor kiálta és monda: Jaj, jaj, édes uram! pedig ezt is kölcsön kértem!
6 Ènìyàn Ọlọ́run sì béèrè pé, “Níbo ni ó bọ́ sí?” Nígbà tí ó fi ibẹ̀ hàn án, Eliṣa gé igi kan ó sì jù ú síbẹ̀, ó sì mú irin náà fò lójú omi.
És monda az Isten embere: Hová esett? És mikor megmutatta néki a helyet, levágott egy fát és utána dobta, és a fejsze feljött a víz színére.
7 Ó wí pé, “Gbé e jáde.” Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú un.
És monda: Vedd ki. És kinyújtván kezét, kivevé azt.
8 Nísinsin yìí ọba Aramu wà ní ogun pẹ̀lú Israẹli ó sì bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ gbèrò, ó wí pé, “Èmi yóò ṣe ibùdó mi sí ibí yìí nínú èyí náà àti bí ibí yìí.”
Siria királya pedig hadat indított Izráel ellen, és tanácsot tartván az ő szolgáival, monda: Itt meg itt lesz az én táborom.
9 Ènìyàn Ọlọ́run rán iṣẹ́ sí ọba Israẹli pé, “Kíyèsi ara láti kọjá ní ibẹ̀ yẹn, nítorí pé ará Aramu wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ síbẹ̀.”
És elkülde az Isten embere az Izráel királyához, mondván: Vigyázz, ne hagyd el azt a helyet, mert ott akarnak a siriaiak betörni.
10 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli wo ibi tí ènìyàn Ọlọ́run náà fihàn, ní ẹ̀ẹ̀kan sí i Eliṣa kìlọ̀ fún ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó wà lórí sísọ ní ibẹ̀.
És elkülde az Izráel királya arra a helyre, a melyről néki az Isten embere szólott, és őt megintette volt, és vigyázott magára nem egyszer, sem kétszer.
11 Èyí mú ọba Aramu bínú. Ó pe àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé ìwọ kò ní sọ fún mi èwo nínú wa ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọba Israẹli?”
És felháborodott ezen a siriai király szíve, és összegyűjtvén az ő szolgáit, monda nékik: Miért nem mondjátok meg nékem, ki tart közülünk az Izráel királyával?!
12 Ọ̀kan lára ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí pé, “Kò sí ọ̀kan nínú wa, olúwa ọba mi, ṣùgbọ́n Eliṣa, wòlíì tí ó wà ní Israẹli, sọ fún ọba Israẹli ọ̀rọ̀ gangan tí ó sọ nínú yàrá rẹ̀.”
Akkor monda egy az ő szolgái közül: Nem úgy, uram király, hanem Elizeus próféta, a ki Izráelben van, jelenti meg az Izráel királyának a beszédeket, a melyeket te a te titkos házadban beszélsz.
13 Ọba pa á láṣẹ, “Lọ, kí ẹ lọ wo ibi tí ó wà, kí èmi kí ó lè rán ènìyàn láti lọ mú un wá.” Ìròyìn padà wá wí pé, “Ó wà ní Dotani.”
És monda: Menjetek el és nézzétek meg, hol van, hogy utána küldjek és elhozassam őt. És megjelenték néki, mondván: Ímé Dótánban van.
14 Nígbà náà ni ó rán àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ àti ogun ńlá tí ó le síbẹ̀. Wọ́n sì lọ ní alẹ́ wọ́n sì yí ìlú náà ká.
Akkor lovakat, szekereket és nagy sereget külde oda, a kik elmenének éjjel, és körülvevék a várost.
15 Nígbà tí ìránṣẹ́ ènìyàn Ọlọ́run dìde ó sì jáde lọ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, ogun pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ wọn ti yí ìlú náà ká. “Yé è, olúwa mi! Kí ni kí àwa kí ó ṣe?” ìránṣẹ́ náà béèrè.
Felkelvén pedig jókor reggel az Isten emberének szolgája, kiméne, és ímé seregek vették körül a várost, és lovak és szekerek. És monda néki az ő szolgája: Jaj, jaj, édes uram! mit cselekedjünk?
16 “Má ṣe bẹ̀rù,” wòlíì náà dáhùn, “Àwọn tí ó wà pẹ̀lú wa, wọ́n pọ̀ ju àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn lọ.”
Felele ő: Ne félj. Mert többen vannak, a kik velünk vannak, mint a kik ő velök.
17 Eliṣa sì gbàdúrà, “Olúwa, la ojú rẹ̀ kí ó ba à lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú ìránṣẹ́ náà, ó sì wò, ó sì rí òkè ńlá tí ó kún fún ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ iná gbogbo yí Eliṣa ká.
És imádkozott Elizeus és monda: Óh Uram! nyisd meg kérlek az ő szemeit, hadd lásson. És megnyitá az Úr a szolga szemeit és láta, és ímé a hegy rakva volt tüzes lovagokkal és szekerekkel Elizeus körül.
18 Bí àwọn ọ̀tá ṣe ń sọ̀kalẹ̀ wá níwájú rẹ, Eliṣa gbàdúrà sí Olúwa pé. “Bu ìfọ́jú lu àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” Olúwa sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Eliṣa ti béèrè.
És mikor azok hozzá lementek, könyörgött Elizeus az Úrnak, mondván: Verd meg ezt a népet vaksággal! És megveré őket vaksággal az Elizeus kivánsága szerint.
19 Eliṣa sọ fún wọn pé, “Èyí kì í ṣe ọ̀nà bẹ́ẹ̀ ni èyí kì í ṣe ìlú náà. Tẹ̀lé mi, èmi yóò mú u yín lọ sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin tí ẹ̀yin ń wá.” Ó sì sìn wọ́n lọ sí Samaria.
És monda nékik Elizeus: Nem ez az út, sem ez a város; jertek el én utánam, és ahhoz a férfiúhoz vezetlek titeket, a kit kerestek. És elvezeté őket Samariába.
20 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n wọ ìlú náà, Eliṣa wí pé, “Olúwa, la ojú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kí wọn kí ó lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú wọn, wọ́n sì ríran, wọ́n sì wà níbẹ̀, nínú Samaria.
És mikor bementek Samariába, monda Elizeus: Óh Uram, nyisd meg ezek szemeit, hogy lássanak. És megnyitá az Úr az ő szemeiket és látának, és ímé Samaria közepében voltak.
21 Nígbà tí ọba Israẹli rí wọn, ó béèrè lọ́wọ́ Eliṣa pé, “Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n, baba mi? Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n?”
Az Izráel királya pedig mikor látta őket, monda Elizeusnak: Vágván vágassam-é őket, atyám?
22 “Má ṣe pa wọ́n,” ó dáhùn. “Ṣé ìwọ yóò pa àwọn ọkùnrin tí ìwọ mú pẹ̀lú idà rẹ tàbí ọrun rẹ? Gbé oúnjẹ àti omi síwájú wọn kí wọn kí ó lè jẹ kí wọn sì mu, nígbà náà kí wọn padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn.”
És monda: Ne vágasd. Le szoktad-é vágatni azokat, a kiket karddal vagy kézívvel fogsz el? Adj nékik kenyeret és vizet, hogy egyenek és igyanak, és elmenjenek az ő urokhoz.
23 Bẹ́ẹ̀ ni ó pèsè àsè ńlá fún wọn, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jẹ tí wọ́n mu, ó sì rán wọn lọ, wọ́n sì padà sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ẹgbẹ́ láti Aramu dáwọ́ ìgbógunti ilẹ̀ Israẹli dúró.
És nagy lakomát szerzett nékik; és miután ettek és ittak, elbocsátá őket. Ők pedig elmenének az ő urokhoz; és ettől fogva többé nem jöttek a siriai portyázó csapatok az Izráel földjére.
24 Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ni Beni-Hadadi ọba Aramu kó gbogbo àwọn ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì yan sókè wọ́n sì dúró ti Samaria.
És lőn ezek után, hogy Benhadád, Siria királya összegyűjté egész seregét, és felment és megszállotta Samariát.
25 Ìyàn ńlá sì mú ní ìlú Samaria; wọ́n dúró tí ì tó bẹ́ẹ̀ tí a fi ń ta orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan ní ọgọ́rùn-ún ìwọ̀n fàdákà àti ìdámẹ́rin òsùwọ̀n kábù imí ẹyẹlé, fún ìwọ̀n fàdákà márùn-ún.
És igen nagy inség lett Samariában, mert addig tartották megszállva a várost, míg egy szamárfej nyolczvan ezüst, és egy véka galambganéj öt ezüst lett.
26 Gẹ́gẹ́ bí ọba Israẹli ti ń kọjá lọ lórí odi, obìnrin kan sọkún sí i pé, “Ràn mí lọ́wọ́, olúwa ọba mi!”
És mikor az Izráel királya a kőfalon széjjeljára, egy asszony kiálta ő hozzá, mondván: Légy segítséggel, uram király!
27 Ọba sì dá a lóhùn pé, “Bí Olúwa kò bá gbà ọ́, níbo ni èmi yóò gbé ti gbà ọ́? Láti inú ilẹ̀ ìpakà, tàbí láti inú ibi ìfúntí?”
A király monda: Ha nem segít meg téged az Isten, hogyan segítselek én meg? A szérűről vagy a sajtóról?
28 Nígbà náà ọba béèrè lọ́wọ́ obìnrin náà pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” Obìnrin náà dáhùn pé, “Obìnrin yìí wí fún mi pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ ẹ́ lónìí, ní ọ̀la àwa yóò jẹ ọmọkùnrin tèmi.’
És monda néki a király: Mit akarsz? Monda az: Ez az asszony azt mondta nékem: Add ide a te fiadat, hogy együk meg őt ma, az én fiamat pedig holnap eszszük meg.
29 Bẹ́ẹ̀ ni a ṣe ọmọkùnrin mi a sì jẹ ẹ́. Ní ọjọ́ kejì mo wí fún un pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ,’ ṣùgbọ́n ó ti gbé e pamọ́.”
És megfőztük az én fiamat, és megettük őt. Mikor azután másnap azt mondtam néki: Add ide a te fiadat, hogy azt is együk meg, ő elrejté az ő fiát.
30 Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ obìnrin náà, ó fa aṣọ rẹ̀ ya. Gẹ́gẹ́ bí ó sì ti ń kọjá lọ sí orí odi, àwọn ènìyàn wò ó níbẹ̀ ní abẹ́, ó ní aṣọ ọ̀fọ̀ ní ara rẹ̀.
Mikor pedig hallotta a király az asszonynak beszédét, megszaggatá az ő ruháit, a mint a kőfalon járt, és meglátta a nép, hogy ímé alól zsákruha van az ő testén.
31 Ó sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó fi ìyà jẹ mí, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ dájúdájú, pé orí ọmọkùnrin Eliṣa ọmọ Ṣafati kì ó wà ní ọrùn rẹ̀ ní òní!”
És monda: Úgy cselekedjék velem az Isten és úgy segéljen, ha Elizeusnak, a Sáfát fiának feje ma rajta marad!
32 Nísinsin yìí Eliṣa jókòó ní ilé rẹ̀ àwọn àgbàgbà náà jókòó pẹ̀lú rẹ̀. Ọba sì rán oníṣẹ́ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó tó dé ibẹ̀, Eliṣa sọ fún àwọn àgbàgbà pé, “Ṣé ẹ̀yin kò rí bí apànìyàn ti ń rán ẹnìkan láti gé orí mi kúrò? Ẹ wò ó, nígbà tí ìránṣẹ́ náà bá dé, ẹ ti ìlẹ̀kùn kí ẹ sì dìímú ṣinṣin ní ẹnu-ọ̀nà, ìró ẹsẹ̀ olúwa rẹ̀ kò ha wà lẹ́yìn rẹ?”
Elizeus pedig ott ült az ő házában, és együtt ültek vele a vének. És elküldött a király egy férfiat maga előtt. Mielőtt azonban hozzá jutott volna a követ, monda Elizeus a véneknek: Látjátok-é, hogy az a gyilkos hogyan küld ide, hogy a fejemet vétesse? Vigyázzatok, hogy mikor ide ér a követ, zárjátok be az ajtót és szorítsátok meg őt az ajtóban: Ímé az ő ura lábainak dobogása követi őt.
33 Nígbà tí ó sì ń sọ̀rọ̀ sí wọn, ìránṣẹ́ náà sọ̀kalẹ̀ wá bá a. Ọba náà sì wí pé, “Ibi yìí láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni. Kí ni ó dé tí èmi yóò fi dúró de Olúwa sí i?”
És mikor még így beszélne velök, már a követ leérkezett hozzá és nyomában a király, és monda: Ímé ilyen veszedelem származott az Úrtól; várjak-é még tovább az Úrra?

< 2 Kings 6 >