< 2 Chronicles 35 >

1 Síwájú sí i, Josiah ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá sí Olúwa ní Jerusalẹmu, Ọ̀dọ́-àgùntàn àjọ ìrékọjá náà ni wọ́n sì pa ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní.
Mai mult, Iosia a ținut paștele DOMNULUI în Ierusalim; și au înjunghiat paștele în a paisprezecea zi a lunii întâi.
2 Ó sì yàn àwọn àlùfáà sí iṣẹ́ wọn, ó sì gbà wọ́n ní ìyànjú ní ìsìn ilé Olúwa.
Și a așezat preoții în sarcinile lor și i-a încurajat în serviciul casei DOMNULUI.
3 Ó sì wí fún àwọn ọmọ Lefi, ẹni tí ń kọ́ gbogbo àwọn Israẹli ẹni tí a ti yà sí mímọ́ fún Olúwa pé ẹ gbé àpótí ẹ̀rí ìyàsọ́tọ̀ sí ilé Olúwa tí Solomoni ọmọ Dafidi ọba Israẹli ti kọ́. Kò gbọdọ̀ jẹ́ ẹrù àgbéká ní èjìká rẹ̀. Nísinsin yìí ẹ sin Olúwa Ọlọ́run yín àti àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli.
Și a spus leviților care învățau pe tot Israelul, care erau sfinți DOMNULUI: Puneți chivotul sfânt în casa pe care Solomon, fiul lui David, împăratul lui Israel, a construit-o; aceasta să nu fie o povară pe umerii voștri, serviți acum DOMNULUI Dumnezeul vostru și poporului său Israel,
4 Ẹ múra sílẹ̀ nípa ìdílé ní ẹsẹẹsẹ yín gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ tí a kọ́ láti ọwọ́ Dafidi ọba Israẹli àti gẹ́gẹ́ bí ọmọ rẹ̀ Solomoni.
Și pregătiți-vă după casele părinților voștri, după rândurile voastre, conform cu scrierea lui David, împăratul lui Israel, și conform cu scrierea lui Solomon, fiul său.
5 “Dúró ní ibi mímọ́ pẹ̀lú àkójọpọ̀ àwọn ọmọ Lefi fún ọ̀kọ̀ọ̀kan ìpín àwọn ìdílé àwọn ẹgbẹ́ ará ìlú, àwọn ènìyàn tí ó dùbúlẹ̀.
Și stați în picioare în locul sfânt după cetele caselor părintești ale fraților voștri ale poporului și după ceata caselor leviților.
6 Ẹ pa ẹran àjọ ìrékọjá náà, ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kí ẹ sì pèsè ẹran fún àwọn ẹgbẹ́ arákùnrin yín, kí ẹ sì ṣe ohun tí Olúwa paláṣẹ láti ọwọ́ Mose.”
Astfel să înjunghiați paștele și să vă sfințiți și să pregătiți pe frații voștri, ca ei să facă după cuvântul DOMNULUI prin mâna lui Moise.
7 Josiah sì pàṣẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn tí ó dùbúlẹ̀ tí ó wà níbẹ̀ iye rẹ̀ jẹ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọmọ ewúrẹ́ fún ẹbọ ìrékọjá, àti pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́ta akọ màlúù, gbogbo wọ̀nyí jẹ́ ohun ìní láti ọ̀dọ̀ ọba.
Și Iosia a dat poporului miei și iezi din turmă, toți pentru ofrandele de paște, pentru toți cei prezenți, până la numărul de treizeci de mii și trei mii de tauri, aceștia erau din averea împăratului.
8 Àwọn ìjòyè rẹ̀ fi tinútinú ta àwọn ènìyàn náà ní ọrẹ àti àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi. Hilkiah, Sekariah àti Jehieli, àti àwọn olórí ilé Ọlọ́run, fún àwọn àlùfáà ní ẹgbẹ̀tàlá ẹbọ àjọ ìrékọjá àti ọ̀ọ́dúnrún ẹran ọ̀sìn.
Și prinții lui au dat de bunăvoie poporului, preoților și leviților: Hilchia și Zaharia și Iehiel, conducători ai casei lui Dumnezeu, au dat preoților pentru ofrandele de paște două mii șase sute de viței și trei sute de boi.
9 Àti pẹ̀lú Konaniah àti pẹ̀lú Ṣemaiah àti Netaneli, àti àwọn arákùnrin rẹ̀, àti Haṣabiah, Jeieli àti Josabadi olórí àwọn ọmọ Lefi, ó sì pèsè ẹgbẹ̀rún márùn-ún ẹbọ ìrékọjá àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta orí ẹran ọ̀sìn fún àwọn ọmọ Lefi.
Conania de asemenea și Șemaia și Natanael, frații săi, și Hașabia și Ieiel și Iozabad, mai marii leviților, au dat leviților pentru ofrandele de paște cinci mii de viței și cinci sute de boi.
10 Nítorí náà, a múra ìsìn náà sílẹ̀, àwọn àlùfáà sì dúró ní ipò wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ Lefi nípa iṣẹ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ọba ti pa á láṣẹ.
Astfel serviciul a fost pregătit și preoții au stat în picioare la locul lor și leviții în rândurile lor, conform poruncii împăratului.
11 Ní ti àjọ ìrékọjá a sì pa ẹran, àwọn àlùfáà sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ náà tí wọ́n gbé sí ọwọ́ wọn, nígbà tí àwọn ọmọ Lefi sì bọ ẹranko.
Și au înjunghiat paștele și preoții au stropit sângele din mâinile lor și leviții le-au jupuit.
12 Wọ́n sì ya àwọn ẹbọ sísun sí apá kan láti fi wọ́n fún gẹ́gẹ́ bí ìpín àwọn ìdílé àwọn ènìyàn láti rú ẹbọ sí Olúwa. Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sínú ìwé Mose. Wọ́n sì ṣe bákan náà pẹ̀lú àwọn ẹran ọ̀sìn.
Și au îndepărtat ofrandele arse, ca să dea conform cu cetele familiilor poporului, pentru a oferi DOMNULUI, precum este scris în cartea lui Moise. Și tot așa au făcut cu boii.
13 Wọ́n sì fi sun àjọ ìrékọjá lórí iná gẹ́gẹ́ bí ìlànà, wọ́n sì bọ ẹbọ mímọ́ nínú ìkòkò, nínú ọpọ́n àti nínú agbada, wọ́n sì pín wọn kíákíá fún gbogbo àwọn ènìyàn.
Și au prăjit paștele cu foc, conform cu rânduiala, dar celelalte ofrande sfinte le-au fiert în oale și în căldări și în tigăi și le-au împărțit în grabă la tot poporul.
14 Lẹ́yìn èyí, wọ́n sì múra sílẹ̀ fún ara wọn àti fún àwọn àlùfáà nítorí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Aaroni, ni wọ́n rú ẹbọ sísun àti ọ̀rá títí di àṣálẹ́. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi sì múra sílẹ̀ fún ara wọn àti fún àwọn ọmọ Aaroni àlùfáà.
Și după aceasta au pregătit pentru ei și pentru preoți, fiindcă preoții, fiii lui Aaron, au fost ocupați cu aducerea ofrandelor arse și cu grăsimea, până noaptea; de aceea leviții au pregătit pentru ei și pentru preoți, fiii lui Aaron.
15 Àwọn akọrin, àwọn ọmọ Asafu, ni wọ́n wà ní ipò wọn tí a sì paláṣẹ fún wọn láti ọwọ́ Dafidi, Asafu, Hemani àti Jedutuni àwọn aríran ọba àti àwọn olùṣọ́nà ní olúkúlùkù ẹnu-ọ̀nà kò gbọdọ̀ fi ojú ọ̀nà wọn sílẹ̀, nítorí àwọn ẹgbẹ́ ọmọ lefi ti múra sílẹ̀ fún wọn.
Și cântăreții, fiii lui Asaf, erau la locul lor, conform poruncii lui David și Asaf și Heman și Iedutun, văzătorul împăratului; și portarii așteptau la fiecare poartă; nu se depărtau din serviciul lor, fiindcă frații lor, leviții, pregăteau pentru ei.
16 Bẹ́ẹ̀ ni àsìkò náà gbogbo àwọn ìsìn Olúwa ni wọ́n gbé jáde fún iṣẹ́ ìrántí àjọ ìrékọjá àti láti rú ẹbọ sísun lórí pẹpẹ Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ọba Josiah ti pa á láṣẹ.
Astfel, tot serviciul DOMNULUI a fost pregătit în aceeași zi, pentru a ține paștele și pentru a aduce ofrande arse pe altarul DOMNULUI, conform poruncii împăratului Iosia.
17 Àwọn ọmọ Israẹli tí ó gbé kalẹ̀ ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá ní àkókò náà àti àjọ àkàrà àìwú fún ọjọ́ méje.
Și copiii lui Israel, care erau prezenți, au ținut paștele în acel timp și sărbătoarea azimelor șapte zile.
18 Àjọ ìrékọjá náà kò sì tí ì sí èyí tí ó dàbí i rẹ̀ ní Israẹli títí dé ọjọ́ wòlíì Samuẹli, kò sì sí ọ̀kan lára àwọn ọba Israẹli tí ó pa irú àjọ ìrékọjá bẹ́ẹ̀ mọ́ gẹ́gẹ́ bí Josiah ti ṣe, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àwọn ọmọ Lefi àti gbogbo àwọn Juda àti Israẹli tí ó wà níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu.
Și nu a fost ținut paște ca acela din zilele profetului Samuel; niciunul dintre toți împărații lui Israel nu au ținut un astfel de paște, precum a ținut Iosia; și preoții și leviții și tot Iuda și Israelul, care au fost prezenți, și locuitorii Ierusalimului.
19 Àjọ ìrékọjá yìí ni a ṣe ìrántí ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Josiah.
Acest paște a fost ținut în al optsprezecelea an al domniei lui Iosia.
20 Lẹ́yìn gbogbo èyí nígbà tí Josiah ti tún ilẹ̀ náà ṣetán, Neko ọba Ejibiti gòkè lọ láti bá Karkemiṣi jà lórí odo Eufurate, Josiah sì jáde lọ láti pàdé rẹ̀ ní ibi ìjà.
După toate acestea, după ce Iosia a pregătit templul, Neco, împăratul Egiptului, a urcat să lupte împotriva Carchemișului, la Eufrat; și Iosia a ieșit împotriva lui.
21 Ṣùgbọ́n Neko rán ìránṣẹ́ sí i wí pé, “Ìjà wo ni ó ń bẹ láàrín èmi àti ìwọ, ọba Juda? Kì í ṣe ìwọ ni èmi tọ̀ wá ní àkókò yìí, ṣùgbọ́n, ilé pẹ̀lú èyí ti mo bá níjà. Ọlọ́run ti sọ fún mi láti yára àti láti dúró nípa ṣíṣe ìdènà Ọlọ́run, ẹni tí ó wà pẹ̀lú mi, kí òun má bá a pa ọ́ run.”
Dar el a trimis ambasadori la el, spunând: Ce am eu a face cu tine, tu împărat al lui Iuda? Eu nu vin împotriva ta în această zi, ci împotriva casei cu care am război, fiindcă Dumnezeu mi-a poruncit să mă grăbesc, ferește-te să te opui lui Dumnezeu, care este cu mine, ca să nu te nimicească.
22 Josiah, kò yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó pa ara rẹ̀ dà kí ó le bá a jà, kó sì fi etí sí ọ̀rọ̀ Neko láti ẹnu Ọlọ́run wá, ó sì wá jagun ní àfonífojì Megido.
Cu toate acestea Iosia a refuzat să își întoarcă fața de la el, ci s-a deghizat, ca să lupte cu el; și nu a dat ascultare cuvintelor lui Neco, din gura lui Dumnezeu, și a venit să lupte în valea Meghido.
23 Tafàtafà sì ta ọfà sí ọba Josiah, ó sì sọ fún àwọn ìjòyè pé, “Ẹ gbé mi kúrò, èmi ti gba ọgbẹ́ gidigidi.”
Și arcașii au tras spre împăratul Iosia; și împăratul a spus servitorilor lui: Luați-mă deoparte, fiindcă sunt grav rănit.
24 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbé e jáde kúrò nínú kẹ̀kẹ́ náà, wọ́n sì gbé e sínú kẹ̀kẹ́ mìíràn, wọ́n sì gbé e wá sí Jerusalẹmu, níbi tí ó ti kú, wọ́n sì sin ín sínú ọ̀kan nínú àwọn ibojì àwọn baba rẹ̀, gbogbo Juda àti gbogbo Jerusalẹmu sì ṣọ̀fọ̀ Josiah.
Și servitorii lui l-au scos din car și l-au pus în al doilea car pe care îl avea; și l-au adus la Ierusalim și el a murit și a fost îngropat într-unul dintre mormintele părinților săi. Și tot Iuda și Ierusalimul au jelit pentru Iosia.
25 Jeremiah sì pohùnréré ẹkún fún Josiah, gbogbo àwọn akọrin ọkùnrin àti gbogbo àwọn akọrin obìnrin sì ń sọ ti Josiah nínú orin ẹkún wọn ní Israẹli títí di òní. Èyí sì di àṣà ní Jerusalẹmu, a sì kọ ọ́ sínú àwọn orin ẹkún.
Și Ieremia a plâns pentru Iosia și toți cântăreții și cântărețele au vorbit despre Iosia în plângerile lor până în această zi și le-au făcut o rânduială în Israel, și, iată, ele sunt scrise în plângeri.
26 Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Josiah àti ìwà rere rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí èyí tí a ti kọ sínú ìwé òfin Olúwa.
Și restul faptelor lui Iosia și bunătatea lui, conform cu cele scrise în legea DOMNULUI,
27 Gbogbo iṣẹ́ náà, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin ni a kọ sínú ìwé àwọn ọba Israẹli àti Juda.
Și faptele lui, cele dintâi și cele din urmă, iată, ele sunt scrise în cartea împăraților lui Israel și Iuda.

< 2 Chronicles 35 >