< Ezra 1 >

1 Ní ọdún kìn-ín-ní Kirusi, ọba Persia, kí a lè mú ọ̀rọ̀ Olúwa tí Jeremiah sọ ṣẹ, Olúwa ru ọkàn Kirusi ọba Persia sókè láti ṣe ìkéde jákèjádò gbogbo agbègbè ìjọba rẹ̀, kí ó sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ pé,
Şi, în anul întâi al lui Cirus, împăratul Persiei, ca să fie împlinit cuvântul DOMNULUI rostit prin gura lui Ieremia, DOMNUL a stârnit duhul lui Cirus împăratul Persiei, încât el a făcut o proclamaţie în toată împărăţia sa şi a pus-o de asemenea în scris, spunând:
2 “Èyí ni ohun tí Kirusi ọba Persia wí pé: “‘Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, ti fún mi ní gbogbo ìjọba ayé. Ó sì ti yàn mí láti kọ́ tẹmpili Olúwa fún un ní Jerusalẹmu tí ó wà ní Juda.
Astfel zice Cirus, împăratul Persiei: DOMNUL Dumnezeul cerului mi-a dat toate împărăţiile pământului; şi mi-a poruncit să îi construiesc o casă în Ierusalim, care este în Iuda.
3 Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ láàrín yín—kí Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀, kí ó sì gòkè lọ sí Jerusalẹmu tí ó wà ní Juda, láti kọ́ tẹmpili Olúwa Ọlọ́run Israẹli, Ọlọ́run tí ó wà ní Jerusalẹmu.
Cine este dintre voi din tot poporul său? Dumnezeul său să fie cu el şi să se urce la Ierusalim, care este în Iuda, şi să construiască acolo casa DOMNULUI Dumnezeului lui Israel (el este Dumnezeul), care este în Ierusalim.
4 Kí àwọn ènìyàn ní ibikíbi tí ẹni náà bá ń gbé kí ó fi fàdákà àti wúrà pẹ̀lú ohun tí ó dára àti ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú ọrẹ àtinúwá ràn án lọ́wọ́ fún tẹmpili Ọlọ́run ní Jerusalẹmu.’”
Şi pe oricine rămâne, în orice loc unde el locuieşte temporar, oamenii locului să îl ajute cu argint şi cu aur şi cu bunuri şi cu animale, în afară de darul de bunăvoie pentru casa lui Dumnezeu care este în Ierusalim.
5 Nígbà náà àwọn olórí ìdílé Juda àti Benjamini àti àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi—olúkúlùkù ẹni tí Ọlọ́run ti fọwọ́ tọ́ ọkàn rẹ̀—múra láti gòkè lọ láti kọ ilé Olúwa ní Jerusalẹmu.
Atunci s-au ridicat mai marii părinţilor lui Iuda şi lui Beniamin şi preoţii şi leviţii, împreună cu toţi aceia al căror duh Dumnezeu îl ridicase, pentru a se urca să construiască acolo casa DOMNULUI care este în Ierusalim.
6 Gbogbo àwọn aládùúgbò wọn ràn wọ́n lọ́wọ́ pẹ̀lú ohun èlò ti fàdákà àti wúrà, pẹ̀lú onírúurú ohun ìní àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹ̀bùn iyebíye, ní àfikún si gbogbo àwọn ọrẹ àtinúwá.
Și toți din împrejurul lor le-au întărit mâinile cu vase de argint, cu aur, cu bunuri şi cu animale şi cu lucruri preţioase, în afară de tot ce era oferit de bunăvoie.
7 Ní àfikún, ọba Kirusi mú àwọn ohun èlò tí ó jẹ́ ti ilé Olúwa jáde wá, tí Nebukadnessari ti kó lọ láti Jerusalẹmu tí ó sì ti kó sí ilé òrìṣà rẹ̀.
De asemenea împăratul Cirus a scos vasele casei DOMNULUI, pe care Nebucadneţar le-a scos din Ierusalim şi le-a pus în casa dumnezeilor săi;
8 Kirusi ọba Persia pàṣẹ fún Mitredati olùṣọ́ ilé ìṣúra láti kó wọn jáde, ó sì kà wọ́n fún Ṣeṣbassari ìjòyè Juda.
Chiar pe acelea Cirus, împăratul Persiei, le-a scos prin mâna lui Mitredat trezorierul, şi le-a numărat lui Şeşbaţar, prinţul lui Iuda.
9 Èyí ni iye wọn. Ọgbọ̀n àwo wúrà 30 Ẹgbẹ̀rún àwo fàdákà 1,000 Àwo ìrúbọ fàdákà mọ́kàndínlọ́gbọ̀n 29
Şi acesta este numărul lor: treizeci de platouri de aur, o mie de platouri de argint, douăzeci şi nouă de cuţite,
10 Ọgbọ̀n àdému wúrà 30 Irinwó ó lé mẹ́wàá oríṣìí àdému fàdákà mìíràn 410 Ẹgbẹ̀rún kan àwọn ohun èlò mìíràn 1,000
Treizeci de oale de aur, oale de argint de al doilea fel patru sute zece şi alte vase o mie.
11 Gbogbo ohun èlò wúrà àti ti fàdákà ní àpapọ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ó lé irinwó. Ṣeṣbassari kó gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí wá pẹ̀lú àwọn ìgbèkùn tí ó gòkè wá láti Babeli sí Jerusalẹmu.
Toate vasele de aur şi de argint erau cinci mii patru sute. Pe toate acestea Şeşbaţar le-a adus cu cei din captivitate care au fost aduşi din Babilon la Ierusalim.

< Ezra 1 >