< 2 Chronicles 31 >

1 Nígbà tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ti dé òpin, àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà níbẹ̀ jáde lọ sí àwọn ìlú Juda, wọ́n fọ́ àwọn òkúta ìyàsọ́tọ̀ sí wẹ́wẹ́, wọ́n gé àwọn ère Aṣerah lulẹ̀. Wọ́n ba àwọn ibi gíga jẹ́ àti àwọn pẹpẹ jákèjádò Juda àti Benjamini àti ní Efraimu àti Manase. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti pa gbogbo wọn run, àwọn ọmọ Israẹli padà sí ìlú wọn àti sí nǹkan ìní wọn.
A gdy to wszystko się zakończyło, cały lud Izraela, który tam się znajdował, wyruszył do miast Judy i potłukł posągi, wyciął gaje, i zburzył do szczętu wyżyny oraz ołtarze w całej Judzie i Beniaminie, w Efraimie i Manassesie. Potem wszyscy synowie Izraela wrócili, każdy do swojej posiadłości [i] do swego miasta.
2 Hesekiah fi lé àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi lọ́wọ́ sí àwọn ìpín olúkúlùkù wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà tàbí ará Lefi láti tẹ́ ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀, láti ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ láti fi ọpẹ́ fún àti láti kọ àwọn orin ìyìn ní ẹnu-ọ̀nà ibùgbé Olúwa.
I Ezechiasz ustanowił zmiany kapłanów i Lewitów według ich podziałów, każdego według jego służby, kapłanów i Lewitów do [składania] całopaleń i ofiar pojednawczych, aby służyli i dziękowali PANU, a także wysławiali go w bramach [jego] obozu.
3 Ọba fi sílẹ̀ láti ara ohun ìní rẹ̀ fun ẹbọ sísun àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ àti fún ẹbọ sísun ní ọjọ́ ìsinmi, òṣùpá tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn gẹ́gẹ́ bi a ti ṣe kọ ọ́ nínú òfin Olúwa.
Przeznaczył także część z majątku królewskiego na całopalenia poranne i wieczorne, na całopalenia w szabaty, nów księżyca i w uroczyste święta, jak to napisane jest w Prawie PANA.
4 Ó pàṣẹ fún àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu láti fi ìpín tí ó yẹ fún àlùfáà fún un àti àwọn ará Lefi, kí wọn kí ó lè fi ara wọn jì fún òfin Olúwa.
Rozkazał też ludowi mieszkającemu w Jerozolimie, aby oddawał należny dział kapłanom i Lewitom, aby mogli wytrwać w prawie PANA.
5 Ní kété tí àṣẹ náà jáde lọ, àwọn ọmọ Israẹli fi tìfẹ́tìfẹ́ fi àkọ́so ti ọkà wọn, ọtí tuntun, òróró àti oyin àti gbogbo ohun tí pápá mú jáde lélẹ̀. Wọ́n kó ọ̀pọ̀ iye, àti ìdámẹ́wàá gbogbo nǹkan wá.
A gdy ten rozkaz rozszedł się, synowie Izraela przynieśli pod dostatkiem pierwocin zboża, moszczu, oliwy, miodu oraz wszelkich płodów rolnych, przynieśli także obfite dziesięciny ze wszystkiego.
6 Àwọn ọkùnrin Israẹli àti Juda ti gbe inú àwọn ìlú Juda pẹ̀lú mú ìdámẹ́wàá agbo ẹran àti ohun èlò àti ohun ọ̀sìn àti ìdámẹ́wàá ti àwọn nǹkan mímọ́ tí a ti yà sọ́tọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì kó wọn jọ ní òkìtì.
Ponadto synowie Izraela i Judy, którzy mieszkali w miastach Judy, również przynieśli dziesięcinę z wołów i owiec oraz dziesięcinę z rzeczy świętych poświęconych PANU, ich Bogu, i składali to wszystko na stosy.
7 Wọ́n bẹ̀rẹ̀ ṣíṣe èyí ní oṣù kẹta, wọ́n sì parí ní oṣù keje.
W trzecim miesiącu rozpoczęli układać te stosy, a w siódmym miesiącu zakończyli.
8 Nígbà tí Hesekiah àti àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ wá, tí wọ́n sì rí òkìtì náà, wọ́n yin Olúwa, pẹ̀lú ìbùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli.
Kiedy przyszedł Ezechiasz wraz z książętami i zobaczyli te stosy, błogosławili PANU i jego ludowi Izraelowi.
9 Hesekiah béèrè lọ́wọ́ àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi nípa òkìtì;
Wtedy Ezechiasz wypytywał kapłanów i Lewitów o te stosy.
10 àti Asariah olórí àlùfáà ti ìdílé Sadoku sì dáhùn pé, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní mú ìdáwó wọn wá sí ilé Olúwa àti ní èyí tí yóò tó jẹ àti ọ̀pọ̀ láti tọ́jú pamọ́ nítorí Olúwa ti bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀, ó sì ṣẹ́kù lọ́pọ̀lọ́pọ̀.”
Odpowiedział mu Azariasz, najwyższy kapłan z domu Sadoka: Kiedy zaczęto przynosić te ofiary do domu PANA, jedliśmy i nasyciliśmy się, a jeszcze wiele pozostało, gdyż PAN błogosławił swojemu ludowi, a pozostało tego wiele.
11 Hesekiah pàṣẹ láti tọ́jú àwọn yàrá ìṣúra nínú ilé Olúwa, wọ́n sì ṣe èyí.
Rozkazał więc Ezechiasz, aby przygotowano spichlerze w domu PANA. I przygotowano je;
12 Nígbà náà wọ́n mú ọrẹ àti ìdámẹ́wàá àti àwọn ẹ̀bùn tí a yà sí mímọ́ wọ ilé náà wá nítòótọ́. Lórí èyí tí Konaniah ọmọ Lefi, ń ṣe olórí, Ṣimei arákùnrin rẹ̀ ni igbákejì rẹ̀.
I złożono tam wiernie ofiary, dziesięciny i rzeczy poświęcone. Przełożonym nad nimi był Konaniasz, Lewita, a jego brat Szimei [był] drugi.
13 Jehieli, Asasiah, Nahati, Asaheli, Jerimoti, Josabadi, Elieli, Ismakia, Mahati àti Benaiah jẹ́ àwọn alábojútó lábẹ́ Konaniah àti Ṣimei arákùnrin rẹ̀ nípa ipá ọba Hesekiah àti Asariah olórí ti ó wà ní ìkáwọ́ ilé Ọlọ́run.
A Jechiel, Azariasz, Nachat, Asahel, Jerimot, Jozabad, Eliel, Ismakiasz, Machat i Benajasz [byli] nadzorcami pod kierunkiem Konaniasza i jego brata Szimejego, zgodnie z rozkazem króla Ezechiasza i Azariasza, przełożonego domu Bożego.
14 Kore ọmọ Imina ará Lefi olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ìlà-oòrùn, wà ní ìkáwọ́ àwọn ọrẹ àtinúwá tí a fi fún Ọlọ́run, o ń pín ìdáwó tí a ṣe fún Olúwa pẹ̀lú àwọn ẹ̀bùn tí a yà sọ́tọ̀
Kore, syn Jimny, Lewita, odźwierny [przy bramie] wschodniej, czuwał nad dobrowolnymi ofiarami dla Boga, rozdzielał ofiary PANA i rzeczy najświętsze.
15 Edeni, Miniamini, Jeṣua, Ṣemaiah, Amariah àti Ṣekaniah ràn án lọ́wọ́ tọkàntọkàn nínú àwọn ìlú àwọn àlùfáà tí ń dáwó fún àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, àgbà àti kékeré.
Jego pomocnikami [byli]: Eden, Miniamin, Jeszua, Szemejasz, Amariasz i Szekaniasz, w miastach kapłanów, aby wiernie rozdawać [zaopatrzenie] swoim braciom według ich zmian, zarówno wielkiemu, jak i małemu;
16 Ní àfikún, wọ́n pín sí àwọn ọkùnrin àgbà ọdún mẹ́ta tàbí ọ̀pọ̀ tí orúkọ wọn wà nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn. Gbogbo àwọn ti yóò wọ ilé Olúwa láti ṣe oríṣìí iṣẹ́ ti a gbà wọ́n fún gẹ́gẹ́ bí ìgbẹ́kẹ̀lé wọn àti ìpín wọn.
A także mężczyznom z ich rodowodu w wieku od trzech lat wzwyż, każdemu wchodzącemu do domu PANA, dzienny dział za ich służbę, według ich obowiązków i zmian;
17 Wọ́n sì pín àwọn àlùfáà, wọn kọ orúkọ àwọn ìdílé wọn sínú ìtàn ìdílé àti sí àwọn ará Lefi ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu àti ìpín wọn.
Zarówno tym, którzy spośród rodowodu kapłańskiego byli policzeni według ich rodów, jak i Lewitom od dwudziestego roku życia wzwyż, według ich obowiązków i zmian;
18 Wọ́n fi gbogbo àwọn ọmọ kéékèèké sí i, àwọn ìyàwó, àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin gbogbo ará ìlú tí a kọ lẹ́sẹẹsẹ sínú ìtàn ìdílé ti baba ńlá wọn fún ìrántí. Nítorí tí wọ́n ṣe òtítọ́ ní yíya ara wọn sí ọ̀tọ̀.
Oraz wszystkim dzieciom, żonom, synom i córkom z ich rodu, [wśród] całego zgromadzenia. Oni bowiem, pełniąc swój urząd, poświęcali się w świętości.
19 Ní ti àwọn àlùfáà, àwọn ìran ọmọ Aaroni, tí ń gbé ni àwọn ilẹ̀ oko lẹ́bàá àwọn ìlú wọn tàbí ní àwọn ìlú mìíràn. A yan àwọn ọkùnrin pẹ̀lú orúkọ láti pín ìlú fún gbogbo ọkùnrin láàrín wọn àti sí gbogbo àwọn tí a kọ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá àwọn ará Lefi.
Także i synom Aarona, kapłanom [mieszkającym] na polach pastwisk ich miast, we wszystkich miastach, tym mężczyznom, wyznaczonym imiennie, aby oddano należny dział wszystkim mężczyznom spośród kapłanów oraz wszystkim spisanym według rodowodów spośród Lewitów.
20 Èyí ni Hesekiah ṣe jákèjádò Juda, ó sì ṣe ohun tí ó dára àti tí ó tọ́ àti ohun òtítọ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
Tak Ezechiasz uczynił w całej Judzie i czynił [to, co] dobre i prawe, i prawdziwe przed PANEM, swoim Bogiem.
21 Nínú ohun gbogbo tí ó dáwọ́lé ní ti iṣẹ́ ìsìn nínú ilé Ọlọ́run àti ní ìgbọ́ràn sí òfin àti àwọn àṣẹ. Ó wá Ọlọ́run rẹ̀, ó sì ṣiṣẹ́ tọkàntọkàn. Ó sì ṣe rere.
W każdej sprawie, którą rozpoczął w służbie domu Bożego, w prawie i przykazaniach, by szukać swojego Boga, czynił [wszystko] z całego serca, i szczęściło mu się.

< 2 Chronicles 31 >