< Ezra 1 >

1 Ní ọdún kìn-ín-ní Kirusi, ọba Persia, kí a lè mú ọ̀rọ̀ Olúwa tí Jeremiah sọ ṣẹ, Olúwa ru ọkàn Kirusi ọba Persia sókè láti ṣe ìkéde jákèjádò gbogbo agbègbè ìjọba rẹ̀, kí ó sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ pé,
W pierwszym roku Cyrusa, króla Persji – aby wypełniło się słowo PANA z ust Jeremiasza – PAN wzbudził ducha Cyrusa, króla Persji, [tak] że ogłosił [ustnie] po całym swoim królestwie, a także na piśmie, co następuje:
2 “Èyí ni ohun tí Kirusi ọba Persia wí pé: “‘Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, ti fún mi ní gbogbo ìjọba ayé. Ó sì ti yàn mí láti kọ́ tẹmpili Olúwa fún un ní Jerusalẹmu tí ó wà ní Juda.
Tak mówi Cyrus, król Persji: PAN, Bóg niebios, dał mi wszystkie królestwa ziemi. On też rozkazał mi, abym zbudował dla niego dom w Jerozolimie, która jest w Judzie.
3 Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ láàrín yín—kí Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀, kí ó sì gòkè lọ sí Jerusalẹmu tí ó wà ní Juda, láti kọ́ tẹmpili Olúwa Ọlọ́run Israẹli, Ọlọ́run tí ó wà ní Jerusalẹmu.
Kto [więc] spośród was należy do jego ludu, niech będzie z nim jego Bóg; [ten] niech uda się do Jerozolimy w Judzie i niech buduje dom PANA, Boga Izraela – on [jest] Bogiem – który [jest] w Jerozolimie.
4 Kí àwọn ènìyàn ní ibikíbi tí ẹni náà bá ń gbé kí ó fi fàdákà àti wúrà pẹ̀lú ohun tí ó dára àti ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú ọrẹ àtinúwá ràn án lọ́wọ́ fún tẹmpili Ọlọ́run ní Jerusalẹmu.’”
A każdego, kto został w jakimkolwiek miejscu, gdzie [teraz] przebywa, niech ludzie tego miejsca wspomagają go srebrem, złotem, dobytkiem i bydłem, a także dobrowolnymi ofiarami dla domu Bożego, który [jest] w Jerozolimie.
5 Nígbà náà àwọn olórí ìdílé Juda àti Benjamini àti àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi—olúkúlùkù ẹni tí Ọlọ́run ti fọwọ́ tọ́ ọkàn rẹ̀—múra láti gòkè lọ láti kọ ilé Olúwa ní Jerusalẹmu.
Wtedy powstali przywódcy rodów Judy i Beniamina, kapłani i Lewici, wszyscy, których ducha Bóg pobudził, aby poszli budować dom PANA, będący w Jerozolimie.
6 Gbogbo àwọn aládùúgbò wọn ràn wọ́n lọ́wọ́ pẹ̀lú ohun èlò ti fàdákà àti wúrà, pẹ̀lú onírúurú ohun ìní àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹ̀bùn iyebíye, ní àfikún si gbogbo àwọn ọrẹ àtinúwá.
Wszyscy, którzy [mieszkali] dokoła nich, wspomogli ich naczyniem srebrnym, złotem, dobytkiem, bydłem i kosztownościami, poza tym wszystkim, co dobrowolnie ofiarowano.
7 Ní àfikún, ọba Kirusi mú àwọn ohun èlò tí ó jẹ́ ti ilé Olúwa jáde wá, tí Nebukadnessari ti kó lọ láti Jerusalẹmu tí ó sì ti kó sí ilé òrìṣà rẹ̀.
Również król Cyrus wyniósł naczynia domu PANA, które Nabuchodonozor zabrał z Jerozolimy, i złożył w domu swego boga.
8 Kirusi ọba Persia pàṣẹ fún Mitredati olùṣọ́ ilé ìṣúra láti kó wọn jáde, ó sì kà wọ́n fún Ṣeṣbassari ìjòyè Juda.
Wyniósł je Cyrus, król Persji, przez ręce skarbnika Mitredata, który rozliczył się z nich z Szeszbassarem, księciem Judy.
9 Èyí ni iye wọn. Ọgbọ̀n àwo wúrà 30 Ẹgbẹ̀rún àwo fàdákà 1,000 Àwo ìrúbọ fàdákà mọ́kàndínlọ́gbọ̀n 29
A oto ich liczba: trzydzieści czasz złotych, tysiąc czasz srebrnych, dwadzieścia dziewięć noży;
10 Ọgbọ̀n àdému wúrà 30 Irinwó ó lé mẹ́wàá oríṣìí àdému fàdákà mìíràn 410 Ẹgbẹ̀rún kan àwọn ohun èlò mìíràn 1,000
Trzydzieści złotych pucharów, czterysta dziesięć pucharów mniejszej wartości i tysiąc innych naczyń.
11 Gbogbo ohun èlò wúrà àti ti fàdákà ní àpapọ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ó lé irinwó. Ṣeṣbassari kó gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí wá pẹ̀lú àwọn ìgbèkùn tí ó gòkè wá láti Babeli sí Jerusalẹmu.
Wszystkich naczyń złotych i srebrnych – pięć tysięcy czterysta. Wszystko to zabrał Szeszbassar, gdy lud powrócił z niewoli, z Babilonu do Jerozolimy.

< Ezra 1 >