< 2 Chronicles 17 >

1 Jehoṣafati ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀ ó sì mú ara rẹ̀ lágbára sí lórí Israẹli.
Potem w jego miejsce królował Jehoszafat, jego syn, i umocnił się przeciwko Izraelowi.
2 Ó sì fi ogun sínú gbogbo ìlú olódi Juda ó sì kó ẹgbẹ́ ológun ní Juda àti nínú ìlú Efraimu tí Asa baba rẹ̀ ti gbà.
I umieścił wojska we wszystkich warownych miastach Judy. Umieścił też załogi w ziemi Judy i w miastach Efraima, które zdobył Asa, jego ojciec.
3 Olúwa sì wà pẹ̀lú Jehoṣafati nítorí, ní ọdún àkọ́kọ́ rẹ̀, ó rìn ní ọ̀nà ti baba rẹ̀ Dafidi ti rìn, kò sì fi ọ̀ràn lọ Baali.
A PAN był z Jehoszafatem, ponieważ chodził on pierwszymi drogami swego ojca Dawida i nie szukał Baalów;
4 Ṣùgbọ́n ó wá Ọlọ́run baba rẹ̀ kiri ó sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ̀ ju iṣẹ́ Israẹli.
Lecz szukał Boga swego ojca i postępował według jego przykazań, a nie według czynów ludu Izraela.
5 Olúwa sì fi ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ lábẹ́ àkóso rẹ̀, gbogbo Juda sì mú ẹ̀bùn wá fún Jehoṣafati, bẹ́ẹ̀ ni ó sì ní ọrọ̀ àti ọlá lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
I PAN utwierdził królestwo w jego rękach, a cały lud Judy składał dary Jehoszafatowi, tak że miał wiele bogactwa i wielką sławę.
6 Ọkàn rẹ̀ sì gbé sókè si ọ̀nà Olúwa, pẹ̀lúpẹ̀lú, ó sì mú ibi gíga wọn àti ère òrìṣà Aṣerah kúrò ní Juda.
Umocniło się jego serce w drogach PANA, tym bardziej więc znosił wyżyny i gaje z ziemi Judy.
7 Ní ọdún kẹta ìjọba rẹ̀, ó rán àwọn ìjòyè rẹ̀ Bene-Haili, Obadiah, Sekariah, Netaneli, Mikaiah láti máa kọ́ ni nínú ìlú Juda.
Potem w trzecim roku swojego panowania posłał swoich książąt: Ben-Chaila, Obadiasza, Zachariasza, Netaneela i Micheasza, aby nauczali w miastach Judy.
8 Wọ́n sì ní díẹ̀ lára àwọn ọmọ Lefi, àní Ṣemaiah, Netaniah, Sebadiah, Asaheli, Ṣemiramotu, Jehonatani, Adonijah, Tobijah àti Tobu-Adonijah àti àwọn àlùfáà Eliṣama àti Jehoramu.
[Posłał] z nimi także Lewitów: Szemajasza, Netaniasza, Zebadiasza, Asahela, Szemiramota, Jehonatana, Adoniasza, Tobiasza i Tobadoniasza – Lewitów, a z nimi Eliszamę i Jehorama, kapłanów.
9 Wọ́n ń kọ́ ni ní agbègbè Juda, wọ́n mú ìwé òfin Olúwa wọ́n sì rìn yíká gbogbo àwọn ìlú Juda wọ́n sì ń kọ́ àwọn ènìyàn.
Nauczali oni w Judzie, mając ze sobą księgę Prawa PANA, i obchodzili wszystkie miasta Judy, i nauczali lud.
10 Ìbẹ̀rù Olúwa bà lórí gbogbo ìjọba ilẹ̀ tí ó yí Juda ká, dé bi pé wọn kò bá Jehoṣafati jagun.
A bojaźń PANA padła na wszystkie królestwa ziemi [położone] dokoła Judy i nie śmiały walczyć przeciwko Jehoszafatowi.
11 Lára àwọn ará Filistini, mú ẹ̀bùn fàdákà gẹ́gẹ́ bí owó ọba wá fún Jehoṣafati, àwọn ará Arabia sì mú ọ̀wọ́ ẹran wá fún un, ẹgbàarindín ní ọ̀ọ́dúnrún àgbò àti ẹgbàarindín ní ọ̀ọ́dúnrún òbúkọ.
[Niektórzy] z Filistynów przynosili Jehoszafatowi dary i daniny w srebrze. Arabowie przyprowadzili mu trzody: siedem tysięcy siedemset baranów i siedem tysięcy siedemset kozłów.
12 Jehoṣafati sì ń di alágbára nínú agbára sí i, ó sì kọ́ ilé olódi àti ilé ìṣúra púpọ̀ ní Juda
I Jehoszafat wzrastał coraz bardziej w potęgę, i budował w Judzie zamki oraz miasta spichlerze.
13 Ó sì ní ìṣúra ní ìlú Juda. Ó sì tún ní àwọn alágbára jagunjagun akọni ọkùnrin ní Jerusalẹmu.
Podjął wiele prac w miastach Judy. I miał wielu dzielnych i potężnych wojowników w Jerozolimie.
14 Iye wọn gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn nìwọ̀nyí. Láti Juda, àwọn olórí ìpín kan ti ẹgbẹ̀rún: Adina olórí, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún alágbára akọni ọkùnrin.
A oto [jest] ich spis według ich rodów: z Judy tysiącznikami byli: dowódca Adna, a z nim trzysta tysięcy dzielnych wojowników.
15 Èkejì, Jehohanani olórí, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlá ọkùnrin;
Przy nim [stał] dowódca Jehochanan, a z nim dwieście osiemdziesiąt tysięcy.
16 àtẹ̀lé Amasiah ọmọ Sikri, ẹni tí ó fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ Olúwa pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́wàá.
Przy nim – Amazjasz, syn Zikriego, który dobrowolnie poświęcił się PANU, a z nim dwieście tysięcy dzielnych wojowników.
17 Láti ọ̀dọ̀ Benjamini: Eliada, alágbára akọni ọkùnrin pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́wàá àwọn jagunjagun ọkùnrin pẹ̀lú ọrun àti àpáta ìhámọ́ra;
A z synów Beniamina: Eliada, dzielny wojownik, a z nim dwieście tysięcy mężczyzn uzbrojonych w łuki i tarcze.
18 àtẹ̀lé Jehosabadi, pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án jagunjagun ọkùnrin múra sílẹ̀ fún ogun.
A przy nim – Jehozabad, a z nim sto osiemdziesiąt tysięcy gotowych do boju.
19 Wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin tí ń dúró níwájú ọba, ní àyíká àwọn ẹni tí ó fi sínú ìlú olódi ní àyíká gbogbo Juda.
Oni służyli królowi, nie licząc tych, których król rozmieścił w warownych miastach po całej ziemi Judy.

< 2 Chronicles 17 >