< 2 Chronicles 11 >

1 Nígbà tí Rehoboamu dé Jerusalẹmu, ó kó ilé Juda àti Benjamini jọ, ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n jẹ́ ológun, láti bá Israẹli jà kí ó lè mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ rẹ̀.
Forsothe Roboam cam in to Jerusalem, and clepide togidere al the hows of Juda and of Beniamyn, `til to nyne scoore thousynde of chosen men and werriouris, for to fiyte ayens Israel, and for to turne his rewme to hym.
2 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
And the word of the Lord was maad to Semeye, the man of God,
3 “Wí fún Rehoboamu ọmọ Solomoni ọba Juda, sí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ní Juda àti Benjamini,
and seide, Speke thou to Roboam, the sone of Salomon, kyng of Juda, and to al Israel, which is in Juda and Beniamyn; The Lord seith these thingis,
4 ‘Èyí ní ohun tí Olúwa wí. Ẹ má ṣe gòkè lọ láti lọ jà pẹ̀lú arákùnrin yín, ẹ lọ sílé, gbogbo yín, nítorí ti ìṣe mi nìyí.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tẹ̀lé ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wọ́n sì padà sẹ́yìn láti yan lọ dojúkọ Jeroboamu.
Ye schulen not stie, nethir ye schulen fiyte ayens youre britheren; ech man turne ayen in to his hows, for this thing is doon bi my wille. And whanne thei hadden herd the word of the Lord, thei turneden ayen, and yeden not ayens kyng Jeroboam.
5 Rehoboamu ń gbe ní Jerusalẹmu ó sì kọ́ àwọn ìlú fún olódi ní Juda.
Forsothe Roboam dwellide in Jerusalem, and he bildide wallid citees in Juda;
6 Bẹtilẹhẹmu, Etamu, Tekoa,
and bildide Bethleem, and Ethan, and Thecue, and Bethsur;
7 Beti-Suri, Soko, Adullamu,
and Sochot, and Odollam;
8 Gati, Meraṣa Sifi,
also and Jeth, and Maresa, and Ziph;
9 Adoraimu, Lakiṣi, Aseka
but also Huram, and Lachis, and Azecha;
10 Sora, Aijaloni, àti Hebroni. Wọ̀nyí ni àwọn ìlú ìdáàbòbò ní Juda àti Benjamini.
and Saraa, and Hailon, and Ebron, that weren in Juda and Beniamyn, ful strong citees.
11 Ó sì mú àwọn ìlú olódi lágbára, ó sì fi àwọn balógun sínú wọn àti àkójọ oúnjẹ, àti òróró àti ọtí wáìnì.
And whanne he hadde closid tho with wallis, he settide `in tho citees princes, and bernes of metis, that is, of oile, and of wyn.
12 Àti ní olúkúlùkù ìlú ni ó fi asà àti ọ̀kọ̀ sí, ó sì mú wọn lágbára gidigidi, ó sì ní Juda àti Benjamini lábẹ́ rẹ̀.
But also in ech citee he made placis of armuris of scheeldis, and speris, and he made tho strong with most diligence; and he regnyde on Juda and Beniamyn.
13 Àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi, láti gbogbo ẹ̀yà wọn jákèjádò Israẹli wà ní ẹ̀bá rẹ̀.
Sotheli the preestis and dekenes, that weren in al Israel, camen to hym fro alle her seetis,
14 Àwọn ará Lefi fi ìgbèríko sílẹ̀, wọ́n sì wá sí Juda àti Jerusalẹmu nítorí Jeroboamu àti àwọn ọmọ rẹ̀, ti kọ̀ wọ́n sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà Olúwa.
and forsoken her subarbis and possessiouns, and thei passiden to Juda and to Jerusalem; for Jeroboam and hise aftir comeris hadden cast hem a wey, that thei schulden not be set in preesthod of the Lord;
15 Ó sì yan àwọn àlùfáà tirẹ̀ fún àwọn ibi gíga wọ̀n-ọn-nì, àti fún àwọn ère òbúkọ, àti fún ẹgbọrọ màlúù tí ó ṣe.
which Jeroboam made to hym preestis of hiye places, and of feendis, and of caluys, which he hadde maad.
16 Àwọn tó wá láti gbogbo ẹ̀yà Israẹli tí wọ́n fi ọkàn wọn fún wíwá Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, tẹ̀lé àwọn ará Lefi lọ sí Jerusalẹmu láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run baba a wọn.
But also of alle the linagis of Israel, whiche euer yauen her herte to seke the Lord God of Israel, thei camen to Jerusalem for to offre her sacrifices bifor the Lord God of her fadris.
17 Ó fún ìjọba Juda ní agbára, ó sì ti Rehoboamu ọmọ Solomoni lẹ́yìn fún ọdún mẹ́ta nítorí ọdún mẹ́ta ni wọ́n fi rìn ní ọ̀nà ti Dafidi àti Solomoni ní àkókò yí.
And thei strengthiden the rewme of Juda, and strengthiden Roboam, the sone of Salomon, bi thre yeer; for thei yeden in the weies of Dauid, and of Salomon, oneli bi thre yeer.
18 Rehoboamu fẹ́ Mahalati tí ó jẹ́ ọmọbìnrin ti ọmọkùnrin Dafidi Jerimoti bi àti ti Abihaili, ọmọbìnrin ti ọmọkùnrin Jese Eliabu bí.
Forsothe Roboam weddide a wijf Malaoth, the douytir of Jerymuth, sone of Dauid, and Abiail, the douytir of Heliab, sone of Ysaye;
19 Ó bí àwọn ọmọ fún un: Jeuṣi, Ṣemariah àti Sahamu.
and sche childide to hym sones, Yeus, and Somorie, and Zerei.
20 Nígbà náà, ó fẹ́ Maaka ọmọbìnrin Absalomu, tí ó bí Abijah fún Attai, Sisa àti Ṣelomiti.
Also after this wijf he took Maacha, the douyter of Abissalon, and sche childide to hym Abia, and Thai, and Ziza, and Salomyth.
21 Rehoboamu fẹ́ràn Maaka ọmọbìnrin Absalomu ju èyíkéyìí nínú àwọn ìyàwó rẹ̀ àti àwọn àlè rẹ̀ lọ. Ní gbogbo rẹ̀, ó ní ìyàwó méjìdínlógún àti ọgọ́ta àlè ọmọkùnrin méjìdínlọ́gbọ̀n àti ọgọ́ta ọmọbìnrin.
Forsothe Roboam louyde Maacha, the douytir of Abissalon, aboue alle hise wyues and secundarie wyues. Forsothe he hadde weddid eiytene wyues, sotheli sixti secundarie wyues; and he gendride eiyte and twenti sones, and sixti douytris.
22 Rehoboamu yan Abijah ọmọ Maaka láti jẹ́ olóyè ọmọ-aládé láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀, kí ó ba à lè ṣe é ní ọba.
Sotheli he ordeynede Abia, the sone of Maacha, in the heed, duyk ouer alle hise britheren; for he thouyte to make Abia kyng,
23 Ó hùwà ọlọ́gbọ́n, nípa fí fọ́n díẹ̀ nínú àwọn ọmọ rẹ̀ jákèjádò ká àwọn agbègbè Juda àti Benjamini àti sí gbogbo àwọn ìlú ńlá olódi. Ó fún wọn ní ọ̀pọ̀ ohun tí wọ́n fẹ́, ó sì fẹ́ ọ̀pọ̀ ìyàwó fún wọn.
for he was wisere and myytiere ouer alle hise sones, and in alle the coostis of Juda and of Beniamyn, and in alle wallid citees; and he yaf to hem ful many metis, and he had many wyues.

< 2 Chronicles 11 >