< 2 Chronicles 15 >

1 Ẹ̀mí Ọlọ́run wá sórí Asariah ọmọ Odedi.
Forsothe Azarie, the sone of Obeth, whanne the spirit of the Lord was comyn in to hym,
2 Ó jáde lọ bá Asa, ó sì wí fún un pé, “Tẹ́tí si mi Asa, àti gbogbo Juda àti Benjamini. Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nígbà tí ìwọ bá wà pẹ̀lú rẹ̀. Ti ìwọ bá wá a, ìwọ yóò rí i ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ bá kọ̀ ọ́ sílẹ̀, òun yóò kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
yede out in to the metyng of Asa; and seide to hym, Asa and al Juda and Beniamyn, here ye me; the Lord is with you, for ye weren with hym; if ye seken hym, ye schulen fynde hym; sotheli if ye forsaken hym, he schal forsake you.
3 Fún ọjọ́ pípẹ́ ni Israẹli ti wà láì sin Ọlọ́run òtítọ́, àti láìní àlùfáà ti ń kọ́ ni, àti láìní òfin.
Forsothe many daies schulen passe in Israel with outen veri God, and without preest, and without techere, and without lawe.
4 Ṣùgbọ́n nínú ìpọ́njú wọn, wọ́n yí padà si Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wọ́n sì wa kiri. Wọ́n sì ri i ní ẹ̀gbẹ́ wọn.
And whanne thei turnen ayen in her angwisch, and crien to the Lord God of Israel, and seken hym, thei schulen fynde hym.
5 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ó léwu kí ènìyàn máa rìn ìrìnàjò kiri, nítorí tí gbogbo àwọn olùgbé ilẹ̀ náà wà nínú làálàá ńlá.
In that tyme schal not be pees to go out and to go in, but dredis on al side on alle the dwelleris of londis.
6 Orílẹ̀-èdè kan ń run èkejì àti ìlú kan sí òmíràn nítorí Ọlọ́run ń yọ wọ́n lẹ́nu pẹ̀lú oríṣìíríṣìí ìpọ́njú.
For a folk schal fiyte ayens folk, and a citee ayens a citee, for the Lord schal disturble hem in al anguysch;
7 Ṣùgbọ́n fun ìwọ, jẹ́ alágbára, kí ó má sì ṣe ṣàárẹ̀. Nítorí tí a ó fi èrè sí iṣẹ́ ẹ̀ rẹ.”
but be ye coumfortid, and youre hondis be not slakid; for mede schal be to youre werk.
8 Nígbà tí Asa gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí àti àsọtẹ́lẹ̀ Asariah ọmọ Odedi wòlíì, ó mú àyà rẹ̀ le. Ó sì mú gbogbo ohun ìríra kúrò ní gbogbo ilẹ̀ Juda àti Benjamini àti kúrò nínú àwọn ìlú tí ó ti fi agbára mú ní orí òkè Efraimu. Ó tún pẹpẹ Olúwa ṣe tí ó wà ní iwájú portiko ti ilé Olúwa.
And whanne Asa hadde herd this thing, that is, the wordis and profesye of Asarie, the sone of Obed, the profete, he was coumfortid, and he dide a wei alle the idols fro al the lond of Juda and of Beniamyn, and fro the citees whiche he hadde take of the hil of Effraym. And he halewide the auter of the Lord, that was bifor the porche of the hows of the Lord.
9 Nígbà náà, ó pe gbogbo Juda àti Benjamini jọ àti àwọn ènìyàn láti Efraimu, Manase àti Simeoni tí ó ti ṣe àtìpó ní àárín wọn. Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Israẹli nígbà tí wọ́n rí i wí pé Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
And he gaderide togidere al Juda and Beniamyn, and with hem the comelyngis of Effraym, and of Manasses, and of Symeon; for manye of Israel, seynge that his Lord God was with hym, fledden ouer to hym.
10 Wọ́n péjọ sí Jerusalẹmu ní oṣù kẹta ọdún kẹ́ẹ̀dógún ti ìjọba Asa.
And whanne thei hadden comun in to Jerusalem, in the thridde monethe, in the fiftenthe yeer of the rewme of Asa,
11 Ní àkókò yìí, wọ́n rú ẹbọ sí Olúwa ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin akọ màlúù àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn àti àwọn ewúrẹ́ láti ibi ìkógun tí wọ́n ti kó padà.
thei offriden `to the Lord in that dai, bothe of the spuylis and of the prey, which thei hadden brouyt, seuene hundrid oxis, and seuene thousynde wetheris.
12 Wọ́n sì tún dá májẹ̀mú láti wá Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn tinútinú wọn àti tọkàntọkàn wọn.
And Asa entride bi custom to make strong the boond of pees, that thei schulden seke the Lord God of her fadris in al her herte, and in al her soule.
13 Pé ẹnikẹ́ni tí kò bá wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli, pípa ni á ó pa á láti ẹni kékeré dé orí ẹni ńlá àti ọkùnrin àti obìnrin.
Sotheli he seide, If ony man sekith not the Lord God of Israel, die he, fro the leeste `til to the mooste, fro man `til to womman.
14 Wọ́n sì búra ní ohùn rara fún Olúwa àti pẹ̀lú ìhó ńlá àti pẹ̀lú ìpè àti pẹ̀lú fèrè.
And alle that weren in Juda sworen with cursyng to the Lord, with greet vois, in hertli song, and in sown of trumpe, and in sown of clariouns;
15 Gbogbo Juda yọ̀ nípa ìbúra náà nítorí wọ́n ti búra tinútinú wọn wọ́n sì fi gbogbo ìfẹ́ inú wọn wá a, wọ́n sì rí i, Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi yí káàkiri.
for thei sworen in al her herte, and in al the wille thei souyten hym, and founden hym; and the Lord yaf to hem reste bi cumpas.
16 Ọba Asa sì mú Maaka ìyá ńlá rẹ̀ kúrò láti máa ṣe ayaba, nítorí tí ó yá ère kan fún Aṣerah òrìṣà rẹ̀. Asa sì ké ère náà lulẹ̀, ó sì jó o ní àfonífojì Kidironi.
But also he puttide doun Maacha, the modir of `Asa the kyng, fro the streit empire, for sche hadde made in a wode the symylacre, `ether licnesse, of a mannus yerde; and he al to-brak al `that symylacre, and pownede it in to gobetis, and `brente it in the stronde of Cedron.
17 Ṣùgbọ́n a kò mú àwọn ibi gíga náà kúrò ní Israẹli; síbẹ̀síbẹ̀ ọkàn Asa wà ní pípé ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo.
But hiy places weren left in Israel; netheles the herte of Asa was riytful in alle hise daies.
18 Ó sì mú àwọn ohun mímọ́ náà ti baba rẹ̀ àti àwọn ohun mímọ́ ti òun tìkára rẹ̀ tirẹ̀ wá sínú ilé Ọlọ́run, wúrà àti fàdákà àti àwọn ohun èlò náà.
And he brouyte in to the hows of the Lord tho thingis that his fadir avowide, siluer and gold, and dyuerse purtenaunce of vessels;
19 Kò sí ogun mọ́ títí fún ọdún márùndínlógójì ti ìjọba Asa.
sotheli batel was not `til to the threttithe yeer of the rewme of Asa.

< 2 Chronicles 15 >