< Ісая 31 >
1 Горе тим, що в Єгипет по поміч ідуть, що на ко́ней спираються, і на колесни́ці надію свою́ покладають, — вони бо числе́нні! та на верхівці́в, — бо вони дуже сильні! але на Святого Ізраїлевого не дивляться, і до Господа не зверта́ються!
Ègbé ni fún àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti fún ìrànlọ́wọ́, tí wọn gbẹ́kẹ̀lé ẹṣin tí wọ́n fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ kẹ̀kẹ́-ẹṣin wọn àti agbára ńlá àwọn ẹlẹ́ṣin wọn, ṣùgbọ́n tiwọn kò bojú wo Ẹni Mímọ́ Israẹli n nì, tàbí kí wọn wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Olúwa.
2 Та мудрий і Він, і спрова́дить лихе, і Своїх слів не відмінить, і піді́йметься Він проти дому безбожних, і проти помочі несправедливих.
Síbẹ̀síbẹ̀ òun pẹ̀lú jẹ́ ọlọ́gbọ́n ó sì lè mú ìparun wá; òun kì í kó ọ̀rọ̀ rẹ̀ jẹ. Òun yóò dìde sí ilé àwọn ìkà, àti sí àwọn tí ń ṣe ìrànlọ́wọ́ fún aṣebi.
3 А Єгипет — не Бог, а люди́на, а коні їхні — тіло, не дух: як простя́гне Господь Свою руку, то спіткне́ться пома́гач, впаде́ і підпома́ганий, — і ра́зом вони всі погинуть!
Ṣùgbọ́n ènìyàn lásán ni àwọn ará Ejibiti wọn kì í ṣe Ọlọ́run; ẹran-ara ni àwọn ẹṣin wọn, kì í ṣe ẹ̀mí. Nígbà tí Olúwa bá na ọwọ́ rẹ̀ jáde, ẹni náà tí ó ń ṣèrànwọ́ yóò kọsẹ̀, ẹni náà tí à ń ràn lọ́wọ́ yóò ṣubú; àwọn méjèèjì yóò sì jùmọ̀ parun.
4 Бо до мене Господь сказав так: Як му́ркає лев чи левчу́к над своєю здоби́ччю, хоч покликана буде на нього юрба́ пастухів, він голосу їхнього не лякається, та не боїться їхнього крику, — так зі́йде Господь Саваот воюва́ти на Сіонській горі та на взгі́р'ї її!
Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Gẹ́gẹ́ bí i kìnnìún ti í ké àní kìnnìún ńlá lórí ẹran ọdẹ rẹ̀ bí a tilẹ̀ rí ẹgbẹ́ àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí a sì pè wọ́n papọ̀ láti kojú rẹ̀, ẹ̀rù kò lè bà á pẹ̀lú igbe wọn akitiyan wọn kò sì lè dí i lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò sọ̀kalẹ̀ wá láti jagun lórí òkè Sioni àti lórí ibi gíga rẹ̀.
5 Як пта́хи летю́чі пташа́т, так Єрусалима Господь Саваот охоро́нить, охоро́нить літа́ючи, та збереже́, пощади́ть та врятує!
Gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹyẹ ti ń rábàbà lókè Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò dáàbò bo Jerusalẹmu, Òun yóò dáàbò bò ó, yóò sì tú u sílẹ̀ Òun yóò ré e kọjá yóò sì gbà á sílẹ̀.”
6 Верніться до Того, від Кого далеко відпа́ли, сино́ве Ізраїлеві!
Ẹ padà sọ́dọ̀ ẹni tí ẹ ti ṣọ̀tẹ̀ sí gidigidi, ẹ̀yin ọmọ Israẹli.
7 Бо дня того обри́дить собі чоловік божків срібних своїх та бовва́нів своїх золотих, що вам наробили на гріх руки ваші.
Nítorí ní ọjọ́ náà, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín yóò kọ àwọn ère fàdákà àti wúrà tí ọwọ́ ẹ̀ṣẹ̀ yín ti ṣe.
8 І Ашшу́р упаде́ від меча не чоловіка, і його пожере́ меч не люди́ни; і він побіжить не перед мечем, і стануть його юнаки́ кріпака́ми.
“Asiria yóò ṣubú lọ́wọ́ idà kan tí kò ti ọwọ́ ènìyàn wá; idà tí kì í ṣe ti ẹ̀dá alààyè ni yóò pa wọ́n. Wọn yóò sì sá níwájú idà náà àti àwọn ọmọkùnrin wọn ni a ó fún ní iṣẹ́ ipá ṣe.
9 А скеля його промине́ться від стра́ху, і владики його затриво́жаться перед прапором. Так говорить Господь, що має огонь на Сіоні, а в Єрусалимі у Нього горни́ло.
Àpáta rẹ yóò kọjá lọ fún ẹ̀rù; àwọn olórí rẹ yóò bẹ̀rù asia náà,” ni Olúwa wí, ẹni tí iná rẹ̀ ń bẹ ní Sioni, ẹni tí ìléru rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu.