< Ісая 30 >
1 Горе синам неслухня́ним, говорить Господь, що чинять наради, які не від Мене, і складають умови, — та без Духа Мого, щоб додати гріх на гріх,
“Ègbé ni àwọn ọmọ fún orílẹ̀-èdè alágídí,” ni Olúwa wí, “Fún àwọn tí ó gbé ètò jáde tí kì í ṣe tèmi, tí wọ́n ń gbìmọ̀ pọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa Ẹ̀mí mi, tí wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ lórí ẹ̀ṣẹ̀;
2 що йдуть, щоб зійти до Єгипту, але Моїх уст не питали, щоб за́хисту у фараона шукати, і щоб сховатися в тіні Єгипту!
tí wọ́n lọ sí Ejibiti láìṣe fún mi, tí ó ń wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Farao fún ààbò, sí òjìji Ejibiti fún ibi ìsádi.
3 І стане вам соромом за́хист отой фараонів, а хова́ння у тіні Єгипту — за га́ньбу,
Ṣùgbọ́n ààbò Farao yóò jásí ìtìjú fún un yín, òjìji Ejibiti yóò mú àbùkù bá a yín.
4 бо в Цоані були його провідники́, і його посланці́ до Ханесу прийшли.
Bí àwọn olórí rẹ tilẹ̀ wà ní Ṣoani, tí àwọn ikọ̀ wọn sì ti dé sí Hanisi,
5 Вони посоро́млені будуть усі за наро́д, що не буде кори́сний для них, що не буде на поміч і не на пожи́ток, а на сором та га́ньбу.
gbogbo wọn ni a ó dójútì, nítorí àwọn ènìyàn kan tí kò wúlò fún wọn, tí kò mú ìrànlọ́wọ́ tàbí àǹfààní wá, bí kò ṣe àbùkù àti ìdójúti ni.”
6 Пророцтво про Бегемота пі́вдня. В краю у́тиску та переслі́дування, звідки леви́ця та лев, гадюка й огни́стий летю́чий драко́н, носять багатство своє на хребті́ молодих ослюкі́в, і скарби свої на верблю́жім горбі́ до наро́ду, який не поможе.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ sí àwọn ẹranko tí ó wà ní gúúsù. Láàrín ilẹ̀ ìnira àti ìpọ́njú, ti kìnnìún àti abo kìnnìún ti paramọ́lẹ̀ àti ejò olóró, àwọn ikọ̀ náà kó ẹrù àti ọrọ̀ wọn lẹ́yìn àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ohun ìní wọn ní orí àwọn ìbákasẹ, sí orílẹ̀-èdè aláìlérè,
7 А Єгипет, — його поміч марна́ та пуста́, тому́ то я кликнув на теє: Рагав, сидіти спокійно!
sí Ejibiti tí ìrànlọ́wọ́ rẹ̀ kò wúlò rárá. Nítorí náà mo pè é ní Rahabu aláìlẹ́ṣẹ̀ nǹkan kan.
8 Тепер увійди, напиши на табли́ці для них, і в книжці спиши це, і нехай на пізніші часи́ воно буде і сві́дком навіки.
Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọ ọ́ sí ara wàláà fún wọn, tẹ̀ ẹ́ sí ara ìwé kíká, pé fún àwọn ọjọ́ tí ó ń bọ̀ kí ó sì lè jẹ́ ẹ̀rí ayérayé.
9 Бо це неслухняний наро́д, це брехливі сини́, сини́, що не хочуть послухати науки Господньої,
Àwọn wọ̀nyí jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn àti ẹlẹ́tanu ọmọ, àwọn ọmọ tí wọn kò ṣetán láti tẹ́tí sí ìtọ́ni Olúwa.
10 що говорять прови́дцям: „Не бачте!“а пророкам: „Не пророкуйте правдивого нам, говоріть нам гладе́ньке, передба́чте ома́нливе,
Wọ́n sọ fún àwọn aríran pé, “Ẹ má ṣe rí ìran mọ́!” Àti fún àwọn wòlíì, “Ẹ má ṣe fi ìran ohun tí ó tọ́ hàn wá mọ́! Ẹ sọ ohun tí ó tura fún wa, ẹ sàsọtẹ́lẹ̀ ẹ̀tàn.
11 уступіться з дороги, збо́чте з путі, заберіть з-перед нас Святого Ізраїлевого!“
Ẹ fi ọ̀nà yìí sílẹ̀, ẹ kúrò ní ọ̀nà yìí ẹ dẹ́kun à ń dojú ìjà kọ wá pẹ̀lú Ẹni Mímọ́ Israẹli!”
12 Тому́ промовляє Святий Ізраїлів так: За те, що ви не́хтуєте оцим словом, і надію кладе́те на тиск та круті́йство, і на це опира́єтеся,
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ẹni Mímọ́ Israẹli wí: “Nítorí pé ẹ ti kọ ọ̀rọ̀ yìí sílẹ̀, ẹ gbára lé ìnilára kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé ẹ̀tàn,
13 тому буде для вас ця прови́на, як ви́лім, що має впасти, що зя́є на мурі високім, що нагло, рапто́вно приходить руїна його!
ẹ̀ṣẹ̀ yìí yóò rí fún ọ gẹ́gẹ́ bí ògiri gíga, tí ó sán tí ó sì fì tí ó sì wó lójijì, àti ní ìṣẹ́jú kan.
14 I Він поруйнує його, як руйнується по́суд ганча́рський, розбиваючи без милосердя його, і в ула́мках його не знайдеться ані черепка́, щоб із о́гнища взяти огню́ чи води зачерпну́ти з кринички.
Yóò sì fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ bí àpáàdì tí a fọ́ pátápátá àti pé a kò ní rí ẹ̀rún kan nínú àfọ́kù rẹ̀, fún mímú èédú kúrò nínú ààrò tàbí gbígbọ́n omi jáde kúrò nínú àmù.” ()
15 Бо так промовляє Господь, Бог, Святий Ізраїлів: Коли ви наве́рнетесь та спочи́нете, то врято́вані будете, сила вам буде в ути́шенні та в сподіва́нні. Та ви не хотіли,
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli wí: “Nínú ìrònúpìwàdà àti ìsinmi ni ìgbàlà rẹ wà, ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé ni agbára rẹ wà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò ní ọ̀kankan nínú wọn.
16 і казали: „О ні, бо на ко́нях втечемо“, тому́ то втікати ви будете, „На баски́х ми поїдемо“, тому стануть баски́ми пого́ничі ваші!
Ẹ̀yin wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò sálọ lórí ẹṣin.’ Nítorí náà ẹ̀yin yóò sá! Ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa yóò gun àwọn ẹṣin tí ó yára lọ.’ Nítorí náà àwọn tí ń lé e yín yóò yára!
17 Від крику одно́го — поли́не одна тисяча, від крику п'ятьох — дремене́те ви всі, аж зоста́нетеся, немов що́гла ота на верше́чку гори, і немов пра́пор на взгі́р'ї!
Ẹgbẹ̀rún yóò sá nípa ìdẹ́rùbà ẹnìkan; nípa ìdẹ́rùbà ẹni márùn-ún gbogbo yín lẹ ó sálọ, títí a ó fi yín sílẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí igi àsíá ní orí òkè, gẹ́gẹ́ bí àsíá lórí òkè.”
18 І проте Господь буде чекати, щоб помилувати вас, і тому́ Він піді́йметься, щоб милосердя вчинити над вами. Бо Господи — то Бог правосу́ддя: блаженні всі ті, хто наді́ю на Нього кладе́!
Síbẹ̀síbẹ̀ Olúwa sì fẹ́ síjú àánú wò ọ́; ó dìde láti ṣàánú fún ọ. Nítorí Olúwa jẹ́ Ọlọ́run ìdájọ́. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó dúró dè é!
19 Бо ти, о наро́де в Сіоні, що в Єрусалимі сидиш, плакати — не будеш ти плакати: милости́вим поправді Він буде до тебе на голос блага́ння твого, і як почує його, відповість Він тобі.
Ẹ̀yin ènìyàn Sioni, tí ń gbé ní Jerusalẹmu, ìwọ kì yóò sọkún mọ́. Báwo ni àánú rẹ̀ yóò ti pọ̀ tó nígbà tí ìwọ bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́! Bí ó bá ti gbọ́, òun yóò dá ọ lóhùn.
20 І дасть вам Господь хліба в у́тиску і воду в гноби́тельстві, та твої вчителі́ вже не бу́дуть хова́тись, і очі твої вчителі́в твоїх бачити бу́дуть.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa fún ọ ní àkàrà ìyà àti omi ìpọ́njú, àwọn olùkọ́ rẹ kì yóò fi ara sin mọ́; pẹ̀lú ojú rẹ ni ìwọ ó rí wọn.
21 А коли ви відхи́литесь право́руч, чи пі́дете ліво́руч, то вуха твої будуть чути те слово, яке позад тебе казатиме: „Це та дорога, — просту́йте ви нею!“
Bí o bá yí sápá ọ̀tún tàbí apá òsì, etí rẹ yóò máa gbọ́ ohùn kan lẹ́yìn rẹ, wí pé, “Ọ̀nà nìyìí, máa rìn nínú rẹ̀.”
22 І нечистим учините ви поволо́ку бовва́нів своїх із срібла́ й покриття́ на божка́ золотого свого, розпоро́шиш ти їх, як нечисте, і „геть" скажеш йому́.
Lẹ́yìn náà ni ẹ ó ba àwọn ère yín jẹ́ àwọn tí ẹ fi fàdákà bò àti àwọn ère tí ẹ fi wúrà bò pẹ̀lú, ẹ ó sọ wọ́n nù bí aṣọ tí obìnrin fi ṣe nǹkan oṣù ẹ ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kúrò níbí!”
23 І Він пошле дощ на насіння твоє, яким бу́деш обсі́ювати землю, та хліб урожаю землі, — і пожи́вний та ситий він буде. Того дня на широкім пасо́виську па́стися буде твоя череда́,
Òun yóò sì rọ òjò fún un yín sí àwọn irúgbìn tí ẹ gbìn sórí ilẹ̀, oúnjẹ tí yóò ti ilẹ̀ náà wá yóò ní ọ̀rá yóò sì pọ̀. Ní ọjọ́ náà ni àwọn ẹran ọ̀sìn yín yóò máa jẹ koríko ní pápá oko tútù tí ó tẹ́jú.
24 а воли й віслюки́, що обро́блюють землю, будуть мі́шанку їсти солону, лопа́тою й ві́ялкою перечи́щену.
Àwọn màlúù àti àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó ń tú ilẹ̀ yóò jẹ oúnjẹ àdídùn tí a fi àmúga àti ṣọ́bìrì fọ́nkálẹ̀.
25 І на кожній високій горі та на кожному взгі́р'ї високому бу́дуть струмки́ та пото́ки води в день великого бо́ю, коли ба́шти попа́дають.
Ní ọjọ́ tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò sọ ẹ̀mí wọn nù nígbà tí ilé ìṣọ́ yóò wó lulẹ̀, odò omi yóò sàn lórí òkè gíga àti lórí àwọn òkè kékeré.
26 І світло місяця стане, немов світло сонця, світло ж сонця усе́меро буде ясніше, як сімох днів, у той день, як Господь перев'я́же злама́ння народу Свого та заго́їть пора́нення вдару Свого!
Òṣùpá yóò sì tàn bí oòrùn, àti ìtànṣán oòrùn yóò mọ́lẹ̀ ní ìlọ́po méje, gẹ́gẹ́ bí ìmọ́lẹ̀ odidi ọjọ́ méje, nígbà tí Olúwa yóò di ojú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ tí yóò sì wo ọgbẹ́ tí ó ti dá sí wọn lára sàn.
27 Ось Іме́ння Господнє прихо́дить здале́ка, палахкоти́ть Його гнів, і здійма́ється тя́жко: Його уста обу́рення повні, язик же Його, як жеру́щий огонь,
Kíyèsi i, orúkọ Olúwa ti òkèèrè wá pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti kurukuru èéfín tí ó nípọn; ètè rẹ̀ kún fún ìbínú ahọ́n rẹ̀ sì jẹ́ iná ajónirun.
28 Його ж подих, як пото́п заливни́й, що до шиї сяга́є, щоб просі́яти люди на ситі погибелі. І буде на ще́лепах людів вузде́чка, що тя́гне до блу́ду.
Èémí rẹ̀ sì dàbí òjò alágbára, tí ó rú sókè dé ọ̀run. Ó jọ àwọn orílẹ̀-èdè nínú kọ̀ǹkọ̀sọ̀; ó sì fi sí ìjánu ní àgbọ̀n àwọn ènìyàn láti ṣì wọ́n lọ́nà.
29 Буде пісня для вас, як за но́чі освя́чення свята, і радість сердечна, мов у то́го, хто ходить з сопі́лкою, щоб вийти на го́ру Господню до Скелі Ізраїля.
Ẹ̀yin ó sì kọrin gẹ́gẹ́ bí i ti alẹ́ tí ẹ̀ ń ṣe àjọyọ̀ àpéjọ mímọ́, ọkàn yín yóò yọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí àwọn ènìyàn gòkè lọ pẹ̀lú fèrè sí orí òkè Olúwa, àní sí àpáta Israẹli.
30 І Господь дасть почути велич голосу Свого, опуска́ння ж раме́на Свого покаже у гніві бурхли́вому та в огняно́му жеру́щому по́лум'ї, у бурі й дощі, та в камі́нному граді!
Olúwa yóò jẹ́ kí wọn ó gbọ́ ohùn ògo rẹ̀ yóò sì jẹ́ kí wọ́n rí apá rẹ̀ tí ó ń bọ̀ wálẹ̀ pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti iná ajónirun, pẹ̀lú mọ̀nàmọ́ná, àrá àti yìnyín.
31 Бо від голосу Господа буде лякатись Ашшу́р, що жезлом буде битий.
Ohùn Olúwa yóò fọ́ Asiria túútúú, pẹ̀lú ọ̀pá aládé rẹ̀ ni yóò lù wọ́n bolẹ̀.
32 І станеться, кожне уда́рення кия кара́ння Його, що на нього Господь покладе, буде з бу́бнами й а́рфою, і Він рухом Своєї руки воюватиме з ним у боя́х.
Ẹgba kọ̀ọ̀kan tí Olúwa bá gbé lé wọn pẹ̀lú ọ̀pá ìjẹníyà rẹ̀ yóò jẹ́ ti ṣaworo àti ti dùùrù, gẹ́gẹ́ bí ó ti ń bá wọn jà lójú ogun pẹ̀lú ìkùùkuu láti apá rẹ̀.
33 Бо давно пригото́влений То́фет, — пригото́влений він і для царя, глибоким, широким учи́нений; на бага́тті огню його й дров багате́нно, — запалить його подих Господній, немов би пото́ка сірча́ного!
A ti tọ́jú Tofeti sílẹ̀ tipẹ́tipẹ́, a ti tọ́jú rẹ̀ sílẹ̀ fún ọba. Ojú ààrò rẹ̀ ni a ti gbẹ́ jì tí ó sì fẹ̀, pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ iná àti igi ìdáná; èémí Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìṣàn sulfuru ń jó ṣe mú un gbiná.