< Esra 7 >

1 Efter en tids förlopp, under den persiske konungen Artasastas regering, hände sig att Esra, son till Seraja, son till Asarja, son till Hilkia,
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ní àkókò ìjọba ọba Artasasta ní Persia, Esra ọmọ Seraiah, ọmọ Asariah, ọmọ Hilkiah,
2 son till Sallum, son till Sadok, son till Ahitub,
ọmọ Ṣallumu, ọmọ Sadoku, ọmọ Ahitubu,
3 son till Amarja, son till Asarja, son till Merajot,
ọmọ Amariah, ọmọ Asariah, ọmọ Meraioti,
4 son till Seraja, son till Ussi, son till Bucki,
ọmọ Serahiah, ọmọ Ussi, ọmọ Bukki,
5 son till Abisua, son till Pinehas, son till Eleasar, son till Aron, översteprästen --
ọmọ Abiṣua, ọmọ Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni olórí àlùfáà—
6 det hände sig att denne Esra drog upp från Babel; han var en skriftlärd, väl förfaren i Moses lag, den som HERREN, Israels Gud, hade utgivit. Och konungen gav honom allt vad han begärde, eftersom HERRENS, hans Guds, hand var över honom.
Esra yìí sì gòkè wá láti Babeli. Olùkọ́ tí ó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa òfin Mose, èyí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ti fi fún wọn. Ọba sì fi gbogbo ohun tí ó béèrè fún un, nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára rẹ̀.
7 Också en del av Israels barn och av prästerna, leviterna, sångarna, dörrvaktarna och tempelträlarna drog upp till Jerusalem i Artasastas sjunde regeringsår.
Ní ọdún keje ọba Artasasta díẹ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà àti àwọn tí ń ṣiṣẹ́ nínú tẹmpili náà gòkè wá sí Jerusalẹmu.
8 Och han kom till Jerusalem i femte månaden, i konungens sjunde regeringsår.
Ní oṣù karùn-ún ọdún keje ọba yìí ni Esra dé sí Jerusalẹmu.
9 Ty på första dagen i första månaden blev det bestämt att man skulle draga upp från Babel; och på första dagen i femte månaden kom han till Jerusalem, eftersom Guds goda hand var över honom.
Ó bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ láti Babeli ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ó sì dé Jerusalẹmu ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run rẹ̀ wà ní ara rẹ̀.
10 Ty Esra hade vänt sitt hjärta till att begrunda HERRENS lag och göra efter den, och till att i Israel undervisa i lag och rätt.
Esra ti fi ara rẹ̀ jì fún kíkọ́ àti pípa òfin Olúwa mọ́, ó sì ń kọ́ òfin àti ìlànà Mose ní Israẹli.
11 Så stod nu skrivet i den skrivelse som konung Artasasta gav åt prästen Esra, den skriftlärde, som var lärd i det som HERREN hade bjudit och stadgat för Israel:
Èyí ni ẹ̀dà lẹ́tà ti ọba Artasasta fún àlùfáà Esra olùkọ́ni, ẹni tó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú àkọsílẹ̀ òfin àti ìlànà Olúwa fún Israẹli.
12 "Artasasta, konungarnas konung, till prästen Esra, den i himmelens Guds lag lärde, o. s. v. med övlig fortsättning.
Artasasta, ọba àwọn ọba. Sí àlùfáà Esra, olùkọ́ òfin Ọlọ́run ọ̀run. Àlàáfíà.
13 Jag giver härmed befallning att var och en i mitt rike av Israels folk och av dess präster och leviter, som är villig att fara till Jerusalem, må fara med dig,
Mo pàṣẹ pé ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi, ti ó wà ní abẹ́ ìṣàkóso ìjọba mi, tí ó bá fẹ́ láti bá ọ lọ sí Jerusalẹmu lè tẹ̀lé ọ lọ.
14 alldenstund du är sänd av konungen och hans sju rådgivare till att hålla undersökning om Juda och Jerusalem efter din Guds lag, som är i din hand,
Ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ̀ méjèèje rán ọ lọ láti wádìí nípa òfin Ọlọ́run rẹ tí ó wà ní ọwọ́ rẹ nípa Juda àti Jerusalẹmu.
15 och till att föra dit det silver och guld som konungen och hans rådgivare av fritt beslut hava givit åt Israels Gud, vilken har sin boning i Jerusalem,
Síwájú sí i, kí ìwọ kí ó kó fàdákà àti wúrà lọ pẹ̀lú rẹ èyí tí ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ fi tọkàntọkàn fún Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ibùjókòó rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu,
16 så ock allt det silver och guld som du kan få i hela Babels hövdingdöme, tillika med de frivilliga gåvor som folket och prästerna giva till sin Guds hus i Jerusalem.
pẹ̀lú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ìwọ lè rí ní agbègbè ìjọba Babeli àti àwọn ọrẹ àtinúwá àwọn ènìyàn àti ti àwọn àlùfáà fún tẹmpili Ọlọ́run wọn ní Jerusalẹmu.
17 Alltså skall du nu för dessa penningar såsom en redlig man köpa tjurar, vädurar och lamm, jämte sådant som behöves till dithörande spisoffer och drickoffer; och detta skall du offra på altaret i eder Guds hus i Jerusalem.
Pẹ̀lú owó yìí, rí i dájú pé ó ra àwọn akọ màlúù, àwọn àgbò àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, àti ọrẹ ohun mímu, kí ìwọ kí ó fi wọ́n rú ẹbọ lórí pẹpẹ tẹmpili Ọlọ́run rẹ ní Jerusalẹmu.
18 Och vad du och dina bröder finnen för gott att göra med det silver och guld som bliver över, det mån I göra efter eder Guds vilja.
Ìwọ àti àwọn Júù arákùnrin rẹ lè fi èyí tókù fàdákà àti wúrà ṣe ohunkóhun tí ó bá dára lójú yín, ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run yín.
19 Och alla de kärl som givas dig till tempeltjänsten i din Guds hus skall du avlämna inför Jerusalems Gud.
Kó gbogbo ohun èlò tí a fi sí ìkáwọ́ rẹ fún Ọlọ́run Jerusalẹmu fún ìsìn nínú tẹmpili Ọlọ́run rẹ.
20 Och vad du måste utbetala för det som härutöver behöves till din Guds hus, det må du låta utbetala ur konungens skattkammare.
Ohunkóhun mìíràn tí o bá nílò fún tẹmpili Ọlọ́run rẹ tí ó sì ní láti pèsè, o lè mú u láti inú ìṣúra ọba.
21 Och jag, konung Artasasta, giver härmed befallning till alla skattmästare i landet på andra sidan floden att allt vad prästen Esra, den i himmelens Guds lag lärde, begär av eder, det skall redligt göras och givas,
Èmi, ọba Artasasta, pàṣẹ fún gbogbo olùtọ́jú ilé ìṣúra agbègbè Eufurate láìrójú láti pèsè ohunkóhun tí àlùfáà Esra, olùkọ́ni ní òfin Ọlọ́run ọ̀run bá béèrè lọ́wọ́ yín
22 ända till hundra talenter silver, hundra korer vete, hundra bat vin och hundra bat olja, så ock salt utan särskild föreskrift.
tó ọgọ́rùn-ún kan tálẹ́ǹtì fàdákà, ọgọ́rùn-ún kan òsùwọ̀n àlìkámà, àti dé ọgọ́rùn-ún bati ọtí wáìnì, àti dé ọgọ́rùn-ún bati òróró olifi, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ iyọ̀.
23 Allt vad himmelens Gud befaller skall noggrant göras och givas till himmelens Guds hus, för att icke vrede må komma över konungens och hans söners rike.
Ohunkóhun tí Ọlọ́run ọ̀run bá fẹ́, jẹ́ kí ó di ṣíṣe ní pípé fún tẹmpili Ọlọ́run ọ̀run. Èéṣe tí ìbínú yóò ṣe wá sí agbègbè ọba àti sí orí àwọn ọmọ rẹ̀?
24 Och vi göra eder veterligt att ingen skall hava makt att lägga skatt, tull eller vägpenningar på någon präst eller levit, sångare, dörrvaktare, tempelträl eller annan tjänare i detta Guds hus.
Ìwọ sì ní láti mọ̀ pé ìwọ kò ní àṣẹ láti sọ sísan owó orí, owó òde tàbí owó bodè di dandan fún àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà, àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili tàbí àwọn òṣìṣẹ́ mìíràn nínú ilé Ọlọ́run yìí.
25 Och du, Esra, må, efter din Guds vishet, den som har blivit dig betrodd, förordna domare och lagkloke till att döma allt folket i landet på andra sidan floden, alla dem som känna din Guds lagar; och om någon icke känner dessa, skolen I lära honom dem.
Ìwọ Esra, ní ìbámu pẹ̀lú ọgbọ́n Ọlọ́run rẹ̀, èyí tí ó ní, yan àwọn adájọ́ àgbà àti àwọn onídàájọ́ láti máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ènìyàn agbègbè Eufurate, gbogbo àwọn tí ó mọ òfin Ọlọ́run rẹ. Ìwọ yóò sì kọ́ ẹnikẹ́ni tí kò mọ̀ àwọn òfin náà.
26 Och var och en som icke gör efter din Guds lag och konungens lag, över honom skall dom fällas med rättvisa, vare sig till död eller till landsförvisning eller till penningböter eller till fängelse."
Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣe ìgbọ́ràn sí òfin Ọlọ́run rẹ àti sí òfin ọba ní ó gbọdọ̀ kú tàbí kí a lé e jáde tàbí kí a gbẹ́sẹ̀ lé ẹrù rẹ̀ tàbí kí a sọ ọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.
27 Lovad vare HERREN, våra fäders Gud, som ingav konungen sådant i hjärtat, nämligen att han skulle förhärliga HERRENS hus i Jerusalem,
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ẹni tí ó fi sí ọkàn ọba láti mú ọlá wá sí ilé Olúwa ní Jerusalẹmu ní ọ̀nà yìí.
28 och som lät mig finna nåd inför konungen och hans rådgivare och inför alla konungens mäktiga hövdingar! Och jag kände mig frimodig, eftersom HERRENS, min Guds, hand var över mig, och jag församlade en del av huvudmännen i Israel till att draga upp med mig.
Ẹni tí ó jẹ́ kí ojúrere rẹ̀ tàn kàn mí níwájú ọba àti àwọn olùbádámọ̀ràn àti ní iwájú àwọn alágbára ìjòyè ọba. Nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára mi, mo mú ọkàn le, mo sì kó àwọn olórí jọ láàrín àwọn ènìyàn Israẹli láti gòkè lọ pẹ̀lú mi.

< Esra 7 >