< Nehemja 1 >

1 Nehemjas, Hakaljas sons, berättelse. I månaden Kisleu, i det tjugonde året, när jag var i Susans borg,
Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah. Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa,
2 hände sig att Hanani, en av mina bröder, och några andra män kommo från Juda. Och jag frågade dem om judarna, den räddade skara som fanns kvar efter fångenskapen, och om Jerusalem.
Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.
3 De sade till mig: "De kvarblivna, de som efter fångenskapen finnas kvar i hövdingdömet, lida stor nöd och smälek, och Jerusalems mur är nedbruten, och dess portar äro uppbrända i eld."
Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”
4 När jag hade hört detta, satt jag gråtande och sörjande i flera dagar och fastade och bad inför himmelens Gud.
Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run.
5 Och jag sade: "Ack HERRE, himmelens Gud, du store och fruktansvärde Gud, du som håller förbund och bevarar nåd mot dem som älska dig och hålla dina bud,
Nígbà náà ni mo wí pé: “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́.
6 låt ditt öra akta härpå, och låt dina ögon vara öppna, och hör din tjänares bön, den som jag nu beder inför dig både dag och natt, för Israels barn, dina tjänare, i det att jag bekänner Israels barns synder, dem som vi hava begått mot dig; ty också jag och min faders hus hava syndat.
Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ.
7 Vi hava svårt förbrutit oss mot dig; vi hava icke hållit de bud och stadgar och rätter som du gav din tjänare Mose.
Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.
8 Men tänk på det ord som du gav din tjänare Mose, när du sade: 'Om I ären otrogna, så skall jag förströ eder bland folken;
“Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
9 men om I vänden om till mig och hållen mina bud och gören efter dem, då vill jag, om än edra fördrivna vore vid himmelens ända, likväl församla dem därifrån och låta dem komma till den plats som jag har utvalt till boning åt mitt namn.'
Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’
10 De äro ju dina tjänare och ditt folk, som du har förlossat genom din stora kraft och din starka hand.
“Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ.
11 Ack Herre, låt ditt öra akta på din tjänares bön, ja, på vad dina tjänare bedja, de som vilja frukta ditt namn; låt nu din tjänare vara lyckosam och låt honom finna barmhärtighet inför denne man." Jag var då munskänk hos konungen.
Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì síjú àánú wò ó níwájú ọkùnrin yìí.” Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.

< Nehemja 1 >