< Jeremija 46 >

1 Beseda od Gospoda, ki je prišla preroku Jeremiju zoper pogane;
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa àwọn Orílẹ̀-èdè.
2 zoper Egipt, zoper vojsko faraona Nehota, egiptovskega kralja, ki je bil pri reki Evfratu v Kárkemišu, ki ga je babilonski kralj Nebukadnezar udaril v četrtem letu Jojakíma, Jošíjevega sina, Judovega kralja.
Nípa Ejibiti. Èyí ni ọ̀rọ̀ nípa àwọn ọmọ-ogun Farao Neko ọba Ejibiti ẹni tí a borí rẹ̀ ní Karkemiṣi, ní odò Eufurate láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda:
3 »›Pripravite majhen ščit in ščit ter se približajte boju.
“Ẹ múra àpáta, èyí tí ó tóbi, àti èyí tí ó kéré, kí ẹ sì súnmọ́ ojú ìjà!
4 Vprezite konje in vstanite, vi konjeniki in postavite se s svojimi čeladami; zgladite sulice in si nadenite oklepe.
Ẹ di ẹṣin ní gàárì, kí ẹ sì gùn ún. Ẹ dúró lẹ́sẹẹsẹ pẹ̀lú àṣíborí yín! Ẹ dán ọ̀kọ̀ yín, kí ẹ sì wọ ẹ̀wù irin.
5 Zakaj sem jih videl zaprepadene in obrnjene nazaj? In njihovi mogočni so potolčeni in so naglo zbežali in niso gledali nazaj, kajti strah je bil naokoli, ‹ govori Gospod.
Kí ni nǹkan tí mo tún rí? Wọ́n bẹ̀rù, wọ́n sì ń padà sẹ́yìn, wọ́n ti ṣẹ́gun àwọn jagunjagun. Wọ́n sá, wọn kò sì bojú wẹ̀yìn, ìbẹ̀rù sì wà níbi gbogbo,” ni Olúwa wí.
6 ›Ne dopusti, da hitri izgine niti da mogočni človek pobegne; opotekali se bodo in padali proti severu, pri reki Evfratu.
“Ẹni tí ó yára kì yóò le sálọ, tàbí alágbára kò ní lè sá àsálà. Ní àríwá ní ibi odò Eufurate wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.
7 Kdo je ta, ki prihaja gor kakor poplava, katerega vode se premikajo kakor reke?‹
“Ta ni èyí tí ó gòkè wá bí odò Ejibiti, tí omi rẹ̀ ń ru gẹ́gẹ́ bí odò wọ̀n-ọn-nì?
8 Egipt se vzdiguje kakor poplava in njegove vode se premikajo kakor reke; in pravi: ›Šel bom gor in pokril zemljo, uničil bom mesto in njegove prebivalce.
Ejibiti dìde bí odò náà, bí omi odò tí ń ru. Ó sì wí pé, ‘Èmi yóò dìde, n ó sì bo gbogbo ilẹ̀ ayé.’ Èmi yóò pa ìlú àti àwọn ènìyàn rẹ̀ run.
9 Pridite gor, vi konji; in besnite, vi bojni vozovi in naj mogočni možje pridejo naprej. Etiopijci in Libijci, ki prijemajo ščit; in Ludéjci, ki prijemajo in napenjajo lok.
Ẹ gòkè wá ẹ̀yin ẹṣin, ẹ sì sáré kíkankíkan ẹ̀yin kẹ̀kẹ́. Kí àwọn alágbára túbọ̀ tẹ̀síwájú, àwọn ará Kuṣi àti àwọn ará Puti tí ń di asà mú; àti àwọn ará Lidia tí ń fa ọrun.
10 Kajti to je dan Gospoda Boga nad bojevniki, dan maščevanja, da se lahko maščuje svojim nasprotnikom in meč bo požiral in ta bo nasičen in opijanjen z njihovo krvjo, kajti Gospod Bog nad bojevniki ima klavno daritev v severni deželi, pri reki Evfratu.
Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà jẹ́ ti Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ọjọ́ ìgbẹ̀san, ìgbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀. Idà yóò sì jẹ́ títí yóò fi ní ìtẹ́lọ́rùn, títí yóò fi pa òǹgbẹ rẹ̀ rẹ́ pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀. Nítorí pé Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò rú ẹbọ ní ilẹ̀ gúúsù ní odò Eufurate.
11 Pojdi gor v Gileád in vzemi balzam, oh devica, egiptovska hči. Zaman boš uporabljala mnoga zdravila, kajti ne boš ozdravljena.
“Gòkè lọ sí Gileadi, kí o sì mú ìkunra, ìwọ wúńdíá ọmọbìnrin Ejibiti. Ṣùgbọ́n ní asán ni ìwọ ń lo oògùn, kì yóò sí ìwòsàn fún ọ.
12 Narodi so slišali o tvoji sramoti in tvoje vpitje je napolnilo deželo, kajti mogočen človek se je spotaknil zoper mogočnega in oba skupaj sta padla.‹«
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbọ́ nípa ìtìjú rẹ, igbe rẹ yóò kún gbogbo ayé. Jagunjagun yóò máa ṣubú lu ara wọn lórí rẹ, àwọn méjèèjì yóò sì jọ ṣubú papọ̀.”
13 Beseda, ki jo je Gospod spregovoril preroku Jeremiju, kako bo babilonski kralj Nebukadnezar prišel in udaril egiptovsko deželo.
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó bá Jeremiah wòlíì nì sọ nípa wíwá Nebukadnessari ọba Babeli láti lọ dojú ìjà kọ Ejibiti:
14 ›Oznanite v Egiptu, razglasite v Migdólu, razglasite v Nofu in v Tahpanhésu, recite: ›Stoj trdno in se pripravi, kajti meč bo požiral okoli tebe.
“Kéde èyí ní Ejibiti, sì sọ ọ́ ní Migdoli, sọ ọ́ ní Memfisi àti Tafanesi: ‘Dúró sí ààyè rẹ kí o sì múra sílẹ̀, nítorí pé idà náà ń pa àwọn tí ó yí ọ ká.’
15 Zakaj so tvoji hrabri možje pometeni proč? Niso obstali, ker jih je Gospod pognal.
Èéṣe tí àwọn akọni rẹ fi ṣubú? Wọn kò ní le dìde dúró, nítorí Olúwa yóò tì wọ́n ṣubú.
16 Mnoge je pripravil, da padejo, da, eden je padel na drugega. Rekli so: ›Vstanimo in ponovno pojdimo k svojemu ljudstvu in k deželi svojega rojstva, proč od zatiralskega meča.‹
Wọn yóò máa ṣubú léraléra wọn yóò máa ṣubú lu ara wọn. Wọn yóò sọ wí pé, ‘Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn wa àti ilẹ̀ ìbí wa, kúrò níbi idà àwọn aninilára.’
17 Tam so vpili: ›Faraon, egiptovski kralj, je samo hrup; zamudil je določeni čas.‹
Níbẹ̀ ni wọn ó kígbe pé, ‘Ariwo lásán ni Farao ọba Ejibiti pa, ó ti sọ àǹfààní rẹ̀ nù.’
18 › Kakor jaz živim, ‹ govori Kralj, čigar ime je Gospod nad bojevniki: ›Zagotovo, kakor je Tabor med gorami in kakor Karmel pri morju, tako bo on prišel.
“Bí èmi ti wà láààyè,” ni ọba, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Nítòótọ́ gẹ́gẹ́ bí Tabori láàrín àwọn òkè àti gẹ́gẹ́ bi Karmeli lẹ́bàá Òkun bẹ́ẹ̀ ni òun yóò dé.
19 Oh ti hči, prebivajoča v Egiptu, oskrbi se, da greš v ujetništvo, kajti Nof bo opustošen in zapuščen, brez prebivalca.
Ìwọ, ọmọbìnrin ti ń gbé Ejibiti pèsè ohun èlò ìrìnàjò fún ara rẹ nítorí Memfisi yóò di ahoro a ó sì fi jóná, láìní olùgbé.
20 Egipt je podoben zelo lepi telici, toda uničenje prihaja; to prihaja iz severa.
“Ẹgbọrọ abo màlúù tó lẹ́wà ní Ejibiti ṣùgbọ́n eṣinṣin ìparun dé, ó dé láti àríwá.
21 Prav tako so njegovi najeti možje v njegovi sredi podobni pitanim bikcem; kajti obrnjeni so tudi nazaj in skupaj so pobegnili proč; niso obstali, ker je nadnje prišel dan njihove katastrofe in čas njihovega obiskanja.
Àwọn jagunjagun rẹ̀ dàbí àbọ́pa akọ màlúù. Àwọn pẹ̀lú yóò yípadà, wọn ó sì jùmọ̀ sá, wọn kò ní le dúró, nítorí tí ọjọ́ ibi ń bọ̀ lórí wọn àsìkò láti jẹ wọ́n ní ìyà.
22 Njihov glas bo šel kakor kača; kajti korakali bodo z vojsko in zoper njega bodo prišli s sekirami kakor drvarji.
Ejibiti yóò pòṣé bí ejò tí ń sá bí ọmọ-ogun ṣe ń tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú agbára. Wọn ó tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú àáké, gẹ́gẹ́ bí i ti agégi.
23 Posekali bodo njegov gozd, ‹ govori Gospod, ›čeprav ta ne more biti preiskan, ker jih je več kakor kobilic in so brezštevilni.
Wọn o gé igbó rẹ̀ lulẹ̀,” ni Olúwa wí, “nítorí ti a kò le rídìí rẹ̀. Nítorí pé wọ́n pọ̀ ju ẹlẹ́ǹgà lọ, wọ́n sì jẹ́ àìníye.
24 Egiptovska hči bo zbegana; izročena bo v roko severnega ljudstva.‹
A ó dójútì ọmọbìnrin Ejibiti, a ó fà á lé ọwọ́ àwọn ènìyàn àríwá.”
25 Gospod nad bojevniki, Izraelov Bog, pravi: ›Glejte, kaznoval bom množico iz Noja in faraona in Egipt z njihovimi bogovi in njihovimi kralji, celo faraona in vse tiste, ki zaupajo vanj.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí pé: “Èmi yóò rọ̀jò ìyà mi sórí Amoni òrìṣà Tebesi, sórí Farao, sórí Ejibiti àti àwọn òrìṣà rẹ̀ àti sórí àwọn ọba rẹ̀ àti sórí àwọn tó gbẹ́kẹ̀lé Farao.
26 Izročil jih bom v roko tistih, ki jim strežejo po življenju, v roko babilonskega kralja Nebukadnezarja in v roko njegovih služabnikov. Potem bo ta naseljen kakor v dneh davnine, ‹ govori Gospod.
Èmi ó sì fi wọ́n lé àwọn tó wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́, lé Nebukadnessari ọba Babeli, ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Ejibiti yóò sì di gbígbé bí i ti àtijọ́,” ni Olúwa wí.
27 ›Vendar se ne boj, oh moj služabnik Jakob in ne bodi zaprepaden, oh Izrael, kajti glej, rešil te bom od daleč in tvoje seme iz dežele njihovega ujetništva. Jakob se bo vrnil in bo počival in bo sproščen in nihče ga ne bo naredil prestrašenega.
“Má bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má fòyà, ìwọ Israẹli. Dájúdájú èmi ó gbà ọ́ láti ọ̀nà jíjìn, àwọn ọmọ ọmọ rẹ ní ilẹ̀ ìgbèkùn. Jakọbu yóò tún ní àlàáfíà àti ààbò, kò sì ṣí ẹni tí yóò dẹ́rùbà á.
28 Ne boj se, Jakob, moj služabnik, ‹ govori Gospod, ›kajti jaz sem s teboj, kajti naredil bom popoln konec vseh narodov, kamor sem te pognal. Toda iz tebe ne bom naredil popolnega konca, temveč te bom grajal po meri; vendar te ne bom pustil v celoti nekaznovanega.‹«
Má bẹ̀rù, Jakọbu ìránṣẹ́ mi, nítorí pé mo wà pẹ̀lú rẹ,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, láàrín àwọn tí mo fọ́n yín ká sí. Èmi kò ní run yín tán. Èmi yóò jẹ ọ́ ní ìyà lórí òdodo, èmi kí yóò jọ̀wọ́ rẹ lọ́wọ́ lọ láìjẹ ọ́ ní yà.”

< Jeremija 46 >